< 2 Chronicles 29 >
1 Hesekiah sì jẹ́ ẹni ọdún mẹ́ẹ̀ẹ́dọ́gbọ̀n nígbà tí ó di ọba, ó sì jẹ ọba ní Jerusalẹmu fún ọdún mọ́kàndínlọ́gbọ̀n orúkọ ìyá rẹ̀ sì ni Abijah ọmọbìnrin Sekariah.
Ezéchias avait vingt-cinq ans lorsqu'il monta sur le trône, et il régna vingt-neuf ans à Jérusalem; sa mère s'appelait Abia, fille de Zacharie.
2 Ó sì ṣe ohun tí ó tọ́ ní ojú Olúwa, gẹ́gẹ́ bí baba rẹ̀ Dafidi ti ṣe.
Et il fit ce qui est droit devant le Seigneur, se conformant à tout ce qu'avait fait David, son aïeul.
3 Ní oṣù àkọ́kọ́ ní ọdún kìn-ín-ní ìjọba rẹ̀, ó sì ṣí àwọn ìlẹ̀kùn ilé Olúwa ó sì tún wọn ṣe.
Dès qu'il fut affermi dans son royaume, le premier mois, il ouvrit les portes du temple du Seigneur, et il les restaura.
4 Ó sì mú àwọn àlùfáà wá àti àwọn ọmọ Lefi, ó sì kó wọn jọ yíká ìta ìlà-oòrùn.
Et il introduisit dans le temple les prêtres et les lévites, et il les réunit dans l'aile orientale de l'édifice.
5 Ó sì wí pé, “Ẹ gbọ́ tèmi, ẹ̀yin ọmọ Lefi! Ẹ ya ara yín sí mímọ́ nísinsin yìí kí ẹ sì ya ilé Olúwa Ọlọ́run sí mímọ́, kí ẹ sì kó ohun àìmọ́ baba mi jáde kúrò ní ibi mímọ́.
Et il leur dit: Écoutez, lévites, purifiez-vous d'abord; puis, vous purifierez le temple du Dieu de vos pères, et vous rejetterez toute impureté du lien saint.
6 Àwọn baba wa jẹ́ aláìṣòótọ́; wọ́n sì ṣe ohun àìtọ́ níwájú Olúwa Ọlọ́run wa, wọ́n sì kọ̀ ọ́ sílẹ̀. Wọ́n sì yí ojú wọn padà kúrò ní ibùgbé Olúwa, wọ́n sì pa ẹ̀yìn wọn dà sí i.
Car VOS père se sont pervertis et ils ont fait le mal devant le Seigneur notre Dieu; ils l'ont abandonné, ils ont détourné leur face du tabernacle du Seigneur, et s'en sont éloignés.
7 Wọ́n sì tún ti ìlẹ̀kùn ìloro náà pẹ̀lú, wọ́n sì pa fìtílà. Wọn kò sì sun tùràrí tàbí pèsè ẹbọ sísun si ibi mímọ́ si Ọlọ́run Israẹli.
Ils ont fermé les portes du temple, ils ont éteint les lampes, ils n'ont plus brûlé d'encens, ils ont cessé d'offrir des holocaustes dans le lieu saint du Dieu d'Israël.
8 Nítorí náà, ìbínú Olúwa ti ru sókè wá sórí Juda àti Jerusalẹmu ó sì ti fi wọ́n ṣe ohun èlò fún wàhálà, àti ìdààmú àti ẹ̀sín, gẹ́gẹ́ bí ó ti ṣe fi ojú rẹ̀ rí i.
Alors, le Seigneur s'est vivement irrité contre Juda et contre Jérusalem; il les a livrés au trouble, à l'extermination et aux railleries, comme vous l'avez vu de vos yeux.
9 Ìdí nìyí tí àwọn baba wa ṣe ṣubú nípa idà àti ìdí tí àwọn ọmọkùnrin àti ọmọbìnrin àti àwọn aya wa tiwọn kó wọ́n ní ìgbèkùn.
Vos pères ont été frappés par le glaive; vos fils, vos filles et vos femmes, ont été emmenés captifs en une contrée étrangère, où ils sont encore.
10 Nísinsin yìí ó wà ní ọkàn mi láti bá Olúwa Ọlọ́run Israẹli dá májẹ̀mú. Bẹ́ẹ̀ ni kí ìbínú rẹ̀ kíkan kí ó lè yípadà kúrò lọ́dọ̀ wa.
A cause de cela, il est maintenant en mon cœur de faire alliance avec le Seigneur Dieu d'Israël, et il détournera de nous sa terrible colère.
11 Àwọn ọmọ mi, ẹ má ṣe jáfara nísinsin yìí, nítorí tí Olúwa ti yàn yín láti dúró níwájú rẹ̀ láti sin, kí ẹ sì máa ṣe ìránṣẹ́ níwájú rẹ̀ àti láti sun tùràrí.”
