< 2 Chronicles 24 >

1 Joaṣi jẹ́ ọmọ ọdún méje nígbà tí ó jẹ ọba, ó sì jẹ ọba ní Jerusalẹmu fún ogójì ọdún. Orúkọ ìyá rẹ̀ ni Sibia ti Beerṣeba.
Joas avait sept ans quand il commença à régner, et il régna quarante ans à Jérusalem; le nom de sa mère était Sébia de Bersabée.
2 Joaṣi ṣe ohun tí ó dára ní ojú Olúwa ní gbogbo àkókò Jehoiada àlùfáà.
Et il fit ce qui est bon devant le Seigneur, durant tous les jours de Joïada, le prêtre.
3 Jehoiada yan ìyàwó méjì fún un, ó sì ní àwọn ọmọkùnrin àti àwọn ọmọbìnrin.
Or Joïada lui fit prendre deux femmes, dont il engendra des fils et des filles.
4 Ní àkókò kan, Joaṣi pinnu láti tún ilé Olúwa ṣe.
Après quoi, il plut à Joas de réparer la maison du Seigneur.
5 Ó pe àwọn àlùfáà àti àwọn ará Lefi jọ, ó wí fún wọn pé, “Ẹ lọ sí àwọn ìlú Juda, kí ẹ sì gba owó ìtọ́sí láti ọwọ́ gbogbo Israẹli láti fi tún ilé Ọlọ́run yín ṣe.” Ṣùgbọ́n àwọn ará Lefi kò ṣe é lẹ́ẹ̀kan náà.
Et il assembla les prêtres et les Lévites, et il leur dit: Sortez dans les villes de Juda, et rassemblez chaque année, de tout Israël, de l’argent pour les réparations du temple de votre Dieu, et faites-le promptement. Mais les Lévites agirent avec beaucoup de négligence.
6 Nítorí náà ọba pa á láṣẹ fún Jehoiada olórí àlùfáà ó sì wí fún un pé, “Kí ni ó dé tí o kò béèrè lọ́wọ́ àwọn ará Lefi láti mú wá láti Juda àti Jerusalẹmu, owó orí tí Mose ìránṣẹ́ Olúwa ti fi lélẹ̀ àti nípasẹ̀ àpéjọ gbogbo Israẹli fún àgọ́ ẹ̀rí?”
Et le roi appela Joïada, le prince, et lui dit: Pourquoi n’as-tu pas eu soin d’obliger les Lévites à apporter de Juda et de Jérusalem l’argent qui a été imposé par Moïse, serviteur du Seigneur, afin que toute la multitude d’Israël rapportât pour le tabernacle de témoignage?
7 Nísinsin yìí, àwọn ọmọkùnrin obìnrin búburú ni Ataliah ti fọ́ ilé Ọlọ́run, ó sì ti lo àwọn nǹkan ìyàsọ́tọ̀ fún àwọn Baali.
Car la très impie Athalie et ses fils avaient détruit la maison de Dieu, et de tout ce qui avait été consacré dans le temple du Seigneur ils avaient orné le temple des Baalim.
8 Nípasẹ̀ ọba, wọn ṣe àpótí wọ́n sì gbé e sí ìta, ní ẹnu-ọ̀nà ilé Olúwa.
Et le roi leur ordonna de faire un coffre, et ils le mirent près de la porte de la maison du Seigneur, en dehors.
9 A ṣe ìkéde ní Juda àti Jerusalẹmu wí pé wọ́n gbọdọ̀ mú wá fún Olúwa, owó orí tí Mose ìránṣẹ́ Olúwa ti béèrè lọ́wọ́ Israẹli ní aginjù.
Et on publia, en Juda et à Jérusalem, que chacun apporterait au Seigneur le prix que Moïse, serviteur de Dieu, avait imposé sur tout Israël dans le désert.
10 Gbogbo àwọn ìjòyè àti gbogbo àwọn ènìyàn sì yọ̀, wọ́n sì mú un wá, wọ́n ń jù ú sínú àpótí títí tí ó fi kún.
Et tous les princes se réjouirent, ainsi que tout le peuple; et, étant entrés, ils le portèrent dans le coffre du Seigneur, et ils y en jetèrent tellement, qu’il fut rempli.
11 Nígbàkígbà tí a bá gbé àpótí wọlé láti ọwọ́ àwọn ará Lefi sí ọwọ́ àwọn ìjòyè ọba, tí wọ́n bá sì rí wí pe owó ńlá wà níbẹ̀ àwọn akọ̀wé ọba àti ìjòyè olórí àlùfáà yóò wá láti kó owó rẹ̀ kúrò, wọn yóò sì dá a padà sí ààyè rẹ̀. Wọ́n ṣe èyí déédé, wọ́n sì kó iye owó ńlá.
