< 2 Chronicles 24 >

1 Joaṣi jẹ́ ọmọ ọdún méje nígbà tí ó jẹ ọba, ó sì jẹ ọba ní Jerusalẹmu fún ogójì ọdún. Orúkọ ìyá rẹ̀ ni Sibia ti Beerṣeba.
Joas avait sept ans lorsqu'il devint roi, et il régna quarante ans à Jérusalem. Le nom de sa mère était Tsibia, de Beer Schéba.
2 Joaṣi ṣe ohun tí ó dára ní ojú Olúwa ní gbogbo àkókò Jehoiada àlùfáà.
Joas fit ce qui est droit aux yeux de l'Éternel pendant toute la durée du règne de Jehojada, le sacrificateur.
3 Jehoiada yan ìyàwó méjì fún un, ó sì ní àwọn ọmọkùnrin àti àwọn ọmọbìnrin.
Jehojada prit pour lui deux femmes, et il engendra des fils et des filles.
4 Ní àkókò kan, Joaṣi pinnu láti tún ilé Olúwa ṣe.
Après cela, Joas eut l'intention de restaurer la maison de Yahvé.
5 Ó pe àwọn àlùfáà àti àwọn ará Lefi jọ, ó wí fún wọn pé, “Ẹ lọ sí àwọn ìlú Juda, kí ẹ sì gba owó ìtọ́sí láti ọwọ́ gbogbo Israẹli láti fi tún ilé Ọlọ́run yín ṣe.” Ṣùgbọ́n àwọn ará Lefi kò ṣe é lẹ́ẹ̀kan náà.
Il rassembla les prêtres et les lévites, et leur dit: « Allez dans les villes de Juda, et recueillez de tout Israël de l'argent pour réparer la maison de votre Dieu d'année en année. Veillez à accélérer cette affaire. » Cependant, les lévites ne le firent pas tout de suite.
6 Nítorí náà ọba pa á láṣẹ fún Jehoiada olórí àlùfáà ó sì wí fún un pé, “Kí ni ó dé tí o kò béèrè lọ́wọ́ àwọn ará Lefi láti mú wá láti Juda àti Jerusalẹmu, owó orí tí Mose ìránṣẹ́ Olúwa ti fi lélẹ̀ àti nípasẹ̀ àpéjọ gbogbo Israẹli fún àgọ́ ẹ̀rí?”
Le roi appela le chef Jehojada et lui dit: « Pourquoi n'as-tu pas exigé des Lévites qu'ils apportent la taxe de Moïse, serviteur de l'Éternel, et de l'assemblée d'Israël, de Juda et de Jérusalem, pour la tente du Témoignage? »
7 Nísinsin yìí, àwọn ọmọkùnrin obìnrin búburú ni Ataliah ti fọ́ ilé Ọlọ́run, ó sì ti lo àwọn nǹkan ìyàsọ́tọ̀ fún àwọn Baali.
Car les fils d'Athalie, cette méchante femme, avaient démoli la maison de Dieu, et ils avaient aussi donné aux Baals toutes les choses consacrées de la maison de l'Éternel.
8 Nípasẹ̀ ọba, wọn ṣe àpótí wọ́n sì gbé e sí ìta, ní ẹnu-ọ̀nà ilé Olúwa.
Le roi donna cet ordre; on fit un coffre, et on le plaça dehors, à la porte de la maison de l'Éternel.
9 A ṣe ìkéde ní Juda àti Jerusalẹmu wí pé wọ́n gbọdọ̀ mú wá fún Olúwa, owó orí tí Mose ìránṣẹ́ Olúwa ti béèrè lọ́wọ́ Israẹli ní aginjù.
On fit une proclamation en Juda et à Jérusalem, pour qu'on apporte à l'Éternel l'impôt que Moïse, serviteur de Dieu, avait imposé à Israël dans le désert.
10 Gbogbo àwọn ìjòyè àti gbogbo àwọn ènìyàn sì yọ̀, wọ́n sì mú un wá, wọ́n ń jù ú sínú àpótí títí tí ó fi kún.
Tous les princes et tout le peuple se réjouissaient, apportaient et jetaient dans le coffre, jusqu'à ce qu'ils l'eussent rempli.
11 Nígbàkígbà tí a bá gbé àpótí wọlé láti ọwọ́ àwọn ará Lefi sí ọwọ́ àwọn ìjòyè ọba, tí wọ́n bá sì rí wí pe owó ńlá wà níbẹ̀ àwọn akọ̀wé ọba àti ìjòyè olórí àlùfáà yóò wá láti kó owó rẹ̀ kúrò, wọn yóò sì dá a padà sí ààyè rẹ̀. Wọ́n ṣe èyí déédé, wọ́n sì kó iye owó ńlá.
