< 2 Chronicles 29 >

1 Hesekiah sì jẹ́ ẹni ọdún mẹ́ẹ̀ẹ́dọ́gbọ̀n nígbà tí ó di ọba, ó sì jẹ ọba ní Jerusalẹmu fún ọdún mọ́kàndínlọ́gbọ̀n orúkọ ìyá rẹ̀ sì ni Abijah ọmọbìnrin Sekariah.
Hezekia aarĩ wa mĩaka mĩrongo ĩĩrĩ na ĩtano rĩrĩa aatuĩkire mũthamaki, nake agĩthamaka arĩ Jerusalemu mĩaka mĩrongo ĩĩrĩ na kenda. Nyina eetagwo Abija mwarĩ wa Zekaria.
2 Ó sì ṣe ohun tí ó tọ́ ní ojú Olúwa, gẹ́gẹ́ bí baba rẹ̀ Dafidi ti ṣe.
Nake agĩĩka maũndũ marĩa maagĩrĩire maitho-inĩ ma Jehova, o ta ũrĩa ithe Daudi eekĩte.
3 Ní oṣù àkọ́kọ́ ní ọdún kìn-ín-ní ìjọba rẹ̀, ó sì ṣí àwọn ìlẹ̀kùn ilé Olúwa ó sì tún wọn ṣe.
Mweri wa mbere wa mwaka wa mbere wa wathani wake-rĩ, nĩahingũrire mĩrango ya hekarũ ya Jehova na akĩmĩthondeka kũrĩa yathũkĩtio.
4 Ó sì mú àwọn àlùfáà wá àti àwọn ọmọ Lefi, ó sì kó wọn jọ yíká ìta ìlà-oòrùn.
Nake akĩrehe athĩnjĩri-Ngai na Alawii, akĩmacookanĩrĩria hamwe nja ya mwena wa irathĩro,
5 Ó sì wí pé, “Ẹ gbọ́ tèmi, ẹ̀yin ọmọ Lefi! Ẹ ya ara yín sí mímọ́ nísinsin yìí kí ẹ sì ya ilé Olúwa Ọlọ́run sí mímọ́, kí ẹ sì kó ohun àìmọ́ baba mi jáde kúrò ní ibi mímọ́.
akiuga atĩrĩ: “Ta thikĩrĩriai inyuĩ Alawii! Mwĩtheriei rĩu, na mũtherie hekarũ ya Jehova Ngai wa maithe manyu. Eheriai kĩndũ gĩothe kĩrĩ thaahu kuuma handũ-harĩa-haamũre.
6 Àwọn baba wa jẹ́ aláìṣòótọ́; wọ́n sì ṣe ohun àìtọ́ níwájú Olúwa Ọlọ́run wa, wọ́n sì kọ̀ ọ́ sílẹ̀. Wọ́n sì yí ojú wọn padà kúrò ní ibùgbé Olúwa, wọ́n sì pa ẹ̀yìn wọn dà sí i.
Maithe maitũ matiarĩ ehokeku; nĩmekire ũũru maitho-inĩ ma Jehova Ngai witũ na makĩmũtirika. Nĩmahũgũrire mothiũ mao makĩaga kũrora gĩikaro kĩa Jehova, makĩmũhutatĩra.
7 Wọ́n sì tún ti ìlẹ̀kùn ìloro náà pẹ̀lú, wọ́n sì pa fìtílà. Wọn kò sì sun tùràrí tàbí pèsè ẹbọ sísun si ibi mímọ́ si Ọlọ́run Israẹli.
O na ningĩ nĩmahingire mĩrango ya gĩthaku na makĩhoria matawa. Matiacinire ũbumba kana makĩrutĩra Ngai wa Isiraeli maruta o na marĩkũ ma njino handũ-inĩ harĩa haamũre.
8 Nítorí náà, ìbínú Olúwa ti ru sókè wá sórí Juda àti Jerusalẹmu ó sì ti fi wọ́n ṣe ohun èlò fún wàhálà, àti ìdààmú àti ẹ̀sín, gẹ́gẹ́ bí ó ti ṣe fi ojú rẹ̀ rí i.
