< 2 Chronicles 29 >

1 Hesekiah sì jẹ́ ẹni ọdún mẹ́ẹ̀ẹ́dọ́gbọ̀n nígbà tí ó di ọba, ó sì jẹ ọba ní Jerusalẹmu fún ọdún mọ́kàndínlọ́gbọ̀n orúkọ ìyá rẹ̀ sì ni Abijah ọmọbìnrin Sekariah.
Hezekiah teh siangpahrang a tawk navah kum 25 touh a pha teh Jerusalem kum 29 touh a uk.
2 Ó sì ṣe ohun tí ó tọ́ ní ojú Olúwa, gẹ́gẹ́ bí baba rẹ̀ Dafidi ti ṣe.
A na pa Devit e a sak e pueng a sak teh, BAWIPA e mithmu vah hawinae a sak.
3 Ní oṣù àkọ́kọ́ ní ọdún kìn-ín-ní ìjọba rẹ̀, ó sì ṣí àwọn ìlẹ̀kùn ilé Olúwa ó sì tún wọn ṣe.
Siangpahrang a tawknae kum thapa yung pasueknae dawkvah, BAWIPA im takhangnaw a paawng teh a pathoup.
4 Ó sì mú àwọn àlùfáà wá àti àwọn ọmọ Lefi, ó sì kó wọn jọ yíká ìta ìlà-oòrùn.
Vaihmanaw hoi Levihnaw a hrawi teh, kanîtholah hmuen akawnae koe a pâkhueng teh,
5 Ó sì wí pé, “Ẹ gbọ́ tèmi, ẹ̀yin ọmọ Lefi! Ẹ ya ara yín sí mímọ́ nísinsin yìí kí ẹ sì ya ilé Olúwa Ọlọ́run sí mímọ́, kí ẹ sì kó ohun àìmọ́ baba mi jáde kúrò ní ibi mímọ́.
ahnimouh koevah, nangmouh Levihnaw ka lawk thai awh haw. Na mamanaw hmaloe kamthoung awh haw. Na mintoenaw e BAWIPA Cathut im thoung sak awh nateh, hmuen kathoung dawk e kakhinnaw hah tâkhawng awh.
6 Àwọn baba wa jẹ́ aláìṣòótọ́; wọ́n sì ṣe ohun àìtọ́ níwájú Olúwa Ọlọ́run wa, wọ́n sì kọ̀ ọ́ sílẹ̀. Wọ́n sì yí ojú wọn padà kúrò ní ibùgbé Olúwa, wọ́n sì pa ẹ̀yìn wọn dà sí i.
Mamae mintoenaw ni kâ a tapoe awh teh, BAWIPA Cathut hmalah hawihoehnae a sak awh teh, a pahnawt awh. BAWIPA onae hmuen hah a hnamthun takhai awh.
7 Wọ́n sì tún ti ìlẹ̀kùn ìloro náà pẹ̀lú, wọ́n sì pa fìtílà. Wọn kò sì sun tùràrí tàbí pèsè ẹbọ sísun si ibi mímọ́ si Ọlọ́run Israẹli.
Longkha takhang a khan awh. Hmaiim a padue awh teh, Isarel Cathut hmuen kathoung dawk hmuitui hai sawi awh hoeh. Hmaisawi thuengnae hai sak awh hoeh.
8 Nítorí náà, ìbínú Olúwa ti ru sókè wá sórí Juda àti Jerusalẹmu ó sì ti fi wọ́n ṣe ohun èlò fún wàhálà, àti ìdààmú àti ẹ̀sín, gẹ́gẹ́ bí ó ti ṣe fi ojú rẹ̀ rí i.
Hatdawkvah, BAWIPA lungkhueknae teh Judahnaw hoi Jerusalem taminaw e lathueng a pha. Na mit hoi na hmu awh e patetlah ram tangkuem hoi hmuen tangkuem vah, rucatnae, lungpuennae, hoi pathoenae lah na coung awh han.
9 Ìdí nìyí tí àwọn baba wa ṣe ṣubú nípa idà àti ìdí tí àwọn ọmọkùnrin àti ọmọbìnrin àti àwọn aya wa tiwọn kó wọ́n ní ìgbèkùn.
