< 2 Chronicles 30 >

1 Hesekiah sì ránṣẹ́ sí gbogbo Israẹli àti Juda, ó sì kọ ìwé sí Efraimu àti Manase, kí wọn kí ó wá sínú ilé Olúwa ní Jerusalẹmu láti pa àjọ ìrékọjá mọ́ sí Olúwa Ọlọ́run Israẹli.
Hezekiah loh Israel pum neh Judah a tah tih Ephraim neh Manasseh ham khaw Jerusalem kah BOEIPA im la a mop ham neh, Israel Pathen BOEIPA taengah Yoom saii ham te ca a daek pah.
2 Nítorí tí ọba ti gbìmọ̀ àti àwọn ìjòyè rẹ̀, àti gbogbo ìjọ ènìyàn ní Jerusalẹmu, láti pa àjọ ìrékọjá mọ́ ní oṣù kejì.
A hla bae dongah tah Yoom saii hamla manghai khaw, a mangpa rhoek khaw, Jerusalem kah hlangping boeih khaw a thui uh.
3 Nítorí wọn kò lè pa á mọ́ ní àkókò náà, nítorí àwọn àlùfáà kò tí i ya ara wọn sí mímọ́ tó; bẹ́ẹ̀ ni àwọn ènìyàn kò tí ì kó ara wọn jọ sí Jerusalẹmu.
Tedae Yoom te te vaeng tue ah saii hamla noeng uh pawh. Khosoih rhoek khaw a rhoeh hil ciim uh hlan tih pilnam khaw Jerusalem ah tingtun hlan.
4 Ọ̀rọ̀ náà sí tọ́ lójú ọba àti lójú gbogbo ìjọ ènìyàn.
Te vaengah ol he manghai mikhmuh ah khaw, hlangping boeih kah mikhmuh ah khaw dueng ngawn.
5 Bẹ́ẹ̀ ni wọ́n fi àṣẹ kan lélẹ̀, láti kéde ká gbogbo Israẹli láti Beerṣeba àní títí dé Dani, láti wá pa àjọ ìrékọjá mọ́ sí Olúwa Ọlọ́run Israẹli ní Jerusalẹmu: nítorí wọn kò pa á mọ́ ní ọjọ́ púpọ̀ gẹ́gẹ́ bí a ti kọ ọ́.
A daek bangla a saii uh dae a cungkuem uh pawt dongah, Israel Pathen BOEIPA kah Yoom saii vaengah tah Jerusalem la mop sak ham, Israel pum ah, Beersheba lamloh Dan duela olthang pat ham ol a cak sakuh.
6 Bẹ́ẹ̀ àwọn oníṣẹ́ tí ń sáré lọ pẹ̀lú ìwé láti ọwọ́ ọba àti àwọn ìjòyè rẹ̀ sí gbogbo Israẹli àti Juda; àti gẹ́gẹ́ bí àṣẹ ọba, wí pé, “Ẹ̀yin ọmọ Israẹli ẹ yí padà sí Olúwa Ọlọ́run Abrahamu, Isaaki, àti Israẹli, òun ó sì yípadà sí àwọn ìyókù nínú yín, tí ó sálà kúrò lọ́wọ́ àwọn ọba Asiria.
Manghai neh a mangpa rhoek kut dongkah ca aka yong puei rhoek tah Judah neh Israel pum ah cet uh tih manghai olpaek bangla, “Israel ca rhoek aw, Abraham, Isaak, Israel Pathen BOEIPA taengla mael uh laeh. Te daengah ni nangmih aka sueng rhoek te Assyria manghai kut lamloh loeihnah la a mael eh.
7 Kí ẹ̀yin kí ó má sì ṣe dàbí àwọn baba yín, àti bí àwọn arákùnrin yín tí ó dẹ́ṣẹ̀ sí Olúwa, Ọlọ́run àwọn baba wọn, nítorí náà ní ó ṣe fi wọ́n fún ìdahoro bí ẹ̀yin ti rí.
