< 2 Chronicles 28 >

1 Ahasi sì jẹ́ ẹni ogún ọdún nígbà tí ó bẹ̀rẹ̀ ìjọba, ó sì jẹ ọba ní Jerusalẹmu fún ọdún mẹ́rìndínlógún. Gẹ́gẹ́ bí i Dafidi baba rẹ̀ kò sì ṣe ohun rere ní ojú Olúwa.
Ahaz te a manghai vaengah kum kul lo ca pueng tih Jerusalem ah kum hlai rhuk manghai. Tedae a napa David bangla BOEIPA mikhmuh ah a thuem a saii moenih.
2 Ó sì rìn ní ọ̀nà àwọn ọba Israẹli ó sì ṣe ère dídá fún ìsìn Baali
Israel manghai rhoek longpuei ah pongpa tih Baal rhoek hamla mueihlawn khaw a saii pah.
3 Ó sì sun ẹbọ ní àfonífojì Hinnomu, ó sì sun àwọn ọmọ rẹ̀ nínú iná, gẹ́gẹ́ bí ohun ìríra àwọn orílẹ̀-èdè tí Olúwa lé jáde níwájú àwọn ọmọ Israẹli
Anih loh kolrhawk ah a phum tih BOEIPA loh Israel ca mikhmuh lamkah a haek namtom rhoek kah a tueilaehkoi la hmai dongah a ca rhoek a pup.
4 Ó sì rú ẹbọ, ó sì sun tùràrí ní ibi gíga wọ́n nì lórí òkè kékeré àti lábẹ́ gbogbo igi tútù.
Hmuensang ah khaw, som ah khaw, thing hing tom kah a hmuiah khaw a nawn tih a phum.
5 Nítorí náà, Olúwa Ọlọ́run rẹ̀ fi lé ọba Siria lọ́wọ́. Àwọn ará Siria sì pa á run, wọ́n sì kó púpọ̀ nínú àwọn ènìyàn rẹ̀ gẹ́gẹ́ bí ẹlẹ́wọ̀n, wọ́n sì kó wọn wá sí Damasku. Ó sì tún fi lé ọwọ́ ọba Israẹli pẹ̀lú, ẹni tí ó kó wọn ní ìgbèkùn púpọ̀ tí ó sì pa wọ́n ní ìpakúpa.
Te dongah anih te a Pathen BOEIPA loh Aram manghai kut ah a paek tih amah ah a ngawn uh. Te vaengah anih taengkah tamna te muep a sol uh tih Damasku la a thak uh. Israel manghai kut dongla a voeih bal tih anih te hmasoe len neh a ngawn.
6 Ní ọjọ́ kan Peka, ọmọ Remaliah, pa ọ̀kẹ́ mẹ́fà àwọn ọmọ-ogun ní Juda nítorí Juda ti kọ Olúwa Ọlọ́run baba wọn sílẹ̀.
A napa rhoek kah Pathen BOEIPA te a toeng uh dongah tatthai ca boeih te hnin at dongah Judah kah Remaliah capa Pekah loh thawng yakhat neh thawng kul a ngawn.
7 Sikri àti Efraimu alágbára sì pa Maaseiah ọmọ ọba, Aṣrikamu ìjòyè tí ó wà ní ìkáwọ́ ilé ọba, àti Elkana igbákejì ọba.
Ephraim hlangrhalh Zikhri loh manghai capa Maaseiah, a im kah rhaengsang Azrikam, manghai hnukthoi Elkanah te a ngawn.
8 Àwọn ọmọ Israẹli sì kó ní ìgbèkùn lára àwọn arákùnrin wọn ọ̀kẹ́ mẹ́wàá àwọn aya wọn, àwọn ọmọkùnrin àti obìnrin wọn sì tún kó ọ̀pọ̀ ìkógun, èyí tí wọn kó padà lọ sí Samaria.
A manuca khui lamkah Israel ca rhoek te a yuu khaw, a capa khaw, a canu khaw thawng yahnih te a sol pa uh. Te lamkah kutbuem muep a poelyoe uh tih kutbuem te Samaria la a khuen uh.
9 Ṣùgbọ́n wòlíì Olúwa tí orúkọ rẹ̀ ń jẹ́ Odedi wà níbẹ̀, ó sì jáde lọ láti lọ pàdé ogun nígbà tí ó padà sí Samaria. Ó sì wí fún wọn pé, “Nítorí Olúwa, Ọlọ́run baba yín bínú sí Juda ó sì fi wọ́n lé yín lọ́wọ́. Ṣùgbọ́n ẹ̀yin pa wọ́n ní ìpa oró tí ó de òkè ọ̀run.
Te vaengah BOEIPA kah tonghma, a ming ah Oded te pahoi om tih Samaria la aka pawk caempuei hmai la cet. Te phoeiah amih te, “Na pa rhoek kah Pathen BOEIPA kah kosi kongah ni amih te Judah neh nang kut ah m'paek. Tedae amih te vaan a pha hil thintoek neh na ngawn.
