< 2 Chronicles 29 >

1 Hesekiah sì jẹ́ ẹni ọdún mẹ́ẹ̀ẹ́dọ́gbọ̀n nígbà tí ó di ọba, ó sì jẹ ọba ní Jerusalẹmu fún ọdún mọ́kàndínlọ́gbọ̀n orúkọ ìyá rẹ̀ sì ni Abijah ọmọbìnrin Sekariah.
Therfor Ezechie bigan to regne, whanne he was of fyue and twenti yeer, and he regnede in Jerusalem nyne and twenti yeer; the name of his modir was Abia, the douytir of Zacharie.
2 Ó sì ṣe ohun tí ó tọ́ ní ojú Olúwa, gẹ́gẹ́ bí baba rẹ̀ Dafidi ti ṣe.
And he dide that, that was pleasaunt in the siyt of the Lord, bi alle thingis whiche Dauid, his fadir, hadde do.
3 Ní oṣù àkọ́kọ́ ní ọdún kìn-ín-ní ìjọba rẹ̀, ó sì ṣí àwọn ìlẹ̀kùn ilé Olúwa ó sì tún wọn ṣe.
In that yeer and the firste monethe of his rewme he openyde the yatis of the hows of the Lord, and restoride tho;
4 Ó sì mú àwọn àlùfáà wá àti àwọn ọmọ Lefi, ó sì kó wọn jọ yíká ìta ìlà-oòrùn.
and he brouyte the preestis and dekenes, and gaderide hem in to the eest strete,
5 Ó sì wí pé, “Ẹ gbọ́ tèmi, ẹ̀yin ọmọ Lefi! Ẹ ya ara yín sí mímọ́ nísinsin yìí kí ẹ sì ya ilé Olúwa Ọlọ́run sí mímọ́, kí ẹ sì kó ohun àìmọ́ baba mi jáde kúrò ní ibi mímọ́.
and seide to hem, Sones of Leuy, here ye me, and be ye halewid; clense ye the hows of the Lord God of youre fadris; do ye awei al vnclennesse fro the seyntuarie.
6 Àwọn baba wa jẹ́ aláìṣòótọ́; wọ́n sì ṣe ohun àìtọ́ níwájú Olúwa Ọlọ́run wa, wọ́n sì kọ̀ ọ́ sílẹ̀. Wọ́n sì yí ojú wọn padà kúrò ní ibùgbé Olúwa, wọ́n sì pa ẹ̀yìn wọn dà sí i.
Oure fadris synneden, and diden yuel in the siyt of `oure Lord God, and forsoken hym; thei turneden awei her faces fro the tabernacle of `oure Lord God, and yauen the bak.
7 Wọ́n sì tún ti ìlẹ̀kùn ìloro náà pẹ̀lú, wọ́n sì pa fìtílà. Wọn kò sì sun tùràrí tàbí pèsè ẹbọ sísun si ibi mímọ́ si Ọlọ́run Israẹli.
Thei closiden the doris that weren in the porche, and quenchiden the lanternes; and thei brenten not encense, and thei offriden not brent sacrifices in the seyntuarie of God of Israel.
8 Nítorí náà, ìbínú Olúwa ti ru sókè wá sórí Juda àti Jerusalẹmu ó sì ti fi wọ́n ṣe ohun èlò fún wàhálà, àti ìdààmú àti ẹ̀sín, gẹ́gẹ́ bí ó ti ṣe fi ojú rẹ̀ rí i.
Therfor the stronge veniaunce of the Lord was reisid on Juda and Jerusalem; and he yaf hem in to stiryng, and in to perischyng, and in to `hisshing, ether scornyng, as ye seen with youre iyen.
9 Ìdí nìyí tí àwọn baba wa ṣe ṣubú nípa idà àti ìdí tí àwọn ọmọkùnrin àti ọmọbìnrin àti àwọn aya wa tiwọn kó wọ́n ní ìgbèkùn.
Lo! oure fadris felden doun bi swerdis; oure sones, and oure douytris, and wyues ben led prisouneris for this greet trespas.
10 Nísinsin yìí ó wà ní ọkàn mi láti bá Olúwa Ọlọ́run Israẹli dá májẹ̀mú. Bẹ́ẹ̀ ni kí ìbínú rẹ̀ kíkan kí ó lè yípadà kúrò lọ́dọ̀ wa.
Now therfor it plesith me, that we make a boond of pees with the Lord God of Israel, and that he turne fro vs the stronge veniaunce of his ire.
11 Àwọn ọmọ mi, ẹ má ṣe jáfara nísinsin yìí, nítorí tí Olúwa ti yàn yín láti dúró níwájú rẹ̀ láti sin, kí ẹ sì máa ṣe ìránṣẹ́ níwájú rẹ̀ àti láti sun tùràrí.”
