< 2 Chronicles 30 >

1 Hesekiah sì ránṣẹ́ sí gbogbo Israẹli àti Juda, ó sì kọ ìwé sí Efraimu àti Manase, kí wọn kí ó wá sínú ilé Olúwa ní Jerusalẹmu láti pa àjọ ìrékọjá mọ́ sí Olúwa Ọlọ́run Israẹli.
És küldött Jechizkijáhú egész Izraelhez s Jehúdához, s leveleket is írt Efraimhoz s Menasséhez, hogy jöjjenek el az Örökkévaló házába Jeruzsálemben, megtartani a pészachot az Örökkévalónak, Izrael Istenének.
2 Nítorí tí ọba ti gbìmọ̀ àti àwọn ìjòyè rẹ̀, àti gbogbo ìjọ ènìyàn ní Jerusalẹmu, láti pa àjọ ìrékọjá mọ́ ní oṣù kejì.
És elhatározta a király meg nagyjai s az egész gyülekezet Jeruzsálemben, hogy megtartják a pészachot a második hónapban.
3 Nítorí wọn kò lè pa á mọ́ ní àkókò náà, nítorí àwọn àlùfáà kò tí i ya ara wọn sí mímọ́ tó; bẹ́ẹ̀ ni àwọn ènìyàn kò tí ì kó ara wọn jọ sí Jerusalẹmu.
Mert nem tudták megtartani abban az időben, mivelhogy a papok nem szentelték meg magukat elegendő számban s a nép nem gyűlt volt össze Jeruzsálembe.
4 Ọ̀rọ̀ náà sí tọ́ lójú ọba àti lójú gbogbo ìjọ ènìyàn.
És helyesnek tetszett a dolog a király szemeiben s az egész gyülekezet szemeiben.
5 Bẹ́ẹ̀ ni wọ́n fi àṣẹ kan lélẹ̀, láti kéde ká gbogbo Israẹli láti Beerṣeba àní títí dé Dani, láti wá pa àjọ ìrékọjá mọ́ sí Olúwa Ọlọ́run Israẹli ní Jerusalẹmu: nítorí wọn kò pa á mọ́ ní ọjọ́ púpọ̀ gẹ́gẹ́ bí a ti kọ ọ́.
És megállapították, hogy hírt vigyenek szét egész Izraelben Beér-Sébától Dánig, hogy jöjjenek a pészachot megtartani az Örökkévalónak, Izrael Istenének. Jeruzsálemben, mert nem sokaságban tartották meg, amint írva van.
6 Bẹ́ẹ̀ àwọn oníṣẹ́ tí ń sáré lọ pẹ̀lú ìwé láti ọwọ́ ọba àti àwọn ìjòyè rẹ̀ sí gbogbo Israẹli àti Juda; àti gẹ́gẹ́ bí àṣẹ ọba, wí pé, “Ẹ̀yin ọmọ Israẹli ẹ yí padà sí Olúwa Ọlọ́run Abrahamu, Isaaki, àti Israẹli, òun ó sì yípadà sí àwọn ìyókù nínú yín, tí ó sálà kúrò lọ́wọ́ àwọn ọba Asiria.
És elmentek a futárok a király s nagyjai kezéből való levelekkel egész Izraelbe s Jehúdába s a király parancsa szerint mondván: Izrael fiai, térjetek vissza az Örökkévalóhoz, Ábrahám, Izsák s Izrael Istenéhez, hogy odaforduljon a maradékhoz, amely megmaradt közületek Assúr királyai kezéből.
7 Kí ẹ̀yin kí ó má sì ṣe dàbí àwọn baba yín, àti bí àwọn arákùnrin yín tí ó dẹ́ṣẹ̀ sí Olúwa, Ọlọ́run àwọn baba wọn, nítorí náà ní ó ṣe fi wọ́n fún ìdahoro bí ẹ̀yin ti rí.
És ne legyetek olyanok, mint őseitek s mint testvéreitek, akik hűtlenkedtek az Örökkévaló, őseik Istene ellen, s tette őket iszonyattá, amint látjátok.
8 Ǹjẹ́ kí ẹ̀yin kí ó má ṣe ṣe ọlọ́rùn líle, bí àwọn baba yín, ṣùgbọ́n ẹ jọ̀wọ́ ara yín lọ́wọ́ fún Olúwa, kí ẹ sì wọ inú ibi mímọ́ rẹ̀ lọ, ti òun ti ìyàsímímọ́ títí láé. Kí ẹ sì sin Olúwa, Ọlọ́run yín kí gbígbóná ìbínú rẹ̀ kí ó lè yípadà kúrò ní ọ̀dọ̀ yín.
Már most ne keményítsétek meg nyakatokat, mint őseitek; adjatok kezet az Örökkévalónak s gyertek az ő szentélyébe, amelyet örökre megszentelt, s szolgáljátok az Örökkévalót a ti Istenteket, hogy elforduljon tőletek az ő föllobbant haragja.
