< 2 Chronicles 28 >

1 Ahasi sì jẹ́ ẹni ogún ọdún nígbà tí ó bẹ̀rẹ̀ ìjọba, ó sì jẹ ọba ní Jerusalẹmu fún ọdún mẹ́rìndínlógún. Gẹ́gẹ́ bí i Dafidi baba rẹ̀ kò sì ṣe ohun rere ní ojú Olúwa.
Ahaz tinha vinte anos de idade quando começou a reinar, e reinou dezesseis anos em Jerusalém. Ele não fez o que era certo aos olhos de Iavé, como Davi, seu pai,
2 Ó sì rìn ní ọ̀nà àwọn ọba Israẹli ó sì ṣe ère dídá fún ìsìn Baali
mas ele andou nos caminhos dos reis de Israel, e também fez imagens derretidas para os Baal.
3 Ó sì sun ẹbọ ní àfonífojì Hinnomu, ó sì sun àwọn ọmọ rẹ̀ nínú iná, gẹ́gẹ́ bí ohun ìríra àwọn orílẹ̀-èdè tí Olúwa lé jáde níwájú àwọn ọmọ Israẹli
Moreover ele queimou incenso no vale do filho de Hinnom, e queimou seus filhos no fogo, de acordo com as abominações das nações que Javé expulsou diante dos filhos de Israel.
4 Ó sì rú ẹbọ, ó sì sun tùràrí ní ibi gíga wọ́n nì lórí òkè kékeré àti lábẹ́ gbogbo igi tútù.
Ele sacrificou e queimou incenso nos lugares altos e nas colinas, e debaixo de cada árvore verde.
5 Nítorí náà, Olúwa Ọlọ́run rẹ̀ fi lé ọba Siria lọ́wọ́. Àwọn ará Siria sì pa á run, wọ́n sì kó púpọ̀ nínú àwọn ènìyàn rẹ̀ gẹ́gẹ́ bí ẹlẹ́wọ̀n, wọ́n sì kó wọn wá sí Damasku. Ó sì tún fi lé ọwọ́ ọba Israẹli pẹ̀lú, ẹni tí ó kó wọn ní ìgbèkùn púpọ̀ tí ó sì pa wọ́n ní ìpakúpa.
Portanto Yahweh seu Deus o entregou nas mãos do rei da Síria. Eles o golpearam, e levaram dele uma grande multidão de cativos, e os trouxeram para Damasco. Ele também foi entregue na mão do rei de Israel, que o atingiu com um grande massacre.
6 Ní ọjọ́ kan Peka, ọmọ Remaliah, pa ọ̀kẹ́ mẹ́fà àwọn ọmọ-ogun ní Juda nítorí Juda ti kọ Olúwa Ọlọ́run baba wọn sílẹ̀.
Para Pekah, o filho de Remalias, matou em Judá cento e vinte mil em um dia, todos homens valentes, porque haviam abandonado Yahweh, o Deus de seus pais.
7 Sikri àti Efraimu alágbára sì pa Maaseiah ọmọ ọba, Aṣrikamu ìjòyè tí ó wà ní ìkáwọ́ ilé ọba, àti Elkana igbákejì ọba.
Zichri, um homem poderoso de Efraim, matou Maaséias, o filho do rei, Azrikam, o governante da casa, e Elkanah, que estava ao lado do rei.
8 Àwọn ọmọ Israẹli sì kó ní ìgbèkùn lára àwọn arákùnrin wọn ọ̀kẹ́ mẹ́wàá àwọn aya wọn, àwọn ọmọkùnrin àti obìnrin wọn sì tún kó ọ̀pọ̀ ìkógun, èyí tí wọn kó padà lọ sí Samaria.
Os filhos de Israel levaram cativas de seus irmãos duzentas mil mulheres, filhos e filhas, e também lhes tiraram muito saque, e levaram o saque para Samaria.
9 Ṣùgbọ́n wòlíì Olúwa tí orúkọ rẹ̀ ń jẹ́ Odedi wà níbẹ̀, ó sì jáde lọ láti lọ pàdé ogun nígbà tí ó padà sí Samaria. Ó sì wí fún wọn pé, “Nítorí Olúwa, Ọlọ́run baba yín bínú sí Juda ó sì fi wọ́n lé yín lọ́wọ́. Ṣùgbọ́n ẹ̀yin pa wọ́n ní ìpa oró tí ó de òkè ọ̀run.
Mas estava lá um profeta de Javé, cujo nome era Oded; e saiu ao encontro do exército que veio a Samaria, e disse-lhes: “Eis que, porque Javé, o Deus de seus pais, se indignou com Judá, entregou-os em suas mãos, e vós os matastes em uma fúria que chegou até o céu”.
