< 2 Chronicles 26 >

1 Nígbà náà gbogbo ènìyàn Juda mú Ussiah, ẹni tí ó jẹ́ ẹni ọdún mẹ́rìndínlógún wọ́n sì fi jẹ ọba ní ipò baba rẹ̀ Amasiah.
Tout le peuple de la terre prit alors Ozias, qui avait seize ans, et ils le proclamèrent roi à la place d'Amasias, son père.
2 Òun ni ẹni náà tí ó tún Elati kọ́, ó sì mú padà sí Juda lẹ́yìn ìgbà tí Amasiah ọba ti sùn pẹ̀lú àwọn baba rẹ̀.
Il rebâtit Elath, et la rendit à Juda lorsque le roi se fut endormi avec ses pères.
3 Ussiah sì jẹ́ ẹni ọdún mẹ́rìndínlógún nígbà tí ó di ọba, ó sì jẹ ọba ní Jerusalẹmu fún ọdún méjìléláàádọ́ta. Orúkọ ìyá rẹ̀ sì ni Jekoliah; ó sì wá láti Jerusalẹmu.
Ozias avait seize ans quand il monta sur le trône, et il régna cinquante- deux ans à Jérusalem; sa mère s'appelait Jéchélie de Jérusalem.
4 Ó sì ṣe ohun tí ó tọ́ ní ojú Olúwa, gẹ́gẹ́ bi baba rẹ̀ Amasiah ti ṣe.
Et il fit ce qui est droit devant le Seigneur, comme avait fait d'abord Amasias, son père.
5 Ó sì wá Olúwa ní ọjọ́ Sekariah, ẹni tí ó ní òye nínú ìran Ọlọ́run. Níwọ́n ọjọ́ tí ó wá ojú Olúwa, Ọlọ́run fún un ní ohun rere.
Il chercha le Seigneur tant que vécut Zacharie, homme sage et craignant Dieu; tant qu'il vécut, Ozias chercha le Seigneur, et le Seigneur le fit prospérer.
6 Ó sì lọ sí ogun pẹ̀lú Filistini ó sì wó odi Gati lulẹ̀, Jabne àti Aṣdodu. Ó sì kó ìlú rẹ̀ tí ó wà ní ẹ̀gbẹ́ Aṣdodu àti níbìkan láàrín àwọn ará Filistini.
Il se mit en campagne, combattit les Philistins, renversa les murs de Geth, les murs de Jabner, les murs d'Azot, et bâtit des villes, près d'Azot, sur la terre des étrangers.
7 Ọlọ́run sì ràn án lọ́wọ́ lórí àwọn ará Filistini àti Arabia tí ń gbé ní Gur-baali àti lórí àwọn ará Mehuni.
Et le Seigneur le fortifia contre les Philistins, contre les Arabes qui habitent au milieu des rochers, et contre les Minéens.
8 Àwọn ará Ammoni gbé ẹ̀bùn wá fún Ussiah, orúkọ rẹ̀ sì tàn káàkiri títí ó fi dé àtiwọ Ejibiti, nítorí ó ti di alágbára ńlá.
Alors, les Minéens lui firent des présents, et son nom se répandit jusqu'à l'entrée de l'Égypte; car il se fortifia extrêmement.
9 Ussiah sì kọ́ ilé ìṣọ́ ní Jerusalẹmu níbi ẹnu-bodè igun, àti níbi ẹnu-bodè àfonífojì àti níbi ìṣẹ́po odi ó sì mú wọn le
Ozias bâtit aussi des tours dans Jérusalem: sur la porte de l'Angle, sur la porte de la Vallée, sur les angles, et il les fortifia.
10 Ó sì tún ilé ìṣọ́ aginjù kọ́, ó sì gbẹ́ kànga púpọ̀, nítorí ó ni ẹran ọ̀sìn púpọ̀ ní ilẹ̀ ìsàlẹ̀ àti ní pẹ̀tẹ́lẹ̀. Ó sì ní àwọn ènìyàn tí ń ṣiṣẹ́ ní pápá àti ọgbà àjàrà ní orí òkè ní ilẹ̀ ọlọ́ràá, nítorí ó fẹ́ràn àgbẹ̀ ṣíṣe.