Khenhaw! maimae mintoenaw teh, tahloi hoi a due awh teh, maimae capanaw hoi canunaw hoi yunaw teh san a toung awh.
10 Nísinsin yìí ó wà ní ọkàn mi láti bá Olúwa Ọlọ́run Israẹli dá májẹ̀mú. Bẹ́ẹ̀ ni kí ìbínú rẹ̀ kíkan kí ó lè yípadà kúrò lọ́dọ̀ wa.
Hatdawkvah, puenghoi a lungkhueknae a roum thai nahanelah, BAWIPA Isarel Cathut koe lawkkamnae sak hanelah ka noe e doeh.
11 Àwọn ọmọ mi, ẹ má ṣe jáfara nísinsin yìí, nítorí tí Olúwa ti yàn yín láti dúró níwájú rẹ̀ láti sin, kí ẹ sì máa ṣe ìránṣẹ́ níwájú rẹ̀ àti láti sun tùràrí.”
Ka canaw, rap awm awh hanh leih. Bangkongtetpawiteh, nangmouh teh BAWIPA ni, a hmalah na kangdue awh vaiteh, thaw tawk hane hoi ama koevah hmuitui sawi hanelah na rawi awh e doeh, telah atipouh.
12 Nígbà náà àwọn ọmọ Lefi wọ̀nyí múra láti ṣe iṣẹ́: nínú àwọn ọmọ Kohati, Mahati ọmọ Amasai: àti Joẹli ọmọ Asariah; nínú àwọn ọmọ Merari, Kiṣi ọmọ Abdi àti Asariah ọmọ Jehaleeli; nínú àwọn ọmọ Gerṣoni, Joah, ọmọ Simma àti Edeni ọmọ Joah;
Hat torei teh, Levih tami Amasa capa Mahath, Kohath tami Azariah capa Joel, Merari capanaw dawk e Addi capa Kish, Jehallelel capa Azariah, Gershon tami Zimmah capa Joah, Joab capa Eden.
13 nínú àwọn ọmọ Elisafani, Ṣimri àti Jeieli; nínú àwọn ọmọ Asafu, Sekariah àti Mattaniah;
Elizaphan capanaw thung dawk e Shimri hoi Jeuel, Asaph capa thung dawk e Zekhariah hoi Mattaniah.
14 nínú àwọn ọmọ Hemani, Jehieli àti Ṣimei; nínú àwọn ọmọ Jedutuni, Ṣemaiah àti Usieli.
Heman capa thung dawk e Jehiel hoi Shimei, Jeduthun capa thung dawk e Shemaiah hoi Uzziel, ahnimanaw a kangdue awh.
15 Nígbà tí wọ́n sì ti kó ara wọn jọ pọ̀ pẹ̀lú àwọn arákùnrin wọn, wọ́n sì ya ara wọn sí mímọ́, wọ́n sì lọ láti gbá ilé Olúwa mọ́, gẹ́gẹ́ bí ọba ti pa á láṣẹ, ẹ tẹ̀lé ọ̀rọ̀ Olúwa.
A hmaunawngha a pâkhueng awh teh, a kamthoung awh. BAWIPA e lawk hoi kâvan lah siangpahrang ni kâ a poe e patetlah BAWIPA imthung thoung sak hanelah a kâen awh.
16 Àwọn àlùfáà sì wọ inú ilé Olúwa lọ́hùn ún lọ láti gbá a mọ́. Wọ́n sì gbé e jáde sí inú àgbàlá ilé Olúwa gbogbo ohun àìmọ́ tí wọ́n rí nínú ilé Olúwa. Àwọn ọmọ Lefi sì mú u wọ́n sì gbangba odò Kidironi.
Hottelah vaihmanaw teh thoung sak hanelah BAWIPA im a thung lae rakhan dawk a kâen awh. BAWIPA im dawk kakhin e a hmuennaw pueng hah BAWIPA im hmalah a tâcokhai awh teh, Levihnaw ni a la awh teh Kidron palang lah a ceikhai awh.
