< 2 Chronicles 25 >

1 Amasiah jẹ́ ẹni ọdún mẹ́ẹ̀ẹ́dọ́gbọ̀n nígbà tí ó di ọba, ó sì jẹ ọba ní Jerusalẹmu fún ọdún mọ́kàndínlọ́gbọ̀n orúkọ ìyá rẹ̀ a máa jẹ́ Jehoadani, ó wá láti Jerusalẹmu.
Forsothe Amasie, `his sone, regnede for hym; Amasie was of fyue and twenti yeer, whanne he bigan to regne, and he regnyde nyne and twenti yeer in Jerusalem; the name of his modir was Joiaden, of Jerusalem.
2 Ó ṣe ohun tí ó dára lójú Olúwa, ṣùgbọ́n kì í ṣe tọkàntọkàn.
And he dide good in the siyt of the Lord, netheles not in perfit herte.
3 Lẹ́yìn tí ìjọba ti wà ní ìdarí rẹ̀, ó pa àwọn oníṣẹ́ tí ó pa baba rẹ̀ ọba.
And whanne he siy the empire strengthid to hym silf, he stranglide the seruauntis, that killiden the kyng, his fadir;
4 Síbẹ̀ kò pa àwọn ọmọ wọn, ṣùgbọ́n ó ṣe ní ìbámu pẹ̀lú ohun tí a kọ nínú òfin nínú ìwé Mose, níbi tí Olúwa ti paláṣẹ pé, “A kò gbọdọ̀ pa àwọn baba fún àwọn ọmọ wọn tàbí àwọn ọmọ fún baba wọn, olúkúlùkù ni kí ó kú fún ẹ̀ṣẹ̀ rẹ̀.”
but he killide not the sones of hem; as it is writun in the book of the lawe of Moises, where the Lord comaundide, seiynge, Fadris schulen not be slayn for the sones, nether the sones for her fadris; but ech man schal die in his owne synne.
5 Amasiah, pe gbogbo àwọn ènìyàn Juda pọ̀, ó sì fi iṣẹ́ lé wọn lọ́wọ́ gẹ́gẹ́ bí ìdílé wọn sí àwọn alákòóso ẹgbẹẹgbẹ̀rún àti àwọn alákòóso ọ̀rọ̀ọ̀rún fún gbogbo Juda àti Benjamini, ó sì gbá iye wọn láti ẹni ogún ọdún àti jù bẹ́ẹ̀ lọ jọ, ó sì rí i pé ọ̀kẹ́ mẹ́ẹ̀ẹ́dógún àwọn ọkùnrin ni ó ti múra fún ìsìn ogun, tí ó lè gbá ọ̀kọ̀ àti àpáta mú.
Therfor Amasie gaderide togidere Juda, and ordeynede hem bi meynees and tribunes and centuriouns, in al Juda and Beniamyn; and he noumbride fro twenti yeer and aboue, and he foonde thritti thousynde of yonge men, that yeden out to batel, and helden spere and scheeld.
6 Ó sì yá ọ̀kẹ́ márùn-ún àwọn ọkùnrin oníjà láti Israẹli fún ọgọ́rùn-ún àwọn tálẹ́ǹtì fàdákà.
Also for mede he hiride of Israel an hundrid thousynde of stronge men, for an hundrid talentis of siluer, that thei schulden fiyte ayens the sones of Edom.
7 Ṣùgbọ́n ènìyàn Ọlọ́run kan tọ̀ ọ́ wá ó sì wí pé, “Ọba, àwọn ọ̀wọ́ ogun láti Israẹli kò gbọdọ̀ yan pẹ̀lú rẹ, nítorí tí Olúwa kò wà pẹ̀lú Israẹli kì í ṣe pẹ̀lú ẹnìkankan láti Efraimu.
Forsothe a man of God cam to hym, and seide, A! kyng, the oost of Israel go not out with thee, for the Lord is not with Israel and with alle the sones of Effraym;
8 Àní, tí ẹ bá lọ jà pẹ̀lú ìmúláyàle ní ojú ogun, Ọlọ́run yóò bì ọ́ ṣubú níwájú àwọn ọ̀tá, nítorí Ọlọ́run ní agbára láti ràn ọ́ lọ́wọ́ àti láti bì ọ́ ṣubú.”
for if thou gessist that batels stonden in the myyt of oost, the Lord schal make thee to be ouercomun of enemyes, for it is of God for to helpe, and to turne in to fliyt.
9 Amasiah sì bi ènìyàn Ọlọ́run pé, “Ọgọ́rùn-ún tálẹ́ǹtì tí mo ti san fún àwọn ọ̀wọ́ ogun àwọn ọmọ Israẹli ń kọ́?” Ènìyàn Ọlọ́run dáhùn pé “Olúwa lè fún ọ ní èyí tí ó ju ìyẹn lọ.”
And Amasie seide to the man of God, What therfor schal be doon of the hundrid talentis, which Y yaf to the knyytis of Israel? And the man of God answeride to hym, The Lord hath, wherof he may yelde to thee myche mo thingis than these.
