< 2 Chronicles 25 >

1 Amasiah jẹ́ ẹni ọdún mẹ́ẹ̀ẹ́dọ́gbọ̀n nígbà tí ó di ọba, ó sì jẹ ọba ní Jerusalẹmu fún ọdún mọ́kàndínlọ́gbọ̀n orúkọ ìyá rẹ̀ a máa jẹ́ Jehoadani, ó wá láti Jerusalẹmu.
Amazia ne ja-higni piero ariyo gabich kane odoko ruoth kendo norito Jerusalem kuom higni piero ariyo gochiko. Min mare ne nyinge Jehoadin nyar Jerusalem.
2 Ó ṣe ohun tí ó dára lójú Olúwa, ṣùgbọ́n kì í ṣe tọkàntọkàn.
Notimo gima kare e nyim Jehova Nyasaye to ok gi chunye duto.
3 Lẹ́yìn tí ìjọba ti wà ní ìdarí rẹ̀, ó pa àwọn oníṣẹ́ tí ó pa baba rẹ̀ ọba.
Bangʼ ka pinyruodhe nosegurore maber, nonego jotelo mane onego wuon mare mane ruoth.
4 Síbẹ̀ kò pa àwọn ọmọ wọn, ṣùgbọ́n ó ṣe ní ìbámu pẹ̀lú ohun tí a kọ nínú òfin nínú ìwé Mose, níbi tí Olúwa ti paláṣẹ pé, “A kò gbọdọ̀ pa àwọn baba fún àwọn ọmọ wọn tàbí àwọn ọmọ fún baba wọn, olúkúlùkù ni kí ó kú fún ẹ̀ṣẹ̀ rẹ̀.”
Kata kamano ne ok onego yawuot jogo nikech noluwo chik manie Kitap Chik mar Musa mane Jehova Nyasaye oketo mawacho niya, “Wuone ok nonegi nikech ketho mag nyithindgi, bende nyithindo kik negi nikech ketho mag wuonegi, to ngʼato ka ngʼato nonegi nikech richone owuon.”
5 Amasiah, pe gbogbo àwọn ènìyàn Juda pọ̀, ó sì fi iṣẹ́ lé wọn lọ́wọ́ gẹ́gẹ́ bí ìdílé wọn sí àwọn alákòóso ẹgbẹẹgbẹ̀rún àti àwọn alákòóso ọ̀rọ̀ọ̀rún fún gbogbo Juda àti Benjamini, ó sì gbá iye wọn láti ẹni ogún ọdún àti jù bẹ́ẹ̀ lọ jọ, ó sì rí i pé ọ̀kẹ́ mẹ́ẹ̀ẹ́dógún àwọn ọkùnrin ni ó ti múra fún ìsìn ogun, tí ó lè gbá ọ̀kọ̀ àti àpáta mú.
Eka Amazia nochoko jo-Juda kod jo-Benjamin kaachiel mopogogi tich kaluwore gi anywolagi kendo noyiero jotend migepe mag jolweny alufu achiel kod migepe mag mia achiel. Bangʼe nokwano jogo mahikgi piero ariyo ka dhi nyime kendo nonwangʼo ni ne gin ji alufu mia adek mane nyalo dhi e lweny kendo mane nyalo kedo gi tongʼ kod okumba.
6 Ó sì yá ọ̀kẹ́ márùn-ún àwọn ọkùnrin oníjà láti Israẹli fún ọgọ́rùn-ún àwọn tálẹ́ǹtì fàdákà.
Bende nondiko jo-Israel mathuondi alufu mia achiel kochulo fedha ma pekne romo kilo alufu adek gi mia angʼwen.
7 Ṣùgbọ́n ènìyàn Ọlọ́run kan tọ̀ ọ́ wá ó sì wí pé, “Ọba, àwọn ọ̀wọ́ ogun láti Israẹli kò gbọdọ̀ yan pẹ̀lú rẹ, nítorí tí Olúwa kò wà pẹ̀lú Israẹli kì í ṣe pẹ̀lú ẹnìkankan láti Efraimu.
