< 2 Chronicles 29 >
1 Hesekiah sì jẹ́ ẹni ọdún mẹ́ẹ̀ẹ́dọ́gbọ̀n nígbà tí ó di ọba, ó sì jẹ ọba ní Jerusalẹmu fún ọdún mọ́kàndínlọ́gbọ̀n orúkọ ìyá rẹ̀ sì ni Abijah ọmọbìnrin Sekariah.
Hezekiah siangpahrang ah oh amtong tangsuek naah saning pumphae pangato oh boeh; anih mah Jerusalem to saning pumphae takawtto thung uk; amno loe Zekariah canu Abijah.
2 Ó sì ṣe ohun tí ó tọ́ ní ojú Olúwa, gẹ́gẹ́ bí baba rẹ̀ Dafidi ti ṣe.
Ampa David mah sak ih baktih toengah, anih doeh Angraeng mikhnukah katoeng hmuennawk boih to sak.
3 Ní oṣù àkọ́kọ́ ní ọdún kìn-ín-ní ìjọba rẹ̀, ó sì ṣí àwọn ìlẹ̀kùn ilé Olúwa ó sì tún wọn ṣe.
Siangpahrang ah ohhaih saningto haih, khrah tangsuek naah, anih mah Angraeng ih im khongkhanawk to paongh moe, pathoep.
4 Ó sì mú àwọn àlùfáà wá àti àwọn ọmọ Lefi, ó sì kó wọn jọ yíká ìta ìlà-oòrùn.
Qaima hoi Levi acaengnawk to a caeh haih moe, ni angyae bang ih loklam ah amkhuengsak.
5 Ó sì wí pé, “Ẹ gbọ́ tèmi, ẹ̀yin ọmọ Lefi! Ẹ ya ara yín sí mímọ́ nísinsin yìí kí ẹ sì ya ilé Olúwa Ọlọ́run sí mímọ́, kí ẹ sì kó ohun àìmọ́ baba mi jáde kúrò ní ibi mímọ́.
Nihcae khaeah, Levi acaengnawk ka lok hae tahngai oh, ciimcai oh loe, nam panawk ih Angraeng Sithaw ih im to ciim o sak ah; hmuenciim thung ih panuet thok hmuennawk boih to takhoe oh.
6 Àwọn baba wa jẹ́ aláìṣòótọ́; wọ́n sì ṣe ohun àìtọ́ níwájú Olúwa Ọlọ́run wa, wọ́n sì kọ̀ ọ́ sílẹ̀. Wọ́n sì yí ojú wọn padà kúrò ní ibùgbé Olúwa, wọ́n sì pa ẹ̀yìn wọn dà sí i.
Aicae ampanawk loe Sithaw hmaa ah zae o boeh; aicae Angraeng Sithaw mikhnukah kahoih ai hmuen to a sak o moe, Angraeng to pahnawt o ving boeh; Angraeng ohhaih ahmuen to anghae o taak moe, hnuk angqoi o taak ving boeh.
7 Wọ́n sì tún ti ìlẹ̀kùn ìloro náà pẹ̀lú, wọ́n sì pa fìtílà. Wọn kò sì sun tùràrí tàbí pèsè ẹbọ sísun si ibi mímọ́ si Ọlọ́run Israẹli.
Imthung akunhaih thoknawk to khah o moe, hmaiim to kalah bangah suek o ving boeh; nihcae loe Israel Sithaw khaeah hmuihoih thlaek o ai moe, angbawnhaih doeh hmuenciim ah sah o ai boeh.
8 Nítorí náà, ìbínú Olúwa ti ru sókè wá sórí Juda àti Jerusalẹmu ó sì ti fi wọ́n ṣe ohun èlò fún wàhálà, àti ìdààmú àti ẹ̀sín, gẹ́gẹ́ bí ó ti ṣe fi ojú rẹ̀ rí i.
To pongah Angraeng palungphuihaih to Judah hoi Israel nuiah phak; na mik hoi na hnuk o ih baktih toengah, nihcae to raihaih paek moe, dawnraihaih hoi minawk mah pahnui thui ih kami ah oh hanah a suek.
9 Ìdí nìyí tí àwọn baba wa ṣe ṣubú nípa idà àti ìdí tí àwọn ọmọkùnrin àti ọmọbìnrin àti àwọn aya wa tiwọn kó wọ́n ní ìgbèkùn.