10 Nísinsin yìí, ẹ̀yin ń pète láti mú ọkùnrin àti obìnrin Juda àti Jerusalẹmu ṣe gẹ́gẹ́ bí ẹrú yín, ẹ̀yin kò ha jẹ̀bi Olúwa Ọlọ́run yín, àní ẹ̀yin?
Agora vocês pretendem degradar os filhos de Judá e Jerusalém como escravos masculinos e femininos para vocês mesmos. Não há, nem mesmo com vocês, transgressões próprias contra Javé, seu Deus?
11 Nísinsin yìí ẹ gbọ́ tèmi! Ẹ rán àwọn ìgbèkùn tí ẹ̀yin ti mú gẹ́gẹ́ bí àwọn ẹlẹ́wọ̀n padà nítorí ìbínú kíkan Olúwa ń bẹ lórí yín.”
Agora, portanto, escutem-me e mandem de volta os cativos que vocês tomaram cativos de seus irmãos, pois a ira feroz de Iavé está sobre vocês”.
12 Lẹ́yìn náà, díẹ̀ nínú àwọn olórí ní Efraimu, Asariah ọmọ Jehohanani, Berekiah ọmọ Meṣilemoti, Jehiskiah ọmọ Ṣallumu, àti Amasa ọmọ Hadlai, dìde sí àwọn tí o ti ogun náà bọ̀.
Então alguns dos chefes dos filhos de Efraim, Azarias, filho de Johananan, Berequias, filho de Mesilemote, Jeizquias, filho de Salum, e Amasa, filho de Hadlai, se levantaram contra aqueles que vieram da guerra,
13 Wọn si wí pé, “Ìwọ kò gbọdọ̀ mú àwọn ẹlẹ́wọ̀n wá síbí,” “tàbí àwa ti jẹ̀bi níwájú Olúwa, ṣe ẹ̀yin ń gbèrò láti fi kún ẹ̀ṣẹ̀ àti ẹ̀bi wa ni: nítorí tí ẹ̀bi wa ti tóbi púpọ̀, ìbínú rẹ̀ kíkan sì wà lórí Israẹli.”
e lhes disseram: “Vocês não devem trazer os cativos para cá, pois pretendem que isso nos traga uma transgressão contra Javé, para acrescentar aos nossos pecados e à nossa culpa; pois nossa culpa é grande, e há uma ira feroz contra Israel”.”
14 Bẹ́ẹ̀ ni àwọn ológun tú àwọn ẹlẹ́wọ̀n àti ìkógun sílẹ̀ níwájú àwọn ìjòyè àti gbogbo ìjọ ènìyàn.
Assim, os homens armados deixaram os cativos e o saque antes dos príncipes e de toda a assembléia.
15 Àwọn ọkùnrin tí a pè pẹ̀lú orúkọ náà sì dìde, wọn sì mú àwọn ìgbèkùn náà, wọ́n sì fi ìkógun náà wọ̀ gbogbo àwọn tí ó wà ní ìhòhò nínú wọn, wọ́n sì wọ̀ wọ́n ní aṣọ, wọ́n sì bọ̀ wọ́n ní bàtà, wọ́n sì fún wọn ní oúnjẹ àti ohun mímu, wọ́n sì fi òróró kùn wọ́n ní ara, wọ́n sì kó gbogbo àwọn tí ó jẹ́ aláìlera nínú wọ́n sórí kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́. Bẹ́ẹ̀ ni wọ́n sì kó wọn padà sí ọ̀dọ̀ àwọn arákùnrin wọn ní Jeriko, ìlú ọ̀pẹ, wọ́n sì padà sí Samaria.
Os homens que foram mencionados pelo nome levantaram-se e levaram os cativos, e com o saque vestiram todos os que estavam nus entre eles, vestiram-nos, deram-lhes sandálias, deram-lhes algo para comer e beber, ungiram-nos, carregaram todos os fracos deles em burros, e os trouxeram para Jericó, a cidade das palmeiras, para seus irmãos. Em seguida, voltaram para Samaria.
16 Ní àkókò ìgbà náà, ọba Ahasi ránṣẹ́ sí ọba Asiria fún ìrànlọ́wọ́.
Naquela época o rei Ahaz enviou aos reis da Assíria para ajudá-lo.
17 Àwọn ará Edomu sì tún padà wá láti kọlu Juda kí wọn sì kó àwọn ẹlẹ́wọ̀n lọ.
Pois novamente os edomitas tinham chegado e atingido Judá, e levado cativos.