9 Nítorí bí ẹ̀yin bá tún yípadà sí Olúwa, àwọn arákùnrin yín, àti àwọn ọmọ yín, yóò rí àánú níwájú àwọn tí ó kó wọn ní ìgbèkùn lọ, kí wọn kí ó lè tún padà wá sí ilẹ̀ yí: nítorí Olúwa Ọlọ́run yín, oníyọnu àti aláàánú ni, kì yóò sì yí ojú rẹ̀ padà kúrò lọ́dọ̀ yín, bí ẹ̀yin bá padà sọ́dọ̀ rẹ̀.”
Mert ha visszatértek az Örökkévalóhoz, testvéreitek s fiaitok irgalomra lesznek foglyul-ejtőik előtt s visszatérnek ebbe az országba, mert könyörületes s irgalmas az Örökkévaló, a ti Istentek, s el nem fordítja arcát tőletek, ha visszatértek hozzá.
10 Bẹ́ẹ̀ ni àwọn oníṣẹ́ náà kọjá láti ìlú dé ìlú, ní ilẹ̀ Efraimu àti Manase títí dé Sebuluni, ṣùgbọ́n wọ́n fi wọ́n rẹ́rìn-ín ẹlẹ́yà, wọ́n sì gàn wọ́n.
De midőn a futárok vonultak városról városra Efraim s Menasse országában egészen Zebúlúnig, nevettek rajtuk s kigúnyolták őket.
11 Síbẹ̀ òmíràn nínú àwọn ènìyàn Aṣeri àti Manase àti Sebuluni rẹ̀ ara wọn sílẹ̀, wọ́n sì wá sí Jerusalẹmu.
Csak némelyek Ásérből, Menasseből és Zebúlúnból megalázkodtak s eljöttek Jeruzsálembe.
12 Ní Juda pẹ̀lú, ọwọ́ Ọlọ́run wá láti fún wọn ní ọkàn kan láti pa òfin ọba mọ́ àti tí àwọn ìjòyè, nípa ọ̀rọ̀ Olúwa.
Jehúdán is volt az Istennek keze; adva nekik szívet, hogy megtegyék a király s a nagyok parancsát az Örökkévaló igéje szerint.
13 Ọ̀pọ̀lọpọ̀ ènìyàn sì péjọ ní Jerusalẹmu, láti pa àjọ àkàrà àìwú mọ́ ní oṣù kejì.
És sok nép gyülekezett Jeruzsálembe, hogy megtartsák a kovásztalan kenyerek ünnepét a második hónapban, fölötte számos gyülekezet.
14 Wọ́n sì dìde, wọ́n sì kó gbogbo pẹpẹ tí ó wà ní Jerusalẹmu lọ, àti gbogbo pẹpẹ tùràrí ni wọ́n kó lọ, wọ́n sì dà wọ́n sí odò Kidironi.
És fölkeltek s eltávolították az oltárokat, amelyek Jeruzsálemben voltak, s mind a füstölőket eltávolították s bedobták a Kidrón patakjába.
15 Nígbà náà ni wọ́n pa ẹran ìrékọjá náà ní ọjọ́ kẹrìnlá oṣù kejì: ojú sì ti àwọn àlùfáà àti àwọn ọmọ Lefi, wọ́n sì yà ara wọn sí mímọ́, wọ́n sì mú ẹbọ sísun wá sínú ilé Olúwa.
És levágták a pészacháldozatot a második hónap tizennegyedikén, és a papok s leviták szégyenkeztek volt és megszentelték magukat s bemutattak égőáldozatokat az Örökkévaló házában.
16 Wọ́n sì dúró ní ipò wọn, bí ètò wọn gẹ́gẹ́ bí òfin Mose, ènìyàn Ọlọ́run: àwọn àlùfáà wọ́n ẹ̀jẹ̀ náà, tí wọ́n gbà lọ́wọ́ àwọn ọmọ Lefi.
És álltak állásukon rendjük szerint, Mózes az Isten emberének tana szerint; a papok hintették a vért a leviták kezéből.
17 Nítorí pé ọ̀pọ̀lọpọ̀ ni ó wà nínú ìjọ ènìyàn náà tí kò yà ara wọn sí mímọ́: nítorí náà ni àwọn ọmọ Lefi ṣe ń tọ́jú àti pa ẹran ìrékọjá fún olúkúlùkù ẹni tí ó ṣe aláìmọ́, láti yà á sí mímọ́ sí Olúwa.
Mert sokan voltak a gyülekezetben, akik nem szentelték meg magukat, tehát a leviták voltak a pészacháldozatok levágásánál minden nem tiszta helyett, hogy megszenteljék az Örökkévalónak.