A napa rhoek kah Pathen BOEIPA taengah boe aka koek na pa rhoek neh na manuca rhoek bangla om uh boeh. Te dongah amih te na hmuh uh bangla imsuep la a khueh.
8 Ǹjẹ́ kí ẹ̀yin kí ó má ṣe ṣe ọlọ́rùn líle, bí àwọn baba yín, ṣùgbọ́n ẹ jọ̀wọ́ ara yín lọ́wọ́ fún Olúwa, kí ẹ sì wọ inú ibi mímọ́ rẹ̀ lọ, ti òun ti ìyàsímímọ́ títí láé. Kí ẹ sì sin Olúwa, Ọlọ́run yín kí gbígbóná ìbínú rẹ̀ kí ó lè yípadà kúrò ní ọ̀dọ̀ yín.
Tahae atah na pa rhoek bangla na rhawn te mangkhak sak uh boeh. BOEIPA taengah kut duen uh laeh. Kumhal hamla a ciim tangtae a rhokso kungla ha mop uh lamtah na Pathen BOEIPA taengah thothueng uh. Te daengah ni a thintoek thinsa te nangmih taeng lamloh a mael eh.
9 Nítorí bí ẹ̀yin bá tún yípadà sí Olúwa, àwọn arákùnrin yín, àti àwọn ọmọ yín, yóò rí àánú níwájú àwọn tí ó kó wọn ní ìgbèkùn lọ, kí wọn kí ó lè tún padà wá sí ilẹ̀ yí: nítorí Olúwa Ọlọ́run yín, oníyọnu àti aláàánú ni, kì yóò sì yí ojú rẹ̀ padà kúrò lọ́dọ̀ yín, bí ẹ̀yin bá padà sọ́dọ̀ rẹ̀.”
BOEIPA taengla na mael uh mak atah na manuca rhoek neh na ca rhoek khaw, amih aka sol rhoek kah mikhmuh ah haidamnah la, te phoeiah he khohmuen la ha mael ni. Nangmih kah Pathen BOEIPA tah lungvatnah neh thinphoei la a om dongah a taengla na mael uh atah nangmih taeng lamloh maelhmai mangthong mahpawh,” a ti nah.
10 Bẹ́ẹ̀ ni àwọn oníṣẹ́ náà kọjá láti ìlú dé ìlú, ní ilẹ̀ Efraimu àti Manase títí dé Sebuluni, ṣùgbọ́n wọ́n fi wọ́n rẹ́rìn-ín ẹlẹ́yà, wọ́n sì gàn wọ́n.
Te phoeiah ca thak la aka om rhoek te khopuei lamloh khopuei khat hil, Ephraim neh Manasseh khohmuen neh Zebulun duela cet uh. Tedae amih aka nueih thil neh amih aka tamdaeng la om uh.
11 Síbẹ̀ òmíràn nínú àwọn ènìyàn Aṣeri àti Manase àti Sebuluni rẹ̀ ara wọn sílẹ̀, wọ́n sì wá sí Jerusalẹmu.
Te cakhaw Asher lamkah, Manasseh neh Zebulun lamkah hlang rhoek tah kunyun uh tih Jerusalem la pawk uh.
12 Ní Juda pẹ̀lú, ọwọ́ Ọlọ́run wá láti fún wọn ní ọkàn kan láti pa òfin ọba mọ́ àti tí àwọn ìjòyè, nípa ọ̀rọ̀ Olúwa.
BOEIPA ol dongah manghai neh mangpa rhoek olpaek te vai sak ham, amih te lungbuei pakhat la khueh sak ham te Pathen kah kut tah Judah ah om bal coeng.
13 Ọ̀pọ̀lọpọ̀ ènìyàn sì péjọ ní Jerusalẹmu, láti pa àjọ àkàrà àìwú mọ́ ní oṣù kejì.
A hla bae dongah tah vaidamding khotue te saii hamla pilnam loh Jerusalem ah muep tingtun uh tih hlangping khaw muep cungkuem uh.
