< 2 Chronicles 29 >

1 Hesekiah sì jẹ́ ẹni ọdún mẹ́ẹ̀ẹ́dọ́gbọ̀n nígbà tí ó di ọba, ó sì jẹ ọba ní Jerusalẹmu fún ọdún mọ́kàndínlọ́gbọ̀n orúkọ ìyá rẹ̀ sì ni Abijah ọmọbìnrin Sekariah.
Єзекі́я зацарював у віці двадцяти́ й п'яти́ літ, а двадцять і дев'ять літ царював він в Єрусалимі. А ім'я́ його матері — Авійя, дочка́ Захарії.
2 Ó sì ṣe ohun tí ó tọ́ ní ojú Olúwa, gẹ́gẹ́ bí baba rẹ̀ Dafidi ti ṣe.
І робив він угодне в Господніх оча́х, як усе, що робив був його ба́тько Давид.
3 Ní oṣù àkọ́kọ́ ní ọdún kìn-ín-ní ìjọba rẹ̀, ó sì ṣí àwọn ìlẹ̀kùn ilé Olúwa ó sì tún wọn ṣe.
Він першого року свого царюва́ння, місяця першого відчини́в двері Господнього дому, і попра́вив їх.
4 Ó sì mú àwọn àlùfáà wá àti àwọn ọmọ Lefi, ó sì kó wọn jọ yíká ìta ìlà-oòrùn.
І привів він священиків та Левитів, і зібрав їх на схі́дню пло́щу,
5 Ó sì wí pé, “Ẹ gbọ́ tèmi, ẹ̀yin ọmọ Lefi! Ẹ ya ara yín sí mímọ́ nísinsin yìí kí ẹ sì ya ilé Olúwa Ọlọ́run sí mímọ́, kí ẹ sì kó ohun àìmọ́ baba mi jáde kúrò ní ibi mímọ́.
та й сказав їм: „Послухайте мене, Левити! Освяті́ться тепер, і освятіть дім Господа, Бога ваших батьків, і ви́несіть нечисть із святині.
6 Àwọn baba wa jẹ́ aláìṣòótọ́; wọ́n sì ṣe ohun àìtọ́ níwájú Olúwa Ọlọ́run wa, wọ́n sì kọ̀ ọ́ sílẹ̀. Wọ́n sì yí ojú wọn padà kúrò ní ibùgbé Olúwa, wọ́n sì pa ẹ̀yìn wọn dà sí i.
Бо наші батьки сироневі́рилися, і робили лихе́ в оча́х Господа, Бога нашого, і залишили Його, і відвернули своє обличчя від Господньої скинії, й обернулися спи́ною до неї.
7 Wọ́n sì tún ti ìlẹ̀kùn ìloro náà pẹ̀lú, wọ́n sì pa fìtílà. Wọn kò sì sun tùràrí tàbí pèsè ẹbọ sísun si ibi mímọ́ si Ọlọ́run Israẹli.
Також замкну́ли вони двері притво́ру, і погасили лямпа́дки, а кадила не кадили, і цілопа́лення не прино́сили в святині для Ізраїлевого Бога.
8 Nítorí náà, ìbínú Olúwa ti ru sókè wá sórí Juda àti Jerusalẹmu ó sì ti fi wọ́n ṣe ohun èlò fún wàhálà, àti ìdààmú àti ẹ̀sín, gẹ́gẹ́ bí ó ti ṣe fi ojú rẹ̀ rí i.
І був Господній гнів на Юду та на Єрусалим, і Він дав їх на га́ньбу, і на спусто́шення, і на посміхо́вище, як ви бачите своїми очи́ма.
9 Ìdí nìyí tí àwọn baba wa ṣe ṣubú nípa idà àti ìdí tí àwọn ọmọkùnrin àti ọmọbìnrin àti àwọn aya wa tiwọn kó wọ́n ní ìgbèkùn.
І ось попа́дали наші батьки від меча, а наші сини, і наші до́чки, і жінки наші в неволі за це!
10 Nísinsin yìí ó wà ní ọkàn mi láti bá Olúwa Ọlọ́run Israẹli dá májẹ̀mú. Bẹ́ẹ̀ ni kí ìbínú rẹ̀ kíkan kí ó lè yípadà kúrò lọ́dọ̀ wa.
Тепер на моєму серці лежить скла́сти заповіта з Господом, Ізра́їлевим Богом, — і нехай Він відве́рне від нас жар гніву Свого.
11 Àwọn ọmọ mi, ẹ má ṣe jáfara nísinsin yìí, nítorí tí Olúwa ti yàn yín láti dúró níwájú rẹ̀ láti sin, kí ẹ sì máa ṣe ìránṣẹ́ níwájú rẹ̀ àti láti sun tùràrí.”
