< 2 Chronicles 3 >

1 Nígbà náà, Solomoni bẹ̀rẹ̀ sí ní kọ́ ilé Olúwa ní Jerusalẹmu lórí òkè Moria, níbi tí Olúwa ti farahan baba a rẹ̀ Dafidi. Ní orí ilẹ̀ ìpakà Arauna ará Jebusi, ibi tí Dafidi pèsè.
Sulayman Yerusalemda Pǝrwǝrdigar atisi Dawutⱪa ayan bolƣan Moriya teƣida, yǝni Yǝbusiy Ornanning haminida, Dawut tǝyyar ⱪilip ⱪoyƣan yǝrdǝ, Pǝrwǝrdigarning ɵyini selix ixini baxlidi.
2 Ó bẹ̀rẹ̀ sí kíkọ́ rẹ̀ ní ọjọ́ kejì oṣù kejì ní ọdún kẹrin ìjọba rẹ̀.
Sulaymanning sǝltǝnitining tɵtinqi yili, ikkinqi ayning ikkinqi küni u ⱪuruluxni baxlidi.
3 Ìpìlẹ̀ tí Solomoni gbé kalẹ̀ fún kíkọ́ ilé Ọlọ́run jẹ́ ọgọ́ta gígùn ìgbọ̀nwọ́ àti ogún fífẹ̀ ìgbọ̀nwọ́.
Sulayman salƣan Hudaning ɵyining uli mundaⱪ: — uzunluⱪi (ⱪǝdimki zamanda ⱪollanƣan ɵlqǝm boyiqǝ) atmix gǝz, kǝngliki yigirmǝ gǝz idi.
4 Ìloro tí ó wà níwájú ilé Olúwa náà jẹ́ ogún ìgbọ̀nwọ́ ní gígùn rékọjá fífẹ̀ ilé náà àti gíga rẹ̀ jẹ́ ogún ìgbọ̀nwọ́ ní gígùn rékọjá fífẹ̀ ilé náà àti gíga rẹ̀ jẹ́ ogún ìgbọ̀nwọ́. Ó tẹ́ inú rẹ̀ pẹ̀lú kìkì wúrà.
Ɵyning aldidiki aywanning uzunluⱪi yigirmǝ gǝz bolup, ɵyning kǝnglikigǝ toƣra kelǝtti; egizliki yigirmǝ gǝz idi; u iqini sap altun bilǝn ⱪaplatti.
5 Ó fi igi firi bo ilé yàrá ńlá náà ó sì bò ó pẹ̀lú kìkì wúrà, ó sì ṣe é lọ́ṣọ̀ọ́ pẹ̀lú igi ọ̀pẹ àti àwòrán ẹ̀wọ̀n.
U ɵyning qong zelining tamlirini arqa-ⱪariƣay tahtayliri bilǝn ⱪaplatti, andin keyin sap altun ⱪaplatti wǝ üstigǝ horma dǝrihining xǝkli bilǝn zǝnjir nǝⱪixlirini oydurdi.
6 Ó ṣe ilé Olúwa náà lọ́ṣọ̀ọ́ pẹ̀lú òkúta iyebíye. Wúrà tí ó lò jẹ́ wúrà parifaimu.
U ɵyni alamǝt qirayliⱪ ⱪilip tamlirini yǝnǝ esil tax-yaⱪutlar bilǝn zinnǝtlǝtti. U ixlǝtkǝn altunlar pütünlǝy parwayim altuni idi.
7 Ó tẹ́ àjà ilé náà pẹ̀lú ìtí igi àti ìlẹ̀kùn ògiri àti àwọn ìlẹ̀kùn ilé Olúwa pẹ̀lú wúrà, ó sì gbẹ́ àwòrán kérúbù sára ògiri.
U pütün ɵyni, ɵyning limliri, ixik bosuƣa-kexǝkliri, barliⱪ tamliri wǝ ixiklirini altun bilǝn ⱪaplidi; u tamƣa kerublarning nǝⱪixlirini oydurdi.
8 Ó kọ́ Ibi Mímọ́ Jùlọ, gígùn rẹ̀ bá fífẹ̀ ilé Olúwa mu, ogún ìgbọ̀nwọ́ fún gígùn, fífẹ̀ rẹ̀ sì jẹ́ ogún ìgbọ̀nwọ́, ó tẹ́ inú rẹ̀ pẹ̀lú ẹgbẹ̀ta tálẹ́ǹtì ti wúrà dáradára.
Sulayman yǝnǝ ǝng muⱪǝddǝs jayni yasatti; uning uzunluⱪi yigirmǝ gǝz bolup (ɵyning kǝngliki bilǝn tǝng idi), kǝnglikimu yigirmǝ gǝz idi; u uning iqini pütünlǝy sap altun bilǝn ⱪaplatti; altun jǝmiy bolup altǝ yüz talalnt idi.
9 Ìwọ̀n àwọn ìṣó náà jẹ́ àádọ́ta ṣékélì. Ó tẹ́ àwọn apẹ òkè pẹ̀lú wúrà.
Altun miⱪning eƣirliⱪi jǝmiy ǝllik xǝkǝl boldi. Balihanilirining iqimu altun bilǝn ⱪaplandi.
