< 2 Chronicles 28 >
1 Ahasi sì jẹ́ ẹni ogún ọdún nígbà tí ó bẹ̀rẹ̀ ìjọba, ó sì jẹ ọba ní Jerusalẹmu fún ọdún mẹ́rìndínlógún. Gẹ́gẹ́ bí i Dafidi baba rẹ̀ kò sì ṣe ohun rere ní ojú Olúwa.
Ahas var tjugu år gammal när han blev konung, och han regerade sexton år i Jerusalem. Han gjorde icke vad rätt var i HERRENS ögon, såsom hans fader David,
2 Ó sì rìn ní ọ̀nà àwọn ọba Israẹli ó sì ṣe ère dídá fún ìsìn Baali
utan vandrade på Israels konungars väg; ja, han lät ock göra gjutna beläten åt Baalerna.
3 Ó sì sun ẹbọ ní àfonífojì Hinnomu, ó sì sun àwọn ọmọ rẹ̀ nínú iná, gẹ́gẹ́ bí ohun ìríra àwọn orílẹ̀-èdè tí Olúwa lé jáde níwájú àwọn ọmọ Israẹli
Och själv tände han offereld i Hinnoms sons dal och brände upp sina barn i eld, efter den styggeliga seden hos de folk som HERREN hade fördrivit för Israels barn.
4 Ó sì rú ẹbọ, ó sì sun tùràrí ní ibi gíga wọ́n nì lórí òkè kékeré àti lábẹ́ gbogbo igi tútù.
Och han frambar offer och tände offereld på höjderna och kullarna och under alla gröna träd.
5 Nítorí náà, Olúwa Ọlọ́run rẹ̀ fi lé ọba Siria lọ́wọ́. Àwọn ará Siria sì pa á run, wọ́n sì kó púpọ̀ nínú àwọn ènìyàn rẹ̀ gẹ́gẹ́ bí ẹlẹ́wọ̀n, wọ́n sì kó wọn wá sí Damasku. Ó sì tún fi lé ọwọ́ ọba Israẹli pẹ̀lú, ẹni tí ó kó wọn ní ìgbèkùn púpọ̀ tí ó sì pa wọ́n ní ìpakúpa.
Därför gav HERREN, hans Gud, honom i den arameiske konungens hand; de slogo honom och togo av hans folk en stor hop fångar och förde dem till Damaskus. Han blev ock given i Israels konungs hand, så att denne tillfogade honom ett stort nederlag.
6 Ní ọjọ́ kan Peka, ọmọ Remaliah, pa ọ̀kẹ́ mẹ́fà àwọn ọmọ-ogun ní Juda nítorí Juda ti kọ Olúwa Ọlọ́run baba wọn sílẹ̀.
Ty Peka, Remaljas son, dräpte av Juda ett hundra tjugu tusen man på en enda dag, allasammans stridbara män. Detta skedde därför att de hade övergivit HERREN, sina fäders Gud.
7 Sikri àti Efraimu alágbára sì pa Maaseiah ọmọ ọba, Aṣrikamu ìjòyè tí ó wà ní ìkáwọ́ ilé ọba, àti Elkana igbákejì ọba.
Och Sikri, en tapper man från Efraim, dräpte Maaseja, konungasonen, och Asrikam, slottshövdingen, och Elkana, konungens närmaste man.
8 Àwọn ọmọ Israẹli sì kó ní ìgbèkùn lára àwọn arákùnrin wọn ọ̀kẹ́ mẹ́wàá àwọn aya wọn, àwọn ọmọkùnrin àti obìnrin wọn sì tún kó ọ̀pọ̀ ìkógun, èyí tí wọn kó padà lọ sí Samaria.
Och Israels barn bortförde från sina bröder två hundra tusen fångar, nämligen deras hustrur, söner och döttrar, och togo därjämte mycket byte från dem och förde bytet till Samaria.
9 Ṣùgbọ́n wòlíì Olúwa tí orúkọ rẹ̀ ń jẹ́ Odedi wà níbẹ̀, ó sì jáde lọ láti lọ pàdé ogun nígbà tí ó padà sí Samaria. Ó sì wí fún wọn pé, “Nítorí Olúwa, Ọlọ́run baba yín bínú sí Juda ó sì fi wọ́n lé yín lọ́wọ́. Ṣùgbọ́n ẹ̀yin pa wọ́n ní ìpa oró tí ó de òkè ọ̀run.
Men där var en HERRENS profet som hette Oded; denne gick ut mot hären, när den kom till Samaria, och sade till dem: "Se, i sin vrede över Juda har HERREN, edra fäders Gud, givit dem i eder hand, men I haven dräpt dem med en hätskhet som har nått upp till himmelen.