14 Wọ́n sì dìde, wọ́n sì kó gbogbo pẹpẹ tí ó wà ní Jerusalẹmu lọ, àti gbogbo pẹpẹ tùràrí ni wọ́n kó lọ, wọ́n sì dà wọ́n sí odò Kidironi.
Te dongah thoo uh tih Jerusalem kah hmueihtuk te a khoe uh. Hlupnah hnopai boeih te khaw a khoe uh tih Kidron soklong la a voeih uh.
15 Nígbà náà ni wọ́n pa ẹran ìrékọjá náà ní ọjọ́ kẹrìnlá oṣù kejì: ojú sì ti àwọn àlùfáà àti àwọn ọmọ Lefi, wọ́n sì yà ara wọn sí mímọ́, wọ́n sì mú ẹbọ sísun wá sínú ilé Olúwa.
A hla bae dongkah hnin hlai li vaengah tah Yoom te a ngawn uh. Te vaengah khosoih rhoek neh Levi rhoek tah a hmaithae uh. Te dongah a ciim uh phoeiah hmueihhlutnah te BOEIPA im la a khuen uh.
16 Wọ́n sì dúró ní ipò wọn, bí ètò wọn gẹ́gẹ́ bí òfin Mose, ènìyàn Ọlọ́run: àwọn àlùfáà wọ́n ẹ̀jẹ̀ náà, tí wọ́n gbà lọ́wọ́ àwọn ọmọ Lefi.
Pathen kah hlang Moses olkhueng dongkah a laitloeknah bangla amamih paihmuen ah pai uh. Khosoih rhoek loh Levi kut lamkah thii te a haeh uh.
17 Nítorí pé ọ̀pọ̀lọpọ̀ ni ó wà nínú ìjọ ènìyàn náà tí kò yà ara wọn sí mímọ́: nítorí náà ni àwọn ọmọ Lefi ṣe ń tọ́jú àti pa ẹran ìrékọjá fún olúkúlùkù ẹni tí ó ṣe aláìmọ́, láti yà á sí mímọ́ sí Olúwa.
Hlangping lakli ah aka ciim uh pawt khaw muep om. Te dongah aka cim pawt boeih kah Yoom ngawnnah ham neh BOEIPA taengah ciim ham te Levi rhoek loh a hut nah.
18 Ọ̀pọ̀lọpọ̀ ènìyàn, àní ọ̀pọ̀lọpọ̀ nínú Efraimu àti Manase, Isakari, àti Sebuluni kò sá wẹ̀ ara wọn mọ́ síbẹ̀ wọ́n jẹ ìrékọjá náà, kì í ṣe gẹ́gẹ́ bí a ti kọ ọ́. Ṣùgbọ́n Hesekiah bẹ̀bẹ̀ fún wọn, wí pé, Olúwa, ẹni rere, dáríjì olúkúlùkù,
A puehkan la pilnam aka ping Ephraim, Manasseh, Issakhar neh Zebulun lamkah tah caihcil uh pawt sitoe cakhaw a daek tangtae neh kalthalh la Yoom a caak uh. Tedae Hezekiah loh amih ham thangthui tih, “BOEIPA aw, a then la dawth pah mai saeh.
19 tí ó múra ọkàn rẹ̀ láti wá Ọlọ́run, Olúwa Ọlọ́run àwọn baba rẹ̀ ṣùgbọ́n tí kì í ṣe nípa ìwẹ̀nùmọ́ mímọ́
Hmuencim kah ciimnah bangla om pawt cakhaw a napa rhoek kah Pathen, Yahweh Pathen te toem hamla a thinko boeih a cikngae sak,” a ti.
20 Olúwa sì gbọ́ ti Hesekiah, ó sì mú àwọn ènìyàn náà láradá.
BOEIPA loh Hezekiah taengkah te a yaak van neh pilnam te a hoeih sak.
