< 2 Chronicles 25 >

1 Amasiah jẹ́ ẹni ọdún mẹ́ẹ̀ẹ́dọ́gbọ̀n nígbà tí ó di ọba, ó sì jẹ ọba ní Jerusalẹmu fún ọdún mọ́kàndínlọ́gbọ̀n orúkọ ìyá rẹ̀ a máa jẹ́ Jehoadani, ó wá láti Jerusalẹmu.
When twenty and five years old did Amazyahu become king, and twenty and nine years did he reign in Jerusalem. And his mother's name was Yeho'addan of Jerusalem.
2 Ó ṣe ohun tí ó dára lójú Olúwa, ṣùgbọ́n kì í ṣe tọkàntọkàn.
And he did what is right in the eyes of the Lord, yet not with an entire heart.
3 Lẹ́yìn tí ìjọba ti wà ní ìdarí rẹ̀, ó pa àwọn oníṣẹ́ tí ó pa baba rẹ̀ ọba.
And it came to pass, when the kingdom was firmly established to him, that he slew his servants that had killed the king his father.
4 Síbẹ̀ kò pa àwọn ọmọ wọn, ṣùgbọ́n ó ṣe ní ìbámu pẹ̀lú ohun tí a kọ nínú òfin nínú ìwé Mose, níbi tí Olúwa ti paláṣẹ pé, “A kò gbọdọ̀ pa àwọn baba fún àwọn ọmọ wọn tàbí àwọn ọmọ fún baba wọn, olúkúlùkù ni kí ó kú fún ẹ̀ṣẹ̀ rẹ̀.”
But their children he put not to death; but [did] as it is written in the law in the book of Moses, that the Lord had commanded, saying, The fathers shall not die for the children, nor shall the children die for the fathers, but every man shall die for his own sin.
5 Amasiah, pe gbogbo àwọn ènìyàn Juda pọ̀, ó sì fi iṣẹ́ lé wọn lọ́wọ́ gẹ́gẹ́ bí ìdílé wọn sí àwọn alákòóso ẹgbẹẹgbẹ̀rún àti àwọn alákòóso ọ̀rọ̀ọ̀rún fún gbogbo Juda àti Benjamini, ó sì gbá iye wọn láti ẹni ogún ọdún àti jù bẹ́ẹ̀ lọ jọ, ó sì rí i pé ọ̀kẹ́ mẹ́ẹ̀ẹ́dógún àwọn ọkùnrin ni ó ti múra fún ìsìn ogun, tí ó lè gbá ọ̀kọ̀ àti àpáta mú.
And Amazyahu gathered Judah together, and stationed them after the family divisions, after the captains over the thousands, and after the captains over the hundreds, of all Judah and Benjamin; and he numbered them from twenty years old and upward, and found them [to be] three hundred thousand chosen men, able to go forth to the army, that could handle spear and shield.
6 Ó sì yá ọ̀kẹ́ márùn-ún àwọn ọkùnrin oníjà láti Israẹli fún ọgọ́rùn-ún àwọn tálẹ́ǹtì fàdákà.
He hired also out of Israel one hundred thousand mighty men of valor for one hundred talents of silver.
7 Ṣùgbọ́n ènìyàn Ọlọ́run kan tọ̀ ọ́ wá ó sì wí pé, “Ọba, àwọn ọ̀wọ́ ogun láti Israẹli kò gbọdọ̀ yan pẹ̀lú rẹ, nítorí tí Olúwa kò wà pẹ̀lú Israẹli kì í ṣe pẹ̀lú ẹnìkankan láti Efraimu.
But a man of God came unto him, saying, O king, let not the army of Israel go with thee; for the Lord is not with Israel, [with] all the children of Ephraim.
8 Àní, tí ẹ bá lọ jà pẹ̀lú ìmúláyàle ní ojú ogun, Ọlọ́run yóò bì ọ́ ṣubú níwájú àwọn ọ̀tá, nítorí Ọlọ́run ní agbára láti ràn ọ́ lọ́wọ́ àti láti bì ọ́ ṣubú.”
But if thou wilt go, [and be ever so] active [and] strong for the battle: God will cause thee to stumble before the enemy; for there is power with God to help, and to cause to stumble.
9 Amasiah sì bi ènìyàn Ọlọ́run pé, “Ọgọ́rùn-ún tálẹ́ǹtì tí mo ti san fún àwọn ọ̀wọ́ ogun àwọn ọmọ Israẹli ń kọ́?” Ènìyàn Ọlọ́run dáhùn pé “Olúwa lè fún ọ ní èyí tí ó ju ìyẹn lọ.”
Then said Amazyahu to the man of God, But what is it to be done for the hundred talents which I have given to the band of Israel? And the man of God said, The Lord hath [enough in his power] to give thee much more than this.