10 Nísinsin yìí, ẹ̀yin ń pète láti mú ọkùnrin àti obìnrin Juda àti Jerusalẹmu ṣe gẹ́gẹ́ bí ẹrú yín, ẹ̀yin kò ha jẹ̀bi Olúwa Ọlọ́run yín, àní ẹ̀yin?
Och nu tänken I göra Judas och Jerusalems barn till trälar och trälinnor åt eder. Därmed dragen I ju allenast skuld över eder själva inför HERREN, eder Gud.
11 Nísinsin yìí ẹ gbọ́ tèmi! Ẹ rán àwọn ìgbèkùn tí ẹ̀yin ti mú gẹ́gẹ́ bí àwọn ẹlẹ́wọ̀n padà nítorí ìbínú kíkan Olúwa ń bẹ lórí yín.”
Så hören mig nu: Sänden tillbaka fångarna som I haven tagit från edra bröder; ty HERRENS vrede är upptänd mot eder."
12 Lẹ́yìn náà, díẹ̀ nínú àwọn olórí ní Efraimu, Asariah ọmọ Jehohanani, Berekiah ọmọ Meṣilemoti, Jehiskiah ọmọ Ṣallumu, àti Amasa ọmọ Hadlai, dìde sí àwọn tí o ti ogun náà bọ̀.
Några av huvudmännen bland Efraims barn, nämligen Asarja, Johanans son, Berekja, Mesillemots son, Hiskia, Sallums son, och Amasa, Hadlais son, stodo då upp och gingo emot dem som kommo från kriget
13 Wọn si wí pé, “Ìwọ kò gbọdọ̀ mú àwọn ẹlẹ́wọ̀n wá síbí,” “tàbí àwa ti jẹ̀bi níwájú Olúwa, ṣe ẹ̀yin ń gbèrò láti fi kún ẹ̀ṣẹ̀ àti ẹ̀bi wa ni: nítorí tí ẹ̀bi wa ti tóbi púpọ̀, ìbínú rẹ̀ kíkan sì wà lórí Israẹli.”
och sade till dem: "I skolen icke föra dessa fångar hitin; ty I förehaven något som drager skuld över oss inför HERREN, och varigenom I ytterligare föröken våra synder och vår skuld. Vår skuld är ju redan stor nog, och vrede är upptänd mot Israel."
14 Bẹ́ẹ̀ ni àwọn ológun tú àwọn ẹlẹ́wọ̀n àti ìkógun sílẹ̀ níwájú àwọn ìjòyè àti gbogbo ìjọ ènìyàn.
Då lämnade krigsfolket ifrån sig fångarna och bytet inför de överste och hela församlingen.
15 Àwọn ọkùnrin tí a pè pẹ̀lú orúkọ náà sì dìde, wọn sì mú àwọn ìgbèkùn náà, wọ́n sì fi ìkógun náà wọ̀ gbogbo àwọn tí ó wà ní ìhòhò nínú wọn, wọ́n sì wọ̀ wọ́n ní aṣọ, wọ́n sì bọ̀ wọ́n ní bàtà, wọ́n sì fún wọn ní oúnjẹ àti ohun mímu, wọ́n sì fi òróró kùn wọ́n ní ara, wọ́n sì kó gbogbo àwọn tí ó jẹ́ aláìlera nínú wọ́n sórí kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́. Bẹ́ẹ̀ ni wọ́n sì kó wọn padà sí ọ̀dọ̀ àwọn arákùnrin wọn ní Jeriko, ìlú ọ̀pẹ, wọ́n sì padà sí Samaria.
Och de nämnda männen stodo upp och togo sig an fångarna. Alla som voro nakna bland dem klädde de upp med vad de hade tagit såsom byte; de gåvo dem kläder och skor, mat och dryck, och smorde dem med olja, och alla som icke orkade gå läto de sätta sig upp på åsnor, och förde dem så till Jeriko, Palmstaden, till deras bröder där. Sedan vände de tillbaka till Samaria.
16 Ní àkókò ìgbà náà, ọba Ahasi ránṣẹ́ sí ọba Asiria fún ìrànlọ́wọ́.
Vid samma tid sände konung Ahas bud till konungarna i Assyrien, med begäran att de skulle hjälpa honom.
17 Àwọn ará Edomu sì tún padà wá láti kọlu Juda kí wọn sì kó àwọn ẹlẹ́wọ̀n lọ.
Ty förutom allt annat hade edoméerna kommit och slagit Juda och tagit fångar.
