< 2 Chronicles 29 >

1 Hesekiah sì jẹ́ ẹni ọdún mẹ́ẹ̀ẹ́dọ́gbọ̀n nígbà tí ó di ọba, ó sì jẹ ọba ní Jerusalẹmu fún ọdún mọ́kàndínlọ́gbọ̀n orúkọ ìyá rẹ̀ sì ni Abijah ọmọbìnrin Sekariah.
Ezéchias avait vingt-cinq ans à son avènement; il régna vingt-neuf ans à Jérusalem; sa mère se nommait Abiyya, fille de Zacharie.
2 Ó sì ṣe ohun tí ó tọ́ ní ojú Olúwa, gẹ́gẹ́ bí baba rẹ̀ Dafidi ti ṣe.
Il fit ce qui est droit aux yeux de l’Eternel, absolument comme avait agi David, son aïeul.
3 Ní oṣù àkọ́kọ́ ní ọdún kìn-ín-ní ìjọba rẹ̀, ó sì ṣí àwọn ìlẹ̀kùn ilé Olúwa ó sì tún wọn ṣe.
C’Est lui qui, la première année de son règne, le premier mois, rouvrit les portes du temple de l’Eternel et les restaura.
4 Ó sì mú àwọn àlùfáà wá àti àwọn ọmọ Lefi, ó sì kó wọn jọ yíká ìta ìlà-oòrùn.
Il fit venir les prêtres et les Lévites et les réunit à la place orientale.
5 Ó sì wí pé, “Ẹ gbọ́ tèmi, ẹ̀yin ọmọ Lefi! Ẹ ya ara yín sí mímọ́ nísinsin yìí kí ẹ sì ya ilé Olúwa Ọlọ́run sí mímọ́, kí ẹ sì kó ohun àìmọ́ baba mi jáde kúrò ní ibi mímọ́.
Puis il leur dit: "Ecoutez-moi, Lévites: à présent, sanctifiez-vous, sanctifiez le temple de l’Eternel, Dieu de vos pères, et faites sortir toute souillure du sanctuaire.
6 Àwọn baba wa jẹ́ aláìṣòótọ́; wọ́n sì ṣe ohun àìtọ́ níwájú Olúwa Ọlọ́run wa, wọ́n sì kọ̀ ọ́ sílẹ̀. Wọ́n sì yí ojú wọn padà kúrò ní ibùgbé Olúwa, wọ́n sì pa ẹ̀yìn wọn dà sí i.
Car nos pères ont été infidèles et ont fait le mal aux yeux de l’Eternel, notre Dieu; ils l’ont abandonné, ont détourné leur face du sanctuaire de l’Eternel et lui ont tourné le dos.
7 Wọ́n sì tún ti ìlẹ̀kùn ìloro náà pẹ̀lú, wọ́n sì pa fìtílà. Wọn kò sì sun tùràrí tàbí pèsè ẹbọ sísun si ibi mímọ́ si Ọlọ́run Israẹli.
Ils ont même fermé les portes du vestibule, éteint les lampes, n’ont point fait fumer d’encens ni offert d’holocaustes dans le sanctuaire au Dieu d’Israël.
8 Nítorí náà, ìbínú Olúwa ti ru sókè wá sórí Juda àti Jerusalẹmu ó sì ti fi wọ́n ṣe ohun èlò fún wàhálà, àti ìdààmú àti ẹ̀sín, gẹ́gẹ́ bí ó ti ṣe fi ojú rẹ̀ rí i.
Aussi le courroux de l’Eternel s’est-il abattu sur Juda et Jérusalem, il a fait d’eux un objet d’horreur, de désolation et de raillerie comme vous le constatez de vos yeux.
9 Ìdí nìyí tí àwọn baba wa ṣe ṣubú nípa idà àti ìdí tí àwọn ọmọkùnrin àti ọmọbìnrin àti àwọn aya wa tiwọn kó wọ́n ní ìgbèkùn.
Et voyez: nos pères sont tombés sous le glaive, nos fils, nos filles et nos femmes ont été emmenés captifs à cause de cela.
10 Nísinsin yìí ó wà ní ọkàn mi láti bá Olúwa Ọlọ́run Israẹli dá májẹ̀mú. Bẹ́ẹ̀ ni kí ìbínú rẹ̀ kíkan kí ó lè yípadà kúrò lọ́dọ̀ wa.
Maintenant j’ai à cœur de contracter alliance avec l’Eternel, Dieu d’Israël, pour qu’il détourne de nous la flamme de sa colère.
11 Àwọn ọmọ mi, ẹ má ṣe jáfara nísinsin yìí, nítorí tí Olúwa ti yàn yín láti dúró níwájú rẹ̀ láti sin, kí ẹ sì máa ṣe ìránṣẹ́ níwájú rẹ̀ àti láti sun tùràrí.”