My sones, nyle ye be reccheles; the Lord hath chose you, that ye stonde bifor hym, and serue hym, that ye herie hym, and brenne encense to hym.
12 Nígbà náà àwọn ọmọ Lefi wọ̀nyí múra láti ṣe iṣẹ́: nínú àwọn ọmọ Kohati, Mahati ọmọ Amasai: àti Joẹli ọmọ Asariah; nínú àwọn ọmọ Merari, Kiṣi ọmọ Abdi àti Asariah ọmọ Jehaleeli; nínú àwọn ọmọ Gerṣoni, Joah, ọmọ Simma àti Edeni ọmọ Joah;
Therfor the dekenes risiden, Mahat, the sone of Amasie, and Johel, the sone of Azarie, of the sones of Caath; sotheli of the sones of Merarye, Cys, the sone of Abdai, and Azarie, the sone of Jelaleel; forsothe of the sones of Jerson, Joha, the sone of Zemma, and Hedem, the sone of Johaa;
13 nínú àwọn ọmọ Elisafani, Ṣimri àti Jeieli; nínú àwọn ọmọ Asafu, Sekariah àti Mattaniah;
and sotheli of the sones of Elisaphan, Samri, and Jahiel; and of the sones of Asaph, Zacharie, and Mathanye;
14 nínú àwọn ọmọ Hemani, Jehieli àti Ṣimei; nínú àwọn ọmọ Jedutuni, Ṣemaiah àti Usieli.
also of the sones of Heman, Jahiel, and Semei; but also of the sones of Iditum, Semei, and Oziel.
15 Nígbà tí wọ́n sì ti kó ara wọn jọ pọ̀ pẹ̀lú àwọn arákùnrin wọn, wọ́n sì ya ara wọn sí mímọ́, wọ́n sì lọ láti gbá ilé Olúwa mọ́, gẹ́gẹ́ bí ọba ti pa á láṣẹ, ẹ tẹ̀lé ọ̀rọ̀ Olúwa.
And thei gaderiden to gidere her britheren, and weren halewid; and thei entriden bi comaundement of the kyng, and bi comaundement of the Lord, for to clense the hows of the Lord.
16 Àwọn àlùfáà sì wọ inú ilé Olúwa lọ́hùn ún lọ láti gbá a mọ́. Wọ́n sì gbé e jáde sí inú àgbàlá ilé Olúwa gbogbo ohun àìmọ́ tí wọ́n rí nínú ilé Olúwa. Àwọn ọmọ Lefi sì mú u wọ́n sì gbangba odò Kidironi.
Also preestis entriden in to the temple of the Lord, for to halewe it, and thei baren out al vnclennesse, which thei founden ther ynne in the porche, `ethir large place, of the hows of the Lord; which vnclennesse the dekenes token, and baren out to the stronde of Cedron with outforth.
17 Wọ́n sì bẹ̀rẹ̀ ìyàsímímọ́ ní ọjọ́ kìn-ín-ní oṣù kìn-ín-ní, àti ní ọjọ́ kẹjọ oṣù náà wọ́n sì dé ìloro Olúwa. Fún ọjọ́ mẹ́jọ mìíràn sí i, wọ́n sì ya ilé Olúwa sí mímọ́ fúnra rẹ̀. Wọ́n sì parí ní ọjọ́ kẹrìndínlógún oṣù kìn-ín-ní.
Sotheli thei bigunnen to clense in the firste dai of the firste monethe, and in the eiyte dai of the same monethe thei entriden in to the porche of the hows of the Lord, and thei clensiden the temple eiyte daies; and in the sixtenthe dai of the same monethe thei filliden that, that thei hadden bigunne.
18 Nígbà náà wọn sì lọ sí ọ̀dọ̀ ọba Hesekiah láti lọ jábọ̀ fún un: “Àwa ti gbá ilé Olúwa mọ́, pẹpẹ ẹbọ sísun pẹ̀lú gbogbo ohun ẹbọ rẹ̀, àti tábìlì àkàrà ìfihàn, pẹ̀lú gbogbo ohun èlò.
And thei entriden to Ezechie, the king, and seiden to hym, We han halewid al the hows of the Lord, and the auter of brent sacrifice therof, and the vessels therof, also and the boord of settyngforth with alle hise vessels,
19 A ti pèsè a sì ti yà sí mímọ́ gbogbo ohun èlò tí ọba Ahasi ti sọ di aláìmọ́ nínú àìṣòótọ́ rẹ̀ nígbà tí ó jẹ́ ọba; nísinsin yìí, wọ́n wà níwájú pẹpẹ Olúwa.”
and al the purtenaunce of the temple, `which purtenaunce king Achaz hadde defoulid in his rewme, aftir that he brak the lawe; and lo! alle thingis ben set forth bifor the auter of the Lord.