18 Ọ̀pọ̀lọpọ̀ ènìyàn, àní ọ̀pọ̀lọpọ̀ nínú Efraimu àti Manase, Isakari, àti Sebuluni kò sá wẹ̀ ara wọn mọ́ síbẹ̀ wọ́n jẹ ìrékọjá náà, kì í ṣe gẹ́gẹ́ bí a ti kọ ọ́. Ṣùgbọ́n Hesekiah bẹ̀bẹ̀ fún wọn, wí pé, Olúwa, ẹni rere, dáríjì olúkúlùkù,
Mert sokasága a népnek, sokan Efráimból meg Menasséből, Jisszákhárból s Zebúlúnból nem tisztálkodtak, hanem ették a pészacháldozatot nem előírás szerint; hanem Jechízkijáhú imádkozott értük, mondván: az Örökkévaló, a jóságos, engesztelést ad
19 tí ó múra ọkàn rẹ̀ láti wá Ọlọ́run, Olúwa Ọlọ́run àwọn baba rẹ̀ ṣùgbọ́n tí kì í ṣe nípa ìwẹ̀nùmọ́ mímọ́
mindenkiért, aki megszilárdította szívét, hogy keresse az Istent, az Örökkévalót, ősei Istenét, ha nem is a szentség tisztasága szerint.
20 Olúwa sì gbọ́ ti Hesekiah, ó sì mú àwọn ènìyàn náà láradá.
És hallgatott az Örökkévaló Jechizkijáhúra s meggyógyította a népet.
21 Àwọn ọmọ Israẹli tí a rí ní Jerusalẹmu fi ayọ̀ ńlá pa àjọ àkàrà àìwú mọ́ ní ọjọ́ méje: àwọn ọmọ Lefi, àti àwọn àlùfáà yin Olúwa lójoojúmọ́, wọ́n ń fi ohun èlò olóhùn gooro kọrin sí Olúwa.
És megtartották Izrael fiai, akik találtattak Jeruzsálemben, a kovásztalan kenyerek ünnepét hét napig nagy örömmel, s dicsérték az Örökkévalót nap-nap után a leviták s a papok hatalmas hangszerekkel az Örökkévalónak.
22 Hesekiah sọ̀rọ̀ ìtùnú fún gbogbo àwọn ọmọ Lefi, tí ó lóye ní ìmọ̀ rere Olúwa: ọjọ́ méje ni wọ́n fi jẹ àsè náà wọ́n rú ẹbọ àlàáfíà, wọ́n sì ń fi ohùn rara dúpẹ́ fún Olúwa, Ọlọ́run àwọn baba wọn.
És szívére szólt Jechizkijáhú mind a levitáknak, akik igazi eszességet tanúsítottak az Örökkévaló iránt, s ették az ünnepi kenyeret hét napig, áldozva békeáldozatokat s vallomást téve az Örökkévalónak, őseik Istenének.
23 Gbogbo ìjọ náà sì gbìmọ̀ láti pa ọjọ́ méje mìíràn mọ́: wọ́n sì fi ayọ̀ pa ọjọ́ méje mìíràn mọ́.
És elhatározta az egész gyülekezet, hogy megtart más hét napot; s tartottak hét napot örömben.
24 Nítorí Hesekiah, ọba Juda, ta ìjọ ènìyàn náà ní ọrẹ, ẹgbẹ̀rún akọ màlúù, àti ẹ̀ẹ́dẹ́gbàárin àgùntàn. Ọ̀pọ̀lọpọ̀ nínú àwọn àlùfáà sì ya ara wọn sí mímọ́.
Mert Chizkijáhú, Jehúdah királya adományozott a gyülekezet részére ezer tulkot s hétezer juhot, s a nagyok adományoztak a gyülekezet részére ezer tulkot s tízezer juhot; és a papok megszentelték magukat sokaságban.
25 Gbogbo ìjọ ènìyàn Juda pẹ̀lú àwọn àlùfáà àti àwọn ọmọ Lefi, àti gbogbo ìjọ ènìyàn tí ó ti inú Israẹli jáde wá, àti àwọn àjèjì tí ó ti ilẹ̀ Israẹli jáde wá, àti àwọn tí ń gbé Juda yọ̀.
És örült Jehúda egész gyülekezete, meg a papok és a leviták, meg az egész gyülekezet, amely Izraelből jött, s a jövevények, akik Izrael országából jöttek, s akik Jehúdában laktak.
26 Bẹ́ẹ̀ ni ayọ̀ ńlá sì wà ní Jerusalẹmu: nítorí láti ọjọ́ Solomoni, ọmọ Dafidi, ọba Israẹli, irú èyí kò sí ní Jerusalẹmu.
És volt nagy öröm Jeruzsálemben, mert Salamonnak, Dávid fiának, Izrael királyának napjai óta nem volt ilyesmi Jeruzsálemben.
27 Nígbà náà ni àwọn àlùfáà, àwọn ọmọ Lefi dìde, wọ́n sì súre fún àwọn ènìyàn náà: a sì gbọ́ ohùn wọn, àdúrà wọn sì gòkè lọ si ibùgbé mímọ́ rẹ̀, àní sí ọ̀run.
És fölkeltek a papok, a leviták, s megáldották a népet; és szavuk meghallgatásra talált s eljutott az imádságuk az ő szent lakába, az égbe.

< 2 Chronicles 30 >