Nĩ ũndũ ũcio-rĩ, marakara ma Jehova magĩkora Juda na Jerusalemu; nake agĩtũma matuĩke ta kĩndũ gĩa kũmakania na kĩa magigi, na gĩa kũnyũrũrio, o ta ũrĩa mũreyonera na maitho manyu.
9 Ìdí nìyí tí àwọn baba wa ṣe ṣubú nípa idà àti ìdí tí àwọn ọmọkùnrin àti ọmọbìnrin àti àwọn aya wa tiwọn kó wọ́n ní ìgbèkùn.
Kĩu nĩkĩo gĩatũmire maithe maitũ mooragwo na rũhiũ rwa njora, na nokĩo gĩtũmĩte ariũ aitũ, na airĩtu aitũ, na atumia aitũ matahwo.
10 Nísinsin yìí ó wà ní ọkàn mi láti bá Olúwa Ọlọ́run Israẹli dá májẹ̀mú. Bẹ́ẹ̀ ni kí ìbínú rẹ̀ kíkan kí ó lè yípadà kúrò lọ́dọ̀ wa.
Na rĩrĩ, ndĩciirĩtie na ngoro yakwa kũrĩkanĩra kĩrĩkanĩro na Jehova, Ngai wa Isiraeli, nĩgeetha marakara make mahiũ matweherere.
11 Àwọn ọmọ mi, ẹ má ṣe jáfara nísinsin yìí, nítorí tí Olúwa ti yàn yín láti dúró níwájú rẹ̀ láti sin, kí ẹ sì máa ṣe ìránṣẹ́ níwájú rẹ̀ àti láti sun tùràrí.”
Atĩrĩrĩ, ariũ akwa, mũtigatuĩke andũ matarũmbũyagia ũndũ, nĩgũkorwo Jehova nĩamũthuurĩte mũrũgamage mbere yake mũmũtungatagĩre, mũtuĩke a gũtungata mũrĩ mbere yake na mũcinage ũbumba.”
12 Nígbà náà àwọn ọmọ Lefi wọ̀nyí múra láti ṣe iṣẹ́: nínú àwọn ọmọ Kohati, Mahati ọmọ Amasai: àti Joẹli ọmọ Asariah; nínú àwọn ọmọ Merari, Kiṣi ọmọ Abdi àti Asariah ọmọ Jehaleeli; nínú àwọn ọmọ Gerṣoni, Joah, ọmọ Simma àti Edeni ọmọ Joah;
Hĩndĩ ĩyo Alawii aya makĩambĩrĩria kũruta wĩra: kuuma kũrĩ Akohathu, maarĩ Mahathu mũrũ wa Amasai, na Joeli mũrũ wa Azaria; kuuma kũrĩ Amerari, maarĩ Kishu mũrũ wa Abudi, na Azaria mũrũ wa Jehaleleli; kuuma kũrĩ Agerishoni, maarĩ Joa mũrũ wa Zima, na Edeni mũrũ wa Joa;
13 nínú àwọn ọmọ Elisafani, Ṣimri àti Jeieli; nínú àwọn ọmọ Asafu, Sekariah àti Mattaniah;
kuuma kũrĩ njiaro cia Elizafani, maarĩ Shimuri na Jeieli; kuuma kũrĩ njiaro cia Asafu, maarĩ Zekaria na Matania;
14 nínú àwọn ọmọ Hemani, Jehieli àti Ṣimei; nínú àwọn ọmọ Jedutuni, Ṣemaiah àti Usieli.
Kuuma kũrĩ njiaro cia Hemani, maarĩ Jehueli na Shimei; kuuma kũrĩ njiaro cia Jeduthuni, maarĩ Shemaia na Uzieli.
