< 2 Chronicles 28 >
1 Ahasi sì jẹ́ ẹni ogún ọdún nígbà tí ó bẹ̀rẹ̀ ìjọba, ó sì jẹ ọba ní Jerusalẹmu fún ọdún mẹ́rìndínlógún. Gẹ́gẹ́ bí i Dafidi baba rẹ̀ kò sì ṣe ohun rere ní ojú Olúwa.
Húsz esztendős volt Akház, mikor uralkodni kezdett, és tizenhat esztendeig uralkodék Jeruzsálemben, és nem cselekedék kedves dolgot az Úr előtt, mint Dávid, az ő atyja;
2 Ó sì rìn ní ọ̀nà àwọn ọba Israẹli ó sì ṣe ère dídá fún ìsìn Baali
Hanem az Izráel királyainak útján járt, és öntött bálványokat is csináltatott a Baál tiszteletére.
3 Ó sì sun ẹbọ ní àfonífojì Hinnomu, ó sì sun àwọn ọmọ rẹ̀ nínú iná, gẹ́gẹ́ bí ohun ìríra àwọn orílẹ̀-èdè tí Olúwa lé jáde níwájú àwọn ọmọ Israẹli
Annakfelette tömjéneze a Hinnom fiának völgyében; fiait is megégeté tűzben, a pogányok útálatosságai szerint, a kiket az Úr az Izráel fiai elől kiűzött volt.
4 Ó sì rú ẹbọ, ó sì sun tùràrí ní ibi gíga wọ́n nì lórí òkè kékeré àti lábẹ́ gbogbo igi tútù.
Áldozék és tömjéneze a magaslatokon is, a halmokon is és minden zöld fa alatt.
5 Nítorí náà, Olúwa Ọlọ́run rẹ̀ fi lé ọba Siria lọ́wọ́. Àwọn ará Siria sì pa á run, wọ́n sì kó púpọ̀ nínú àwọn ènìyàn rẹ̀ gẹ́gẹ́ bí ẹlẹ́wọ̀n, wọ́n sì kó wọn wá sí Damasku. Ó sì tún fi lé ọwọ́ ọba Israẹli pẹ̀lú, ẹni tí ó kó wọn ní ìgbèkùn púpọ̀ tí ó sì pa wọ́n ní ìpakúpa.
Ezért az Úr az ő Istene adá őt a Siriabeli király kezébe, és őt igen megverék, és sok foglyot hurczolának el ő tőle, a kiket Damaskusba vivének. Sőt még az Izráel királya kezébe is adaték, és az is igen megveré őt.
6 Ní ọjọ́ kan Peka, ọmọ Remaliah, pa ọ̀kẹ́ mẹ́fà àwọn ọmọ-ogun ní Juda nítorí Juda ti kọ Olúwa Ọlọ́run baba wọn sílẹ̀.
Mert Pékah, a Rémália fia, Júdában egy nap levága százhúszezer embert, mind vitézeket; mivel elhagyták az Urat, atyáik Istenét.
7 Sikri àti Efraimu alágbára sì pa Maaseiah ọmọ ọba, Aṣrikamu ìjòyè tí ó wà ní ìkáwọ́ ilé ọba, àti Elkana igbákejì ọba.
Annakfelette az Efraimbeli vitéz Zikri megölé Maásiát, a király fiát, Azrikámot, az ő házának gondviselőjét, és Elkánát, a ki a király után második vala.
8 Àwọn ọmọ Israẹli sì kó ní ìgbèkùn lára àwọn arákùnrin wọn ọ̀kẹ́ mẹ́wàá àwọn aya wọn, àwọn ọmọkùnrin àti obìnrin wọn sì tún kó ọ̀pọ̀ ìkógun, èyí tí wọn kó padà lọ sí Samaria.
És elvivének az Izráel fiai az ő atyjokfiai közül kétszázezer asszonyt, fiút, leányt, és nagy vagyont rablának el tőlök, és azzal a zsákmánynyal mennek vala Samariába.
9 Ṣùgbọ́n wòlíì Olúwa tí orúkọ rẹ̀ ń jẹ́ Odedi wà níbẹ̀, ó sì jáde lọ láti lọ pàdé ogun nígbà tí ó padà sí Samaria. Ó sì wí fún wọn pé, “Nítorí Olúwa, Ọlọ́run baba yín bínú sí Juda ó sì fi wọ́n lé yín lọ́wọ́. Ṣùgbọ́n ẹ̀yin pa wọ́n ní ìpa oró tí ó de òkè ọ̀run.
