< 2 Chronicles 25 >

1 Amasiah jẹ́ ẹni ọdún mẹ́ẹ̀ẹ́dọ́gbọ̀n nígbà tí ó di ọba, ó sì jẹ ọba ní Jerusalẹmu fún ọdún mọ́kàndínlọ́gbọ̀n orúkọ ìyá rẹ̀ a máa jẹ́ Jehoadani, ó wá láti Jerusalẹmu.
Amazjasz miał dwadzieścia pięć lat, kiedy zaczął królować, i królował dwadzieścia dziewięć lat w Jerozolimie. Jego matka miała na imię Jehoaddan, [była] z Jerozolimy.
2 Ó ṣe ohun tí ó dára lójú Olúwa, ṣùgbọ́n kì í ṣe tọkàntọkàn.
I czynił to, co dobre w oczach PANA, ale niedoskonałym sercem.
3 Lẹ́yìn tí ìjọba ti wà ní ìdarí rẹ̀, ó pa àwọn oníṣẹ́ tí ó pa baba rẹ̀ ọba.
I kiedy jego królestwo było utwierdzone, zabił te spośród swoich sług, które zabiły króla, jego ojca.
4 Síbẹ̀ kò pa àwọn ọmọ wọn, ṣùgbọ́n ó ṣe ní ìbámu pẹ̀lú ohun tí a kọ nínú òfin nínú ìwé Mose, níbi tí Olúwa ti paláṣẹ pé, “A kò gbọdọ̀ pa àwọn baba fún àwọn ọmọ wọn tàbí àwọn ọmọ fún baba wọn, olúkúlùkù ni kí ó kú fún ẹ̀ṣẹ̀ rẹ̀.”
Ich synów jednak nie zabił. [Postąpił] tak, jak jest napisane w prawie, w Księdze Mojżesza, gdzie PAN dał nakaz, mówiąc: Nie umrą ojcowie za synów ani synowie nie umrą za ojców, ale każdy umrze za swój własny grzech.
5 Amasiah, pe gbogbo àwọn ènìyàn Juda pọ̀, ó sì fi iṣẹ́ lé wọn lọ́wọ́ gẹ́gẹ́ bí ìdílé wọn sí àwọn alákòóso ẹgbẹẹgbẹ̀rún àti àwọn alákòóso ọ̀rọ̀ọ̀rún fún gbogbo Juda àti Benjamini, ó sì gbá iye wọn láti ẹni ogún ọdún àti jù bẹ́ẹ̀ lọ jọ, ó sì rí i pé ọ̀kẹ́ mẹ́ẹ̀ẹ́dógún àwọn ọkùnrin ni ó ti múra fún ìsìn ogun, tí ó lè gbá ọ̀kọ̀ àti àpáta mú.
Wtedy Amazjasz zgromadził lud Judy i ustanowił nad nim dowódców nad tysiącami i setników, według ich rodów, dla całej Judy i Beniamina. Następnie policzył tych, [którzy mieli] dwadzieścia lat i więcej, a było ich trzysta tysięcy wyborowych mężczyzn gotowych do boju, uzbrojonych w dzidę i tarczę.
6 Ó sì yá ọ̀kẹ́ márùn-ún àwọn ọkùnrin oníjà láti Israẹli fún ọgọ́rùn-ún àwọn tálẹ́ǹtì fàdákà.
Najął też z Izraela sto tysięcy dzielnych wojowników za sto talentów srebra.
7 Ṣùgbọ́n ènìyàn Ọlọ́run kan tọ̀ ọ́ wá ó sì wí pé, “Ọba, àwọn ọ̀wọ́ ogun láti Israẹli kò gbọdọ̀ yan pẹ̀lú rẹ, nítorí tí Olúwa kò wà pẹ̀lú Israẹli kì í ṣe pẹ̀lú ẹnìkankan láti Efraimu.