Сини мої, не будьте недбалі тепер, бо вас Господь вибрав ставати перед лицем Його на службу Йому, та щоб служити Йому й кадити Йому!“
12 Nígbà náà àwọn ọmọ Lefi wọ̀nyí múra láti ṣe iṣẹ́: nínú àwọn ọmọ Kohati, Mahati ọmọ Amasai: àti Joẹli ọmọ Asariah; nínú àwọn ọmọ Merari, Kiṣi ọmọ Abdi àti Asariah ọmọ Jehaleeli; nínú àwọn ọmọ Gerṣoni, Joah, ọmọ Simma àti Edeni ọmọ Joah;
І встали Левити: Махат, син Амасаїв, і Йоїл, син Азарії, від синів Кегатових; а від синів Мерарієвих: Кіш, син Авдіїв, і Азарія, син Єгаллел'їлів; а від Ґершонівців: Йоах, син Зіммин, і Еден, син Йоахів;
13 nínú àwọn ọmọ Elisafani, Ṣimri àti Jeieli; nínú àwọn ọmọ Asafu, Sekariah àti Mattaniah;
а від синів Еліцафанових: Шімрі, і Єіїл; а від синів Асафових: Захарій та Маттанія.
14 nínú àwọn ọmọ Hemani, Jehieli àti Ṣimei; nínú àwọn ọmọ Jedutuni, Ṣemaiah àti Usieli.
А від Геманових синів: Єхіїл, і Шім'ї; а від синів Єдутунових: Шемая та Уззіїл.
15 Nígbà tí wọ́n sì ti kó ara wọn jọ pọ̀ pẹ̀lú àwọn arákùnrin wọn, wọ́n sì ya ara wọn sí mímọ́, wọ́n sì lọ láti gbá ilé Olúwa mọ́, gẹ́gẹ́ bí ọba ti pa á láṣẹ, ẹ tẹ̀lé ọ̀rọ̀ Olúwa.
І зібрали вони братів своїх, і освятилися, і пішли за нака́зом царськи́м у справах Господніх, щоб очистити Господній дім.
16 Àwọn àlùfáà sì wọ inú ilé Olúwa lọ́hùn ún lọ láti gbá a mọ́. Wọ́n sì gbé e jáde sí inú àgbàlá ilé Olúwa gbogbo ohun àìmọ́ tí wọ́n rí nínú ilé Olúwa. Àwọn ọmọ Lefi sì mú u wọ́n sì gbangba odò Kidironi.
І повхо́дили священики до сере́дини Господнього дому на очи́щення. І повино́сили вони всю нечистість, яку знайшли в Господньому храмі, до подвір'я Господнього дому, а Левити взяли́ це, щоб винести назо́вні до долини Кедро́н.
17 Wọ́n sì bẹ̀rẹ̀ ìyàsímímọ́ ní ọjọ́ kìn-ín-ní oṣù kìn-ín-ní, àti ní ọjọ́ kẹjọ oṣù náà wọ́n sì dé ìloro Olúwa. Fún ọjọ́ mẹ́jọ mìíràn sí i, wọ́n sì ya ilé Olúwa sí mímọ́ fúnra rẹ̀. Wọ́n sì parí ní ọjọ́ kẹrìndínlógún oṣù kìn-ín-ní.
І зачали́ вони першого дня першого місяця освящати, а восьмого дня того місяця ввійшли до Господнього притво́ру. І освятили вони Господній дім за вісім день, а шістнадцятого дня першого місяця закінчи́ли.
18 Nígbà náà wọn sì lọ sí ọ̀dọ̀ ọba Hesekiah láti lọ jábọ̀ fún un: “Àwa ti gbá ilé Olúwa mọ́, pẹpẹ ẹbọ sísun pẹ̀lú gbogbo ohun ẹbọ rẹ̀, àti tábìlì àkàrà ìfihàn, pẹ̀lú gbogbo ohun èlò.
І ввійшли вони в сере́дину дому до царя Єзекії та й сказали: „Очистили ми ввесь Господній дім, і же́ртівника цілопа́лення, та всі його речі, і стіл укладання хлібі́в та всі його речі.
19 A ti pèsè a sì ti yà sí mímọ́ gbogbo ohun èlò tí ọba Ahasi ti sọ di aláìmọ́ nínú àìṣòótọ́ rẹ̀ nígbà tí ó jẹ́ ọba; nísinsin yìí, wọ́n wà níwájú pẹpẹ Olúwa.”
А всі ті речі, які цар Ахаз занеха́в був за свого царюва́ння, коли спроневі́рився, ми приготовили та освятили, і ось вони перед Господнім же́ртівником“.