Ne différez pas, car le Seigneur vous a choisis pour que vous vous teniez en sa présence, pour que vous le serviez et que vous brûliez devant lui de l'encens.
12 Nígbà náà àwọn ọmọ Lefi wọ̀nyí múra láti ṣe iṣẹ́: nínú àwọn ọmọ Kohati, Mahati ọmọ Amasai: àti Joẹli ọmọ Asariah; nínú àwọn ọmọ Merari, Kiṣi ọmọ Abdi àti Asariah ọmọ Jehaleeli; nínú àwọn ọmọ Gerṣoni, Joah, ọmọ Simma àti Edeni ọmọ Joah;
Et les lévites se levèrent, savoir: Des fils de Caath, Maath, fils d'Amasi, et Johel, fils d'Azarias; des fils de Mérari: Cis, fils d'Abdi, et Azarias, fils d'Ilaélel; des fils de Gerson: Jodaad, fils de Zemmath, et Joadam; ceux-ci descendaient de Joacha;
13 nínú àwọn ọmọ Elisafani, Ṣimri àti Jeieli; nínú àwọn ọmọ Asafu, Sekariah àti Mattaniah;
Des fils d'Elisaphan: Zambri et Jehiel; des fils d'Asaph: Zacharie et Matlhanias;
14 nínú àwọn ọmọ Hemani, Jehieli àti Ṣimei; nínú àwọn ọmọ Jedutuni, Ṣemaiah àti Usieli.
Des fils d'Hêman: Jehiel et Sémeï; des fils d'Idithun: Samaias et Oziel.
15 Nígbà tí wọ́n sì ti kó ara wọn jọ pọ̀ pẹ̀lú àwọn arákùnrin wọn, wọ́n sì ya ara wọn sí mímọ́, wọ́n sì lọ láti gbá ilé Olúwa mọ́, gẹ́gẹ́ bí ọba ti pa á láṣẹ, ẹ tẹ̀lé ọ̀rọ̀ Olúwa.
Et ils réunirent leurs frères, et ils se purifièrent selon l'ordre du roi, pour purifier ensuite le peuple du Seigneur, comme lui-même l'avait prescrit.
16 Àwọn àlùfáà sì wọ inú ilé Olúwa lọ́hùn ún lọ láti gbá a mọ́. Wọ́n sì gbé e jáde sí inú àgbàlá ilé Olúwa gbogbo ohun àìmọ́ tí wọ́n rí nínú ilé Olúwa. Àwọn ọmọ Lefi sì mú u wọ́n sì gbangba odò Kidironi.
Et les prêtres entrèrent dans le temple du Seigneur pour le purifier, et ils rejetèrent toute impureté qu'ils trouvèrent dans le temple et dans le parvis; puis, les lévites prirent les choses impures pour les porter au torrent de Cédron.
17 Wọ́n sì bẹ̀rẹ̀ ìyàsímímọ́ ní ọjọ́ kìn-ín-ní oṣù kìn-ín-ní, àti ní ọjọ́ kẹjọ oṣù náà wọ́n sì dé ìloro Olúwa. Fún ọjọ́ mẹ́jọ mìíràn sí i, wọ́n sì ya ilé Olúwa sí mímọ́ fúnra rẹ̀. Wọ́n sì parí ní ọjọ́ kẹrìndínlógún oṣù kìn-ín-ní.
La purification commença le premier jour du premier mois, pendant la nouvelle lune, et, le huitième jour, ils entrèrent dans le temple du Seigneur, et ils le purifièrent en huit jours; le seizième jour du premier mois, tout était terminé.
18 Nígbà náà wọn sì lọ sí ọ̀dọ̀ ọba Hesekiah láti lọ jábọ̀ fún un: “Àwa ti gbá ilé Olúwa mọ́, pẹpẹ ẹbọ sísun pẹ̀lú gbogbo ohun ẹbọ rẹ̀, àti tábìlì àkàrà ìfihàn, pẹ̀lú gbogbo ohun èlò.
Et ils allèrent trouver le roi Ezéchias, et ils lui dirent: Nous avons tout purifié dans le temple du Seigneur: l'autel des holocaustes et ses ustensiles, la table de proposition et ses accessoires.
19 A ti pèsè a sì ti yà sí mímọ́ gbogbo ohun èlò tí ọba Ahasi ti sọ di aláìmọ́ nínú àìṣòótọ́ rẹ̀ nígbà tí ó jẹ́ ọba; nísinsin yìí, wọ́n wà níwájú pẹpẹ Olúwa.”
Tous les objets que le roi Achaz avait souillés pendant son règne et son apostasie, nous les avons purifiés 'et mis en ordre; voilà que tout est exposé devant l'autel du Seigneur.