Lecz przybył do niego mąż Boży i powiedział: Królu, niech wojsko Izraela nie wyrusza z tobą, bo PAN nie jest z Izraelem, z nikim spośród synów Efraima.
8 Àní, tí ẹ bá lọ jà pẹ̀lú ìmúláyàle ní ojú ogun, Ọlọ́run yóò bì ọ́ ṣubú níwájú àwọn ọ̀tá, nítorí Ọlọ́run ní agbára láti ràn ọ́ lọ́wọ́ àti láti bì ọ́ ṣubú.”
Ale jeśli [chcesz], idź i umocnij się do bitwy, a Bóg powali cię przed wrogiem. Bóg bowiem ma moc i wspomagać, i przywieść do upadku.
9 Amasiah sì bi ènìyàn Ọlọ́run pé, “Ọgọ́rùn-ún tálẹ́ǹtì tí mo ti san fún àwọn ọ̀wọ́ ogun àwọn ọmọ Israẹli ń kọ́?” Ènìyàn Ọlọ́run dáhùn pé “Olúwa lè fún ọ ní èyí tí ó ju ìyẹn lọ.”
Wtedy Amazjasz zapytał męża Bożego: A co mam czynić ze stoma talentami, które dałem wojsku Izraela? Mąż Boży odpowiedział: PAN może ci dać o wiele więcej niż to.
10 Bẹ́ẹ̀ ni Amasiah, tú àwọn ọwọ́ ogun tí ó ti wá sí ọ̀dọ̀ rẹ̀ láti Efraimu ká. Ó sì rán wọn lọ ilé. Wọ́n kún fún ìbínú pẹ̀lú Juda, wọ́n sì padà lọ ilé pẹ̀lú ìbínú ńlá.
Oddzielił więc Amazjasz to wojsko, które przybyło do niego z Efraima, aby wróciło do siebie. I rozgniewali się bardzo na Judę, i wrócili do siebie w wielkim gniewie.
11 Nígbà náà, Amasiah ko ogun rẹ jọ àti àwọn ọmọ-ogun rẹ̀ lọ sí àfonífojì iyọ̀, níbi tí ó ti pa ẹgbẹ̀rún mẹ́wàá àwọn ọkùnrin Seiri.
Lecz Amazjasz umocnił się, wyprowadził swój lud i nadciągnął do Doliny Soli, i pobił dziesięć tysięcy synów Seiru.
12 Àwọn ọkùnrin Juda pẹ̀lú fi agbára mú àwọn ọkùnrin ẹgbẹ̀rún mẹ́wàá láààyè. Wọ́n mú wọn lọ sí orí òkè bèbè òkúta, wọ́n jù wọ́n sílẹ̀, kí gbogbo wọn sì fọ́ sí wẹ́wẹ́.
A synowie Judy uprowadzili dziesięć tysięcy żywych, przyprowadzili ich na szczyt skały i zrzucili stamtąd, tak że się wszyscy porozbijali.
13 Ní báyìí àwọn ọ̀wọ́ ogun tí Amasiah ti rán lọ padà, tí wọn kò nípa nínú ogun gbógun sí àwọn ìlú Juda láti Samaria sí Beti-Horoni. Wọ́n pa ẹgbẹ̀rún mẹ́ta nínú wọn, wọ́n sì kó ọ̀pọ̀ ìkógun ńlá.
Żołnierze wojska zaś, których Amazjasz odesłał, aby nie ruszyli z nim na wojnę, wtargnęli do miast Judy, od Samarii aż do Bet-Choron. Zabili w nich trzy tysiące [ludzi] i zebrali wielką zdobycz.
14 Nígbà tí Amasiah padà láti ibi pípa àwọn ará Edomu, ó mú àwọn ọlọ́run àwọn ènìyàn Seiri padà wá. Ó gbé wọn kalẹ̀ gẹ́gẹ́ bi àwọn ọlọ́run tirẹ̀. Ó tẹríba fún wọn, ó sì rú ẹbọ fún wọn.