17 Wọ́n sì bẹ̀rẹ̀ ìyàsímímọ́ ní ọjọ́ kìn-ín-ní oṣù kìn-ín-ní, àti ní ọjọ́ kẹjọ oṣù náà wọ́n sì dé ìloro Olúwa. Fún ọjọ́ mẹ́jọ mìíràn sí i, wọ́n sì ya ilé Olúwa sí mímọ́ fúnra rẹ̀. Wọ́n sì parí ní ọjọ́ kẹrìndínlógún oṣù kìn-ín-ní.
Thapa yung pasuek, apasuek hnin a kamtawng awh teh, hote thapa hnin taroe hnin vah, BAWIPA im alawilah totouh, a thoung sak awh. Hathnukkhu, BAWIPA im hnin taroe touh thung a thoung sak awh teh, thapa yung pasuek e hnin hlaitaruk hnin a cum awh.
18 Nígbà náà wọn sì lọ sí ọ̀dọ̀ ọba Hesekiah láti lọ jábọ̀ fún un: “Àwa ti gbá ilé Olúwa mọ́, pẹpẹ ẹbọ sísun pẹ̀lú gbogbo ohun ẹbọ rẹ̀, àti tábìlì àkàrà ìfihàn, pẹ̀lú gbogbo ohun èlò.
Hottelah siangpahrang Hezekiah koe, siangpahrang im a kâen awh teh, BAWIPA im e hmaisawi thuengnae khoungroe hoi hawvah, hno e hnopai pueng vaiyei pâhungnae caboi hoi hnopai pueng koung ka thoung sak awh toe.
19 A ti pèsè a sì ti yà sí mímọ́ gbogbo ohun èlò tí ọba Ahasi ti sọ di aláìmọ́ nínú àìṣòótọ́ rẹ̀ nígbà tí ó jẹ́ ọba; nísinsin yìí, wọ́n wà níwájú pẹpẹ Olúwa.”
Hahoi siangpahrang Ahaz a bawi navah, yonnae a sak teh, a hnoun e hnopai pueng hai koung ka thoung sak awh. Khenhaw! BAWIPA e thuengnae khoungroe hmalah ao awh, telah atipouh awh.
20 Ní kùtùkùtù òwúrọ̀ ọjọ́ kejì, ọba Hesekiah sì kó olórí àwọn ìjòyè jọ, ó sì lọ sókè ilé Olúwa.
Hatnavah, siangpahrang Hezekiah teh amom a thaw teh, khothung e kahrawikungnaw a kaw teh, BAWIPA im dawk a cei.
21 Wọ́n sì mú akọ màlúù méje wá, àti àgbò méje, àti ọ̀dọ́-àgùntàn méje àti òbúkọ méje gẹ́gẹ́ bí ẹbọ ẹ̀ṣẹ̀ fún ìjọba, fún ibi mímọ́ àti fún Juda. Ọba pàṣẹ fun àwọn àlùfáà, àwọn ọmọ Aaroni, láti ṣe èyí lórí pẹpẹ Olúwa.
Uknaeram hoi hmuen kathoung Judah hanelah yon thueng nahane maitotan sari, tutan sari, tuca sari touh hoi hmaetan sari touh a ceikhai. Aron capa vaihmanaw hah BAWIPA e thuengnae khoungroe koe thuengnae sak hanelah kâ a poe.
22 Bẹ́ẹ̀ ni wọ́n sì pa akọ màlúù, àwọn àlùfáà mú ẹ̀jẹ̀ náà, wọ́n sì fi wọ́n ara pẹpẹ. Bẹ́ẹ̀ gẹ́gẹ́ ni nígbà tí wọ́n pa àgbò, wọ́n sì fi ẹ̀jẹ̀ wọ́n orí pẹpẹ. Nígbà náà wọ́n sì pa ọ̀dọ́-àgùntàn, wọ́n sì fi ẹ̀jẹ̀ wọn ara pẹpẹ.
Maitotannaw a thei awh teh, vaihma ni a thipaling a la teh, thuengnae khoungroe dawk a kathek. Hahoi tutannaw hai a thei awh teh, a thipaling hah thuengnae khoungroe dawk a kathek awh. Hahoi tucanaw hai a thei awh teh, a thipaling hah thuengnae khoungroe dawk a kathek awh.