To ngʼat Nyasaye moro nobiro ire mowachone niya, “Ruoth momi luor, kik iyie mondo jolweny ma jo-Israel dhi kodi nimar Jehova Nyasaye ok ni kod jo-Israel ma jo-Efraim-gi.
8 Àní, tí ẹ bá lọ jà pẹ̀lú ìmúláyàle ní ojú ogun, Ọlọ́run yóò bì ọ́ ṣubú níwájú àwọn ọ̀tá, nítorí Ọlọ́run ní agbára láti ràn ọ́ lọ́wọ́ àti láti bì ọ́ ṣubú.”
To kata kidhi ma ikedo gi chir e lweny, to Nyasaye nomi wasiki loyi, nikech Nyasayeno nigi teko mar konyi kata miyo wasiki loyi.”
9 Amasiah sì bi ènìyàn Ọlọ́run pé, “Ọgọ́rùn-ún tálẹ́ǹtì tí mo ti san fún àwọn ọ̀wọ́ ogun àwọn ọmọ Israẹli ń kọ́?” Ènìyàn Ọlọ́run dáhùn pé “Olúwa lè fún ọ ní èyí tí ó ju ìyẹn lọ.”
Amazia nopenjo ngʼat Nyasaye niya, “To wabiro timo angʼo kuom fedha mapekgi romo kilo alufu adek gi mia angʼwen mane wachulo kuom jolweny mag jo-Israel?” Ngʼat Nyasaye nodwoko niya, “Jehova Nyasaye nyalo miyi mangʼeny moloyo mano.”
10 Bẹ́ẹ̀ ni Amasiah, tú àwọn ọwọ́ ogun tí ó ti wá sí ọ̀dọ̀ rẹ̀ láti Efraimu ká. Ó sì rán wọn lọ ilé. Wọ́n kún fún ìbínú pẹ̀lú Juda, wọ́n sì padà lọ ilé pẹ̀lú ìbínú ńlá.
Eka Amazia noriembo jolweny mane oa Efraim mine gidok e miechgi ka igi owangʼ kendo gikecho malich gi Juda.
11 Nígbà náà, Amasiah ko ogun rẹ jọ àti àwọn ọmọ-ogun rẹ̀ lọ sí àfonífojì iyọ̀, níbi tí ó ti pa ẹgbẹ̀rún mẹ́wàá àwọn ọkùnrin Seiri.
To Amazia notimo chir kendo nowuok motelone jolweny mage kagidhi e Holo mar Chumbi kama nonege jo-Seir alufu apar.
12 Àwọn ọkùnrin Juda pẹ̀lú fi agbára mú àwọn ọkùnrin ẹgbẹ̀rún mẹ́wàá láààyè. Wọ́n mú wọn lọ sí orí òkè bèbè òkúta, wọ́n jù wọ́n sílẹ̀, kí gbogbo wọn sì fọ́ sí wẹ́wẹ́.
Jolweny mag Juda nomako ji alufu apar kangima mi negiterogi ewi lwanda moro kendo negidirogi piny ma githo kendo gitur matindo tindo.
13 Ní báyìí àwọn ọ̀wọ́ ogun tí Amasiah ti rán lọ padà, tí wọn kò nípa nínú ogun gbógun sí àwọn ìlú Juda láti Samaria sí Beti-Horoni. Wọ́n pa ẹgbẹ̀rún mẹ́ta nínú wọn, wọ́n sì kó ọ̀pọ̀ ìkógun ńlá.
To e sechego jolweny mane Amazia oriembo ni ok inyal dhi kode e lweny nomonjo miech Juda chakre Samaria nyaka Beth Horon. Neginego ji alufu adek kendo negipeyo gik moko mangʼeny.
14 Nígbà tí Amasiah padà láti ibi pípa àwọn ará Edomu, ó mú àwọn ọlọ́run àwọn ènìyàn Seiri padà wá. Ó gbé wọn kalẹ̀ gẹ́gẹ́ bi àwọn ọlọ́run tirẹ̀. Ó tẹríba fún wọn, ó sì rú ẹbọ fún wọn.