10 Bẹ́ẹ̀ ni Amasiah, tú àwọn ọwọ́ ogun tí ó ti wá sí ọ̀dọ̀ rẹ̀ láti Efraimu ká. Ó sì rán wọn lọ ilé. Wọ́n kún fún ìbínú pẹ̀lú Juda, wọ́n sì padà lọ ilé pẹ̀lú ìbínú ńlá.
Then did Amazyahu separate them, [to wit, ] the band that was come to him out of Ephraim, that they might go to their place: wherefore their anger was greatly kindled against Judah, and they returned to their home in burning anger.
11 Nígbà náà, Amasiah ko ogun rẹ jọ àti àwọn ọmọ-ogun rẹ̀ lọ sí àfonífojì iyọ̀, níbi tí ó ti pa ẹgbẹ̀rún mẹ́wàá àwọn ọkùnrin Seiri.
And Amazyahu strengthened himself, and led forth his people, and went to the Valley of Salt, and smote of the children of Se'ir ten thousand [men].
12 Àwọn ọkùnrin Juda pẹ̀lú fi agbára mú àwọn ọkùnrin ẹgbẹ̀rún mẹ́wàá láààyè. Wọ́n mú wọn lọ sí orí òkè bèbè òkúta, wọ́n jù wọ́n sílẹ̀, kí gbogbo wọn sì fọ́ sí wẹ́wẹ́.
And ten thousand did the children of Judah take captive alive, and brought them to the top of the rock, and cast them down from the top of the rock, so that they all were crushed.
13 Ní báyìí àwọn ọ̀wọ́ ogun tí Amasiah ti rán lọ padà, tí wọn kò nípa nínú ogun gbógun sí àwọn ìlú Juda láti Samaria sí Beti-Horoni. Wọ́n pa ẹgbẹ̀rún mẹ́ta nínú wọn, wọ́n sì kó ọ̀pọ̀ ìkógun ńlá.
But the men of the band whom Amazyahu had sent back, that they should not go with him to battle, spread themselves about in the cities of Judah, from Samaria even unto Beth-choron, and smote of them three thousand [persons], and plundered much spoil.
14 Nígbà tí Amasiah padà láti ibi pípa àwọn ará Edomu, ó mú àwọn ọlọ́run àwọn ènìyàn Seiri padà wá. Ó gbé wọn kalẹ̀ gẹ́gẹ́ bi àwọn ọlọ́run tirẹ̀. Ó tẹríba fún wọn, ó sì rú ẹbọ fún wọn.
And it came to pass, after Amazyahu was come home from smiting the Edomites, that he brought the gods of the children of Se'ir, and set them up unto himself as gods, and before them he used to prostrate himself and unto them he used to burn incense.
15 Ìbínú Olúwa ru sí Amasiah, ó sì rán wòlíì kan sí i, tí ó wí pé, “Kí ni ó dé tí ìwọ fi ń béèrè lọ́wọ́ àwọn ọlọ́run àwọn ènìyàn yìí, tí wọn kò le gba àwọn ènìyàn tiwọn kúrò lọ́wọ́ rẹ?”
Wherefore the anger of the Lord was kindled against Amazyahu, and he sent unto him a prophet, who said unto him, Why hast thou sought after the gods of the people, that have not delivered their own people out of thy hand?
16 Bí ó ti n sọ̀rọ̀, ọba wí fún un pé, “Ṣé a yàn ọ́ ní olùgba ọba lámọ̀ràn ni? Dúró! Èéṣe tí a ó fi lù ọ́ bolẹ̀?” Bẹ́ẹ̀ ni, wòlíì náà dúró ṣùgbọ́n ó wí pé, “Èmi mọ̀ pé Ọlọ́run ti pinnu láti pa ọ́ run nítorí ìwọ ti ṣe èyí, ìwọ kò sì tẹ́tí sí ìmọ̀ràn mi.”
And it came to pass, as he was speaking unto him, that he said unto him, Have we ever appointed thee as a counsellor to the king? forbear this: why shouldst thou be smitten? Then did the prophet forbear; and he said, I know that God hath resolved to destroy thee, because thou hast done this, and hast not hearkened unto my counsel.
17 Lẹ́yìn tí Amasiah ọba Juda ti béèrè lọ́wọ́ àwọn olùdámọ̀ràn, ó rán ìpèníjà yìí sí Jehoaṣi ọmọ Jehoahasi ọmọ Jehu, ọba Israẹli pé, “Wá bá mi lójúkojú.”
Then held Amazyahu the king of Judah a council, and sent to Joash, the son of Jehoachaz, the son of Jehu, the king of Israel, saying, Come, let us look one another in the face.
18 Ṣùgbọ́n Jehoaṣi ọba Israẹli fèsì padà sí Amasiah ọba Juda pé, “Koríko kékeré kan ní Lebanoni rán iṣẹ́ sí igi kedari ní Lebanoni, fi ọmọbìnrin rẹ fún ọmọkùnrin mi ní ìgbéyàwó. Nígbà náà, ẹhànnà ẹranko ènìyàn ni Lebanoni wá, ó sì tẹ òṣùṣú náà lábẹ́ ẹsẹ̀.