O mes fils, à présent point de négligence, car c’est de vous que l’Eternel a fait choix pour vous tenir prêts devant lui à le servir, pour être ses ministres et lui offrir l’encens."
12 Nígbà náà àwọn ọmọ Lefi wọ̀nyí múra láti ṣe iṣẹ́: nínú àwọn ọmọ Kohati, Mahati ọmọ Amasai: àti Joẹli ọmọ Asariah; nínú àwọn ọmọ Merari, Kiṣi ọmọ Abdi àti Asariah ọmọ Jehaleeli; nínú àwọn ọmọ Gerṣoni, Joah, ọmọ Simma àti Edeni ọmọ Joah;
Alors se levèrent les Lévites, Mahat, fils d’Amachaï, Joël, fils d’Azariahou, des enfants de Kehat; des enfants de Merari, Kich, fils d’Abdi, et Azariahou, fils de Yehallélel; des Gersonites, Yoah, fils de Zimma, et Eden, fils de Yoah;
13 nínú àwọn ọmọ Elisafani, Ṣimri àti Jeieli; nínú àwọn ọmọ Asafu, Sekariah àti Mattaniah;
des enfants d’Eliçafan, Chimri et Yeïêl; des enfants d’Assaph, Zacharie et Mattanyahou;
14 nínú àwọn ọmọ Hemani, Jehieli àti Ṣimei; nínú àwọn ọmọ Jedutuni, Ṣemaiah àti Usieli.
des enfants de Hêman, Yehïêl et Chimeï, et des enfants de Yedoutoun, Chemaya et Ouzziêl.
15 Nígbà tí wọ́n sì ti kó ara wọn jọ pọ̀ pẹ̀lú àwọn arákùnrin wọn, wọ́n sì ya ara wọn sí mímọ́, wọ́n sì lọ láti gbá ilé Olúwa mọ́, gẹ́gẹ́ bí ọba ti pa á láṣẹ, ẹ tẹ̀lé ọ̀rọ̀ Olúwa.
Ils rassemblèrent leurs frères, se sanctifièrent et vinrent selon l’ordre du roi, conforme aux prescriptions de l’Eternel, pour purifier le temple de l’Eternel.
16 Àwọn àlùfáà sì wọ inú ilé Olúwa lọ́hùn ún lọ láti gbá a mọ́. Wọ́n sì gbé e jáde sí inú àgbàlá ilé Olúwa gbogbo ohun àìmọ́ tí wọ́n rí nínú ilé Olúwa. Àwọn ọmọ Lefi sì mú u wọ́n sì gbangba odò Kidironi.
Les prêtres pénétrèrent à l’intérieur du temple de l’Eternel pour le purifier; ils rejetèrent dans le parvis du temple de l’Eternel toutes les impuretés qu’ils trouvèrent dans le sanctuaire de l’Eternel, et les Lévites les reçurent pour les transporter dehors au ravin du Cédron.
17 Wọ́n sì bẹ̀rẹ̀ ìyàsímímọ́ ní ọjọ́ kìn-ín-ní oṣù kìn-ín-ní, àti ní ọjọ́ kẹjọ oṣù náà wọ́n sì dé ìloro Olúwa. Fún ọjọ́ mẹ́jọ mìíràn sí i, wọ́n sì ya ilé Olúwa sí mímọ́ fúnra rẹ̀. Wọ́n sì parí ní ọjọ́ kẹrìndínlógún oṣù kìn-ín-ní.
Ils commencèrent cette sanctification le premier du premier mois, et le huitième jour du mois ils vinrent dans le vestibule de l’Eternel et sanctifièrent le temple de l’Eternel en huit jours; ce fut le seizième jour du premier mois qu’ils terminèrent.
18 Nígbà náà wọn sì lọ sí ọ̀dọ̀ ọba Hesekiah láti lọ jábọ̀ fún un: “Àwa ti gbá ilé Olúwa mọ́, pẹpẹ ẹbọ sísun pẹ̀lú gbogbo ohun ẹbọ rẹ̀, àti tábìlì àkàrà ìfihàn, pẹ̀lú gbogbo ohun èlò.
Puis, ils vinrent à l’intérieur auprès du roi Ezéchias et lui dirent: "Nous avons purifié tout le temple de l’Eternel, l’autel des holocaustes avec tous ses ustensiles, et la table de proposition avec tous ses ustensiles.
19 A ti pèsè a sì ti yà sí mímọ́ gbogbo ohun èlò tí ọba Ahasi ti sọ di aláìmọ́ nínú àìṣòótọ́ rẹ̀ nígbà tí ó jẹ́ ọba; nísinsin yìí, wọ́n wà níwájú pẹpẹ Olúwa.”
Tous les ustensiles que le roi Achaz avait écartés durant son règne, dans son infidélité, nous les avons réparés et consacrés, et ils se trouvent maintenant devant l’autel du Seigneur."