Et lorsqu’il était temps de porter le coffre devant le roi par les mains des Lévites (parce qu’ils voyaient beaucoup d’argent), entraient le scribe du roi et celui que le premier prêtre avait désigné; et ils vidaient l’argent qui était dans le coffre: pour le coffre, ils le reportaient en son lieu, et c’est ainsi qu’ils faisaient chaque jour, et que fut amassé un argent infini,
12 Ọba àti Jehoiada fi fún àwọn ọkùnrin náà tí ó sì ń ṣiṣẹ́ nínú ilé Olúwa. Wọ́n fi owó gba ẹni tí ń fi òkúta mọ ilé àti àwọn gbẹ́nàgbẹ́nà láti kọ́ ilé Olúwa padà, àti àwọn òṣìṣẹ́ pẹ̀lú irin àti idẹ láti tún ilé Olúwa ṣe.
Que donnèrent le roi et Joïada à ceux qui présidaient aux ouvrages de la maison du Seigneur; mais ceux-ci louaient avec cet argent des tailleurs de pierre et des ouvriers pour tous les ouvrages, afin qu’ils réparassent la maison du Seigneur, comme aussi des artisans qui travaillaient le fer et l’airain, afin que ce qui avait commencé de tomber fût étayé.
13 Bẹ́ẹ̀ ni àwọn tí ó ń ṣiṣẹ́ náà, sì lọ síwájú àti síwájú ní ọwọ́ wọn, wọ́n sì tún mú ilé Ọlọ́run dúró sí ipò rẹ̀, wọ́n mú un le.
Ainsi ceux qui travaillaient agirent avec activité; les crevasses des murailles étaient bouchées par leurs mains; et ils rétablirent la maison du Seigneur en son premier état, et firent qu’elle se maintint solidement.
14 Nígbà tí wọ́n sì parí rẹ̀ tán, wọ́n mú owó ìyókù wá sí iwájú ọba àti Jehoiada, a sì fi ohun èlò fún ilé Olúwa, àní ohun èlò fún ìsìn àti fún ẹbọ pẹ̀lú ọpọ́n, àní ohun èlò wúrà àti fàdákà. Wọ́n sì ń rú ẹbọ sísun ní ilé Olúwa nígbà gbogbo ní gbogbo ọjọ́ Jehoiada.
Et lorsqu’ils eurent achevé tous les ouvrages, ils portèrent devant le roi et Joïada le reste de l’argent, dont on fit les vases du temple pour le service et pour les holocaustes, comme aussi des fioles, et tous les au très vases d’or et d’argent; et l’on offrit des holocaustes dans la maison du Seigneur continuellement durant tous les jours de Joïada.
15 Ṣùgbọ́n Jehoiada di arúgbó, ó sì kún fún ọjọ́, ó sì kú, ẹni àádóje ọdún ni nígbà tí ó kú.
Or Joïada vieillit plein de jours, et il mourut lorsqu’il était âgé de cent trente ans;
16 Wọ́n sì sin ín ní ìlú Dafidi pẹ̀lú àwọn ọba, nítorí tí ó ṣe rere ní Israẹli, àti sí Ọlọ́run àti sí ilé rẹ̀.
Et on l’ensevelit avec les rois dans la cité de David, parce qu’il avait fait du bien à Israël et à sa maison.
17 Lẹ́yìn ikú Jehoiada, àwọn oníṣẹ́ Juda wá láti fi ìforíbalẹ̀ wọn hàn sí ọba. Ó sì fèsì sí wọn.
Après que Joïada fut mort, les princes de Juda vinrent et se prosternèrent devant le roi, qui, séduit par leurs soumissions, les écouta.
18 Wọ́n pa ilé Olúwa tì, Ọlọ́run baba a wọn. Wọ́n sì ń sin àwọn ère Aṣerah àti àwọn òrìṣà. Nítorí ẹ̀ṣẹ̀ wọn yìí, ìbínú Ọlọ́run dé sórí Juda àti Jerusalẹmu.
Et ils abandonnèrent le temple du Seigneur Dieu de leurs pères, et s’attachèrent au culte des bois sacrés et des images taillées au ciseau; et la colère du Seigneur s’alluma contre Juda et contre Jérusalem, à cause de ce péché.
19 Bí ó ti wù kí ó rí, Olúwa rán àwọn wòlíì sí àwọn ènìyàn láti mú wọn padà sí ọ̀dọ̀ rẹ̀. Bí ó tilẹ̀ jẹ́ wí pé, wọ́n jẹ́rìí nípa wọn, wọn kì yóò gbọ́.
Et il leur envoyait des prophètes pour qu’ils revinssent au Seigneur; mais ils ne voulaient point les écouter.
20 Nígbà náà, Ẹ̀mí Ọlọ́run wá sórí Sekariah ọmọ Jehoiada wòlíì, ó dúró níwájú àwọn ènìyàn ó sì wí pé, “Èyí ni ohun tí Olúwa wí: ‘Kí ni ó dé tí ẹ̀yin kò fi tẹ̀lé àṣẹ Olúwa? Ìwọ kì yóò ṣe rere. Nítorí tí ìwọ ti kọ Olúwa sílẹ̀, òun pẹ̀lú ti kọ̀ yín sílẹ̀.’”