Et il bâtit des tours dans le désert, et il fit, en pierres de taille, une multitude de citernes, parce qu'il possédait de nombreux troupeaux dans les basses terres et dans la plaine, et il employait beaucoup de vignerons sur la montagne et sur le Carmel, car il était cultivateur.
11 Ussiah sì ní àwọn ẹgbẹ́ ogun tí wọ́n kọ́ dáradára, wọ́n múra tán láti lọ pẹ̀lú ẹgbẹgbẹ́ gẹ́gẹ́ bí iye kíkà wọn gẹ́gẹ́ bí ọwọ́ Jeieli akọ̀wé àti Maaseiah ìjòyè lábẹ́ ọwọ́ Hananiah, ọ̀kan lára àwọn olórí ogun ọba.
Son armée était aguerrie; au dehors, elle se rangeait en bataille; à l'intérieur, elle se déployait pour qu'on en fit la revue; ceux qui la dénombraient étaient le scribe Jehiel, le juge Maasias, et Ananias le lieutenant du roi.
12 Àpapọ̀ iye olórí àwọn alágbára akọni ogun jẹ́ ẹgbẹ̀tàlá.
Le nombre des vaillants, chefs de familles, qui allaient en guerre, s'élevait à deux mille deux cents.
13 Lábẹ́ olórí àti olùdarí wọn, wọ́n sì jẹ́ alágbára akọni ogun ọ̀kẹ́ mẹ́ẹ̀ẹ́dógún ó lé ẹ̀ẹ́dẹ́gbàárin, tí ó ti múra fún ogun ńlá náà, àti alágbára ńlá jagunjagun kan láti ran ọba lọ́wọ́ sí ọ̀tá rẹ̀.
Et ils commandaient une armée aguerrie de trois cent soixante-dix mille cinq cents hommes, qui marchaient au combat, pleins de force et de vaillance, pour défendre le roi contre ses ennemis.
14 Ussiah sì pèsè ọ̀kọ̀, asà, akọ́rọ́, àti ohun èlò ìhámọ́ra ọrun títí dé òkúta kànnàkànnà fún ọwọ́ àwọn ọmọ-ogun.
Ozias les avait tous armés de longs boucliers, de javelines, de casques, d'arcs et de frondes.
15 Ní Jerusalẹmu ó sì ṣe ohun ẹ̀rọ ìjagun, iṣẹ́ ọwọ́ ọlọ́gbọ́n ènìyàn, láti wà lórí ilé ìṣọ́ àti lórí igun odi láti fi tafà àti láti fi sọ òkúta ńlá. Orúkọ rẹ̀ sì tàn káàkiri, nítorí a ṣe ìrànlọ́wọ́ ìyanu fún un títí ó fi di alágbára.
Et il fit exécuter à Jérusalem des machines, œuvres d'un habile calculateur, pour être sur les tours et sur les angles, ou pour lancer des traits ou de grosses pierres; partout, même au loin, on parla beaucoup de ses engins; car il en était merveilleusement secouru, et en tirait une grande force.
16 Ṣùgbọ́n lẹ́yìn ìgbà tí Ussiah jẹ́ alágbára tán, ìgbéraga rẹ̀ sì gbé e ṣubú. Ó sì di aláìṣòótọ́ sí Olúwa Ọlọ́run rẹ̀. Ó sì wọ ilé Olúwa láti sun tùràrí lórí pẹpẹ tùràrí.
Mais, comme il se fortifiait, son cœur s'enorgueillit pour sa perte; et il pécha contre le Seigneur son Dieu, et il entra dans le temple du Seigneur pour brûler de l'encens sur l'autel des parfums.
17 Asariah àlùfáà pẹ̀lú àwọn ọgọ́rin alágbára àlùfáà Olúwa mìíràn sì tẹ̀lé e.
Et Azarias le prêtre y entra sur ses pas, accompagné de quatre-vingts prêtres du Seigneur, hommes intrépides.