Kane Amazia odwogo koa nego jo-Edom nokelo nyiseche mag jo-Seir moketogi ka nyisechege kokulore nigi kendo notimonigi misango.
15 Ìbínú Olúwa ru sí Amasiah, ó sì rán wòlíì kan sí i, tí ó wí pé, “Kí ni ó dé tí ìwọ fi ń béèrè lọ́wọ́ àwọn ọlọ́run àwọn ènìyàn yìí, tí wọn kò le gba àwọn ènìyàn tiwọn kúrò lọ́wọ́ rẹ?”
Jehova Nyasaye nokecho ahinya gi Amazia kendo noorone janabi manowachone niya, “Angʼo momiyo igeno kuom nyiseche mag jogi mane ok nyal reso jogi giwegi e lweti?”
16 Bí ó ti n sọ̀rọ̀, ọba wí fún un pé, “Ṣé a yàn ọ́ ní olùgba ọba lámọ̀ràn ni? Dúró! Èéṣe tí a ó fi lù ọ́ bolẹ̀?” Bẹ́ẹ̀ ni, wòlíì náà dúró ṣùgbọ́n ó wí pé, “Èmi mọ̀ pé Ọlọ́run ti pinnu láti pa ọ́ run nítorí ìwọ ti ṣe èyí, ìwọ kò sì tẹ́tí sí ìmọ̀ràn mi.”
Kane pod janabino wuoyo, ruoth nowachone niya, “Bende waseketi jangʼad rieko ne ruoth? Lingʼ thi! Koso idwaro tho?” Omiyo janabi nolingʼ, to bangʼe nowacho niya, “Angʼeyo ni Nyasaye osechano ni mondo otieki nikech gima isetimo kendo ok isewinjo puonjna.”
17 Lẹ́yìn tí Amasiah ọba Juda ti béèrè lọ́wọ́ àwọn olùdámọ̀ràn, ó rán ìpèníjà yìí sí Jehoaṣi ọmọ Jehoahasi ọmọ Jehu, ọba Israẹli pé, “Wá bá mi lójúkojú.”
Bangʼe Amazia ruodh Juda nopenjo jongʼadne rieko mi nooro joote ir Jehoash wuod Jehoahaz ma wuod Jehu ruoth Israel kowacho niya, “Bi warom wangʼ gi wangʼ.”
18 Ṣùgbọ́n Jehoaṣi ọba Israẹli fèsì padà sí Amasiah ọba Juda pé, “Koríko kékeré kan ní Lebanoni rán iṣẹ́ sí igi kedari ní Lebanoni, fi ọmọbìnrin rẹ fún ọmọkùnrin mi ní ìgbéyàwó. Nígbà náà, ẹhànnà ẹranko ènìyàn ni Lebanoni wá, ó sì tẹ òṣùṣú náà lábẹ́ ẹsẹ̀.
To Jehoash ruodh Israel nodwoko Amazia ruodh Juda gi ngero niya, “Kuth alii man Lebanon nooro wach ne yiend sida man Lebanon ni, ‘Yie ichiw nyari ne wuoda mondo okendi.’ To le moro mar bungu mowuok Lebanon nokadho kanyo monyono kuth aliino gi tiende.
19 Ìwọ wí fún ara à rẹ wí pé, ìwọ ti ṣẹ́gun Edomu àti nísinsin yìí ìwọ ní ìhàlẹ̀ àti ìgbéraga. Ṣùgbọ́n dúró ní ilé! Kí ni ó dé tí ìwọ fi ń wá wàhálà tí o sì fi ń fa ìṣubú rẹ àti ti Juda pẹ̀lú?”
In iwuorori ni iseloyo jo-Edom kendo koro iwuoyo marach kisungori. To ber mondo ibed mana e dala. Angʼo momiyo imanyo lweny mabiro tieki kaachiel gi jo-Juda duto?”
20 Amasiah, bí ó tì wù kí ó rí kò tẹ́tí nítorí Ọlọ́run ṣe é kí ó lè gbé wọn lé Jehoaṣi lọ́wọ́: nítorí wọ́n wá àwọn ọlọ́run Edomu.