20 Ní kùtùkùtù òwúrọ̀ ọjọ́ kejì, ọba Hesekiah sì kó olórí àwọn ìjòyè jọ, ó sì lọ sókè ilé Olúwa.
Le roi Ezéchias se leva de bon matin, assembla les chefs de la ville, et monta au temple de l’Eternel.
21 Wọ́n sì mú akọ màlúù méje wá, àti àgbò méje, àti ọ̀dọ́-àgùntàn méje àti òbúkọ méje gẹ́gẹ́ bí ẹbọ ẹ̀ṣẹ̀ fún ìjọba, fún ibi mímọ́ àti fún Juda. Ọba pàṣẹ fun àwọn àlùfáà, àwọn ọmọ Aaroni, láti ṣe èyí lórí pẹpẹ Olúwa.
On amena sept taureaux, sept béliers, sept agneaux et sept boucs expiatoires pour la royauté, pour le sanctuaire et pour Juda, et il prescrivit aux prêtres de la famille d’Aaron de les offrir sur l’autel de l’Eternel.
22 Bẹ́ẹ̀ ni wọ́n sì pa akọ màlúù, àwọn àlùfáà mú ẹ̀jẹ̀ náà, wọ́n sì fi wọ́n ara pẹpẹ. Bẹ́ẹ̀ gẹ́gẹ́ ni nígbà tí wọ́n pa àgbò, wọ́n sì fi ẹ̀jẹ̀ wọ́n orí pẹpẹ. Nígbà náà wọ́n sì pa ọ̀dọ́-àgùntàn, wọ́n sì fi ẹ̀jẹ̀ wọn ara pẹpẹ.
Alors ils immolèrent les taureaux, et les prêtres reçurent le sang et en aspergèrent l’autel. Ils immolèrent les béliers et lancèrent le sang sur l’autel. Ils immolèrent les agneaux et lancèrent le sang sur l’autel.
23 Òbúkọ fún ẹbọ ẹ̀ṣẹ̀ ni wọ́n gbé wá síwájú ọba àti ìjọ ènìyàn, wọ́n sì gbé ọwọ́ lé wọn.
Puis ils amenèrent les boucs expiatoires devant le roi et le peuple et imposèrent leurs mains sur eux.
24 Àwọn àlùfáà wọn sì pa òbúkọ, wọ́n sì gbé ẹ̀jẹ̀ kalẹ̀ lórí pẹpẹ fún ẹbọ ẹ̀ṣẹ̀ láti ṣe ètùtù fún gbogbo Israẹli, nítorí ọba ti pàṣẹ kí a ṣe ẹbọ sísun àti ẹbọ ẹ̀ṣẹ̀ fún gbogbo Israẹli.
Les prêtres les immolèrent et offrirent leur sang sur l’autel pour faire propitiation sur tout Israël, car c’est pour tout Israël que le roi avait prescrit l’holocauste et l’expiatoire.
25 Ó sì mú àwọn Lefi dúró nínú ilé Olúwa pẹ̀lú Kimbali, ohun èlò orin olókùn àti dùùrù ní ọ̀nà tí a ti paláṣẹ fún wọn láti ọ̀dọ̀ Dafidi àti Gadi aríran ọba àti Natani wòlíì. Èyí ni a pàṣẹ láti ọ̀dọ̀ Olúwa láti ọwọ́ àwọn wòlíì rẹ̀.
Il posta les Lévites dans le temple de l’Eternel avec des cymbales, des luths et des harpes, selon l’ordonnance de David, de Gad, Voyant du roi, et du prophète Nathan, car l’ordre en avait été donné par Dieu, par l’entremise de ses prophètes.
26 Bẹ́ẹ̀ ni àwọn ọmọ Lefi sì dúró pẹ̀lú ohun èlò orin Dafidi, àti àwọn àlùfáà pẹ̀lú ìpè wọn.
Les Lévites se tinrent avec les instruments de David, et les prêtres avec les trompettes.
27 Hesekiah sì pa á láṣẹ láti rú ẹbọ sísun lórí pẹpẹ, bí ẹbọ sísun náà ti bẹ̀rẹ̀, orin sí Olúwa bẹ̀rẹ̀ pẹ̀lú ìpè àti pẹ̀lú ohun èlò orin Dafidi ọba Israẹli.
Puis, Ezéchias ordonna d’offrir l’holocauste sur l’autel, et en même temps que l’holocauste commencèrent le cantique à l’Eternel et les trompettes, avec accompagnement des instruments de David, roi d’Israël.
28 Gbogbo ìjọ ènìyàn náà sì wólẹ̀ sìn, àwọn akọrin kọrin, àwọn afùnpè sì fọn ìpè, gbogbo wọ̀nyí sì wà bẹ́ẹ̀ títí ẹbọ sísun náà fi parí tán.