To tiah oh o pongah khenah, aicae ampanawk loe sumsen hoiah duek o moe, aicae ih canu, capa hoi zunawk to misong ah caeh o haih.
10 Nísinsin yìí ó wà ní ọkàn mi láti bá Olúwa Ọlọ́run Israẹli dá májẹ̀mú. Bẹ́ẹ̀ ni kí ìbínú rẹ̀ kíkan kí ó lè yípadà kúrò lọ́dọ̀ wa.
Aicae nuiah palungphuihaih dipsak hanah, vaihi Israel Angraeng Sithaw hoi lokmaihaih sak hanah ka poek.
11 Àwọn ọmọ mi, ẹ má ṣe jáfara nísinsin yìí, nítorí tí Olúwa ti yàn yín láti dúró níwájú rẹ̀ láti sin, kí ẹ sì máa ṣe ìránṣẹ́ níwájú rẹ̀ àti láti sun tùràrí.”
Ka capanawk, Angraeng hmaa ah angdoet han ih, a tok sak pae han ih, hmuihoih thlaek han ih, Anih mah ang qoih o pongah, vaihi tidoeh sah ai ah om o hmah, tiah a naa.
12 Nígbà náà àwọn ọmọ Lefi wọ̀nyí múra láti ṣe iṣẹ́: nínú àwọn ọmọ Kohati, Mahati ọmọ Amasai: àti Joẹli ọmọ Asariah; nínú àwọn ọmọ Merari, Kiṣi ọmọ Abdi àti Asariah ọmọ Jehaleeli; nínú àwọn ọmọ Gerṣoni, Joah, ọmọ Simma àti Edeni ọmọ Joah;
To naah to ih Levi acaengnawk, Kohat acaeng thung hoiah Amasai capa Mahat, Azariah capa Joel; Merari acaeng thung hoiah Abdi capa Kish, Jehalelel capa Azariah; Gershon acaeng thung hoiah Zimmah capa Joah, Joah capa Eden;
13 nínú àwọn ọmọ Elisafani, Ṣimri àti Jeieli; nínú àwọn ọmọ Asafu, Sekariah àti Mattaniah;
Elizaphan acaeng thung hoiah Shimri hoi Jeiel; Asaph acaeng thung hoiah Zekariah hoi Mattaniah;
14 nínú àwọn ọmọ Hemani, Jehieli àti Ṣimei; nínú àwọn ọmọ Jedutuni, Ṣemaiah àti Usieli.
Heman acaeng thung hoiah Jeiel hoi Shimei; Jeduthun acaeng thung hoiah Shemaiah hoi Uzziel cae toksak hanah angthawk o.
15 Nígbà tí wọ́n sì ti kó ara wọn jọ pọ̀ pẹ̀lú àwọn arákùnrin wọn, wọ́n sì ya ara wọn sí mímọ́, wọ́n sì lọ láti gbá ilé Olúwa mọ́, gẹ́gẹ́ bí ọba ti pa á láṣẹ, ẹ tẹ̀lé ọ̀rọ̀ Olúwa.
Angmacae nawkamyanawk nawnto amkhueng o pacoengah, Angraeng ih im to ciimsak hanah, Angraeng ih lokpaekhaih hoi siangpahrang mah thuih ih loknawk baktih toengah, angmacae hoi angmacae to ciimcai o sak.
16 Àwọn àlùfáà sì wọ inú ilé Olúwa lọ́hùn ún lọ láti gbá a mọ́. Wọ́n sì gbé e jáde sí inú àgbàlá ilé Olúwa gbogbo ohun àìmọ́ tí wọ́n rí nínú ilé Olúwa. Àwọn ọmọ Lefi sì mú u wọ́n sì gbangba odò Kidironi.
Qaimanawk loe Angraeng ih hmuen ciimsak hanah, imthung bangah akun o; Angraeng im thungah hnuk o ih kaciim ai hmuennawk to Angraeng im longhmaa ah suek o boih. To hmuennawk to Levi acaengnawk mah lak o moe, Kidron tava ah suek o.