Kiedy Amazjasz wrócił po porażce Edomitów, przyprowadził [ze sobą] bogów synów Seiru i postawił ich jako swoich bogów. Kłaniał się przed nimi i palił im kadzidło.
15 Ìbínú Olúwa ru sí Amasiah, ó sì rán wòlíì kan sí i, tí ó wí pé, “Kí ni ó dé tí ìwọ fi ń béèrè lọ́wọ́ àwọn ọlọ́run àwọn ènìyàn yìí, tí wọn kò le gba àwọn ènìyàn tiwọn kúrò lọ́wọ́ rẹ?”
PAN więc rozgniewał się bardzo na Amazjasza i posłał do niego proroka, który mu powiedział: Czemu szukasz bogów [tego] ludu, którzy nie potrafili wyrwać swojego ludu z twojej ręki?
16 Bí ó ti n sọ̀rọ̀, ọba wí fún un pé, “Ṣé a yàn ọ́ ní olùgba ọba lámọ̀ràn ni? Dúró! Èéṣe tí a ó fi lù ọ́ bolẹ̀?” Bẹ́ẹ̀ ni, wòlíì náà dúró ṣùgbọ́n ó wí pé, “Èmi mọ̀ pé Ọlọ́run ti pinnu láti pa ọ́ run nítorí ìwọ ti ṣe èyí, ìwọ kò sì tẹ́tí sí ìmọ̀ràn mi.”
A gdy on do niego mówił, [król] mu powiedział: Czy wybrano cię doradcą króla? Przestań. Po co mają cię zabić? Prorok więc zaprzestał, ale dodał: Wiem, Bóg zamierza cię zniszczyć za to, że to uczyniłeś i nie posłuchałeś mojej rady.
17 Lẹ́yìn tí Amasiah ọba Juda ti béèrè lọ́wọ́ àwọn olùdámọ̀ràn, ó rán ìpèníjà yìí sí Jehoaṣi ọmọ Jehoahasi ọmọ Jehu, ọba Israẹli pé, “Wá bá mi lójúkojú.”
Wtedy Amazjasz, król Judy, naradził się i posłał [sługę] do Joasza, syna Jehoachaza, syna Jehu, króla Izraela, ze słowami: Przyjdź i spójrzmy sobie w oczy.
18 Ṣùgbọ́n Jehoaṣi ọba Israẹli fèsì padà sí Amasiah ọba Juda pé, “Koríko kékeré kan ní Lebanoni rán iṣẹ́ sí igi kedari ní Lebanoni, fi ọmọbìnrin rẹ fún ọmọkùnrin mi ní ìgbéyàwó. Nígbà náà, ẹhànnà ẹranko ènìyàn ni Lebanoni wá, ó sì tẹ òṣùṣú náà lábẹ́ ẹsẹ̀.
A Joasz, król Izraela, posłał do Amazjasza, króla Judy, odpowiedź: Oset w Libanie posłał do cedru w Libanie prośbę: Daj swoją córkę mojemu synowi za żonę. Wtedy przechodził dziki zwierz z Libanu i podeptał oset.
19 Ìwọ wí fún ara à rẹ wí pé, ìwọ ti ṣẹ́gun Edomu àti nísinsin yìí ìwọ ní ìhàlẹ̀ àti ìgbéraga. Ṣùgbọ́n dúró ní ilé! Kí ni ó dé tí ìwọ fi ń wá wàhálà tí o sì fi ń fa ìṣubú rẹ àti ti Juda pẹ̀lú?”
Myślisz: Oto pobiłem Edomitów – dlatego uniosło się twoje serce, by się chlubić. Siedź teraz w domu. Po co masz się narażać na nieszczęście, abyś upadł ty i Juda z tobą?
20 Amasiah, bí ó tì wù kí ó rí kò tẹ́tí nítorí Ọlọ́run ṣe é kí ó lè gbé wọn lé Jehoaṣi lọ́wọ́: nítorí wọ́n wá àwọn ọlọ́run Edomu.