Chaque fois que le coffre était apporté aux officiers du roi par la main des Lévites, et qu'ils voyaient qu'il y avait beaucoup d'argent, le scribe du roi et l'officier du grand prêtre venaient vider le coffre, le prenaient et le remettaient à sa place. Ils firent ainsi jour après jour, et ils recueillirent de l'argent en abondance.
12 Ọba àti Jehoiada fi fún àwọn ọkùnrin náà tí ó sì ń ṣiṣẹ́ nínú ilé Olúwa. Wọ́n fi owó gba ẹni tí ń fi òkúta mọ ilé àti àwọn gbẹ́nàgbẹ́nà láti kọ́ ilé Olúwa padà, àti àwọn òṣìṣẹ́ pẹ̀lú irin àti idẹ láti tún ilé Olúwa ṣe.
Le roi et Jehoïada le donnèrent à ceux qui s'occupaient du service de la maison de Yahvé. Ils engagèrent des maçons et des charpentiers pour restaurer la maison de l'Éternel, et aussi ceux qui travaillaient le fer et le bronze pour réparer la maison de l'Éternel.
13 Bẹ́ẹ̀ ni àwọn tí ó ń ṣiṣẹ́ náà, sì lọ síwájú àti síwájú ní ọwọ́ wọn, wọ́n sì tún mú ilé Ọlọ́run dúró sí ipò rẹ̀, wọ́n mú un le.
Les ouvriers travaillèrent donc, et l'œuvre de réparation avança entre leurs mains. Ils remirent en place la maison de Dieu telle qu'elle avait été conçue, et la consolidèrent.
14 Nígbà tí wọ́n sì parí rẹ̀ tán, wọ́n mú owó ìyókù wá sí iwájú ọba àti Jehoiada, a sì fi ohun èlò fún ilé Olúwa, àní ohun èlò fún ìsìn àti fún ẹbọ pẹ̀lú ọpọ́n, àní ohun èlò wúrà àti fàdákà. Wọ́n sì ń rú ẹbọ sísun ní ilé Olúwa nígbà gbogbo ní gbogbo ọjọ́ Jehoiada.
Lorsqu'ils eurent terminé, ils apportèrent le reste de l'argent devant le roi et devant Jehojada, avec lequel on fabriqua des ustensiles pour la maison de l'Éternel, des ustensiles pour le service et pour les offrandes, des coupes et des récipients d'or et d'argent. Ils offrirent des holocaustes dans la maison de Yahvé, sans interruption pendant toute la durée de Jehojada.
15 Ṣùgbọ́n Jehoiada di arúgbó, ó sì kún fún ọjọ́, ó sì kú, ẹni àádóje ọdún ni nígbà tí ó kú.
Mais Jehoïada devint vieux, et ses jours furent comptés, et il mourut. Il avait cent trente ans lorsqu'il mourut.
16 Wọ́n sì sin ín ní ìlú Dafidi pẹ̀lú àwọn ọba, nítorí tí ó ṣe rere ní Israẹli, àti sí Ọlọ́run àti sí ilé rẹ̀.
On l'enterra dans la ville de David, au milieu des rois, parce qu'il avait fait du bien en Israël, à l'égard de Dieu et de sa maison.
17 Lẹ́yìn ikú Jehoiada, àwọn oníṣẹ́ Juda wá láti fi ìforíbalẹ̀ wọn hàn sí ọba. Ó sì fèsì sí wọn.
Après la mort de Jehoïada, les princes de Juda vinrent se prosterner devant le roi. Et le roi les écouta.
18 Wọ́n pa ilé Olúwa tì, Ọlọ́run baba a wọn. Wọ́n sì ń sin àwọn ère Aṣerah àti àwọn òrìṣà. Nítorí ẹ̀ṣẹ̀ wọn yìí, ìbínú Ọlọ́run dé sórí Juda àti Jerusalẹmu.
Ils abandonnèrent la maison de Yahvé, le Dieu de leurs pères, et servirent les mâts d'Ashéra et les idoles, de sorte que la colère s'abattit sur Juda et Jérusalem à cause de leur culpabilité.
19 Bí ó ti wù kí ó rí, Olúwa rán àwọn wòlíì sí àwọn ènìyàn láti mú wọn padà sí ọ̀dọ̀ rẹ̀. Bí ó tilẹ̀ jẹ́ wí pé, wọ́n jẹ́rìí nípa wọn, wọn kì yóò gbọ́.
Il leur envoya pourtant des prophètes pour les ramener à l'Éternel, et ils témoignèrent contre eux, mais ils ne voulurent pas écouter.
20 Nígbà náà, Ẹ̀mí Ọlọ́run wá sórí Sekariah ọmọ Jehoiada wòlíì, ó dúró níwájú àwọn ènìyàn ó sì wí pé, “Èyí ni ohun tí Olúwa wí: ‘Kí ni ó dé tí ẹ̀yin kò fi tẹ̀lé àṣẹ Olúwa? Ìwọ kì yóò ṣe rere. Nítorí tí ìwọ ti kọ Olúwa sílẹ̀, òun pẹ̀lú ti kọ̀ yín sílẹ̀.’”