17 Wọ́n sì bẹ̀rẹ̀ ìyàsímímọ́ ní ọjọ́ kìn-ín-ní oṣù kìn-ín-ní, àti ní ọjọ́ kẹjọ oṣù náà wọ́n sì dé ìloro Olúwa. Fún ọjọ́ mẹ́jọ mìíràn sí i, wọ́n sì ya ilé Olúwa sí mímọ́ fúnra rẹ̀. Wọ́n sì parí ní ọjọ́ kẹrìndínlógún oṣù kìn-ín-ní.
Khrah hmaloe amtong tangsuekhaih niah ciimcaihaih to amtong o moe, ni tazetto naah Angraeng im hmaa ah phak o; ni tazetto thung Angraeng im to ciimcai o sak; krah hmaloe koek ni hatlai tarukto naah pacoeng o.
18 Nígbà náà wọn sì lọ sí ọ̀dọ̀ ọba Hesekiah láti lọ jábọ̀ fún un: “Àwa ti gbá ilé Olúwa mọ́, pẹpẹ ẹbọ sísun pẹ̀lú gbogbo ohun ẹbọ rẹ̀, àti tábìlì àkàrà ìfihàn, pẹ̀lú gbogbo ohun èlò.
To pacoengah Hezekiah siangpahrang khaeah caeh o moe, anih khaeah, Angraeng im, angbawnhaih hmaicam hoi laom sabaenawk boih, takaw suekhaih caboinawk hoi laom sabaenawk to ciimcai o sak boih.
19 A ti pèsè a sì ti yà sí mímọ́ gbogbo ohun èlò tí ọba Ahasi ti sọ di aláìmọ́ nínú àìṣòótọ́ rẹ̀ nígbà tí ó jẹ́ ọba; nísinsin yìí, wọ́n wà níwájú pẹpẹ Olúwa.”
Ahaz siangpahrang ah oh naah, zaehaih sak pongah vah ving ih laom sabaenawk boih to pakhraih o moe, ka ciim o sak boeh; khenah, to baktih hmuennawk boih Angraeng ih hmaicam hmaa ah oh, tiah a naa.
20 Ní kùtùkùtù òwúrọ̀ ọjọ́ kejì, ọba Hesekiah sì kó olórí àwọn ìjòyè jọ, ó sì lọ sókè ilé Olúwa.
Hezekiah siangpahrang loe khawnbang khawnthaw ah angthawk, vangpui ukkung angraengnawk boih to nawnto amkhuengsak pacoengah, Angraeng im ah caeh o tahang.
21 Wọ́n sì mú akọ màlúù méje wá, àti àgbò méje, àti ọ̀dọ́-àgùntàn méje àti òbúkọ méje gẹ́gẹ́ bí ẹbọ ẹ̀ṣẹ̀ fún ìjọba, fún ibi mímọ́ àti fún Juda. Ọba pàṣẹ fun àwọn àlùfáà, àwọn ọmọ Aaroni, láti ṣe èyí lórí pẹpẹ Olúwa.
Maitaw tae sarihto, tuutae sarihto, tuucaa sarihto hoi maeh tae sarihto siangpahrang ih prae zaehaih, hmuenciim zaehaih hoi Judahnawk zae angbawnhaih ah paek hanah a sinh o. Aaron ih caanawk hoi qaimanawk mah Angraeng ih hmaicam ah angbawnhaih sak hanah siangpahrang mah lokpaek.
22 Bẹ́ẹ̀ ni wọ́n sì pa akọ màlúù, àwọn àlùfáà mú ẹ̀jẹ̀ náà, wọ́n sì fi wọ́n ara pẹpẹ. Bẹ́ẹ̀ gẹ́gẹ́ ni nígbà tí wọ́n pa àgbò, wọ́n sì fi ẹ̀jẹ̀ wọ́n orí pẹpẹ. Nígbà náà wọ́n sì pa ọ̀dọ́-àgùntàn, wọ́n sì fi ẹ̀jẹ̀ wọn ara pẹpẹ.
To pongah maitaw taenawk to boh o, qaimanawk mah athii to lak o moe, hmaicam ah haeh o; tuu taenawk boh o naah doeh, athii to hmaicam ah haeh o; tuucaanawk doeh boh o moe, athii to hmaicam ah haeh o.