15 Nígbà tí wọ́n sì ti kó ara wọn jọ pọ̀ pẹ̀lú àwọn arákùnrin wọn, wọ́n sì ya ara wọn sí mímọ́, wọ́n sì lọ láti gbá ilé Olúwa mọ́, gẹ́gẹ́ bí ọba ti pa á láṣẹ, ẹ tẹ̀lé ọ̀rọ̀ Olúwa.
Maarĩkia gũcookanĩrĩria ariũ a ithe wao hamwe na meetheria-rĩ, magĩtoonya hekarũ ya Jehova, makĩmĩtheria, o ta ũrĩa mũthamaki aathanĩte arũmĩrĩire kiugo kĩa Jehova.
16 Àwọn àlùfáà sì wọ inú ilé Olúwa lọ́hùn ún lọ láti gbá a mọ́. Wọ́n sì gbé e jáde sí inú àgbàlá ilé Olúwa gbogbo ohun àìmọ́ tí wọ́n rí nínú ilé Olúwa. Àwọn ọmọ Lefi sì mú u wọ́n sì gbangba odò Kidironi.
Nao athĩnjĩri-Ngai magĩtoonya handũ-harĩa-haamũre ha Jehova nĩguo mahatherie. Na indo ciothe iria itaarĩ theru iria maakorire kũu hekarũ-inĩ ya Jehova magĩciruta magĩciiga nja ya hekarũ ya Jehova. Nao Alawii magĩcioya magĩcitwara Gĩtuamba-inĩ gĩa Kidironi.
17 Wọ́n sì bẹ̀rẹ̀ ìyàsímímọ́ ní ọjọ́ kìn-ín-ní oṣù kìn-ín-ní, àti ní ọjọ́ kẹjọ oṣù náà wọ́n sì dé ìloro Olúwa. Fún ọjọ́ mẹ́jọ mìíràn sí i, wọ́n sì ya ilé Olúwa sí mímọ́ fúnra rẹ̀. Wọ́n sì parí ní ọjọ́ kẹrìndínlógún oṣù kìn-ín-ní.
Maambĩrĩirie wĩra wa gũtheria hekarũ mũthenya wa mbere wa mweri wa mbere, na mũthenya wa ĩnana wa mweri ũcio magĩkinya gĩthaku-inĩ kĩa Jehova. Na handũ ha matukũ mangĩ manana-rĩ, magĩtheria hekarũ ya Jehova yo nyene, na makĩrĩkia wĩra ũcio mũthenya wa ikũmi na ĩtandatũ wa mweri ũcio wa mbere.
18 Nígbà náà wọn sì lọ sí ọ̀dọ̀ ọba Hesekiah láti lọ jábọ̀ fún un: “Àwa ti gbá ilé Olúwa mọ́, pẹpẹ ẹbọ sísun pẹ̀lú gbogbo ohun ẹbọ rẹ̀, àti tábìlì àkàrà ìfihàn, pẹ̀lú gbogbo ohun èlò.
Magĩcooka magĩthiĩ kũrĩ Mũthamaki Hezekia, makĩmwĩra atĩrĩ: “Nĩtũtheretie hekarũ ya Jehova yothe, kĩgongona kĩa maruta ma njino, na indo ciakĩo ciothe, na metha ĩrĩa ĩigagĩrĩrwo mĩgate ĩrĩa mĩamũre, na indo ciayo ciothe.
19 A ti pèsè a sì ti yà sí mímọ́ gbogbo ohun èlò tí ọba Ahasi ti sọ di aláìmọ́ nínú àìṣòótọ́ rẹ̀ nígbà tí ó jẹ́ ọba; nísinsin yìí, wọ́n wà níwájú pẹpẹ Olúwa.”
Nĩtũhaarĩirie na tũkaamũra indo iria ciothe Mũthamaki Ahazu ehereetie Hekarũ-inĩ rĩrĩa aarĩ mũthamaki nĩ ũndũ wa kwaga wĩhokeku. Na rĩrĩ, rĩu irĩ mbere ya kĩgongona kĩa Jehova.”