Kata kamano, Amazia ne ok odewo, nimar ne en dwaro Nyasaye mondo ochiwe e lwet Jehoash nikech negiluwo nyiseche mag Edom.
21 Bẹ́ẹ̀ ni Jehoaṣi, ọba Israẹli: òun àti Amasiah ọba Juda dojúkọ ara wọn ní Beti-Ṣemeṣi ní Juda.
Omiyo Jehoash ruodh Israel nomonje. Jehoash kod Amazia ruodh Juda ne joromo e lweny e dala mar Beth Shemesh man Juda.
22 Àwọn ọmọ Israẹli da Juda rú, gbogbo olúkúlùkù ènìyàn sì sálọ sí ìlú rẹ̀.
Jo-Israel noloyo jo-Juda kendo ngʼato ka ngʼato noringo kochomo dalane.
23 Jehoaṣi ọba Israẹli fi agbára mú Amasiah ọba Juda, ọmọ Joaṣi ọmọ Ahasiah ní Beti-Ṣemeṣi. Nígbà náà Joaṣi mú u wá sí Jerusalẹmu. Ó sì wó ògiri Jerusalẹmu lulẹ̀ láti ẹnu-ọ̀nà Efraimu sí igun ẹnu-ọ̀nà apá kan títí ń lọ sí irinwó ìgbọ̀nwọ́ ní gígùn.
Jehoash ruodh Israel nomako Amazia wuod Joash ma wuod Ahazia, ruodh Juda e Beth Shemesh. Bangʼe Jehoash nokele Jerusalem kendo nomuko ohinga mar Jerusalem chakre e Dhoranga Efraim nyaka kama ohinga ogomogo, bor kama ne omuko ne romo fut mia abich gi piero ochiko gachiel.
24 Ọba kó gbogbo wúrà àti fàdákà àti gbogbo ohun èlò tí wọ́n rí ni ilé Ọlọ́run tí ọ́ wà ní àbojútó Obedi-Edomu, lápapọ̀ pẹ̀lú àwọn ìṣúra ààfin àti àwọn ògo pẹ̀lú, ó sì padà lọ sí Samaria.
Nokawo dhahabu gi fedha duto kod gik moko duto mane oyudo e hekalu mar Nyasaye mane Obed-Edom orito kaachiel gi keno mar ruoth kod ji moko mano mako e lweny, bangʼe nodok e piny Samaria.
25 Amasiah ọmọ Joaṣi ọba Juda gbé fún ọdún mẹ́ẹ̀ẹ́dógún lẹ́yìn ikú Jehoaṣi ọmọ Jehoahasi ọba Israẹli.
Amazia wuod Joash ruodh Juda nodak higni apar gabich bangʼ tho Jehoash wuod Jehoahaz ruodh Israel.
26 Fún ti iṣẹ́ mìíràn ti ìjọba Amasiah láti ìbẹ̀rẹ̀ dé ìparí, ṣé a kò kọ wọ́n sínú ìwé àwọn ọba Juda àti Israẹli?
To weche mamoko mag loch Amazia kar chakruokgi nyaka gikogi donge ondikgi e kitap ruodhi mag Juda kod Israel?
27 Láti ìgbà tí Amasiah ti yípadà kúrò láti máa tẹ̀lé Olúwa, wọ́n dìtẹ̀ sí i ní Jerusalẹmu, ó sì sálọ sí Lakiṣi ṣùgbọ́n, wọ́n rán àwọn ọkùnrin tẹ̀lé e lọ sí Lakiṣi, wọ́n sì pa á síbẹ̀.
Chakre ndalo mane Amazia oweyo luwo Jehova Nyasaye, negichikone obadho e Jerusalem mi oringo odhi Lakish, to negioro ji bangʼe Lakish ma onege kuno.
28 A gbé e padà pẹ̀lú ẹṣin. A sì sin ín pẹ̀lú àwọn baba rẹ̀ ní ìlú ńlá ti Juda.
Noduog ringre kotingʼ gi faras kendo noyike but kwerene e Dala Maduongʼ mar Juda.

< 2 Chronicles 25 >