23 Òbúkọ fún ẹbọ ẹ̀ṣẹ̀ ni wọ́n gbé wá síwájú ọba àti ìjọ ènìyàn, wọ́n sì gbé ọwọ́ lé wọn.
Zae angbawnhaih ah maeh taenawk to siangpahrang hoi kaminawk hmaa ah hoih o moe, lu nuiah ban koeng o;
24 Àwọn àlùfáà wọn sì pa òbúkọ, wọ́n sì gbé ẹ̀jẹ̀ kalẹ̀ lórí pẹpẹ fún ẹbọ ẹ̀ṣẹ̀ láti ṣe ètùtù fún gbogbo Israẹli, nítorí ọba ti pàṣẹ kí a ṣe ẹbọ sísun àti ẹbọ ẹ̀ṣẹ̀ fún gbogbo Israẹli.
siangpahrang mah Israelnawk boih hanah, hmai angbawnhaih hoi zae angbawnhaih sak hanah siangpahrang mah paek ih lok baktih toengah, qaimanawk mah maeh taenawk to boh o moe, Israel kaminawk boih zae loih hanah, athii hoiah hmaicam nuiah angdaehhaih to sak o.
25 Ó sì mú àwọn Lefi dúró nínú ilé Olúwa pẹ̀lú Kimbali, ohun èlò orin olókùn àti dùùrù ní ọ̀nà tí a ti paláṣẹ fún wọn láti ọ̀dọ̀ Dafidi àti Gadi aríran ọba àti Natani wòlíì. Èyí ni a pàṣẹ láti ọ̀dọ̀ Olúwa láti ọwọ́ àwọn wòlíì rẹ̀.
David hoi siangpahrang ih tahmaa Gad hoi tahmaa Nathan cae mah thuih ih lok baktih toengah, cingceng, tamoi hoi katoengnawk kruek kop Levi acaengnawk to im thungah ohsak; tahmaanawk khaeah Angraeng mah paek ih lok baktih toengah hae hmuen hae a sak.
26 Bẹ́ẹ̀ ni àwọn ọmọ Lefi sì dúró pẹ̀lú ohun èlò orin Dafidi, àti àwọn àlùfáà pẹ̀lú ìpè wọn.
Levi acaengnawk loe David ih atuenpawknawk hoiah angdoet o, qaimanawk doeh mongkahnawk hoiah angdoet o toeng.
27 Hesekiah sì pa á láṣẹ láti rú ẹbọ sísun lórí pẹpẹ, bí ẹbọ sísun náà ti bẹ̀rẹ̀, orin sí Olúwa bẹ̀rẹ̀ pẹ̀lú ìpè àti pẹ̀lú ohun èlò orin Dafidi ọba Israẹli.
Hezekiah mah hmaicam ah hmai angbawnhaih sak hanah lokpaek; hmai angbawnhaih sak amtong o naah, mongkah hoi Israel siangpahrang David mah sak ih atuenpawknawk hoiah Angraeng khaeah laasak amtong o.
28 Gbogbo ìjọ ènìyàn náà sì wólẹ̀ sìn, àwọn akọrin kọrin, àwọn afùnpè sì fọn ìpè, gbogbo wọ̀nyí sì wà bẹ́ẹ̀ títí ẹbọ sísun náà fi parí tán.
Hmai angbawnhaih boeng ai karoek to, laasah kaminawk mah laa to sak o moe, mongkah ueng kaminawk mah doeh mongkah to ueng o; to tiah kaminawk boih mah Sithaw to bok o.
29 Nígbà tí wọ́n sì ṣe ìparí ẹbọ rírú, ọba àti gbogbo àwọn tí ó wà pẹ̀lú rẹ̀ tẹ ara wọn ba, wọ́n sì sìn.
Hmuen tathlanghaih boeng pacoengah, siangpahrang hoi to ih kaminawk boih mah akuep hoiah Sithaw to bok o.
30 Pẹ̀lúpẹ̀lú Hesekiah ọba, àti àwọn ìjòyè pàṣẹ fún àwọn ọmọ Lefi, láti fi ọ̀rọ̀ Dafidi àti ti Asafu aríran, kọrin ìyìn sí Olúwa: wọ́n sì fi inú dídùn kọrin ìyìn, wọ́n sì tẹrí wọn ba, wọ́n sì sìn.