Vala pedig ott az Úrnak egy prófétája, a kinek neve Odéd, a ki eleibe menvén a hadnak, a mely Samariába megy vala, monda nékik: Ímé, mivel az Úrnak, atyáitok Istenének haragja Júda ellen felgerjedett, őket kezetekbe adta, és ti sokat megölétek közülök haragotokban, a mely szintén az égig felhatott;
10 Nísinsin yìí, ẹ̀yin ń pète láti mú ọkùnrin àti obìnrin Juda àti Jerusalẹmu ṣe gẹ́gẹ́ bí ẹrú yín, ẹ̀yin kò ha jẹ̀bi Olúwa Ọlọ́run yín, àní ẹ̀yin?
És immár arra gondoltok, hogy Júdának és Jeruzsálemnek fiait megalázzátok, hogy néktek szolgáitok és szolgálóleányitok legyenek: avagy ezáltal nem teszitek-é magatokat bűnösökké az Úrnál, a ti Isteneteknél?
11 Nísinsin yìí ẹ gbọ́ tèmi! Ẹ rán àwọn ìgbèkùn tí ẹ̀yin ti mú gẹ́gẹ́ bí àwọn ẹlẹ́wọ̀n padà nítorí ìbínú kíkan Olúwa ń bẹ lórí yín.”
Azért halljátok meg szómat: Vigyétek vissza a ti atyátokfiai közül való foglyokat, a kiket ide hoztatok; különben az Úrnak nagy haragja lészen rajtatok.
12 Lẹ́yìn náà, díẹ̀ nínú àwọn olórí ní Efraimu, Asariah ọmọ Jehohanani, Berekiah ọmọ Meṣilemoti, Jehiskiah ọmọ Ṣallumu, àti Amasa ọmọ Hadlai, dìde sí àwọn tí o ti ogun náà bọ̀.
Akkor felkelének némelyek az Efraimból való vezérek közül: Azáriás, a Jóhanán fia; Berékiás, a Mesillemót fia; Ezékiás, a Sallum fia, és Amása a Hadlai fia, azok ellen, a kik a viadalból jőnek vala.
13 Wọn si wí pé, “Ìwọ kò gbọdọ̀ mú àwọn ẹlẹ́wọ̀n wá síbí,” “tàbí àwa ti jẹ̀bi níwájú Olúwa, ṣe ẹ̀yin ń gbèrò láti fi kún ẹ̀ṣẹ̀ àti ẹ̀bi wa ni: nítorí tí ẹ̀bi wa ti tóbi púpọ̀, ìbínú rẹ̀ kíkan sì wà lórí Israẹli.”
És mondának nékik: Ne hozzátok ide be a foglyokat, mert felette igen nagy bűn lesz az, a mit akartok művelni, és ezzel a mi bűneinket és vétkeinket megsokasítjátok; mert e nélkül is sok bűnünk van, és felgerjedt a harag Izráel ellen.
14 Bẹ́ẹ̀ ni àwọn ológun tú àwọn ẹlẹ́wọ̀n àti ìkógun sílẹ̀ níwájú àwọn ìjòyè àti gbogbo ìjọ ènìyàn.
Ott hagyá azért a sereg a foglyokat és a zsákmányt a vezérek és az egész gyülekezet előtt.
15 Àwọn ọkùnrin tí a pè pẹ̀lú orúkọ náà sì dìde, wọn sì mú àwọn ìgbèkùn náà, wọ́n sì fi ìkógun náà wọ̀ gbogbo àwọn tí ó wà ní ìhòhò nínú wọn, wọ́n sì wọ̀ wọ́n ní aṣọ, wọ́n sì bọ̀ wọ́n ní bàtà, wọ́n sì fún wọn ní oúnjẹ àti ohun mímu, wọ́n sì fi òróró kùn wọ́n ní ara, wọ́n sì kó gbogbo àwọn tí ó jẹ́ aláìlera nínú wọ́n sórí kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́. Bẹ́ẹ̀ ni wọ́n sì kó wọn padà sí ọ̀dọ̀ àwọn arákùnrin wọn ní Jeriko, ìlú ọ̀pẹ, wọ́n sì padà sí Samaria.
És felállának a névszerint megnevezett férfiak, s felvevék a foglyokat, és a kik mezítelenek valának közülök, felöltözteték a zsákmányból; felöltözteték azokat, sarukat is adának lábaikra; ételt és italt is adának nékik; sőt meg is kenék őket, és a gyengélkedőket szamarakra helyezék, és vivék őket a pálmafák városába, Jérikhóba, az ő atyjokfiaihoz; azután megtérének Samariába.
16 Ní àkókò ìgbà náà, ọba Ahasi ránṣẹ́ sí ọba Asiria fún ìrànlọ́wọ́.
Az időben külde Akház király az Assiriabeli királyhoz, hogy megsegítené őt.
17 Àwọn ará Edomu sì tún padà wá láti kọlu Juda kí wọn sì kó àwọn ẹlẹ́wọ̀n lọ.
Mert még az Edomiták is eljöttek vala, és a Júdabeliek közül sokat levágának, vagy rabságba hurczolának.