C’est pourquoi l’Esprit de Dieu remplit Zacharie, le prêtre, fils de Joïada, et il se tint en présence du peuple, et leur dit: Voici ce que dit le Seigneur Dieu: Pourquoi transgressez-vous le précepte du Seigneur, ce qui ne vous servira pas, et avez-vous abandonné le Seigneur, de manière qu’il vous abandonnât?
21 Ṣùgbọ́n wọ́n dìtẹ̀ sí i, àti nípa àṣẹ ọba, wọ́n sọ ọ́ lókùúta pa nínú àgbàlá ààfin ilé Olúwa.
Ceux-ci s’assemblèrent contre lui, et lui jetèrent des pierres, selon l’ordre du roi, dans le parvis de la maison du Seigneur.
22 Ọba Joaṣi kò rántí inú rere tí Jehoiada baba Sakariah ti fihàn án ṣùgbọ́n, ó pa ọmọ rẹ̀, tí ó wí bí ó ti ń kú lọ pé, “Kí Olúwa kí ó rí èyí kí ó sì pè ọ́ sí ìṣirò.”
Et Joas ne se souvint point de la miséricorde que lui avait faite Joïada, père de Zacharie; mais il tua son fils, qui, comme il mourait, dit: Que le Seigneur voie et qu’il tire vengeance.
23 Ní òpin ọdún, àwọn ọmọ-ogun Aramu yàn láti dojúkọ Joaṣi; wọ́n gbógun ti Juda àti Jerusalẹmu, wọ́n sì pa gbogbo àwọn aṣáájú àwọn ènìyàn. Wọ́n rán gbogbo àwọn ìkógun sí ọba wọn ní Damasku.
Or, lorsque l’année se fut écoulée, l’armée de Syrie monta contre lui, et elle vint en Juda et à Jérusalem; elle tua tous les princes du peuple, et elle envoya tout le butin au roi à Damas.
24 Bí ó ti wù kí ó rí, àwọn ọmọ-ogun Aramu ti wá pẹ̀lú àwọn ọkùnrin díẹ̀ Olúwa sì fi ọ̀pọ̀ àwọn ọmọ-ogun lé wọn lọ́wọ́, nítorí tí Juda ti kọ Olúwa Ọlọ́run àwọn baba wọn sílẹ̀. Bẹ́ẹ̀ ni wọ́n sì ṣe ìdájọ́ Joaṣi.
Et certes, quoiqu’il ne fût venu qu’un très petit nombre de Syriens, le Seigneur livra en leurs mains une multitude infinie, parce qu’ils avaient abandonné le Seigneur Dieu de leurs pères; contre Joas aussi, ils exercèrent d’ignominieux châtiments.
25 Nígbà tí àwọn ará Aramu kúrò, wọ́n fi Joaṣi sílẹ̀ pẹ̀lú ọ̀pọ̀ ọgbẹ́. Àwọn oníṣẹ́ rẹ̀ dìtẹ̀ si fún pípa ọmọ Jehoiada àlùfáà, wọ́n sì pa á ní orí ibùsùn rẹ̀. Bẹ́ẹ̀ ó sì kú, a sì sin ín sínú ìlú ńlá ti Dafidi, ṣùgbọ́n kì í ṣe nínú àwọn ibojì àwọn ọba.
Et, s’en allant, ils le laissèrent dans de grandes langueurs; ses serviteurs mêmes s’élevèrent contre lui pour venger le sang du fils de Joïada, le prêtre, et ils le tuèrent dans son lit: on l’ensevelit dans la cité de David, mais non dans le tombeau des rois.
26 Àwọn tí ó dìtẹ̀ sì jẹ́ Sabadi, ọmọ Ṣimeati arábìnrin Ammoni àti Jehosabadi ọmọ Ṣimiriti arábìnrin Moabu.
Or ceux qui conspirèrent contre lui sont Zabad, fils de Semmaath, l’Ammanite, et Jozabad, fils de Sémarith, la Moabite.
27 Àkọsílẹ̀ àwọn ọmọ rẹ̀, àwọn ọ̀pọ̀lọpọ̀ àsọtẹ́lẹ̀ nípa rẹ̀, àti àkọsílẹ̀ ti ìmúpadà sípò ilé Ọlọ́run ní a kọ sínú ìwé ìtumọ̀ ti àwọn ọba. Amasiah ọmọ rẹ̀ sì rọ́pò rẹ̀ gẹ́gẹ́ bí ọba.
Ce qui regarde ses fils, la somme d’argent amassée sous lui, et le rétablissement de la maison de Dieu, est écrit avec plus de soin dans le Livre des rois; or Amasias, son fils, régna en sa place.

< 2 Chronicles 24 >