L'Esprit de Dieu descendit sur Zacharie, fils du prêtre Jehoïada. Il se tint debout au-dessus du peuple et lui dit: « Dieu dit: « Pourquoi désobéissez-vous aux commandements de l'Éternel, de sorte que vous ne pouvez pas prospérer? Parce que vous avez abandonné Yahvé, il vous a aussi abandonnés. »
21 Ṣùgbọ́n wọ́n dìtẹ̀ sí i, àti nípa àṣẹ ọba, wọ́n sọ ọ́ lókùúta pa nínú àgbàlá ààfin ilé Olúwa.
Ils conspirèrent contre lui et le lapidèrent, sur l'ordre du roi, dans le parvis de la maison de l'Éternel.
22 Ọba Joaṣi kò rántí inú rere tí Jehoiada baba Sakariah ti fihàn án ṣùgbọ́n, ó pa ọmọ rẹ̀, tí ó wí bí ó ti ń kú lọ pé, “Kí Olúwa kí ó rí èyí kí ó sì pè ọ́ sí ìṣirò.”
Ainsi, le roi Joas ne se souvint pas de la bonté que Jehojada, son père, avait eue pour lui, mais il tua son fils. Lorsqu'il mourut, il dit: « Que Yahvé y jette un regard et lui rende la pareille. »
23 Ní òpin ọdún, àwọn ọmọ-ogun Aramu yàn láti dojúkọ Joaṣi; wọ́n gbógun ti Juda àti Jerusalẹmu, wọ́n sì pa gbogbo àwọn aṣáájú àwọn ènìyàn. Wọ́n rán gbogbo àwọn ìkógun sí ọba wọn ní Damasku.
A la fin de l'année, l'armée des Syriens monta contre lui. Ils arrivèrent en Juda et à Jérusalem, firent périr tous les princes du peuple et envoyèrent tout leur butin au roi de Damas.
24 Bí ó ti wù kí ó rí, àwọn ọmọ-ogun Aramu ti wá pẹ̀lú àwọn ọkùnrin díẹ̀ Olúwa sì fi ọ̀pọ̀ àwọn ọmọ-ogun lé wọn lọ́wọ́, nítorí tí Juda ti kọ Olúwa Ọlọ́run àwọn baba wọn sílẹ̀. Bẹ́ẹ̀ ni wọ́n sì ṣe ìdájọ́ Joaṣi.
Car l'armée des Syriens était venue avec une petite troupe d'hommes, et l'Éternel livra entre leurs mains une très grande armée, parce qu'ils avaient abandonné l'Éternel, le Dieu de leurs pères. Ils firent donc justice à Joas.
25 Nígbà tí àwọn ará Aramu kúrò, wọ́n fi Joaṣi sílẹ̀ pẹ̀lú ọ̀pọ̀ ọgbẹ́. Àwọn oníṣẹ́ rẹ̀ dìtẹ̀ si fún pípa ọmọ Jehoiada àlùfáà, wọ́n sì pa á ní orí ibùsùn rẹ̀. Bẹ́ẹ̀ ó sì kú, a sì sin ín sínú ìlú ńlá ti Dafidi, ṣùgbọ́n kì í ṣe nínú àwọn ibojì àwọn ọba.
Lorsqu'ils se furent éloignés de lui (car ils le laissèrent gravement blessé), ses propres serviteurs conspirèrent contre lui pour le sang des fils du prêtre Jehoïada, ils le tuèrent sur son lit, et il mourut. On l'enterra dans la ville de David, mais on ne l'enterra pas dans les tombeaux des rois.
26 Àwọn tí ó dìtẹ̀ sì jẹ́ Sabadi, ọmọ Ṣimeati arábìnrin Ammoni àti Jehosabadi ọmọ Ṣimiriti arábìnrin Moabu.
Voici ceux qui conspirèrent contre lui: Zabad, fils de Shimeath, l'Ammonite, et Jehozabad, fils de Shimrith, la Moabite.
27 Àkọsílẹ̀ àwọn ọmọ rẹ̀, àwọn ọ̀pọ̀lọpọ̀ àsọtẹ́lẹ̀ nípa rẹ̀, àti àkọsílẹ̀ ti ìmúpadà sípò ilé Ọlọ́run ní a kọ sínú ìwé ìtumọ̀ ti àwọn ọba. Amasiah ọmọ rẹ̀ sì rọ́pò rẹ̀ gẹ́gẹ́ bí ọba.
En ce qui concerne ses fils, la grandeur des charges qui lui ont été imposées et la reconstruction de la maison de Dieu, voici ce qui est écrit dans le commentaire du livre des rois. Amatsia, son fils, régna à sa place.

< 2 Chronicles 24 >