23 Òbúkọ fún ẹbọ ẹ̀ṣẹ̀ ni wọ́n gbé wá síwájú ọba àti ìjọ ènìyàn, wọ́n sì gbé ọwọ́ lé wọn.
Hmaetannaw teh yon thueng nahanlah siangpahrang hoi rangpuinaw e hmalah a thokhai awh teh, a lathueng vah a kut a toung sin awh.
24 Àwọn àlùfáà wọn sì pa òbúkọ, wọ́n sì gbé ẹ̀jẹ̀ kalẹ̀ lórí pẹpẹ fún ẹbọ ẹ̀ṣẹ̀ láti ṣe ètùtù fún gbogbo Israẹli, nítorí ọba ti pàṣẹ kí a ṣe ẹbọ sísun àti ẹbọ ẹ̀ṣẹ̀ fún gbogbo Israẹli.
Vaihmanaw ni a thei awh teh, thipaling hoi Isarelnaw pueng e yontha nahanelah thuengnae khoungroe dawk yon thuengnae a sak. Isarelnaw abuemlah hanelah hmaisawi thuengnae hoi yon thueng nahanelah siangpahrang ni kâ a poe.
25 Ó sì mú àwọn Lefi dúró nínú ilé Olúwa pẹ̀lú Kimbali, ohun èlò orin olókùn àti dùùrù ní ọ̀nà tí a ti paláṣẹ fún wọn láti ọ̀dọ̀ Dafidi àti Gadi aríran ọba àti Natani wòlíì. Èyí ni a pàṣẹ láti ọ̀dọ̀ Olúwa láti ọwọ́ àwọn wòlíì rẹ̀.
Devit siangpahrang hoi ahnimae profet hah profet Nathan e kâpoelawk patetlah BAWIPA im dawk Levihnaw teh cecak, tamawi hoi ratoung, tumkhawng hanelah a hruek. Bangkongtetpawiteh, kâpoelawk teh BAWIPA ni profetnaw hno lahoi a poe e doeh.
26 Bẹ́ẹ̀ ni àwọn ọmọ Lefi sì dúró pẹ̀lú ohun èlò orin Dafidi, àti àwọn àlùfáà pẹ̀lú ìpè wọn.
Levihnaw teh Devit ni sak e tumkhawngnaw hoi vaihmanaw teh mongkanaw patuep hoi a kangdue awh.
27 Hesekiah sì pa á láṣẹ láti rú ẹbọ sísun lórí pẹpẹ, bí ẹbọ sísun náà ti bẹ̀rẹ̀, orin sí Olúwa bẹ̀rẹ̀ pẹ̀lú ìpè àti pẹ̀lú ohun èlò orin Dafidi ọba Israẹli.
Hezekiah ni thuengnae khoungroe dawk hmaisawi thuengnae thueng hanelah, kâ a poe. Hahoi hmaisawi thuengnae a kamtawng awh navah, mongka hoi Devit ni a sak e tumkhawng khawng laihoi, BAWIPA a pholen awh.
28 Gbogbo ìjọ ènìyàn náà sì wólẹ̀ sìn, àwọn akọrin kọrin, àwọn afùnpè sì fọn ìpè, gbogbo wọ̀nyí sì wà bẹ́ẹ̀ títí ẹbọ sísun náà fi parí tán.
Rangpuinaw ni Cathut a bawk awh teh, la kasaknaw ni la a sak awh. Mongka kauengnaw ni mongka a ueng awh. Hmaisawi thuengnae abaw hoehroukrak hottelah kâhat laipalah a sak awh.
29 Nígbà tí wọ́n sì ṣe ìparí ẹbọ rírú, ọba àti gbogbo àwọn tí ó wà pẹ̀lú rẹ̀ tẹ ara wọn ba, wọ́n sì sìn.
Hahoi, thuengnae abaw toteh, siangpahrang hoi ahni koe kaawm e pueng ni tabo laihoi Cathut a bawk awh.
30 Pẹ̀lúpẹ̀lú Hesekiah ọba, àti àwọn ìjòyè pàṣẹ fún àwọn ọmọ Lefi, láti fi ọ̀rọ̀ Dafidi àti ti Asafu aríran, kọrin ìyìn sí Olúwa: wọ́n sì fi inú dídùn kọrin ìyìn, wọ́n sì tẹrí wọn ba, wọ́n sì sìn.