20 Ní kùtùkùtù òwúrọ̀ ọjọ́ kejì, ọba Hesekiah sì kó olórí àwọn ìjòyè jọ, ó sì lọ sókè ilé Olúwa.
Na rĩrĩ, rũciinĩ tene, Mũthamaki Hezekia agĩcookanĩrĩria anene a itũũra rĩu inene na magĩthiĩ hekarũ-inĩ ya Jehova.
21 Wọ́n sì mú akọ màlúù méje wá, àti àgbò méje, àti ọ̀dọ́-àgùntàn méje àti òbúkọ méje gẹ́gẹ́ bí ẹbọ ẹ̀ṣẹ̀ fún ìjọba, fún ibi mímọ́ àti fún Juda. Ọba pàṣẹ fun àwọn àlùfáà, àwọn ọmọ Aaroni, láti ṣe èyí lórí pẹpẹ Olúwa.
Nao makĩrehe ndegwa mũgwanja, na ndũrũme mũgwanja, na tũtũrũme mũgwanja, o na thenge mũgwanja cia igongona rĩa kũhoroherio mehia makoniĩ ũthamaki ũcio, na ma handũ-harĩa-haamũre o na ma Juda. Nake mũthamaki agĩatha athĩnjĩri-Ngai, o acio a njiaro cia Harũni, macithĩnjĩre hau kĩgongona-inĩ kĩa Jehova.
22 Bẹ́ẹ̀ ni wọ́n sì pa akọ màlúù, àwọn àlùfáà mú ẹ̀jẹ̀ náà, wọ́n sì fi wọ́n ara pẹpẹ. Bẹ́ẹ̀ gẹ́gẹ́ ni nígbà tí wọ́n pa àgbò, wọ́n sì fi ẹ̀jẹ̀ wọ́n orí pẹpẹ. Nígbà náà wọ́n sì pa ọ̀dọ́-àgùntàn, wọ́n sì fi ẹ̀jẹ̀ wọn ara pẹpẹ.
Nĩ ũndũ ũcio magĩthĩnja ndegwa icio, nao athĩnjĩri-Ngai makĩoya thakame yacio makĩmĩminjaminjĩria kĩgongona; magĩcooka magĩthĩnja ndũrũme icio na makĩminjaminjĩria kĩgongona thakame yacio; magĩcooka magĩthĩnja tũtũrũme tũu na makĩminjaminjĩria kĩgongona thakame yatuo.
23 Òbúkọ fún ẹbọ ẹ̀ṣẹ̀ ni wọ́n gbé wá síwájú ọba àti ìjọ ènìyàn, wọ́n sì gbé ọwọ́ lé wọn.
Nacio thenge cia igongona rĩa kũhoroherio mehia ikĩrehwo mbere ya mũthamaki na kĩũngano kĩu, nao magĩciigĩrĩra moko.
24 Àwọn àlùfáà wọn sì pa òbúkọ, wọ́n sì gbé ẹ̀jẹ̀ kalẹ̀ lórí pẹpẹ fún ẹbọ ẹ̀ṣẹ̀ láti ṣe ètùtù fún gbogbo Israẹli, nítorí ọba ti pàṣẹ kí a ṣe ẹbọ sísun àti ẹbọ ẹ̀ṣẹ̀ fún gbogbo Israẹli.
Nao athĩnjĩri-Ngai magĩcooka magĩthĩnja thenge icio hamwe na thakame yacio, magĩcirutĩra hau kĩgongona-inĩ irĩ maruta ma kũhoroheria mehia nĩguo ihoroherie andũ a Isiraeli othe, nĩ tondũ mũthamaki nĩathanĩte kũrutwo iruta rĩa njino na iruta rĩa kũhoroheria mehia rĩrĩ rĩa andũ othe a Isiraeli.
25 Ó sì mú àwọn Lefi dúró nínú ilé Olúwa pẹ̀lú Kimbali, ohun èlò orin olókùn àti dùùrù ní ọ̀nà tí a ti paláṣẹ fún wọn láti ọ̀dọ̀ Dafidi àti Gadi aríran ọba àti Natani wòlíì. Èyí ni a pàṣẹ láti ọ̀dọ̀ Olúwa láti ọwọ́ àwọn wòlíì rẹ̀.
