< 2 Chronicles 26 >

1 Nígbà náà gbogbo ènìyàn Juda mú Ussiah, ẹni tí ó jẹ́ ẹni ọdún mẹ́rìndínlógún wọ́n sì fi jẹ ọba ní ipò baba rẹ̀ Amasiah.
Ningĩ andũ othe a Juda makĩoya Uzia, arĩ wa mĩaka ikũmi na ĩtandatũ, na makĩmũtua mũthamaki ithenya rĩa ithe Amazia.
2 Òun ni ẹni náà tí ó tún Elati kọ́, ó sì mú padà sí Juda lẹ́yìn ìgbà tí Amasiah ọba ti sùn pẹ̀lú àwọn baba rẹ̀.
Nĩwe waakithirie Elothu rĩngĩ, na akĩrĩcookeria Juda thuutha wa Amazia kũhurũka hamwe na maithe make.
3 Ussiah sì jẹ́ ẹni ọdún mẹ́rìndínlógún nígbà tí ó di ọba, ó sì jẹ ọba ní Jerusalẹmu fún ọdún méjìléláàádọ́ta. Orúkọ ìyá rẹ̀ sì ni Jekoliah; ó sì wá láti Jerusalẹmu.
Uzia aarĩ wa mĩaka ikũmi na ĩtandatũ rĩrĩa aatuĩkire mũthamaki, nake agĩthamaka arĩ Jerusalemu mĩaka mĩrongo ĩtano na ĩĩrĩ. Nyina eetagwo Jekolia, na oimĩte Jerusalemu.
4 Ó sì ṣe ohun tí ó tọ́ ní ojú Olúwa, gẹ́gẹ́ bi baba rẹ̀ Amasiah ti ṣe.
Nake nĩekire maũndũ marĩa maarĩ magĩrĩru maitho-inĩ ma Jehova, o ta ũrĩa ithe Amazia eekĩte.
5 Ó sì wá Olúwa ní ọjọ́ Sekariah, ẹni tí ó ní òye nínú ìran Ọlọ́run. Níwọ́n ọjọ́ tí ó wá ojú Olúwa, Ọlọ́run fún un ní ohun rere.
Nĩarongooragia Ngai matukũ-inĩ ma Zekaria, ũrĩa wamũrutĩte gwĩtigĩra Ngai. Narĩo ihinda rĩrĩa rĩothe aarongoragia Jehova-rĩ, Ngai nĩamũheaga ũgaacĩru.
6 Ó sì lọ sí ogun pẹ̀lú Filistini ó sì wó odi Gati lulẹ̀, Jabne àti Aṣdodu. Ó sì kó ìlú rẹ̀ tí ó wà ní ẹ̀gbẹ́ Aṣdodu àti níbìkan láàrín àwọn ará Filistini.
Uzia nĩathiire kũrũa na Afilisti, na akĩmomora thingo cia Gathu, na cia Jabine, na cia Ashidodi. Ningĩ agĩcooka agĩaka rĩngĩ matũũra marĩa maarĩ hakuhĩ na Ashidodi na kũndũ kũngĩ gatagatĩ-inĩ ka Afilisti.
7 Ọlọ́run sì ràn án lọ́wọ́ lórí àwọn ará Filistini àti Arabia tí ń gbé ní Gur-baali àti lórí àwọn ará Mehuni.
Ngai akĩmũteithia kũhũũrana na Afilisti na Arabu arĩa maatũũraga Guri-Baali na Ameuni.
8 Àwọn ará Ammoni gbé ẹ̀bùn wá fún Ussiah, orúkọ rẹ̀ sì tàn káàkiri títí ó fi dé àtiwọ Ejibiti, nítorí ó ti di alágbára ńlá.
Aamoni nĩmarehire igooti kũrĩ Uzia, nayo ngumo yake ĩkĩhunja o nginya mũhaka wa Misiri, nĩ ũndũ nĩagĩĩte na hinya mũno.
9 Ussiah sì kọ́ ilé ìṣọ́ ní Jerusalẹmu níbi ẹnu-bodè igun, àti níbi ẹnu-bodè àfonífojì àti níbi ìṣẹ́po odi ó sì mú wọn le
Uzia nĩaakire mĩthiringo mĩraihu na igũrũ kũu Jerusalemu hau Kĩhingo-inĩ gĩa Koine, na hau Kĩhingo-inĩ gĩa Gĩtuamba, na hau koine-inĩ ya rũthingo, na akĩmĩirigĩra na thingo cia hinya.
10 Ó sì tún ilé ìṣọ́ aginjù kọ́, ó sì gbẹ́ kànga púpọ̀, nítorí ó ni ẹran ọ̀sìn púpọ̀ ní ilẹ̀ ìsàlẹ̀ àti ní pẹ̀tẹ́lẹ̀. Ó sì ní àwọn ènìyàn tí ń ṣiṣẹ́ ní pápá àti ọgbà àjàrà ní orí òkè ní ilẹ̀ ọlọ́ràá, nítorí ó fẹ́ràn àgbẹ̀ ṣíṣe.