10 Bẹ́ẹ̀ ni Amasiah, tú àwọn ọwọ́ ogun tí ó ti wá sí ọ̀dọ̀ rẹ̀ láti Efraimu ká. Ó sì rán wọn lọ ilé. Wọ́n kún fún ìbínú pẹ̀lú Juda, wọ́n sì padà lọ ilé pẹ̀lú ìbínú ńlá.
Therfor Amasie departide the oost that cam to hym fro Effraym, that it schulde turne ayen in to his place; and thei weren wrooth greetli ayens Juda, and turneden ayen in to her cuntrei.
11 Nígbà náà, Amasiah ko ogun rẹ jọ àti àwọn ọmọ-ogun rẹ̀ lọ sí àfonífojì iyọ̀, níbi tí ó ti pa ẹgbẹ̀rún mẹ́wàá àwọn ọkùnrin Seiri.
Forsothe Amasie ledde out tristili his puple, and yede in to the valei of makyngis of salt, and he killide of the sones of Seir ten thousynde.
12 Àwọn ọkùnrin Juda pẹ̀lú fi agbára mú àwọn ọkùnrin ẹgbẹ̀rún mẹ́wàá láààyè. Wọ́n mú wọn lọ sí orí òkè bèbè òkúta, wọ́n jù wọ́n sílẹ̀, kí gbogbo wọn sì fọ́ sí wẹ́wẹ́.
And the sones of Juda token othere ten thousynde of men, and brouyten to the hiy scarre of summe stoon; and castiden hem doun fro the hiyeste in to the pit; whiche alle braken.
13 Ní báyìí àwọn ọ̀wọ́ ogun tí Amasiah ti rán lọ padà, tí wọn kò nípa nínú ogun gbógun sí àwọn ìlú Juda láti Samaria sí Beti-Horoni. Wọ́n pa ẹgbẹ̀rún mẹ́ta nínú wọn, wọ́n sì kó ọ̀pọ̀ ìkógun ńlá.
And thilke oost whom Amasie hadde sent ayen, that it schulde not go with him to batel, was spred abrood in the citees of Juda fro Samarie `til to Betheron; and aftir `that it hadde slayn thre thousynde, it took awey a greet preie.
14 Nígbà tí Amasiah padà láti ibi pípa àwọn ará Edomu, ó mú àwọn ọlọ́run àwọn ènìyàn Seiri padà wá. Ó gbé wọn kalẹ̀ gẹ́gẹ́ bi àwọn ọlọ́run tirẹ̀. Ó tẹríba fún wọn, ó sì rú ẹbọ fún wọn.
And Amasie, after the sleyng of Idumeis, and after that he hadde brouyt the goddis of the sones of Seir, ordeynede hem `in to goddis to hym silf, and worschipide hem, and brente encense to hem.
15 Ìbínú Olúwa ru sí Amasiah, ó sì rán wòlíì kan sí i, tí ó wí pé, “Kí ni ó dé tí ìwọ fi ń béèrè lọ́wọ́ àwọn ọlọ́run àwọn ènìyàn yìí, tí wọn kò le gba àwọn ènìyàn tiwọn kúrò lọ́wọ́ rẹ?”
Wherfor the Lord was wrooth ayens Amasie, and sente to hym a profete, that seide to hym, Whi worschipist thou goddis that `delyueriden not her puple fro thin hond?
16 Bí ó ti n sọ̀rọ̀, ọba wí fún un pé, “Ṣé a yàn ọ́ ní olùgba ọba lámọ̀ràn ni? Dúró! Èéṣe tí a ó fi lù ọ́ bolẹ̀?” Bẹ́ẹ̀ ni, wòlíì náà dúró ṣùgbọ́n ó wí pé, “Èmi mọ̀ pé Ọlọ́run ti pinnu láti pa ọ́ run nítorí ìwọ ti ṣe èyí, ìwọ kò sì tẹ́tí sí ìmọ̀ràn mi.”
Whanne the profete spak these thingis, Amasie answeride to hym, Whether thou art a counselour of the king? ceesse thou, lest perauenture Y sle thee. Therfor the profete yede awei, and seide, Y woot, that the Lord thouyte to sle thee; for thou didist this yuel, and ferthermore thou assentidist not to my counsel.
17 Lẹ́yìn tí Amasiah ọba Juda ti béèrè lọ́wọ́ àwọn olùdámọ̀ràn, ó rán ìpèníjà yìí sí Jehoaṣi ọmọ Jehoahasi ọmọ Jehu, ọba Israẹli pé, “Wá bá mi lójúkojú.”
Therfor Amasie, the king of Juda, whanne he hadde take a ful yuel counsel, sente to the kyng of Israel Joas, the sone of Joachaz, the sone of Hieu, and seide, Come thou, se we vs togidere.
18 Ṣùgbọ́n Jehoaṣi ọba Israẹli fèsì padà sí Amasiah ọba Juda pé, “Koríko kékeré kan ní Lebanoni rán iṣẹ́ sí igi kedari ní Lebanoni, fi ọmọbìnrin rẹ fún ọmọkùnrin mi ní ìgbéyàwó. Nígbà náà, ẹhànnà ẹranko ènìyàn ni Lebanoni wá, ó sì tẹ òṣùṣú náà lábẹ́ ẹsẹ̀.