And Joash the king of Israel sent to Amazyahu the king of Judah, saying, The thorn-bush that was in the Lebanon sent to the cedar that was in the Lebanon, saying, Give thy daughter to my son for wife. And there passed along the wild beasts that were in the Lebanon, and trod down the thorn-bush.
19 Ìwọ wí fún ara à rẹ wí pé, ìwọ ti ṣẹ́gun Edomu àti nísinsin yìí ìwọ ní ìhàlẹ̀ àti ìgbéraga. Ṣùgbọ́n dúró ní ilé! Kí ni ó dé tí ìwọ fi ń wá wàhálà tí o sì fi ń fa ìṣubú rẹ àti ti Juda pẹ̀lú?”
Thou hast thought, Lo, thou hast smitten Edom; and thy heart hath lifted thee up to acquire much glory: now stay in thy house; why wilt thou meddle with misfortune, that thou mayest fall, thou, and Judah with thee?
20 Amasiah, bí ó tì wù kí ó rí kò tẹ́tí nítorí Ọlọ́run ṣe é kí ó lè gbé wọn lé Jehoaṣi lọ́wọ́: nítorí wọ́n wá àwọn ọlọ́run Edomu.
But Amazyahu would not hear; for it was [ordained] by God, in order to deliver them into the hand [of Joash]; because they had sought after the gods of Edom.
21 Bẹ́ẹ̀ ni Jehoaṣi, ọba Israẹli: òun àti Amasiah ọba Juda dojúkọ ara wọn ní Beti-Ṣemeṣi ní Juda.
Thereupon did Joash the king of Israel go up: and they looked one another in the face, he and Amazyahu the king of Judah, at Beth-shemesh, which belongeth to Judah.
22 Àwọn ọmọ Israẹli da Juda rú, gbogbo olúkúlùkù ènìyàn sì sálọ sí ìlú rẹ̀.
And Judah was defeated before Israel, and they fled every man to his tents.
23 Jehoaṣi ọba Israẹli fi agbára mú Amasiah ọba Juda, ọmọ Joaṣi ọmọ Ahasiah ní Beti-Ṣemeṣi. Nígbà náà Joaṣi mú u wá sí Jerusalẹmu. Ó sì wó ògiri Jerusalẹmu lulẹ̀ láti ẹnu-ọ̀nà Efraimu sí igun ẹnu-ọ̀nà apá kan títí ń lọ sí irinwó ìgbọ̀nwọ́ ní gígùn.
And Joash the king of Israel caught Amazyahu the king of Judah, the son of Joash, the son of Jehoachaz, at Beth-shemesh; and he brought him to Jerusalem, and made a breach in the wall of Jerusalem, from the gate of Ephraim unto the corner-gate, four hundred cubits.
24 Ọba kó gbogbo wúrà àti fàdákà àti gbogbo ohun èlò tí wọ́n rí ni ilé Ọlọ́run tí ọ́ wà ní àbojútó Obedi-Edomu, lápapọ̀ pẹ̀lú àwọn ìṣúra ààfin àti àwọn ògo pẹ̀lú, ó sì padà lọ sí Samaria.
And [taking] all the gold and the silver, and all the vessels that were found in the house of God with 'Obed-edom, and the treasures of the king's house, and the children of the chiefs as hostages, he returned to Samaria.
25 Amasiah ọmọ Joaṣi ọba Juda gbé fún ọdún mẹ́ẹ̀ẹ́dógún lẹ́yìn ikú Jehoaṣi ọmọ Jehoahasi ọba Israẹli.
And Amazyahu the son of Joash the king of Judah lived after the death of Joash the son of Jehoachaz the king of Israel fifteen years.
26 Fún ti iṣẹ́ mìíràn ti ìjọba Amasiah láti ìbẹ̀rẹ̀ dé ìparí, ṣé a kò kọ wọ́n sínú ìwé àwọn ọba Juda àti Israẹli?
And the rest of the acts of Amazyahu the first and the last, behold, they are fully written in the book of the kings of Judah and Israel.
27 Láti ìgbà tí Amasiah ti yípadà kúrò láti máa tẹ̀lé Olúwa, wọ́n dìtẹ̀ sí i ní Jerusalẹmu, ó sì sálọ sí Lakiṣi ṣùgbọ́n, wọ́n rán àwọn ọkùnrin tẹ̀lé e lọ sí Lakiṣi, wọ́n sì pa á síbẹ̀.
Now from the time that Amazyahu departed from following the Lord, they raised a conspiracy against him in Jerusalem: wherefore he fled to Lachish; but they sent after him to Lachish, and slew him there.
28 A gbé e padà pẹ̀lú ẹṣin. A sì sin ín pẹ̀lú àwọn baba rẹ̀ ní ìlú ńlá ti Juda.
And they carried him on horses, and buried him with his fathers in the city of Judah.

< 2 Chronicles 25 >