20 Ní kùtùkùtù òwúrọ̀ ọjọ́ kejì, ọba Hesekiah sì kó olórí àwọn ìjòyè jọ, ó sì lọ sókè ilé Olúwa.
And Ezechie, the kyng, roos in the morwetid, and gaderide togidere alle the princes of the citee, and stiede in to the hows of the Lord;
21 Wọ́n sì mú akọ màlúù méje wá, àti àgbò méje, àti ọ̀dọ́-àgùntàn méje àti òbúkọ méje gẹ́gẹ́ bí ẹbọ ẹ̀ṣẹ̀ fún ìjọba, fún ibi mímọ́ àti fún Juda. Ọba pàṣẹ fun àwọn àlùfáà, àwọn ọmọ Aaroni, láti ṣe èyí lórí pẹpẹ Olúwa.
and thei offriden togidere seuene bolis, and seuene rammes, seuene lambren, and seuene buckis of geet, for synne, for the rewme, for the seyntuarye, and for Juda. And he seide to preestis, the sones of Aaron, that thei schulden offre on the auter of the Lord.
22 Bẹ́ẹ̀ ni wọ́n sì pa akọ màlúù, àwọn àlùfáà mú ẹ̀jẹ̀ náà, wọ́n sì fi wọ́n ara pẹpẹ. Bẹ́ẹ̀ gẹ́gẹ́ ni nígbà tí wọ́n pa àgbò, wọ́n sì fi ẹ̀jẹ̀ wọ́n orí pẹpẹ. Nígbà náà wọ́n sì pa ọ̀dọ́-àgùntàn, wọ́n sì fi ẹ̀jẹ̀ wọn ara pẹpẹ.
Therfor thei killiden bolis, and `the preestis tooken the blood, and schedden it on the auter; also thei killiden rammes, and `the preestis schedden the blood of tho on the auter; thei offriden lambren, and `the preestis schedden the blood on the auter.
23 Òbúkọ fún ẹbọ ẹ̀ṣẹ̀ ni wọ́n gbé wá síwájú ọba àti ìjọ ènìyàn, wọ́n sì gbé ọwọ́ lé wọn.
And thei brouyten buckis of geet `for synne bifor the kyng and al the multitude, and thei settiden her hondis on tho;
24 Àwọn àlùfáà wọn sì pa òbúkọ, wọ́n sì gbé ẹ̀jẹ̀ kalẹ̀ lórí pẹpẹ fún ẹbọ ẹ̀ṣẹ̀ láti ṣe ètùtù fún gbogbo Israẹli, nítorí ọba ti pàṣẹ kí a ṣe ẹbọ sísun àti ẹbọ ẹ̀ṣẹ̀ fún gbogbo Israẹli.
and the preestis offriden tho, and spreynten the blood of tho bifor the auter, for the clensyng of al Israel. For the king comaundide, that brent sacrifice shulde be made for al Israel, and for synne.
25 Ó sì mú àwọn Lefi dúró nínú ilé Olúwa pẹ̀lú Kimbali, ohun èlò orin olókùn àti dùùrù ní ọ̀nà tí a ti paláṣẹ fún wọn láti ọ̀dọ̀ Dafidi àti Gadi aríran ọba àti Natani wòlíì. Èyí ni a pàṣẹ láti ọ̀dọ̀ Olúwa láti ọwọ́ àwọn wòlíì rẹ̀.
Also he ordeynede dekenes in the hows of the Lord, with cymbalis, and sawtrees, and harpis, bi the ordenaunce of `Dauid the kyng, and of Gad, the profete, and of Nathan, the profete; for it was the comaundement of the Lord bi the hond of hise prophetis.
26 Bẹ́ẹ̀ ni àwọn ọmọ Lefi sì dúró pẹ̀lú ohun èlò orin Dafidi, àti àwọn àlùfáà pẹ̀lú ìpè wọn.
And the dekenes stoden, and helden the orguns of Dauid; and preestis helden trumpis.
27 Hesekiah sì pa á láṣẹ láti rú ẹbọ sísun lórí pẹpẹ, bí ẹbọ sísun náà ti bẹ̀rẹ̀, orin sí Olúwa bẹ̀rẹ̀ pẹ̀lú ìpè àti pẹ̀lú ohun èlò orin Dafidi ọba Israẹli.
And Ezechie comaundide, that thei schulden offre brent sacrifices on the auter; and whanne brent sacrifices weren offrid, thei bigunnen to synge preisyngis to the Lord, and to sowne with trumpis, and in dyuerse orguns, whiche Dauid, the kyng of Israel, hadde maad redi for to sowne.