20 Ní kùtùkùtù òwúrọ̀ ọjọ́ kejì, ọba Hesekiah sì kó olórí àwọn ìjòyè jọ, ó sì lọ sókè ilé Olúwa.
Et le roi Ezéchias se leva de grand matin, et il assembla tous les chefs de la ville, et il monta au temple du Seigneur.
21 Wọ́n sì mú akọ màlúù méje wá, àti àgbò méje, àti ọ̀dọ́-àgùntàn méje àti òbúkọ méje gẹ́gẹ́ bí ẹbọ ẹ̀ṣẹ̀ fún ìjọba, fún ibi mímọ́ àti fún Juda. Ọba pàṣẹ fun àwọn àlùfáà, àwọn ọmọ Aaroni, láti ṣe èyí lórí pẹpẹ Olúwa.
Et il offrit sept bœufs, sept béliers, sept agneaux et sept boucs, pour les péchés, pour le royaume, pour les saints et pour Israël; et il dit aux prêtres, fils d'Aaron, de monter à l'autel du Seigneur.
22 Bẹ́ẹ̀ ni wọ́n sì pa akọ màlúù, àwọn àlùfáà mú ẹ̀jẹ̀ náà, wọ́n sì fi wọ́n ara pẹpẹ. Bẹ́ẹ̀ gẹ́gẹ́ ni nígbà tí wọ́n pa àgbò, wọ́n sì fi ẹ̀jẹ̀ wọ́n orí pẹpẹ. Nígbà náà wọ́n sì pa ọ̀dọ́-àgùntàn, wọ́n sì fi ẹ̀jẹ̀ wọn ara pẹpẹ.
Et ils immolèrent les bœufs, et ils recueillirent le sang, et ils le répandirent sur l'autel; et ils immolèrent les béliers, et ils répandirent le sang sur l'autel; et ils immolèrent les agneaux, et ils répandirent le sang sur l'autel.
23 Òbúkọ fún ẹbọ ẹ̀ṣẹ̀ ni wọ́n gbé wá síwájú ọba àti ìjọ ènìyàn, wọ́n sì gbé ọwọ́ lé wọn.
Et ils traînèrent devant le roi et devant l'assemblée entière les boucs pour les péchés, et ils imposèrent sur eux les mains;
24 Àwọn àlùfáà wọn sì pa òbúkọ, wọ́n sì gbé ẹ̀jẹ̀ kalẹ̀ lórí pẹpẹ fún ẹbọ ẹ̀ṣẹ̀ láti ṣe ètùtù fún gbogbo Israẹli, nítorí ọba ti pàṣẹ kí a ṣe ẹbọ sísun àti ẹbọ ẹ̀ṣẹ̀ fún gbogbo Israẹli.
Et les prêtres les immolèrent, et ils firent l'expiation en versant leur sang devant l'autel, et ils firent l'expiation en faveur de tout Israël; car le roi avait dit: L'holocauste et le sacrifice pour les péchés sont pour tout Israël.
25 Ó sì mú àwọn Lefi dúró nínú ilé Olúwa pẹ̀lú Kimbali, ohun èlò orin olókùn àti dùùrù ní ọ̀nà tí a ti paláṣẹ fún wọn láti ọ̀dọ̀ Dafidi àti Gadi aríran ọba àti Natani wòlíì. Èyí ni a pàṣẹ láti ọ̀dọ̀ Olúwa láti ọwọ́ àwọn wòlíì rẹ̀.
Et il établit les lévites dans le temple du Seigneur au son des cymbales, des cithares et des harpes, comme l'avait réglé le roi David, d'accord avec Gad le voyant, et Nathan le prophète; car le Seigneur transmet ses commandements par les prophètes.
26 Bẹ́ẹ̀ ni àwọn ọmọ Lefi sì dúró pẹ̀lú ohun èlò orin Dafidi, àti àwọn àlùfáà pẹ̀lú ìpè wọn.
Les lévites furent installés au son des instruments de David, et les prêtres au son des trompettes sacrées.
27 Hesekiah sì pa á láṣẹ láti rú ẹbọ sísun lórí pẹpẹ, bí ẹbọ sísun náà ti bẹ̀rẹ̀, orin sí Olúwa bẹ̀rẹ̀ pẹ̀lú ìpè àti pẹ̀lú ohun èlò orin Dafidi ọba Israẹli.
Ensuite, Ezéchias ordonna de porter l'holocauste sur l'autel; et, lorsque l'on commença l'offrande de l'holocauste, on commença à chanter les louanges du Seigneur, au son des trompettes et des instruments de David, roi d'Israël.
28 Gbogbo ìjọ ènìyàn náà sì wólẹ̀ sìn, àwọn akọrin kọrin, àwọn afùnpè sì fọn ìpè, gbogbo wọ̀nyí sì wà bẹ́ẹ̀ títí ẹbọ sísun náà fi parí tán.