Ale Amazjasz nie posłuchał, a [było] to od Boga, aby ich wydać w ręce [wrogów] za to, że szukali bogów Edomu.
21 Bẹ́ẹ̀ ni Jehoaṣi, ọba Israẹli: òun àti Amasiah ọba Juda dojúkọ ara wọn ní Beti-Ṣemeṣi ní Juda.
Wyruszył więc Joasz, król Izraela, i spojrzeli sobie w oczy, on i Amazjasz, król Judy, w Bet-Szemesz, które [należy do] Judy.
22 Àwọn ọmọ Israẹli da Juda rú, gbogbo olúkúlùkù ènìyàn sì sálọ sí ìlú rẹ̀.
I Juda został rozgromiony przez Izraela, i każdy uciekał do swojego namiotu.
23 Jehoaṣi ọba Israẹli fi agbára mú Amasiah ọba Juda, ọmọ Joaṣi ọmọ Ahasiah ní Beti-Ṣemeṣi. Nígbà náà Joaṣi mú u wá sí Jerusalẹmu. Ó sì wó ògiri Jerusalẹmu lulẹ̀ láti ẹnu-ọ̀nà Efraimu sí igun ẹnu-ọ̀nà apá kan títí ń lọ sí irinwó ìgbọ̀nwọ́ ní gígùn.
A Joasz, król Izraela, pojmał w Bet-Szemesz Amazjasza, króla Judy, syna Joasza, syna Jehoachaza, i przyprowadził go do Jerozolimy, gdzie zburzył mur Jerozolimy od Bramy Efraima aż do Bramy Narożnej – na czterysta łokci.
24 Ọba kó gbogbo wúrà àti fàdákà àti gbogbo ohun èlò tí wọ́n rí ni ilé Ọlọ́run tí ọ́ wà ní àbojútó Obedi-Edomu, lápapọ̀ pẹ̀lú àwọn ìṣúra ààfin àti àwọn ògo pẹ̀lú, ó sì padà lọ sí Samaria.
I [zabrał] całe złoto i srebro oraz wszystkie naczynia, które znajdowały się w domu Bożym u Obed-Edoma i w skarbcach domu królewskiego, a także zakładników, i wrócił do Samarii.
25 Amasiah ọmọ Joaṣi ọba Juda gbé fún ọdún mẹ́ẹ̀ẹ́dógún lẹ́yìn ikú Jehoaṣi ọmọ Jehoahasi ọba Israẹli.
Amazjasz, syn Joasza, król Judy, żył jeszcze piętnaście lat po śmierci Joasza, syna Jehoachaza, króla Izraela.
26 Fún ti iṣẹ́ mìíràn ti ìjọba Amasiah láti ìbẹ̀rẹ̀ dé ìparí, ṣé a kò kọ wọ́n sínú ìwé àwọn ọba Juda àti Israẹli?
A pozostałe dzieje Amazjasza, od pierwszych do ostatnich, czy nie są zapisane w księdze królów Judy i Izraela?
27 Láti ìgbà tí Amasiah ti yípadà kúrò láti máa tẹ̀lé Olúwa, wọ́n dìtẹ̀ sí i ní Jerusalẹmu, ó sì sálọ sí Lakiṣi ṣùgbọ́n, wọ́n rán àwọn ọkùnrin tẹ̀lé e lọ sí Lakiṣi, wọ́n sì pa á síbẹ̀.
A od czasu, kiedy Amazjasz odwrócił się od PANA, uknuli przeciwko niemu spisek w Jerozolimie. Uciekł więc do Lakisz, lecz wysłali za nim [pościg] do Lakisz i tam go zabili.
28 A gbé e padà pẹ̀lú ẹṣin. A sì sin ín pẹ̀lú àwọn baba rẹ̀ ní ìlú ńlá ti Juda.
Potem przywieźli go na koniach i pogrzebali go z jego ojcami w mieście Judy.

< 2 Chronicles 25 >