18 Wọ́n sì takò ọba Ussiah, wọn sì wí pé, “Kò dára fún ọ, Ussiah, láti sun tùràrí sí Olúwa. Èyí fún àwọn àlùfáà, àwọn ọmọ Aaroni, ẹni tí ó ti yà sí mímọ́ láti sun tùràrí. Fi ibi mímọ́ sílẹ̀, nítorí tí ìwọ ti jẹ́ aláìṣòótọ́, ìwọ kò sì ní jẹ́ ẹni ọlá láti ọ̀dọ̀ Olúwa Ọlọ́run.”
Et ils s'arrêtèrent devant le roi Ozias, et ils lui dirent: Ce n'est pas à toi, Ozias, d'encenser le Seigneur, mais aux prêtres, fils d'Aaron, qui sont consacrés pour faire les sacrifices. Sors du Saint des saints, car tu t'es séparé du Seigneur, et cela ne tournera pas à ta gloire auprès de Dieu.
19 Ussiah, ẹni tí ó ní àwo tùràrí ní ọwọ́ rẹ̀ tó ṣetán láti sun tùràrí sì bínú. Nígbà tí ó sì ń bínú sí àwọn àlùfáà níwájú wọn, níwájú pẹpẹ tùràrí ní ilé Olúwa, ẹ̀tẹ̀ sì yọ jáde ní iwájú orí rẹ̀.
Mais Ozias s'irrita; or, il avait à la main l'encensoir pour brûler de l'encens dans le temple, et, pendant qu'il s'irritait contre les prêtres, la lèpre parut sur son front, devant les prêtres dans le temple du Seigneur, au pied de l'autel des parfums.
20 Nígbà tí Asariah olórí àlùfáà àti gbogbo àwọn àlùfáà yòókù sì wò ó, wọ́n sì rí i wí pé ó ní ẹ̀tẹ̀ níwájú orí rẹ̀, bẹ́ẹ̀ ni wọ́n sì sáré gbé e jáde pẹ̀lúpẹ̀lú, òun tìkára rẹ̀ ti fẹ́ láti jáde, nítorí tí Olúwa ti kọlù ú.
Et le grand prêtre Azarias et les prêtres, en se retournant vers lui, virent la lèpre sur son front; ils eurent hâte de le faire sortir, et lui-même n'était pas moins empressé, car le Seigneur l'avait châtié.
21 Ọba Ussiah sì ní ẹ̀tẹ̀ títí di ọjọ́ ikú rẹ̀. Ó sì gbé ní ilé àwọn adẹ́tẹ̀, a sì ké e kúrò ní ilé Olúwa. Jotamu ọmọ rẹ̀ sì gba ipò rẹ̀, ó sì ń ṣe ìdájọ́ lórí àwọn ènìyàn ilẹ̀ náà.
Le roi Ozias resta lépreux jusqu'au jour de sa mort; et lépreux, il demeura dans une maison isolée, parce qu'il avait été retranché du temple du Seigneur. Et Joatham, son fils, fut mis à la tête du royaume, jugeant le peuple de la terre.
22 Ìyókù iṣẹ́ ìjọba Ussiah láti ìbẹ̀rẹ̀ títí dé òpin, ni a kọ láti ọwọ́ wòlíì Isaiah ọmọ Amosi.
Le reste des actes d'Ozias, les premiers et les derniers, ont été écrits par le prophète Jessé (Isaïe).
23 Ussiah sì sùn pẹ̀lú àwọn baba, rẹ̀ a sì sin sí ẹ̀gbẹ́ wọn nínú oko ìsìnkú fún ti iṣẹ́ tí àwọn ọba, nítorí àwọn ènìyàn wí pé “Ó ní ààrùn ẹ̀tẹ̀,” Jotamu ọmọ rẹ̀ sì jẹ ọba ní ipò rẹ̀.
Et Ozias s'endormit avec ses pères, et on l'ensevelit auprès d'eux, dans le champ où est le sépulcre des rois, parce que, dirent-ils, il était lépreux. Et Joatham, son fils, régna à sa place.

< 2 Chronicles 26 >