28 Gbogbo ìjọ ènìyàn náà sì wólẹ̀ sìn, àwọn akọrin kọrin, àwọn afùnpè sì fọn ìpè, gbogbo wọ̀nyí sì wà bẹ́ẹ̀ títí ẹbọ sísun náà fi parí tán.
Forsothe whanne al the cumpenye worschipide, syngeris and thei that helden trumpis weren in her office, til the brent sacrifice was fillid.
29 Nígbà tí wọ́n sì ṣe ìparí ẹbọ rírú, ọba àti gbogbo àwọn tí ó wà pẹ̀lú rẹ̀ tẹ ara wọn ba, wọ́n sì sìn.
And whanne the offryng was endid, the kyng was bowid, and alle that weren with hym, and thei worschipiden God.
30 Pẹ̀lúpẹ̀lú Hesekiah ọba, àti àwọn ìjòyè pàṣẹ fún àwọn ọmọ Lefi, láti fi ọ̀rọ̀ Dafidi àti ti Asafu aríran, kọrin ìyìn sí Olúwa: wọ́n sì fi inú dídùn kọrin ìyìn, wọ́n sì tẹrí wọn ba, wọ́n sì sìn.
And Ezechie and the princes comaundiden to the dekenes, that thei schulden preise the Lord with the wordis of Dauith, and of Asaph, the profete; whiche preisiden hym with greet gladnesse, and kneliden, and worschipiden.
31 Nígbà náà ni Hesekiah dáhùn, ó sì wí pé, nísinsin yìí, ọwọ́ yín kún fún ẹ̀bùn fún Olúwa, ẹ súnmọ́ ìhín, kí ẹ sì mú ẹbọ àti ọrẹ-ọpẹ́ wá sínú ilé Olúwa. Ìjọ ènìyàn sì mú ẹbọ àti ọrẹ-ọpẹ́ wá; àti olúkúlùkù tí ọkàn rẹ̀ fẹ́, mú ẹbọ sísun wá.
Sothely Ezechie addide also these thingis, Ye han fillid youre hondis to the Lord; neiye ye, and offre sacrifices and preisyngis in the hows of the Lord.
32 Iye ẹbọ sísun, tí ìjọ ènìyàn mú wá, sì jẹ́ àádọ́rin akọ màlúù, àti ọgọ́rùn-ún àgbò, àti igba ọ̀dọ́-àgùntàn, gbogbo wọ̀nyí sì ni fún ẹbọ sísun sí Olúwa.
Therfor al the multitude offride with deuoute soule sacrifices, and preisyngis, and brent sacrifices. Sotheli this was the noumbre of brent sacrifices, whiche the multitude offride; seuenti bolis, and an hundrid rammes, two hundrid lambren.
33 Àwọn ohun ìyàsímímọ́ sì jẹ́ ẹgbẹ̀ta màlúù, àti ẹgbẹ̀rún mẹ́ta àgùntàn.
Also thei halewiden to the Lord sixe hundrid oxis, and thre thousynde sheep.
34 Ṣùgbọ́n àwọn àlùfáà kò pọ̀ tó, wọn kò sì le bó gbogbo àwọn ẹran ẹbọ sísun náà: nítorí náà àwọn arákùnrin wọn, àwọn Lefi ràn wọ́n lọ́wọ́, títí iṣẹ́ náà fi parí, àti títí àwọn àlùfáà ìyókù fi yà wọ́n sí mímọ́: nítorí àwọn ọmọ Lefi ṣe olóòtítọ́ ní ọkàn ju àwọn àlùfáà lọ láti ya ara wọn sí mímọ́.
Forsothe the preestis weren fewe, and myyten not suffice for to `drawe awei the skynnes of brent sacrifices; wherfor and the dekenes her britheren helpiden hem, til the werk was fillid, and the preestis weren halewid; for the dekenes ben halewid bi liytere custom than the preestis.
35 Àti pẹ̀lú, àwọn ẹbọ sísun pàpọ̀jù, pẹ̀lú ọ̀rá ẹbọ àlàáfíà, pẹ̀lú ẹbọ ohun mímu fún ẹbọ sísun. Bẹ́ẹ̀ ni a sì tún bẹ̀rẹ̀ iṣẹ́ ìsìn ilé Olúwa.
Therfor there weren ful many brent sacrifices, ynnere fatnessis of pesible sacrifices, and the moyste sacrifices of brent sacrifices, and the worschip, `ethir ournyng, of the `Lordis hows was fillid.
36 Hesekiah sì yọ̀, àti gbogbo ènìyàn pé, Ọlọ́run ti múra àwọn ènìyàn náà sílẹ̀, nítorí lójijì ni a ṣe nǹkan náà.
And Ezechie was glad, and al the puple, for the seruyce of the Lord was fillid; for it pleside, that this was doon sodeynly.

< 2 Chronicles 29 >