18 Nígbà tí àwọn ará Filistini sì ti jagun ní ìlú pẹ̀tẹ́lẹ̀ wọ́n nì àti síhà gúúsù Juda. Wọ́n ṣẹ́gun wọ́n sì gba Beti-Ṣemeṣi, Aijaloni àti Gederoti, àti Soko, Timna, a ri Gimiso, pẹ̀lú ìletò wọn.
A Filiszteusok is mind ellepék a lapályon való városokat és Júdának dél felől való részét, és elfoglalák Béth-Semest, Ajalont, Gederótot, Sókot és annak faluit; Timnát és annak faluit; Gimzót és annak faluit, és ott laknak vala;
19 Olúwa sì rẹ Juda sílẹ̀ nítorí Ahasi ọba Israẹli, nítorí ó sọ Juda di aláìní ìrànlọ́wọ́, ó sì ṣe ìrékọjá gidigidi sí Olúwa.
Mert az Úr megalázta Júdát Akházért, az Izráel királyáért; mert arra indítá Júdát, hogy vétkezzék az Úr ellen.
20 Tiglat-Pileseri ọba Asiria wá sí ọ̀dọ̀ rẹ̀, ṣùgbọ́n ó fún ní ìpọ́njú dípò ìrànlọ́wọ́.
Eljöve azért ő ellene Tiglát-Piléser, Assiria királya, a ki sanyargatá őt, és nem segítette meg.
21 Ahasi mú díẹ̀ nínú ìní ilé Olúwa àti láti ilé ọba àti láti ọ̀dọ̀ ọba ó sì fi wọ́n fún ọba Asiria: ṣùgbọ́n èyí kò ràn wọ́n lọ́wọ́.
Mert Akház kifosztá az Úr házát, a királyét, a fejedelmekét, és az Assiriabeli királynak adá, de azért nem lőn néki segítségére.
22 Ní àkókò ìpọ́njú rẹ̀ ọba Ahasi sì di aláìṣòótọ́ sí Olúwa.
Sőt még a szorongattatás idejében is tovább vétkezék az Úr ellen; ilyen vala Akház király.
23 Ó sì rú ẹbọ sí òrìṣà àwọn Damasku, ẹni tí ó ṣẹ́gun wọn, nítorí ó rò wí pé, “Nítorí àwọn òrìṣà àwọn ọba Siria ti ràn wọ́n lọ́wọ́ kí wọn kí ó bà lè ràn mí lọ́wọ́.” Ṣùgbọ́n àwọn ni ìparun rẹ̀ àti ti gbogbo Israẹli.
Mert áldozék Damaskus isteneinek, a kik őt megverték vala, ezt mondván: Mivel Siria királyainak istenei megsegítik őket, azért én is azoknak áldozom, hogy segéljenek engem is, holott mind néki, mind az egész Izráelnek azok okozták romlását.
24 Ahasi sì kó gbogbo ohun èlò láti ilé Olúwa jọ ó sì kó wọn lọ. Ó sì ti ìlẹ̀kùn ilé Olúwa ó sì tẹ́ pẹpẹ fún ara rẹ̀ ní gbogbo igun Jerusalẹmu.
És összehordá Akház az Isten házának edényeit, és összetöré az Isten házának edényeit, és az Úr házának ajtait bezárá, és csinála a maga számára oltárokat Jeruzsálemnek minden szegletén;
25 Ní gbogbo ìlú Juda ó sì kọ́ ibi gíga láti sun ẹbọ fún àwọn ọlọ́run mìíràn. Kí ó sì mú Olúwa, Ọlọ́run àwọn baba wọn bínú.
Júdának minden városaiban is magaslatokat építe, hogy az idegen isteneknek tömjénezzen, és haragra ingerlé az Urat, atyái Istenét.
26 Ìyókù iṣẹ́ ìjọba rẹ̀ àti gbogbo ọ̀nà rẹ̀, láti ìbẹ̀rẹ̀ títí dé òpin, ni a kọ sínú ìwé àwọn ọba Juda àti ti Israẹli.
Az ő több dolgai pedig és útjai, úgy az elsők, mint utolsók, ímé meg vannak írva a Júda és az Izráel királyainak könyvében.
27 Ahasi sì sùn pẹ̀lú àwọn baba rẹ̀ a sì sin ín ní ìlú Jerusalẹmu ṣùgbọ́n wọn kò mú un wá sínú àwọn isà òkú àwọn ọba Israẹli. Hesekiah ọmọ rẹ sì jẹ ọba ní ipò rẹ̀.
Meghala pedig Akház az ő atyáival, és eltemeték őt Jeruzsálem városában; mert nem vivék őt az Izráel királyainak sírjába. És uralkodék az ő fia, Ezékiás, ő helyette.