Siangpahrang Hezekiah hoi kahrawikungnaw Levihnaw hah Devit hoi profet Asaph ni a phueng e pholen la sak hanlah kâ a poe. Hahoi lunghawinae hoi pholennae la sak laihoi a tabo awh teh Cathut a bawk awh.
31 Nígbà náà ni Hesekiah dáhùn, ó sì wí pé, nísinsin yìí, ọwọ́ yín kún fún ẹ̀bùn fún Olúwa, ẹ súnmọ́ ìhín, kí ẹ sì mú ẹbọ àti ọrẹ-ọpẹ́ wá sínú ilé Olúwa. Ìjọ ènìyàn sì mú ẹbọ àti ọrẹ-ọpẹ́ wá; àti olúkúlùkù tí ọkàn rẹ̀ fẹ́, mú ẹbọ sísun wá.
Hottelah, Hezekiah ni, BAWIPA hanelah na thoung awh toe, tho awh haw, BAWIPA im dawk thueng hane hoi lunghawi lawk dei thueng nahanelah poe awh haw, telah atipouh.
32 Iye ẹbọ sísun, tí ìjọ ènìyàn mú wá, sì jẹ́ àádọ́rin akọ màlúù, àti ọgọ́rùn-ún àgbò, àti igba ọ̀dọ́-àgùntàn, gbogbo wọ̀nyí sì ni fún ẹbọ sísun sí Olúwa.
Hahoi rangpuinaw ni sathei thueng hane hoi lunghawi lawk dei thueng hane a poe awh. Poe han a lung ka tho pueng ni a poe e naw pueng teh, maitotan 70, tutan 100 touh hoi tuca 200 touh a pha.
33 Àwọn ohun ìyàsímímọ́ sì jẹ́ ẹgbẹ̀ta màlúù, àti ẹgbẹ̀rún mẹ́ta àgùntàn.
Hno poe e abuemlah maitotan 600, tutan 3000 touh a pha.
34 Ṣùgbọ́n àwọn àlùfáà kò pọ̀ tó, wọn kò sì le bó gbogbo àwọn ẹran ẹbọ sísun náà: nítorí náà àwọn arákùnrin wọn, àwọn Lefi ràn wọ́n lọ́wọ́, títí iṣẹ́ náà fi parí, àti títí àwọn àlùfáà ìyókù fi yà wọ́n sí mímọ́: nítorí àwọn ọmọ Lefi ṣe olóòtítọ́ ní ọkàn ju àwọn àlùfáà lọ láti ya ara wọn sí mímọ́.
Hatei, vaihmanaw ayounca dawkvah, hmaisawi thuengnae sathei be thet thai awh hoeh. Hatdawkvah, a hmaunawngha Levihnaw ni pâbaw hoehroukrak, vaihmanaw kamthoung totouh a kabawp awh. Levihnaw teh vaihmanaw hlak kamthoung hane lungthin a lan awh.
35 Àti pẹ̀lú, àwọn ẹbọ sísun pàpọ̀jù, pẹ̀lú ọ̀rá ẹbọ àlàáfíà, pẹ̀lú ẹbọ ohun mímu fún ẹbọ sísun. Bẹ́ẹ̀ ni a sì tún bẹ̀rẹ̀ iṣẹ́ ìsìn ilé Olúwa.
Hmaisawi thuengnae apap poung dawkvah, hmaisawi thuengnae pueng koe, roum thuengnae sathei thaw hoi nei thueng nahane hai apap poung. Hottelah BAWIPA im dawk thaw tawknae hah a khuekhawcalah a tawk awh.
36 Hesekiah sì yọ̀, àti gbogbo ènìyàn pé, Ọlọ́run ti múra àwọn ènìyàn náà sílẹ̀, nítorí lójijì ni a ṣe nǹkan náà.
Rangpuinaw hanelah Cathut ni a rakueng pouh e hno kecu dawk Hezekiah hoi taminaw pueng teh puenghoi a lunghawi awh. Bangkongtetpawiteh, pouk laipalah ka tho e hno doeh.

< 2 Chronicles 29 >