18 Nígbà tí àwọn ará Filistini sì ti jagun ní ìlú pẹ̀tẹ́lẹ̀ wọ́n nì àti síhà gúúsù Juda. Wọ́n ṣẹ́gun wọ́n sì gba Beti-Ṣemeṣi, Aijaloni àti Gederoti, àti Soko, Timna, a ri Gimiso, pẹ̀lú ìletò wọn.
Os filisteus também tinham invadido as cidades da planície e do sul de Judá, e tinham tomado Beth Shemesh, Aijalon, Gederoth, Soco com suas aldeias, Timnah com suas aldeias, e também Gimzo e suas aldeias; e eles viviam lá.
19 Olúwa sì rẹ Juda sílẹ̀ nítorí Ahasi ọba Israẹli, nítorí ó sọ Juda di aláìní ìrànlọ́wọ́, ó sì ṣe ìrékọjá gidigidi sí Olúwa.
Pois Yahweh trouxe Judá para baixo por causa de Ahaz, rei de Israel, porque ele agiu sem restrições em Judá e transgrediu severamente contra Yahweh.
20 Tiglat-Pileseri ọba Asiria wá sí ọ̀dọ̀ rẹ̀, ṣùgbọ́n ó fún ní ìpọ́njú dípò ìrànlọ́wọ́.
Tilgath-pilneser, rei da Assíria, veio até ele e lhe deu problemas, mas não o fortaleceu.
21 Ahasi mú díẹ̀ nínú ìní ilé Olúwa àti láti ilé ọba àti láti ọ̀dọ̀ ọba ó sì fi wọ́n fún ọba Asiria: ṣùgbọ́n èyí kò ràn wọ́n lọ́wọ́.
Pois Ahaz tirou uma porção da casa de Iavé, e da casa do rei e dos príncipes, e a deu ao rei da Assíria; mas isso não o ajudou.
22 Ní àkókò ìpọ́njú rẹ̀ ọba Ahasi sì di aláìṣòótọ́ sí Olúwa.
Na época de sua angústia, ele transgrediu ainda mais contra Yahweh, esse mesmo Rei Ahaz.
23 Ó sì rú ẹbọ sí òrìṣà àwọn Damasku, ẹni tí ó ṣẹ́gun wọn, nítorí ó rò wí pé, “Nítorí àwọn òrìṣà àwọn ọba Siria ti ràn wọ́n lọ́wọ́ kí wọn kí ó bà lè ràn mí lọ́wọ́.” Ṣùgbọ́n àwọn ni ìparun rẹ̀ àti ti gbogbo Israẹli.
Pois ele se sacrificou aos deuses de Damasco que o haviam derrotado. Ele disse: “Porque os deuses dos reis da Síria os ajudaram, eu me sacrificarei a eles, para que eles me ajudem”. Mas eles foram a ruína dele e de todo Israel.
24 Ahasi sì kó gbogbo ohun èlò láti ilé Olúwa jọ ó sì kó wọn lọ. Ó sì ti ìlẹ̀kùn ilé Olúwa ó sì tẹ́ pẹpẹ fún ara rẹ̀ ní gbogbo igun Jerusalẹmu.
Ahaz reuniu os vasos da casa de Deus, cortou os vasos da casa de Deus em pedaços e fechou as portas da casa de Iavé; e fez altares em todos os cantos de Jerusalém.
25 Ní gbogbo ìlú Juda ó sì kọ́ ibi gíga láti sun ẹbọ fún àwọn ọlọ́run mìíràn. Kí ó sì mú Olúwa, Ọlọ́run àwọn baba wọn bínú.
Em cada cidade de Judá ele fez altos lugares para queimar incenso a outros deuses, e provocou Yavé, o Deus de seus pais, à cólera.
26 Ìyókù iṣẹ́ ìjọba rẹ̀ àti gbogbo ọ̀nà rẹ̀, láti ìbẹ̀rẹ̀ títí dé òpin, ni a kọ sínú ìwé àwọn ọba Juda àti ti Israẹli.
Agora o resto de seus atos, e todos os seus caminhos, primeiro e último, eis que estão escritos no livro dos reis de Judá e Israel.
27 Ahasi sì sùn pẹ̀lú àwọn baba rẹ̀ a sì sin ín ní ìlú Jerusalẹmu ṣùgbọ́n wọn kò mú un wá sínú àwọn isà òkú àwọn ọba Israẹli. Hesekiah ọmọ rẹ sì jẹ ọba ní ipò rẹ̀.
Acaz dormiu com seus pais, e o enterraram na cidade, mesmo em Jerusalém, porque não o trouxeram aos túmulos dos reis de Israel; e Ezequias, seu filho, reinou em seu lugar.

< 2 Chronicles 28 >