< 2 Chronicles 25 >

1 Amasiah jẹ́ ẹni ọdún mẹ́ẹ̀ẹ́dọ́gbọ̀n nígbà tí ó di ọba, ó sì jẹ ọba ní Jerusalẹmu fún ọdún mọ́kàndínlọ́gbọ̀n orúkọ ìyá rẹ̀ a máa jẹ́ Jehoadani, ó wá láti Jerusalẹmu.
Twenty-five years old, was Amaziah, when he began to reign, and, twenty-nine years, reigned he in Jerusalem, —and, the name of his mother, was Jehoaddan, of Jerusalem.
2 Ó ṣe ohun tí ó dára lójú Olúwa, ṣùgbọ́n kì í ṣe tọkàntọkàn.
And he did that which was right in the eyes of Yahweh, —only not with a whole heart.
3 Lẹ́yìn tí ìjọba ti wà ní ìdarí rẹ̀, ó pa àwọn oníṣẹ́ tí ó pa baba rẹ̀ ọba.
And it came to pass, when the kingdom was confirmed unto him, that he slew his servants who had smitten the king his father;
4 Síbẹ̀ kò pa àwọn ọmọ wọn, ṣùgbọ́n ó ṣe ní ìbámu pẹ̀lú ohun tí a kọ nínú òfin nínú ìwé Mose, níbi tí Olúwa ti paláṣẹ pé, “A kò gbọdọ̀ pa àwọn baba fún àwọn ọmọ wọn tàbí àwọn ọmọ fún baba wọn, olúkúlùkù ni kí ó kú fún ẹ̀ṣẹ̀ rẹ̀.”
but, their sons, he put not to death, —but as it is written in the law—in the book of Moses—how that Yahweh commanded, saying-Fathers, shall not die for, sons, and Sons, shall not die, for, fathers, but Each man, for his own sin, shall die.
5 Amasiah, pe gbogbo àwọn ènìyàn Juda pọ̀, ó sì fi iṣẹ́ lé wọn lọ́wọ́ gẹ́gẹ́ bí ìdílé wọn sí àwọn alákòóso ẹgbẹẹgbẹ̀rún àti àwọn alákòóso ọ̀rọ̀ọ̀rún fún gbogbo Juda àti Benjamini, ó sì gbá iye wọn láti ẹni ogún ọdún àti jù bẹ́ẹ̀ lọ jọ, ó sì rí i pé ọ̀kẹ́ mẹ́ẹ̀ẹ́dógún àwọn ọkùnrin ni ó ti múra fún ìsìn ogun, tí ó lè gbá ọ̀kọ̀ àti àpáta mú.
And Amaziah gathered Judah together, and appointed them by their ancestral houses, as rulers of thousands and as rulers of hundreds, for all Judah and Benjamin, —and he numbered them, from twenty years old and upwards, and found them three hundred thousand choice men, able to go forth to war, who could grasp spear and shield.
6 Ó sì yá ọ̀kẹ́ márùn-ún àwọn ọkùnrin oníjà láti Israẹli fún ọgọ́rùn-ún àwọn tálẹ́ǹtì fàdákà.
And he hired out of Israel, a hundred thousand heroes of valour, for a hundred talents of silver.
7 Ṣùgbọ́n ènìyàn Ọlọ́run kan tọ̀ ọ́ wá ó sì wí pé, “Ọba, àwọn ọ̀wọ́ ogun láti Israẹli kò gbọdọ̀ yan pẹ̀lú rẹ, nítorí tí Olúwa kò wà pẹ̀lú Israẹli kì í ṣe pẹ̀lú ẹnìkankan láti Efraimu.
But, a man of God, came unto him, saying, O king! let not the host of Israel come with thee, —for Yahweh is not with Israel, [with] any of the sons of Ephraim.
8 Àní, tí ẹ bá lọ jà pẹ̀lú ìmúláyàle ní ojú ogun, Ọlọ́run yóò bì ọ́ ṣubú níwájú àwọn ọ̀tá, nítorí Ọlọ́run ní agbára láti ràn ọ́ lọ́wọ́ àti láti bì ọ́ ṣubú.”
But, if thou art going, do, be strong for the battle, —God will cause thee to fall before the enemy, for there is strength in God, to help or to cause to fall.
9 Amasiah sì bi ènìyàn Ọlọ́run pé, “Ọgọ́rùn-ún tálẹ́ǹtì tí mo ti san fún àwọn ọ̀wọ́ ogun àwọn ọmọ Israẹli ń kọ́?” Ènìyàn Ọlọ́run dáhùn pé “Olúwa lè fún ọ ní èyí tí ó ju ìyẹn lọ.”
And Amaziah said unto the man of God, What then shall be done as to the hundred talents, which I have given to the company of Israel? Then said the man of God, Yahweh is able to give thee much more than this.