Ningĩ agĩaka mĩthiringo mĩraihu na igũrũ kũu werũ-inĩ na akĩenja ithima nyingĩ, nĩ ũndũ aarĩ na mahiũ maingĩ kũu mũhuro-inĩ wa irĩma, o na kũu werũ wa irĩma-inĩ. Aarĩ na andũ maarutaga wĩra mĩgũnda-inĩ yake ya irio na ya mĩthabibũ kũu irĩma-inĩ o na mĩgũnda-inĩ ĩrĩa mĩnoru, tondũ nĩendete ũrĩmi.
11 Ussiah sì ní àwọn ẹgbẹ́ ogun tí wọ́n kọ́ dáradára, wọ́n múra tán láti lọ pẹ̀lú ẹgbẹgbẹ́ gẹ́gẹ́ bí iye kíkà wọn gẹ́gẹ́ bí ọwọ́ Jeieli akọ̀wé àti Maaseiah ìjòyè lábẹ́ ọwọ́ Hananiah, ọ̀kan lára àwọn olórí ogun ọba.
Uzia aarĩ na mbũtũ ya ita ĩrĩa yarutĩtwo wega mũno, na yakoragwo ĩĩhaarĩirie gũthiĩ mbaara-inĩ, ĩgayanĩtio ikundi kũringana na mũigana wayo na kũringana na ũrĩa yacookanĩrĩirio nĩ Jeieli ũrĩa warĩ mwandĩki na Maaseia ũrĩa warĩ mũnene wao, matongoretio nĩ Hanania, ũmwe wa anene a nyũmba ya ũthamaki.
12 Àpapọ̀ iye olórí àwọn alágbára akọni ogun jẹ́ ẹgbẹ̀tàlá.
Naguo mũigana wothe wa atongoria a nyũmba arĩa maarũgamagĩrĩra thigari warĩ 2,600.
13 Lábẹ́ olórí àti olùdarí wọn, wọ́n sì jẹ́ alágbára akọni ogun ọ̀kẹ́ mẹ́ẹ̀ẹ́dógún ó lé ẹ̀ẹ́dẹ́gbàárin, tí ó ti múra fún ogun ńlá náà, àti alágbára ńlá jagunjagun kan láti ran ọba lọ́wọ́ sí ọ̀tá rẹ̀.
Wathani-inĩ wao haarĩ na mbũtũ ya ita ya andũ 307,500 arĩa maarutĩtwo ũhoro wa mbaara, mbũtũ ĩyo yarĩ na hinya na nĩyo yateithagia mũthamaki akĩrũa na thũ ciake.
14 Ussiah sì pèsè ọ̀kọ̀, asà, akọ́rọ́, àti ohun èlò ìhámọ́ra ọrun títí dé òkúta kànnàkànnà fún ọwọ́ àwọn ọmọ-ogun.
Uzia nĩaheire mbũtũ ĩyo yake ya ita ngo, na matimũ, na ngũbia, na nguo cia igera, na mota na mahiga ma igũtha.
15 Ní Jerusalẹmu ó sì ṣe ohun ẹ̀rọ ìjagun, iṣẹ́ ọwọ́ ọlọ́gbọ́n ènìyàn, láti wà lórí ilé ìṣọ́ àti lórí igun odi láti fi tafà àti láti fi sọ òkúta ńlá. Orúkọ rẹ̀ sì tàn káàkiri, nítorí a ṣe ìrànlọ́wọ́ ìyanu fún un títí ó fi di alágbára.
Kũu Jerusalemu-rĩ, andũ maarĩ oogĩ mũno magĩthondeka ikaari ciahũthagĩrwo mĩthiringo-inĩ na koine-inĩ cia ũgitĩri na njĩra ya gũikia mĩguĩ na gũikia mahiga manene. Ngumo yake ĩkĩhunja kũndũ kũraya nĩgũkorwo nĩateithirio mũno nginya akĩgĩa na hinya mũno.
16 Ṣùgbọ́n lẹ́yìn ìgbà tí Ussiah jẹ́ alágbára tán, ìgbéraga rẹ̀ sì gbé e ṣubú. Ó sì di aláìṣòótọ́ sí Olúwa Ọlọ́run rẹ̀. Ó sì wọ ilé Olúwa láti sun tùràrí lórí pẹpẹ tùràrí.
No thuutha wa Uzia kũgĩa na hinya-rĩ, gwĩtũũgĩria gwake gũkĩmũniina. Akĩaga gũtuĩka mwĩhokeku harĩ Jehova Ngai wake, na agĩtoonya hekarũ ya Jehova nĩguo acine ũbumba kĩgongona-inĩ kĩa ũbumba.
17 Asariah àlùfáà pẹ̀lú àwọn ọgọ́rin alágbára àlùfáà Olúwa mìíràn sì tẹ̀lé e.
Nake Azaria ũrĩa mũthĩnjĩri-Ngai hamwe na athĩnjĩri-Ngai omĩrĩru mĩrongo ĩnana a Jehova, makĩmuuma thuutha o nginya na kũu thĩinĩ.