10 Nísinsin yìí, ẹ̀yin ń pète láti mú ọkùnrin àti obìnrin Juda àti Jerusalẹmu ṣe gẹ́gẹ́ bí ẹrú yín, ẹ̀yin kò ha jẹ̀bi Olúwa Ọlọ́run yín, àní ẹ̀yin?
Judah koca neh Jerusalem nang te salnu la, salpa la kang khoh eh a ti coeng. Nangmih kongah namah neh na taengkah khaw, na Pathen BOEIPA taengah dumlai moenih a?
11 Nísinsin yìí ẹ gbọ́ tèmi! Ẹ rán àwọn ìgbèkùn tí ẹ̀yin ti mú gẹ́gẹ́ bí àwọn ẹlẹ́wọ̀n padà nítorí ìbínú kíkan Olúwa ń bẹ lórí yín.”
Kai ol he hnatun lamtah na manuca taeng lamkah na sol tamna te mael laeh. BOEIPA kah thintoek thinsa tah nangmih soah om coeng,” a ti nah.
12 Lẹ́yìn náà, díẹ̀ nínú àwọn olórí ní Efraimu, Asariah ọmọ Jehohanani, Berekiah ọmọ Meṣilemoti, Jehiskiah ọmọ Ṣallumu, àti Amasa ọmọ Hadlai, dìde sí àwọn tí o ti ogun náà bọ̀.
Ephraim koca boeilu lamkah hlang rhoek Jehohanan capa Azariah, Meshillemith capa Berekiah, Shallum capa Hezekiah, Hadlai capa Amasa loh caempuei lamkah aka pawk rhoek te a mah uh.
13 Wọn si wí pé, “Ìwọ kò gbọdọ̀ mú àwọn ẹlẹ́wọ̀n wá síbí,” “tàbí àwa ti jẹ̀bi níwájú Olúwa, ṣe ẹ̀yin ń gbèrò láti fi kún ẹ̀ṣẹ̀ àti ẹ̀bi wa ni: nítorí tí ẹ̀bi wa ti tóbi púpọ̀, ìbínú rẹ̀ kíkan sì wà lórí Israẹli.”
Te phoeiah amih te, “Tamna te hela hang khuen uh boeh. Kaimih ham BOEIPA kah dumlai rhung la. Mamih kah tholhnah ham neh mamih kah dumlai ham ka koei eh na ti uh te. Mamih kah dumlai neh Israel sokah thintoek thinsa mah khawk coeng,” a ti uh.
14 Bẹ́ẹ̀ ni àwọn ológun tú àwọn ẹlẹ́wọ̀n àti ìkógun sílẹ̀ níwájú àwọn ìjòyè àti gbogbo ìjọ ènìyàn.
Te dongah aka pumcum rhoek long khaw tamna neh kutbuem te mangpa rhoek neh hlangping boeih kah mikhmuh ah a toeng.
15 Àwọn ọkùnrin tí a pè pẹ̀lú orúkọ náà sì dìde, wọn sì mú àwọn ìgbèkùn náà, wọ́n sì fi ìkógun náà wọ̀ gbogbo àwọn tí ó wà ní ìhòhò nínú wọn, wọ́n sì wọ̀ wọ́n ní aṣọ, wọ́n sì bọ̀ wọ́n ní bàtà, wọ́n sì fún wọn ní oúnjẹ àti ohun mímu, wọ́n sì fi òróró kùn wọ́n ní ara, wọ́n sì kó gbogbo àwọn tí ó jẹ́ aláìlera nínú wọ́n sórí kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́. Bẹ́ẹ̀ ni wọ́n sì kó wọn padà sí ọ̀dọ̀ àwọn arákùnrin wọn ní Jeriko, ìlú ọ̀pẹ, wọ́n sì padà sí Samaria.
Te vaengah ming neh a phoei hlang rhoek te thoo uh tih tamna te a talong uh. Amih pumtling boeih te khaw kutbuem lamkah neh a khuk uh tih amih a bai sak uh. Amih te a khom sak phoeiah a cah uh tih a tul uh. Amih te a yuh uh phoeiah tattloel boeih ham te laak dongah a khool uh. Amih te rhophoe khopuei Jerikho kah a manuca taengla a thak uh phoeiah Samaria la mael uh.
16 Ní àkókò ìgbà náà, ọba Ahasi ránṣẹ́ sí ọba Asiria fún ìrànlọ́wọ́.
Te vaeng tue ah manghai Ahaz loh amah aka bom la Assyria manghai te a tah.
17 Àwọn ará Edomu sì tún padà wá láti kọlu Juda kí wọn sì kó àwọn ẹlẹ́wọ̀n lọ.
Edom khaw koep ha pawk tih Judah te a ngawn phoeiah tamna la a sol uh.