Mũthamaki akĩiga Alawii hekarũ-inĩ ya Jehova marĩ na thaani iria ihũũrithanagio ikagamba, na inanda cia mũgeeto na cia kĩnũbi ta ũrĩa gwaathanĩtwo nĩ Daudi na Gadi mũndũ ũrĩa wonagĩra mũthamaki maũndũ, na Nathani ũrĩa mũnabii; ũndũ ũyũ waathanĩtwo nĩ Jehova na tũnua twa anabii ake.
26 Bẹ́ẹ̀ ni àwọn ọmọ Lefi sì dúró pẹ̀lú ohun èlò orin Dafidi, àti àwọn àlùfáà pẹ̀lú ìpè wọn.
Nĩ ũndũ ũcio Alawii makĩrũgama mehaarĩirie na inanda cia Daudi cia kũina, na athĩnjĩri-Ngai marĩ na tũrumbeta twao.
27 Hesekiah sì pa á láṣẹ láti rú ẹbọ sísun lórí pẹpẹ, bí ẹbọ sísun náà ti bẹ̀rẹ̀, orin sí Olúwa bẹ̀rẹ̀ pẹ̀lú ìpè àti pẹ̀lú ohun èlò orin Dafidi ọba Israẹli.
Hezekia agĩathana atĩ kũrutwo iruta rĩa njino kĩgongona-inĩ. Narĩo igongona rĩambĩrĩria kũrutwo-rĩ, andũ makĩambĩrĩria kũinĩra Jehova marĩ na tũrumbeta na inanda cia kũina cia Daudi mũthamaki wa Isiraeli.
28 Gbogbo ìjọ ènìyàn náà sì wólẹ̀ sìn, àwọn akọrin kọrin, àwọn afùnpè sì fọn ìpè, gbogbo wọ̀nyí sì wà bẹ́ẹ̀ títí ẹbọ sísun náà fi parí tán.
Kĩũngano kĩu gĩothe gĩkĩinamĩrĩra, gĩkĩhooya, nao aini makĩinaga na tũrumbeta tũkĩhuhagwo. Maũndũ macio mothe magĩthiĩ na mbere nginya igongona rĩu rĩa njino rĩkĩrĩka kũrutwo.
29 Nígbà tí wọ́n sì ṣe ìparí ẹbọ rírú, ọba àti gbogbo àwọn tí ó wà pẹ̀lú rẹ̀ tẹ ara wọn ba, wọ́n sì sìn.
Na rĩrĩa maruta maarĩkirie kũrutwo-rĩ, mũthamaki na andũ othe arĩa maarĩ nake hau magĩturia maru makĩhooya.
30 Pẹ̀lúpẹ̀lú Hesekiah ọba, àti àwọn ìjòyè pàṣẹ fún àwọn ọmọ Lefi, láti fi ọ̀rọ̀ Dafidi àti ti Asafu aríran, kọrin ìyìn sí Olúwa: wọ́n sì fi inú dídùn kọrin ìyìn, wọ́n sì tẹrí wọn ba, wọ́n sì sìn.
Nake Mũthamaki Hezekia na anene ake magĩatha Alawii magooce Jehova na ciugo cia Daudi na cia Asafu mũndũ ũrĩa muoni-maũndũ. Nĩ ũndũ ũcio makĩina nyĩmbo cia kũgooca Jehova marĩ na gĩkeno na makĩinamia mĩtwe yao makĩmũhooya.
31 Nígbà náà ni Hesekiah dáhùn, ó sì wí pé, nísinsin yìí, ọwọ́ yín kún fún ẹ̀bùn fún Olúwa, ẹ súnmọ́ ìhín, kí ẹ sì mú ẹbọ àti ọrẹ-ọpẹ́ wá sínú ilé Olúwa. Ìjọ ènìyàn sì mú ẹbọ àti ọrẹ-ọpẹ́ wá; àti olúkúlùkù tí ọkàn rẹ̀ fẹ́, mú ẹbọ sísun wá.