18 Wọ́n sì takò ọba Ussiah, wọn sì wí pé, “Kò dára fún ọ, Ussiah, láti sun tùràrí sí Olúwa. Èyí fún àwọn àlùfáà, àwọn ọmọ Aaroni, ẹni tí ó ti yà sí mímọ́ láti sun tùràrí. Fi ibi mímọ́ sílẹ̀, nítorí tí ìwọ ti jẹ́ aláìṣòótọ́, ìwọ kò sì ní jẹ́ ẹni ọlá láti ọ̀dọ̀ Olúwa Ọlọ́run.”
Nao makĩmũngʼethera mamũkaanie, makĩmwĩra atĩrĩ, “Gũtiagĩrĩire, wee Uzia, ũcinĩre Jehova ũbumba. Ũcio nĩ wĩra wa athĩnjĩri-Ngai arĩa marĩ a rũciaro rwa Harũni, arĩa maamũrĩtwo macinage ũbumba. Uma handũ haha haamũre nĩgũkorwo ndũrĩ mwĩhokeku, na Jehova Ngai ndangĩgũtĩĩa.”
19 Ussiah, ẹni tí ó ní àwo tùràrí ní ọwọ́ rẹ̀ tó ṣetán láti sun tùràrí sì bínú. Nígbà tí ó sì ń bínú sí àwọn àlùfáà níwájú wọn, níwájú pẹpẹ tùràrí ní ilé Olúwa, ẹ̀tẹ̀ sì yọ jáde ní iwájú orí rẹ̀.
Uzia, ũrĩa wanyiitĩte rũgĩo na guoko ehaarĩirie gũcina ũbumba, akĩrakara mũno. Na o hĩndĩ ĩyo aagũthũkagĩra athĩnjĩri-Ngai marĩ hau mbere ya kĩgongona kĩa ũbumba, hekarũ-inĩ ya Jehova, mũrimũ wa mangũ ũgĩtuthũka thiithi-inĩ wake.
20 Nígbà tí Asariah olórí àlùfáà àti gbogbo àwọn àlùfáà yòókù sì wò ó, wọ́n sì rí i wí pé ó ní ẹ̀tẹ̀ níwájú orí rẹ̀, bẹ́ẹ̀ ni wọ́n sì sáré gbé e jáde pẹ̀lúpẹ̀lú, òun tìkára rẹ̀ ti fẹ́ láti jáde, nítorí tí Olúwa ti kọlù ú.
Na rĩrĩa Azaria, mũthĩnjĩri-Ngai ũrĩa mũnene na athĩnjĩri-Ngai acio angĩ othe maamũrorire-rĩ, makĩona atĩ aarĩ na mangũ thiithi; nĩ ũndũ ũcio makĩmuumia na nja na ihenya. O nake we mwene nĩaiguaga kwenda mũno kuuma nja, nĩ ũndũ Jehova nĩamũhũũrĩte na mũrimũ ũcio.
21 Ọba Ussiah sì ní ẹ̀tẹ̀ títí di ọjọ́ ikú rẹ̀. Ó sì gbé ní ilé àwọn adẹ́tẹ̀, a sì ké e kúrò ní ilé Olúwa. Jotamu ọmọ rẹ̀ sì gba ipò rẹ̀, ó sì ń ṣe ìdájọ́ lórí àwọn ènìyàn ilẹ̀ náà.
Mũthamaki Uzia aatũũrire arĩ na mangũ nginya rĩrĩa aakuire. Aatũũrire nyũmba arĩ wiki, arĩ na mangũ, na agirĩtio gũthiiaga hekarũ ya Jehova. Mũriũ Jothamu akĩrũgamĩrĩra nyũmba ya ũthamaki, na agaathaga andũ a bũrũri ũcio.
22 Ìyókù iṣẹ́ ìjọba Ussiah láti ìbẹ̀rẹ̀ títí dé òpin, ni a kọ láti ọwọ́ wòlíì Isaiah ọmọ Amosi.
Namo maũndũ marĩa mangĩ makoniĩ wathani wa Uzia-rĩ, kuuma kĩambĩrĩria nginya mũthia, nĩmandĩkĩtwo nĩ mũnabii Isaia mũrũ wa Amozu.
23 Ussiah sì sùn pẹ̀lú àwọn baba, rẹ̀ a sì sin sí ẹ̀gbẹ́ wọn nínú oko ìsìnkú fún ti iṣẹ́ tí àwọn ọba, nítorí àwọn ènìyàn wí pé “Ó ní ààrùn ẹ̀tẹ̀,” Jotamu ọmọ rẹ̀ sì jẹ ọba ní ipò rẹ̀.
Nake Uzia akĩhurũka hamwe na maithe make, na agĩthikwo hakuhĩ nao gĩthaka-inĩ kĩrĩa kĩarĩ gĩa gũthikanwo gĩa athamaki, nĩgũkorwo andũ moigire atĩrĩ, “Ararĩ na mangũ.” Nake mũriũ Jothamu agĩtuĩka mũthamaki ithenya rĩake.

< 2 Chronicles 26 >