Et toute l'Église adora, et les chantres-harpistes chantèrent, et les trompettes sonnèrent jusqu'à ce que l'holocauste fût achevé.
29 Nígbà tí wọ́n sì ṣe ìparí ẹbọ rírú, ọba àti gbogbo àwọn tí ó wà pẹ̀lú rẹ̀ tẹ ara wọn ba, wọ́n sì sìn.
Et, lorsque les victimes furent consumées, le roi se prosterna, ainsi que toute l'assistance, et ils adorèrent.
30 Pẹ̀lúpẹ̀lú Hesekiah ọba, àti àwọn ìjòyè pàṣẹ fún àwọn ọmọ Lefi, láti fi ọ̀rọ̀ Dafidi àti ti Asafu aríran, kọrin ìyìn sí Olúwa: wọ́n sì fi inú dídùn kọrin ìyìn, wọ́n sì tẹrí wọn ba, wọ́n sì sìn.
Et le roi Ezéchias et les princes dirent aux lévites de chanter au Seigneur les psaumes tant du roi David que du prophète Asaph; ils chantèrent avec allégresse; puis, se prosternant, ils adorèrent.
31 Nígbà náà ni Hesekiah dáhùn, ó sì wí pé, nísinsin yìí, ọwọ́ yín kún fún ẹ̀bùn fún Olúwa, ẹ súnmọ́ ìhín, kí ẹ sì mú ẹbọ àti ọrẹ-ọpẹ́ wá sínú ilé Olúwa. Ìjọ ènìyàn sì mú ẹbọ àti ọrẹ-ọpẹ́ wá; àti olúkúlùkù tí ọkàn rẹ̀ fẹ́, mú ẹbọ sísun wá.
Et le roi Ézéchias prit la parole, et dit: Maintenant que vous vous êtes consacrés au Seigneur, amenez et offrez les victimes de louanges dans le temple du, Seigneur; et l'Église offrit dans le temple des sacrifices et des louanges; et ceux qui avaient le cœur plein de zèle amenèrent des holocaustes.
32 Iye ẹbọ sísun, tí ìjọ ènìyàn mú wá, sì jẹ́ àádọ́rin akọ màlúù, àti ọgọ́rùn-ún àgbò, àti igba ọ̀dọ́-àgùntàn, gbogbo wọ̀nyí sì ni fún ẹbọ sísun sí Olúwa.
Voici le nombre des holocaustes qu'offrit l'Église: soixante-dix bœufs, cent béliers, deux cents agneaux; tous pour les holocaustes au Seigneur.
33 Àwọn ohun ìyàsímímọ́ sì jẹ́ ẹgbẹ̀ta màlúù, àti ẹgbẹ̀rún mẹ́ta àgùntàn.
Il y eut en outre: six cents bœufs consacrés, et trois mille brebis.
34 Ṣùgbọ́n àwọn àlùfáà kò pọ̀ tó, wọn kò sì le bó gbogbo àwọn ẹran ẹbọ sísun náà: nítorí náà àwọn arákùnrin wọn, àwọn Lefi ràn wọ́n lọ́wọ́, títí iṣẹ́ náà fi parí, àti títí àwọn àlùfáà ìyókù fi yà wọ́n sí mímọ́: nítorí àwọn ọmọ Lefi ṣe olóòtítọ́ ní ọkàn ju àwọn àlùfáà lọ láti ya ara wọn sí mímọ́.
Or, les prêtres étaient en petit nombre, et ils ne suffisaient pas à enlever les peaux des victimes; leurs frères, les lévites, les aidèrent jusqu'à ce que l'œuvre fût achevée, et que les prêtres se fussent purifiés; car les lévites sont plus promptement purifiés que les prêtres.
35 Àti pẹ̀lú, àwọn ẹbọ sísun pàpọ̀jù, pẹ̀lú ọ̀rá ẹbọ àlàáfíà, pẹ̀lú ẹbọ ohun mímu fún ẹbọ sísun. Bẹ́ẹ̀ ni a sì tún bẹ̀rẹ̀ iṣẹ́ ìsìn ilé Olúwa.
Il y eut donc nombre de victimes pour les holocaustes; on brûla en grande quantité la graisse des hosties pacifiques, on répandit à flots les libations de l'holocauste, et les cérémonies du temple furent rétablies.
36 Hesekiah sì yọ̀, àti gbogbo ènìyàn pé, Ọlọ́run ti múra àwọn ènìyàn náà sílẹ̀, nítorí lójijì ni a ṣe nǹkan náà.
Et Ezéchias et tout le peuple ressentirent une vive allégresse de ce que Dieu avait préparé cette fête à son peuple; car la chose s'était faite soudainement.