Toute l’assemblée se prosternait, les chants s’élevaient, et les trompettes sonnaient, tout cela jusqu’à l’achèvement de l’holocauste.
29 Nígbà tí wọ́n sì ṣe ìparí ẹbọ rírú, ọba àti gbogbo àwọn tí ó wà pẹ̀lú rẹ̀ tẹ ara wọn ba, wọ́n sì sìn.
Dès que fut terminé l’holocauste; le roi et tous ceux qui étaient avec lui fléchirent les genoux et se prosternèrent.
30 Pẹ̀lúpẹ̀lú Hesekiah ọba, àti àwọn ìjòyè pàṣẹ fún àwọn ọmọ Lefi, láti fi ọ̀rọ̀ Dafidi àti ti Asafu aríran, kọrin ìyìn sí Olúwa: wọ́n sì fi inú dídùn kọrin ìyìn, wọ́n sì tẹrí wọn ba, wọ́n sì sìn.
Alors le roi Ezéchias et les chefs ordonnèrent aux Lévites de louer le Seigneur sur les paroles de David et d’Assaph, le Voyant, et ils chantèrent avec allégresse, s’inclinèrent et se prosternèrent.
31 Nígbà náà ni Hesekiah dáhùn, ó sì wí pé, nísinsin yìí, ọwọ́ yín kún fún ẹ̀bùn fún Olúwa, ẹ súnmọ́ ìhín, kí ẹ sì mú ẹbọ àti ọrẹ-ọpẹ́ wá sínú ilé Olúwa. Ìjọ ènìyàn sì mú ẹbọ àti ọrẹ-ọpẹ́ wá; àti olúkúlùkù tí ọkàn rẹ̀ fẹ́, mú ẹbọ sísun wá.
Puis Ezéchias prit la parole et dit: "Maintenant, vous vous êtes consacrés à l’Eternel, approchez et offrez des victimes et des sacrifices d’actions de grâces dans le temple de l’Eternel", et l’assemblée offrit des victimes et des sacrifices d’actions de grâces, et, selon les libéralités, des holocaustes.
32 Iye ẹbọ sísun, tí ìjọ ènìyàn mú wá, sì jẹ́ àádọ́rin akọ màlúù, àti ọgọ́rùn-ún àgbò, àti igba ọ̀dọ́-àgùntàn, gbogbo wọ̀nyí sì ni fún ẹbọ sísun sí Olúwa.
Le nombre des holocaustes qu’offrit l’assemblée fut de soixante-dix têtes de gros bétail, cent béliers, deux cents agneaux; tout cela fut offert en holocauste à l’Eternel.
33 Àwọn ohun ìyàsímímọ́ sì jẹ́ ẹgbẹ̀ta màlúù, àti ẹgbẹ̀rún mẹ́ta àgùntàn.
Les autres sacrifices furent de six cents têtes de gros et de trois mille têtes de menu bétail.
34 Ṣùgbọ́n àwọn àlùfáà kò pọ̀ tó, wọn kò sì le bó gbogbo àwọn ẹran ẹbọ sísun náà: nítorí náà àwọn arákùnrin wọn, àwọn Lefi ràn wọ́n lọ́wọ́, títí iṣẹ́ náà fi parí, àti títí àwọn àlùfáà ìyókù fi yà wọ́n sí mímọ́: nítorí àwọn ọmọ Lefi ṣe olóòtítọ́ ní ọkàn ju àwọn àlùfáà lọ láti ya ara wọn sí mímọ́.
Seulement les prêtres furent en trop petit nombre et ils ne purent dépouiller tous les holocaustes; ils furent secondés par leurs frères, les Lévites, jusqu’à ce que fût achevée la besogne et que les prêtres se fussent purifiés, car les Lévites étaient plus consciencieux pour se sanctifier que les prêtres.
35 Àti pẹ̀lú, àwọn ẹbọ sísun pàpọ̀jù, pẹ̀lú ọ̀rá ẹbọ àlàáfíà, pẹ̀lú ẹbọ ohun mímu fún ẹbọ sísun. Bẹ́ẹ̀ ni a sì tún bẹ̀rẹ̀ iṣẹ́ ìsìn ilé Olúwa.
Il y eut aussi quantité d’holocaustes avec les graisses des sacrifices rémunératoires et avec les libations des holocaustes. Ainsi fut rétabli le service du temple de l’Eternel.
36 Hesekiah sì yọ̀, àti gbogbo ènìyàn pé, Ọlọ́run ti múra àwọn ènìyàn náà sílẹ̀, nítorí lójijì ni a ṣe nǹkan náà.
Ezéchias et tout le peuple se réjouirent de ce que Dieu eût agi en faveur du peuple, car la chose se fit rapidement.

< 2 Chronicles 29 >