And he sente ayen messangeris, and seide, A `cardue, ether a tasil, which is in the Liban sente to the cedre of the Liban, and seide, Yyue thi douyter a wijf to my sone; and lo! beestis that weren in the wode of the Liban yeden and defouliden the cardue.
19 Ìwọ wí fún ara à rẹ wí pé, ìwọ ti ṣẹ́gun Edomu àti nísinsin yìí ìwọ ní ìhàlẹ̀ àti ìgbéraga. Ṣùgbọ́n dúró ní ilé! Kí ni ó dé tí ìwọ fi ń wá wàhálà tí o sì fi ń fa ìṣubú rẹ àti ti Juda pẹ̀lú?”
Thou seidist, Y haue smyte Edom, and therfor thin herte is reysid in to pride; sitte thou in thin hows; whi stirist thou yuel ayens thee, that thou falle, and Juda with thee?
20 Amasiah, bí ó tì wù kí ó rí kò tẹ́tí nítorí Ọlọ́run ṣe é kí ó lè gbé wọn lé Jehoaṣi lọ́wọ́: nítorí wọ́n wá àwọn ọlọ́run Edomu.
Amasie nolde here, for it was the wille of the Lord, that he schulde be bitakun in to the hondis of enemyes, for the goddis of Edom.
21 Bẹ́ẹ̀ ni Jehoaṣi, ọba Israẹli: òun àti Amasiah ọba Juda dojúkọ ara wọn ní Beti-Ṣemeṣi ní Juda.
Therfor Joas, kyng of Israel, stiede, and thei siyen hem silf togidere. Sotheli Amasie, the kyng of Juda, was in Bethsames of Juda;
22 Àwọn ọmọ Israẹli da Juda rú, gbogbo olúkúlùkù ènìyàn sì sálọ sí ìlú rẹ̀.
and Juda felde doun bifor Israel, and fledde in to his tabernaclis.
23 Jehoaṣi ọba Israẹli fi agbára mú Amasiah ọba Juda, ọmọ Joaṣi ọmọ Ahasiah ní Beti-Ṣemeṣi. Nígbà náà Joaṣi mú u wá sí Jerusalẹmu. Ó sì wó ògiri Jerusalẹmu lulẹ̀ láti ẹnu-ọ̀nà Efraimu sí igun ẹnu-ọ̀nà apá kan títí ń lọ sí irinwó ìgbọ̀nwọ́ ní gígùn.
Certis the kyng of Israel took in Bethsames Amasie, the kyng of Juda, the sone of Joas, sone of Joachaz, and brouyte in to Jerusalem; and he destriede the wallis therof fro the yate of Effraym `til to the yate of the corner, bi foure hundrid cubitis.
24 Ọba kó gbogbo wúrà àti fàdákà àti gbogbo ohun èlò tí wọ́n rí ni ilé Ọlọ́run tí ọ́ wà ní àbojútó Obedi-Edomu, lápapọ̀ pẹ̀lú àwọn ìṣúra ààfin àti àwọn ògo pẹ̀lú, ó sì padà lọ sí Samaria.
And be ledde ayen in to Samarie al the gold and siluer, and alle vessels whiche he foond in the hows of the Lord, and at Obededom, in the tresouris also of the kyngis hows, also and the sones of ostagis.
25 Amasiah ọmọ Joaṣi ọba Juda gbé fún ọdún mẹ́ẹ̀ẹ́dógún lẹ́yìn ikú Jehoaṣi ọmọ Jehoahasi ọba Israẹli.
Forsothe Amasie, kyng of Juda, the sone of Joas, lyuede fiftene yeer aftir that Joas, kyng of Israel, the sone of Joachaz, was deed.
26 Fún ti iṣẹ́ mìíràn ti ìjọba Amasiah láti ìbẹ̀rẹ̀ dé ìparí, ṣé a kò kọ wọ́n sínú ìwé àwọn ọba Juda àti Israẹli?
Sotheli the residue of the formere and the laste wordis of Amasie ben writun in the book of kyngis of Juda and of Israel.
27 Láti ìgbà tí Amasiah ti yípadà kúrò láti máa tẹ̀lé Olúwa, wọ́n dìtẹ̀ sí i ní Jerusalẹmu, ó sì sálọ sí Lakiṣi ṣùgbọ́n, wọ́n rán àwọn ọkùnrin tẹ̀lé e lọ sí Lakiṣi, wọ́n sì pa á síbẹ̀.
And aftir that he yede awei fro the Lord, thei settiden to hym tresouns in Jerusalem; and whanne he hadde fledde to Lachis, thei senten and killiden hym there;
28 A gbé e padà pẹ̀lú ẹṣin. A sì sin ín pẹ̀lú àwọn baba rẹ̀ ní ìlú ńlá ti Juda.
and thei brouyten ayen on horsis, and birieden hym with his fadris in the citee of Dauid.

< 2 Chronicles 25 >