18 Nígbà tí àwọn ará Filistini sì ti jagun ní ìlú pẹ̀tẹ́lẹ̀ wọ́n nì àti síhà gúúsù Juda. Wọ́n ṣẹ́gun wọ́n sì gba Beti-Ṣemeṣi, Aijaloni àti Gederoti, àti Soko, Timna, a ri Gimiso, pẹ̀lú ìletò wọn.
Och filistéerna hade fallit in i städerna i Juda lågland och sydland och hade intagit Bet-Semes, Ajalon och Gederot, så ock Soko med underlydande orter, Timna med underlydande orter och Gimso med underlydande orter, och hade bosatt sig i dem.
19 Olúwa sì rẹ Juda sílẹ̀ nítorí Ahasi ọba Israẹli, nítorí ó sọ Juda di aláìní ìrànlọ́wọ́, ó sì ṣe ìrékọjá gidigidi sí Olúwa.
Ty HERREN ville förödmjuka Juda, för Ahas', den israelitiske konungens, skull, därför att denne hade vållat oordning i Juda och varit otrogen mot HERREN.
20 Tiglat-Pileseri ọba Asiria wá sí ọ̀dọ̀ rẹ̀, ṣùgbọ́n ó fún ní ìpọ́njú dípò ìrànlọ́wọ́.
Men Tillegat-Pilneeser, konungen i Assyrien, drog emot honom och angrep honom, i stället för att understödja honom.
21 Ahasi mú díẹ̀ nínú ìní ilé Olúwa àti láti ilé ọba àti láti ọ̀dọ̀ ọba ó sì fi wọ́n fún ọba Asiria: ṣùgbọ́n èyí kò ràn wọ́n lọ́wọ́.
Ty fastän Ahas plundrade HERRENS hus och konungshuset och de överstes hus och gav allt åt konungen i Assyrien, så hjälpte det honom dock icke.
22 Ní àkókò ìpọ́njú rẹ̀ ọba Ahasi sì di aláìṣòótọ́ sí Olúwa.
Och i sin nöd försyndade sig samme konung Ahas ännu mer genom otrohet mot HERREN.
23 Ó sì rú ẹbọ sí òrìṣà àwọn Damasku, ẹni tí ó ṣẹ́gun wọn, nítorí ó rò wí pé, “Nítorí àwọn òrìṣà àwọn ọba Siria ti ràn wọ́n lọ́wọ́ kí wọn kí ó bà lè ràn mí lọ́wọ́.” Ṣùgbọ́n àwọn ni ìparun rẹ̀ àti ti gbogbo Israẹli.
Han offrade nämligen åt gudarna i Damaskus, som hade slagit honom; ty han tänkte: "Eftersom de arameiska konungarnas gudar hava förmått hjälpa dem, vill jag offra åt dessa gudar, för att de ock må hjälpa mig." Men i stället var det dessa som kommo honom och hela Israel på fall.
24 Ahasi sì kó gbogbo ohun èlò láti ilé Olúwa jọ ó sì kó wọn lọ. Ó sì ti ìlẹ̀kùn ilé Olúwa ó sì tẹ́ pẹpẹ fún ara rẹ̀ ní gbogbo igun Jerusalẹmu.
Ahas samlade ihop de kärl som funnos i Guds hus och bröt sönder kärlen i Guds hus och stängde igen dörrarna till HERRENS hus, och gjorde sig altaren i vart hörn i Jerusalem.
25 Ní gbogbo ìlú Juda ó sì kọ́ ibi gíga láti sun ẹbọ fún àwọn ọlọ́run mìíràn. Kí ó sì mú Olúwa, Ọlọ́run àwọn baba wọn bínú.
Och i var och en av Juda städer uppförde han offerhöjder för att där tända offereld åt andra gudar, och han förtörnade så HERREN, sina fäders Gud.
26 Ìyókù iṣẹ́ ìjọba rẹ̀ àti gbogbo ọ̀nà rẹ̀, láti ìbẹ̀rẹ̀ títí dé òpin, ni a kọ sínú ìwé àwọn ọba Juda àti ti Israẹli.
Vad nu mer är att säga om honom och om alla hans företag, under hans första tid såväl som under hans sista, det finnes upptecknat i boken om Judas och Israels konungar.
27 Ahasi sì sùn pẹ̀lú àwọn baba rẹ̀ a sì sin ín ní ìlú Jerusalẹmu ṣùgbọ́n wọn kò mú un wá sínú àwọn isà òkú àwọn ọba Israẹli. Hesekiah ọmọ rẹ sì jẹ ọba ní ipò rẹ̀.
Och Ahas gick till vila hos sina fäder, och man begrov honom i Jerusalem, inne i själva staden; de lade honom nämligen icke i Israels konungars gravar. Och hans son Hiskia blev konung efter honom.