10 Bẹ́ẹ̀ ni Amasiah, tú àwọn ọwọ́ ogun tí ó ti wá sí ọ̀dọ̀ rẹ̀ láti Efraimu ká. Ó sì rán wọn lọ ilé. Wọ́n kún fún ìbínú pẹ̀lú Juda, wọ́n sì padà lọ ilé pẹ̀lú ìbínú ńlá.
So Amaziah separated them, [appointing] unto the company which had come unto him out of Ephraim, to depart unto their own place, —wherefore their anger was greatly kindled against Judah, so they returned to their own place, in a heat of anger.
11 Nígbà náà, Amasiah ko ogun rẹ jọ àti àwọn ọmọ-ogun rẹ̀ lọ sí àfonífojì iyọ̀, níbi tí ó ti pa ẹgbẹ̀rún mẹ́wàá àwọn ọkùnrin Seiri.
And, Amaziah, took courage, and led forth his people, and went to the valley of salt, —and smote of the sons of Seir, ten thousand;
12 Àwọn ọkùnrin Juda pẹ̀lú fi agbára mú àwọn ọkùnrin ẹgbẹ̀rún mẹ́wàá láààyè. Wọ́n mú wọn lọ sí orí òkè bèbè òkúta, wọ́n jù wọ́n sílẹ̀, kí gbogbo wọn sì fọ́ sí wẹ́wẹ́.
and the sons of Judah took captive, ten thousand alive, and brought to the top of the crag, —and cast them down from the top of the crag, and, all of them, were torn asunder.
13 Ní báyìí àwọn ọ̀wọ́ ogun tí Amasiah ti rán lọ padà, tí wọn kò nípa nínú ogun gbógun sí àwọn ìlú Juda láti Samaria sí Beti-Horoni. Wọ́n pa ẹgbẹ̀rún mẹ́ta nínú wọn, wọ́n sì kó ọ̀pọ̀ ìkógun ńlá.
But, as for the sons of the company which Amaziah sent back from going with him to the war, they spread themselves out against the cities of Judah, from Samaria, even unto Beth-horon, —and smote of them three thousand, and took great plunder.
14 Nígbà tí Amasiah padà láti ibi pípa àwọn ará Edomu, ó mú àwọn ọlọ́run àwọn ènìyàn Seiri padà wá. Ó gbé wọn kalẹ̀ gẹ́gẹ́ bi àwọn ọlọ́run tirẹ̀. Ó tẹríba fún wọn, ó sì rú ẹbọ fún wọn.
And so it was, after Amaziah came in from smiting the Edomites, that he brought in the gods of the sons of Seir, and set them up for himself, as gods, —and, before them, used he to bow himself down, and, unto them, used he to burn a perfume.
15 Ìbínú Olúwa ru sí Amasiah, ó sì rán wòlíì kan sí i, tí ó wí pé, “Kí ni ó dé tí ìwọ fi ń béèrè lọ́wọ́ àwọn ọlọ́run àwọn ènìyàn yìí, tí wọn kò le gba àwọn ènìyàn tiwọn kúrò lọ́wọ́ rẹ?”
Then was kindled the anger of Yahweh, against Amaziah, —and he sent unto him a prophet, and said unto him, Wherefore hast thou sought the gods of the people, which delivered not their own people out of thy hand?
16 Bí ó ti n sọ̀rọ̀, ọba wí fún un pé, “Ṣé a yàn ọ́ ní olùgba ọba lámọ̀ràn ni? Dúró! Èéṣe tí a ó fi lù ọ́ bolẹ̀?” Bẹ́ẹ̀ ni, wòlíì náà dúró ṣùgbọ́n ó wí pé, “Èmi mọ̀ pé Ọlọ́run ti pinnu láti pa ọ́ run nítorí ìwọ ti ṣe èyí, ìwọ kò sì tẹ́tí sí ìmọ̀ràn mi.”
And it came to pass, as he spake unto him, that he said to him, To be, counselor to the king, have we appointed thee? forbear thou, wherefore should they smite thee? So the prophet forbare, and said—I know that God hath determined to destroy thee, because thou hast done this, and hast not hearkened unto my counsel.
17 Lẹ́yìn tí Amasiah ọba Juda ti béèrè lọ́wọ́ àwọn olùdámọ̀ràn, ó rán ìpèníjà yìí sí Jehoaṣi ọmọ Jehoahasi ọmọ Jehu, ọba Israẹli pé, “Wá bá mi lójúkojú.”
Then Amaziah king of Judah took counsel, and sent unto Joash, son of Jehoahaz son of Jehu king of Israel, saying, —Come, let us look one another in the face!
18 Ṣùgbọ́n Jehoaṣi ọba Israẹli fèsì padà sí Amasiah ọba Juda pé, “Koríko kékeré kan ní Lebanoni rán iṣẹ́ sí igi kedari ní Lebanoni, fi ọmọbìnrin rẹ fún ọmọkùnrin mi ní ìgbéyàwó. Nígbà náà, ẹhànnà ẹranko ènìyàn ni Lebanoni wá, ó sì tẹ òṣùṣú náà lábẹ́ ẹsẹ̀.