Ningĩ Hezekia akiuga atĩrĩ, “Rĩu nĩmweyamũrĩra Jehova. Rehei magongona na maruta ma gũcookia ngaatho hekarũ-inĩ ya Jehova.” Nĩ ũndũ ũcio kĩũngano kĩu gĩkĩrehe magongona na maruta ma gũcookia ngaatho, na andũ othe arĩa ngoro ciao cieyendeire makĩrehe maruta ma njino.
32 Iye ẹbọ sísun, tí ìjọ ènìyàn mú wá, sì jẹ́ àádọ́rin akọ màlúù, àti ọgọ́rùn-ún àgbò, àti igba ọ̀dọ́-àgùntàn, gbogbo wọ̀nyí sì ni fún ẹbọ sísun sí Olúwa.
Naguo mũigana wa maruta ma njino marĩa maarehirwo nĩ kĩũngano kĩu warĩ ndegwa mĩrongo mũgwanja, na ndũrũme 100 na tũtũrũme 200, ciothe ciarĩ cia maruta ma njino ma kũrutĩrwo Jehova.
33 Àwọn ohun ìyàsímímọ́ sì jẹ́ ẹgbẹ̀ta màlúù, àti ẹgbẹ̀rún mẹ́ta àgùntàn.
Nyamũ ciothe iria ciaamũrĩtwo cia magongona ciarĩ ndegwa 600 na ngʼondu hamwe na mbũri 3,000.
34 Ṣùgbọ́n àwọn àlùfáà kò pọ̀ tó, wọn kò sì le bó gbogbo àwọn ẹran ẹbọ sísun náà: nítorí náà àwọn arákùnrin wọn, àwọn Lefi ràn wọ́n lọ́wọ́, títí iṣẹ́ náà fi parí, àti títí àwọn àlùfáà ìyókù fi yà wọ́n sí mímọ́: nítorí àwọn ọmọ Lefi ṣe olóòtítọ́ ní ọkàn ju àwọn àlùfáà lọ láti ya ara wọn sí mímọ́.
Na rĩrĩ, athĩnjĩri-Ngai maarĩ anini mũno matingĩahotire gũthĩnja nyamũ ciothe cia maruta ma njino; nĩ ũndũ ũcio andũ a nyũmba ciao, nĩo Alawii, makĩmateithĩrĩria nginya wĩra ũcio ũkĩrĩka nginya rĩrĩa athĩnjĩri-Ngai angĩ maamũrirwo, nĩgũkorwo Alawii maarĩ na kĩyo gĩa kwĩyamũra gũkĩra athĩnjĩri-Ngai.
35 Àti pẹ̀lú, àwọn ẹbọ sísun pàpọ̀jù, pẹ̀lú ọ̀rá ẹbọ àlàáfíà, pẹ̀lú ẹbọ ohun mímu fún ẹbọ sísun. Bẹ́ẹ̀ ni a sì tún bẹ̀rẹ̀ iṣẹ́ ìsìn ilé Olúwa.
Na rĩrĩ, nĩ kwarĩ na maruta ma njino maingĩ mũno, hamwe na maguta ma maruta ma ũiguano, o na maruta ma indo cia kũnyuuo marĩa maarutanagĩrio na maruta ma njino. Nĩ ũndũ ũcio wĩra wa ũtungata wa hekarũ ya Jehova ũgĩcookio rĩngĩ.
36 Hesekiah sì yọ̀, àti gbogbo ènìyàn pé, Ọlọ́run ti múra àwọn ènìyàn náà sílẹ̀, nítorí lójijì ni a ṣe nǹkan náà.
Nake Hezekia na andũ othe magĩkena nĩ ũndũ wa ũrĩa Ngai eekĩire andũ ake, tondũ ũndũ ũcio wekirwo narua mũno.

< 2 Chronicles 29 >