10 Ní Ibi Mímọ́ Jùlọ, ó gbẹ́ àwòrán igi kérúbù kan, ó sì tẹ́ wọn pẹ̀lú wúrà.
Əng muⱪǝddǝs jay iqidǝ u ikki kerubning ⱨǝykilini yasap, ularni pütünlǝy altun bilǝn ⱪaplidi.
11 Iye ìyẹ́ apá ìbú àtẹ́lẹwọ́ lápapọ̀ ní ti kérúbù, jẹ́ ogún ìgbọ̀nwọ́ ọ̀kan nínú ìyẹ́ apá ti kérúbù àkọ́kọ́ jẹ́ ìgbọ̀nwọ́ márùn-ún ní gígùn, ó sì farakan ògiri ilé Olúwa. Nígbà tí ìyẹ́ apá kejì jẹ́ ìgbọ̀nwọ́ márùn-ún ní gígùn ó sì, farakan ìyẹ́ apá kérúbù mìíràn.
Ikki kerubning ⱪanitining uzunluⱪi jǝmiy yigirmǝ gǝz idi; bir kerubning bir ⱪanitining uzunluⱪi bǝx gǝz bolup, ɵyning temiƣa tegip turatti; ikkinqi tǝrǝptiki ⱪanitining uzunluⱪimu bǝx gǝz bolup, ikkinqi bir kerubning ⱪanitiƣa yetǝtti.
12 Ní ìjọra, ìyẹ́ apá kan ti kérúbù kejì jẹ́ ìgbọ̀nwọ́ márùn-ún ní gígùn, ó sì farakan ògiri ilé Olúwa mìíràn; ìyẹ́ apá rẹ̀ mìíràn sì jẹ́ ìgbọ̀nwọ́ márùn ní gígùn pẹ̀lú tí ó farakan ìyẹ́ apá kérúbù àkọ́kọ́.
Yǝnǝ bir kerubning ⱪanitining uzunluⱪimu bǝx gǝz bolup, umu ɵy temiƣa tegip turatti; ikkinqi bir ⱪanitining uzunluⱪimu bǝx gǝz bolup, aldinⱪi bir kerubning ⱪanitiƣa yetǝtti.
13 Ìyẹ́ apá àwọn kérúbù wọ̀nyí gbà tó ogún ìgbọ̀nwọ́. Wọ́n dúró ní ẹsẹ̀ wọn, wọ́n kọjú sí yàrá pàtàkì ńlá náà.
Bu ikki kerubning ⱪanatliri yeyilƣan ⱨalda bolup, uzunluⱪi jǝmiy yigirmǝ gǝz kelǝtti; ikkila kerub ɵrǝ turƣuzulƣan bolup, yüzliri ɵyning iqigǝ ⱪaraytti.
14 Ó ṣe aṣọ títa ní àwọ̀ ojú ọ̀run, àwọ̀ àlùkò àti àwọ̀ pupa fòò àti aṣọ ọ̀gbọ̀ pẹ̀lú kérúbù tí a ṣe sórí i rẹ̀.
Sulayman yǝnǝ kɵk rǝnglik, sɵsün rǝnglik, toⱪ ⱪizil wǝ aⱪ rǝnglik yip toⱪulmiliridin wǝ nǝpis kanaptin [ɵyning iqidiki] pǝrdisini yasatti, uning üstigǝ kerublarni kǝxtǝ ⱪilip toⱪutti.
15 Níwájú ilé Olúwa náà ó ṣe òpó méjì tí lápapọ̀ jẹ́ márùn-ún dín lógójì ìgbọ̀nwọ́ ní gígùn, olúkúlùkù pẹ̀lú olórí lórí rẹ̀ tí o ń wọn ìgbọ̀nwọ́ márùn-ún.
Ɵyning aldiƣa yǝnǝ egizliki ottuz bǝx gǝz kelidiƣan ikki tüwrük yasap ⱪoydurdi; ⱨǝr tüwrükning bexining egizliki bǝx gǝz kelǝtti.
16 Ó ṣe ẹ̀wọ̀n tí a hun wọ inú ara wọn, ó gbé wọn ká orí òpó náà. Ó ṣe ọgọ́rùn-ún pomegiranate (orúkọ èso igi) ó sì so wọ́n mọ́ àwọn ẹ̀wọ̀n náà
U yǝnǝ (iqki kalamhanidikidǝk) marjansiman zǝnjir yasitip, tüwrük baxliri üstigǝ ornatti; u yüz danǝ anar yasitip ularni zǝnjirlǝrgǝ ornatti.
17 Ó gbe òpó náà dúró níwájú ilé Olúwa, ọ̀kan sí gúúsù, pẹ̀lú ọ̀kan sí àríwá. Èyí ti gúúsù, ó sọ ní Jakini àti èyí ti àríwá, ó sọ ní Boasi.
U bu ikki tüwrükni ɵyning aldiƣa, birsini ong tǝripidǝ, birsini sol tǝripidǝ turƣuzdi; u ong tǝrǝptikisini Yaⱪin, sol tǝrǝptikisini Boaz dǝp atidi.

< 2 Chronicles 3 >