And Joash king of Israel sent unto Amaziah king of Judah, saying, A thistle that was in Lebanon, sent unto a cedar that was in Lebanon, saying, Come! give thy daughter unto my son to wife, —but there passed by a beast of the field that was in Lebanon, and trampled down the thistle.
19 Ìwọ wí fún ara à rẹ wí pé, ìwọ ti ṣẹ́gun Edomu àti nísinsin yìí ìwọ ní ìhàlẹ̀ àti ìgbéraga. Ṣùgbọ́n dúró ní ilé! Kí ni ó dé tí ìwọ fi ń wá wàhálà tí o sì fi ń fa ìṣubú rẹ àti ti Juda pẹ̀lú?”
Thou hast said-Lo! thou hast smitten the Edomites, and thy heart hath lifted thee up to display honour, -Now, abide in thine own house, wherefore shouldst thou engage in strife with Misfortune, and fall, thou and Judah with thee?
20 Amasiah, bí ó tì wù kí ó rí kò tẹ́tí nítorí Ọlọ́run ṣe é kí ó lè gbé wọn lé Jehoaṣi lọ́wọ́: nítorí wọ́n wá àwọn ọlọ́run Edomu.
But Amaziah hearkened not, because, from God, it was, to the end he might deliver them up into [their enemies’] hand, —because they had sought the gods of Edom.
21 Bẹ́ẹ̀ ni Jehoaṣi, ọba Israẹli: òun àti Amasiah ọba Juda dojúkọ ara wọn ní Beti-Ṣemeṣi ní Juda.
So Joash king of Israel came up, and they looked one another in the face, he, and Amaziah king of Judah, —in Beth-shemesh, which belongeth unto Judah.
22 Àwọn ọmọ Israẹli da Juda rú, gbogbo olúkúlùkù ènìyàn sì sálọ sí ìlú rẹ̀.
Then was Judah defeated, before Israel, —and they fled every man to his own home;
23 Jehoaṣi ọba Israẹli fi agbára mú Amasiah ọba Juda, ọmọ Joaṣi ọmọ Ahasiah ní Beti-Ṣemeṣi. Nígbà náà Joaṣi mú u wá sí Jerusalẹmu. Ó sì wó ògiri Jerusalẹmu lulẹ̀ láti ẹnu-ọ̀nà Efraimu sí igun ẹnu-ọ̀nà apá kan títí ń lọ sí irinwó ìgbọ̀nwọ́ ní gígùn.
and, Amaziah king of Judah, son of Joash son of Jehoahaz, was taken by Joash king of Israel, in Beth-shemesh, —and he brought him to Jerusalem, and brake down the wall of Jerusalem, from the gate of Ephraim as far as the corner-gate, four hundred cubits;
24 Ọba kó gbogbo wúrà àti fàdákà àti gbogbo ohun èlò tí wọ́n rí ni ilé Ọlọ́run tí ọ́ wà ní àbojútó Obedi-Edomu, lápapọ̀ pẹ̀lú àwọn ìṣúra ààfin àti àwọn ògo pẹ̀lú, ó sì padà lọ sí Samaria.
and, all the gold and the silver and all the utensils that were found in the house of God with Obed-edom, and the treasures of the house of the king, and hostages, he took, -and returned to Samaria.
25 Amasiah ọmọ Joaṣi ọba Juda gbé fún ọdún mẹ́ẹ̀ẹ́dógún lẹ́yìn ikú Jehoaṣi ọmọ Jehoahasi ọba Israẹli.
And Amaziah son of Joash king of Judah lived, after the death of Joash son of Jehoahaz king of Israel, —fifteen years.
26 Fún ti iṣẹ́ mìíràn ti ìjọba Amasiah láti ìbẹ̀rẹ̀ dé ìparí, ṣé a kò kọ wọ́n sínú ìwé àwọn ọba Juda àti Israẹli?
Now, the rest of the story of Amaziah, first and last, lo! it is written in the book of the Kings of Judah and Israel.
27 Láti ìgbà tí Amasiah ti yípadà kúrò láti máa tẹ̀lé Olúwa, wọ́n dìtẹ̀ sí i ní Jerusalẹmu, ó sì sálọ sí Lakiṣi ṣùgbọ́n, wọ́n rán àwọn ọkùnrin tẹ̀lé e lọ sí Lakiṣi, wọ́n sì pa á síbẹ̀.
And, after the time that Amaziah turned away from following Yahweh, they made against him a conspiracy in Jerusalem, and he fled to Lachish, —but they sent after him to Lachish, and slew him there.
28 A gbé e padà pẹ̀lú ẹṣin. A sì sin ín pẹ̀lú àwọn baba rẹ̀ ní ìlú ńlá ti Juda.
And they brought him on horses, -and buried him with his fathers, in the city of Judah.

< 2 Chronicles 25 >