20 Ní kùtùkùtù òwúrọ̀ ọjọ́ kejì, ọba Hesekiah sì kó olórí àwọn ìjòyè jọ, ó sì lọ sókè ilé Olúwa.
І встав рано цар Єзекія, і зібрав зверхників міста та й увійшов до Господнього дому.
21 Wọ́n sì mú akọ màlúù méje wá, àti àgbò méje, àti ọ̀dọ́-àgùntàn méje àti òbúkọ méje gẹ́gẹ́ bí ẹbọ ẹ̀ṣẹ̀ fún ìjọba, fún ibi mímọ́ àti fún Juda. Ọba pàṣẹ fun àwọn àlùfáà, àwọn ọmọ Aaroni, láti ṣe èyí lórí pẹpẹ Olúwa.
І привели́ вони сім биків, і сім барані́в, і сім ове́чок, і сім козлів на жертву за гріх: за царство, і за святиню, і за Юду, а він звелів Ааро́новим синам, священикам, прине́сти це в жертву на Господньому же́ртівнику.
22 Bẹ́ẹ̀ ni wọ́n sì pa akọ màlúù, àwọn àlùfáà mú ẹ̀jẹ̀ náà, wọ́n sì fi wọ́n ara pẹpẹ. Bẹ́ẹ̀ gẹ́gẹ́ ni nígbà tí wọ́n pa àgbò, wọ́n sì fi ẹ̀jẹ̀ wọ́n orí pẹpẹ. Nígbà náà wọ́n sì pa ọ̀dọ́-àgùntàn, wọ́n sì fi ẹ̀jẹ̀ wọn ara pẹpẹ.
І порізали ту велику худобу, а священики прийняли́ кров і покропи́ли на жертівника; і порізали баранів, і покропили ту кров на жертівника; і порізали ове́чок, і покропили ту кров на жертівника.
23 Òbúkọ fún ẹbọ ẹ̀ṣẹ̀ ni wọ́n gbé wá síwájú ọba àti ìjọ ènìyàn, wọ́n sì gbé ọwọ́ lé wọn.
І привели́ козлів жертви за гріх перед царя та збори, і вони поклали свої руки на них.
24 Àwọn àlùfáà wọn sì pa òbúkọ, wọ́n sì gbé ẹ̀jẹ̀ kalẹ̀ lórí pẹpẹ fún ẹbọ ẹ̀ṣẹ̀ láti ṣe ètùtù fún gbogbo Israẹli, nítorí ọba ti pàṣẹ kí a ṣe ẹbọ sísun àti ẹbọ ẹ̀ṣẹ̀ fún gbogbo Israẹli.
І зарізали їх священики, а їхньою кров'ю очи́стили жертівника, щоб очистити всього Ізраїля, бо за всього Ізраїля звелів цар принести це цілопа́лення та цю жертву за гріх.
25 Ó sì mú àwọn Lefi dúró nínú ilé Olúwa pẹ̀lú Kimbali, ohun èlò orin olókùn àti dùùrù ní ọ̀nà tí a ti paláṣẹ fún wọn láti ọ̀dọ̀ Dafidi àti Gadi aríran ọba àti Natani wòlíì. Èyí ni a pàṣẹ láti ọ̀dọ̀ Olúwa láti ọwọ́ àwọn wòlíì rẹ̀.
І поставив він Левитів Господнього дому з цимба́лами, з а́рфами та з ци́трами, за нака́зом Давида та Ґада, царе́вого прозорли́вця, та пророка Ната́на, бо в руці Господа наказ, що йде через пророків Його.
26 Bẹ́ẹ̀ ni àwọn ọmọ Lefi sì dúró pẹ̀lú ohun èlò orin Dafidi, àti àwọn àlùfáà pẹ̀lú ìpè wọn.
І постава́ли Левити з Давидовим знаря́ддям, а священики — із су́рмами.
27 Hesekiah sì pa á láṣẹ láti rú ẹbọ sísun lórí pẹpẹ, bí ẹbọ sísun náà ti bẹ̀rẹ̀, orin sí Olúwa bẹ̀rẹ̀ pẹ̀lú ìpè àti pẹ̀lú ohun èlò orin Dafidi ọba Israẹli.
І сказав Єзекі́я принести цілопа́лення на жертівника. А коли розпочали́ цілопа́лення, зачався спів Господе́ві та звуки су́рем і музи́чного знаря́ддя Давида, Ізраїлевого царя.
28 Gbogbo ìjọ ènìyàn náà sì wólẹ̀ sìn, àwọn akọrin kọrin, àwọn afùnpè sì fọn ìpè, gbogbo wọ̀nyí sì wà bẹ́ẹ̀ títí ẹbọ sísun náà fi parí tán.