Hezekiah siangpahrang hoi angraengnawk loe David hoi tahmaa Asaph ih loknawk baktih toengah Angraeng saphawhaih laasak hanah Levi acaengnawk to lokpaek. To pongah nihcae mah anghoehaih hoi saphawhaih laa to sak o moe, akuephaih hoiah Sithaw to bok o.
31 Nígbà náà ni Hesekiah dáhùn, ó sì wí pé, nísinsin yìí, ọwọ́ yín kún fún ẹ̀bùn fún Olúwa, ẹ súnmọ́ ìhín, kí ẹ sì mú ẹbọ àti ọrẹ-ọpẹ́ wá sínú ilé Olúwa. Ìjọ ènìyàn sì mú ẹbọ àti ọrẹ-ọpẹ́ wá; àti olúkúlùkù tí ọkàn rẹ̀ fẹ́, mú ẹbọ sísun wá.
To naah Hezekiah mah, Vaihiah nangmacae hoi nangmacae Angraeng khaeah nang paek o boeh pongah, Angraeng im ah angzo oh loe, angbawnhaih hoiah paek ih hmuen, anghoehaih hoiah paek ih hmuennawk to sin oh, tiah a naa. To pongah rangpuinawk mah angbawnhaih hmuennawk, anghoehaih hoiah paek ih hmuennawk, palunghuemhaih hoiah paek ih hmuennawk to sin o.
32 Iye ẹbọ sísun, tí ìjọ ènìyàn mú wá, sì jẹ́ àádọ́rin akọ màlúù, àti ọgọ́rùn-ún àgbò, àti igba ọ̀dọ́-àgùntàn, gbogbo wọ̀nyí sì ni fún ẹbọ sísun sí Olúwa.
Rangpui mah angbawnhaih ah sin o ih hmuennawk loe maitaw tae quisarihto, tuu tae cumvaito hoi tuucaa cumvai hnetto phak; Angraeng khaeah angbawnhaih sak han ih ni hae hmuennawk boih hae a sinh o.
33 Àwọn ohun ìyàsímímọ́ sì jẹ́ ẹgbẹ̀ta màlúù, àti ẹgbẹ̀rún mẹ́ta àgùntàn.
Angbawnhaih ah paek ih hmuennawk loe maitaw tae cumvai tarukto, tuu sang thumto phak.
34 Ṣùgbọ́n àwọn àlùfáà kò pọ̀ tó, wọn kò sì le bó gbogbo àwọn ẹran ẹbọ sísun náà: nítorí náà àwọn arákùnrin wọn, àwọn Lefi ràn wọ́n lọ́wọ́, títí iṣẹ́ náà fi parí, àti títí àwọn àlùfáà ìyókù fi yà wọ́n sí mímọ́: nítorí àwọn ọmọ Lefi ṣe olóòtítọ́ ní ọkàn ju àwọn àlùfáà lọ láti ya ara wọn sí mímọ́.
Toe qaimanawk loe tamsi o pongah, angbawnhaih moi ahin to khok o boih thai ai; kalah qaimanawk loe ciimcai ah oh o, toksak boeng o ai karoek to, angmacae nawkamya Levi acaengnawk mah nihcae to abomh o. Levi acaengnawk loe qaimanawk pongah poekhaih palungthin ciim o kue.
35 Àti pẹ̀lú, àwọn ẹbọ sísun pàpọ̀jù, pẹ̀lú ọ̀rá ẹbọ àlàáfíà, pẹ̀lú ẹbọ ohun mímu fún ẹbọ sísun. Bẹ́ẹ̀ ni a sì tún bẹ̀rẹ̀ iṣẹ́ ìsìn ilé Olúwa.
Hmai angbawnhaih, angdaeh angbawnhaih moithawk, angbawnhaih hmuen hoi nawnto paek ih hmuen loe paroeai pop. Angraeng im thungah toksakhaih to kahoih ah raemh o.
36 Hesekiah sì yọ̀, àti gbogbo ènìyàn pé, Ọlọ́run ti múra àwọn ènìyàn náà sílẹ̀, nítorí lójijì ni a ṣe nǹkan náà.
Sithaw mah to baktih hmuen to karangah sak pacoeng hanah abomh pongah, Hezekiah hoi angmah ih kaminawk boih anghoe o.