21 Àwọn ọmọ Israẹli tí a rí ní Jerusalẹmu fi ayọ̀ ńlá pa àjọ àkàrà àìwú mọ́ ní ọjọ́ méje: àwọn ọmọ Lefi, àti àwọn àlùfáà yin Olúwa lójoojúmọ́, wọ́n ń fi ohun èlò olóhùn gooro kọrin sí Olúwa.
Jerusalem ah aka mop Israel ca rhoek loh hnin rhih khuiah vaidamding khotue te a saii uh. Hnin bal hnin bal BOEIPA taengah kohoenah a len neh a thangthen uh. Khosoih neh Levi rhoek loh BOEIPA te a sarhi tumbael neh a thangthenuh.
22 Hesekiah sọ̀rọ̀ ìtùnú fún gbogbo àwọn ọmọ Lefi, tí ó lóye ní ìmọ̀ rere Olúwa: ọjọ́ méje ni wọ́n fi jẹ àsè náà wọ́n rú ẹbọ àlàáfíà, wọ́n sì ń fi ohùn rara dúpẹ́ fún Olúwa, Ọlọ́run àwọn baba wọn.
BOEIPA kah lungmingnah then neh aka cangbam Levi pum kah lungbuei ah Hezekiah loh a thui pah. Te dongah hnin rhih tingtunnah khuiah tah rhoepnah hmueih la a nawn te a caak uh tih a napa rhoek kah Pathen BOEIPA te a uem uh.
23 Gbogbo ìjọ náà sì gbìmọ̀ láti pa ọjọ́ méje mìíràn mọ́: wọ́n sì fi ayọ̀ pa ọjọ́ méje mìíràn mọ́.
Te phoeiah hnin rhih koep saii ham te hlangping boeih loh a thui dongah kohoenah neh hnin rhih a saii uh.
24 Nítorí Hesekiah, ọba Juda, ta ìjọ ènìyàn náà ní ọrẹ, ẹgbẹ̀rún akọ màlúù, àti ẹ̀ẹ́dẹ́gbàárin àgùntàn. Ọ̀pọ̀lọpọ̀ nínú àwọn àlùfáà sì ya ara wọn sí mímọ́.
Judah manghai Hezekiah loh hlangping ham vaito thawng khat, boiva thawng rhih a pom pah. Mangpa rhoek long khaw hlangping ham te vaito thawng khat, boiva thawng rha a pom pah tih khosoih rhoek te a cungkuem la a ciim uh.
25 Gbogbo ìjọ ènìyàn Juda pẹ̀lú àwọn àlùfáà àti àwọn ọmọ Lefi, àti gbogbo ìjọ ènìyàn tí ó ti inú Israẹli jáde wá, àti àwọn àjèjì tí ó ti ilẹ̀ Israẹli jáde wá, àti àwọn tí ń gbé Juda yọ̀.
Te vaengah Judah hlangping boeih khaw, khosoih neh Levi rhoek khaw, Israel lamkah aka pawk hlangping boeih neh Israel khohmuen lamkah aka pawk yinlai khaw, Judah kah khosa rhoek kaw a kohoe uh.
26 Bẹ́ẹ̀ ni ayọ̀ ńlá sì wà ní Jerusalẹmu: nítorí láti ọjọ́ Solomoni, ọmọ Dafidi, ọba Israẹli, irú èyí kò sí ní Jerusalẹmu.
Te dongah Jerusalem ah kohoenah a len om coeng. Israel manghai David capa Solomon tue lamloh he bang he Jerusalem ah a om noek moenih.
27 Nígbà náà ni àwọn àlùfáà, àwọn ọmọ Lefi dìde, wọ́n sì súre fún àwọn ènìyàn náà: a sì gbọ́ ohùn wọn, àdúrà wọn sì gòkè lọ si ibùgbé mímọ́ rẹ̀, àní sí ọ̀run.
Levi khosoih rhoek te pai uh tih pilnam yoethen a paekuh. Amih kah thangthuinah loh a hmuencim kah khuirhung vaan duela a pha dongah amih ol te a hnatun pah.

< 2 Chronicles 30 >