18 Nígbà tí àwọn ará Filistini sì ti jagun ní ìlú pẹ̀tẹ́lẹ̀ wọ́n nì àti síhà gúúsù Juda. Wọ́n ṣẹ́gun wọ́n sì gba Beti-Ṣemeṣi, Aijaloni àti Gederoti, àti Soko, Timna, a ri Gimiso, pẹ̀lú ìletò wọn.
Philisti khaw kolrhawk khopuei neh Judah kah Negev ah capit tih Bethshemesh khaw, Aijalon khaw, Gederoth khaw, Sokoh neh a khobuel rhoek khaw, Timnah neh a khobuel rhoek khaw, Gimzo neh a khobuel rhoek khaw a loh uh tih pahoi kho a sak uh.
19 Olúwa sì rẹ Juda sílẹ̀ nítorí Ahasi ọba Israẹli, nítorí ó sọ Juda di aláìní ìrànlọ́wọ́, ó sì ṣe ìrékọjá gidigidi sí Olúwa.
Israel manghai Ahaz kong ah ni BOEIPA loh Judah te a kunyun sak. Anih loh Judah ah a hlahpham dongah ni BOEIPA taengah boekoeknah la boe a koek uh.
20 Tiglat-Pileseri ọba Asiria wá sí ọ̀dọ̀ rẹ̀, ṣùgbọ́n ó fún ní ìpọ́njú dípò ìrànlọ́wọ́.
Assyria manghai Tiglathpileser khaw anih taengla pawk dae anih te a daengdaeh tih a duel moenih.
21 Ahasi mú díẹ̀ nínú ìní ilé Olúwa àti láti ilé ọba àti láti ọ̀dọ̀ ọba ó sì fi wọ́n fún ọba Asiria: ṣùgbọ́n èyí kò ràn wọ́n lọ́wọ́.
Ahaz loh BOEIPA im neh manghai im te khaw, mangpa rhoek khaw a tael tih Assyria manghai taengla a paek dae anih ham bomnah la a om pah moenih.
22 Ní àkókò ìpọ́njú rẹ̀ ọba Ahasi sì di aláìṣòótọ́ sí Olúwa.
Amah kah puencak tue vaengah pataeng khaw BOEIPA taengah boekoek ham aka khoep tah manghai Ahaz amah ni.
23 Ó sì rú ẹbọ sí òrìṣà àwọn Damasku, ẹni tí ó ṣẹ́gun wọn, nítorí ó rò wí pé, “Nítorí àwọn òrìṣà àwọn ọba Siria ti ràn wọ́n lọ́wọ́ kí wọn kí ó bà lè ràn mí lọ́wọ́.” Ṣùgbọ́n àwọn ni ìparun rẹ̀ àti ti gbogbo Israẹli.
Amih aka bom Aram manghai rhoek kah pathen te ka nawn daengah ni kai m'bom uh van eh a ti tih, amah aka ngawn Damasku pathen te a nawn. Tedae te anih taengah tah amah neh Israel pum te aka paloe sak la poeh uh.
24 Ahasi sì kó gbogbo ohun èlò láti ilé Olúwa jọ ó sì kó wọn lọ. Ó sì ti ìlẹ̀kùn ilé Olúwa ó sì tẹ́ pẹpẹ fún ara rẹ̀ ní gbogbo igun Jerusalẹmu.
Ahaz loh Pathen im kah hnopai te a coi tih Pathen im kah hnopai te a top. Te phoeiah BOEIPA im kah thohkhaih te a khaih tih Jerusalem kah bangkil boeih ah amah ham hmueihtuk a suem.
25 Ní gbogbo ìlú Juda ó sì kọ́ ibi gíga láti sun ẹbọ fún àwọn ọlọ́run mìíràn. Kí ó sì mú Olúwa, Ọlọ́run àwọn baba wọn bínú.
Pathen tloe rhoek taengah phum hamla Judah kah khopuei, khopuei boeih ah hmuensang te a saii tih a napa rhoek kah Pathen BOEIPA te a veet.
26 Ìyókù iṣẹ́ ìjọba rẹ̀ àti gbogbo ọ̀nà rẹ̀, láti ìbẹ̀rẹ̀ títí dé òpin, ni a kọ sínú ìwé àwọn ọba Juda àti ti Israẹli.
Anih kah ol noi neh a longpuei boeih te a kung a dong khaw, Judah neh Israel manghai rhoek cabu khuiah a daek uh coeng he.
27 Ahasi sì sùn pẹ̀lú àwọn baba rẹ̀ a sì sin ín ní ìlú Jerusalẹmu ṣùgbọ́n wọn kò mú un wá sínú àwọn isà òkú àwọn ọba Israẹli. Hesekiah ọmọ rẹ sì jẹ ọba ní ipò rẹ̀.
Ahaz te a napa rhoek taengla a khoem uh vaengah tah anih te Jerusalem khopuei ah a up uh ngawn dae Israel manghai rhoek kah phuel ah tah anih te tlak sak uh pawh. Te phoeiah a capa Hezekiah te anih yueng la manghai.

< 2 Chronicles 28 >