І ввесь збір вклонився, і співаки́ співали, а су́рми сурми́ли, — це все аж до кінця цілопа́лення!
29 Nígbà tí wọ́n sì ṣe ìparí ẹbọ rírú, ọba àti gbogbo àwọn tí ó wà pẹ̀lú rẹ̀ tẹ ara wọn ba, wọ́n sì sìn.
А як скінчи́ли прино́сити жертву, попа́дали навко́лішки цар та всі, що були з ним, і вклони́лися.
30 Pẹ̀lúpẹ̀lú Hesekiah ọba, àti àwọn ìjòyè pàṣẹ fún àwọn ọmọ Lefi, láti fi ọ̀rọ̀ Dafidi àti ti Asafu aríran, kọrin ìyìn sí Olúwa: wọ́n sì fi inú dídùn kọrin ìyìn, wọ́n sì tẹrí wọn ba, wọ́n sì sìn.
І сказав цар Єзекія та зверхники до Левитів, щоб вони хвалили Господа словами Давида та прозорли́вця Асафа, — і вони хвалили з великою радістю, і схилялися, і вклоня́лися до землі.
31 Nígbà náà ni Hesekiah dáhùn, ó sì wí pé, nísinsin yìí, ọwọ́ yín kún fún ẹ̀bùn fún Olúwa, ẹ súnmọ́ ìhín, kí ẹ sì mú ẹbọ àti ọrẹ-ọpẹ́ wá sínú ilé Olúwa. Ìjọ ènìyàn sì mú ẹbọ àti ọrẹ-ọpẹ́ wá; àti olúkúlùkù tí ọkàn rẹ̀ fẹ́, mú ẹbọ sísun wá.
І відпові́в Єзекі́я й сказав: „Тепер ви освя́чені для Господа. Підійдіть, і приведі́ть жертви та при́носи вдячні для Господнього дому“. І привів збір жертви та при́носи вдячні, і кожен, хто мав жертве́нне серце, — прино́сив цілопа́лення.
32 Iye ẹbọ sísun, tí ìjọ ènìyàn mú wá, sì jẹ́ àádọ́rin akọ màlúù, àti ọgọ́rùn-ún àgbò, àti igba ọ̀dọ́-àgùntàn, gbogbo wọ̀nyí sì ni fún ẹbọ sísun sí Olúwa.
І було число цілопа́лення, що спрова́див збір: худоби великої — сімдеся́т, барані́в — сотня, ове́чок — двісті, для цілопа́лення Господе́ві все це.
33 Àwọn ohun ìyàsímímọ́ sì jẹ́ ẹgbẹ̀ta màlúù, àti ẹgbẹ̀rún mẹ́ta àgùntàn.
А для святости: худоби великої — шість сотень, а худоби дрібно́ї — три тисячі.
34 Ṣùgbọ́n àwọn àlùfáà kò pọ̀ tó, wọn kò sì le bó gbogbo àwọn ẹran ẹbọ sísun náà: nítorí náà àwọn arákùnrin wọn, àwọn Lefi ràn wọ́n lọ́wọ́, títí iṣẹ́ náà fi parí, àti títí àwọn àlùfáà ìyókù fi yà wọ́n sí mímọ́: nítorí àwọn ọmọ Lefi ṣe olóòtítọ́ ní ọkàn ju àwọn àlùfáà lọ láti ya ara wọn sí mímọ́.
Тільки священиків було мало, і не могли́ вони обдира́ти шкур зо всіх цілопа́лень; і допомага́ли їм їхні брати Левити аж до скі́нчення праці, і поки освятилися священики, бо Левити були простосердіші на освя́чення, аніж священики.
35 Àti pẹ̀lú, àwọn ẹbọ sísun pàpọ̀jù, pẹ̀lú ọ̀rá ẹbọ àlàáfíà, pẹ̀lú ẹbọ ohun mímu fún ẹbọ sísun. Bẹ́ẹ̀ ni a sì tún bẹ̀rẹ̀ iṣẹ́ ìsìn ilé Olúwa.
І також було багато па́лень серед мирних жертов і серед жертов литих до цілопа́лення. І так була відновлена служба Господнього дому.
36 Hesekiah sì yọ̀, àti gbogbo ènìyàn pé, Ọlọ́run ti múra àwọn ènìyàn náà sílẹ̀, nítorí lójijì ni a ṣe nǹkan náà.
І радів Єзекі́я та ввесь народ тим, що́ Бог приготовив для народу, бо та річ сталася несподі́вано!

< 2 Chronicles 29 >