< 2 Chronicles 23 >

1 Ní ọdún keje, Jehoiada fi agbára rẹ̀ hàn. O dá májẹ̀mú pẹ̀lú àwọn alákòóso ọ̀rọ̀ọ̀rún kan, Asariah ọmọ Jerohamu, Iṣmaeli ọmọ Jehohanani Asariah ọmọ Obedi, Maaseiah ọmọ Adaiah àti Elisafati ọmọ Sikri.
W roku siódmym Jehojada umocnił się i zawarł przymierze z setnikami: Azariaszem, synem Jerochama, Izmaelem, synem Jochanana, Azariaszem, synem Obeda, Maasejaszem, synem Adajasza, i Elisafatem, synem Zikriego.
2 Wọ́n lọ sí gbogbo Juda, wọ́n sì pe àwọn ará Lefi àti àwọn olórí àwọn ìdílé àwọn ará Israẹli láti gbogbo àwọn ìlú jọ. Nígbà tí wọ́n wá sí Jerusalẹmu.
Obeszli oni ziemię Judy, zebrali Lewitów ze wszystkich miast Judy oraz naczelników rodów Izraela i przybyli do Jerozolimy.
3 Gbogbo ìpéjọ náà dá májẹ̀mú pẹ̀lú ọba ní ilé Ọlọ́run. Jehoiada wí fún wọn pé, “Ọmọkùnrin ọba yóò jẹ ọba, bí Olúwa ti ṣèlérí nípa àwọn ìran Dafidi.
Całe to zgromadzenie zawarło z królem przymierze w domu Bożym. I powiedział im: Oto syn króla będzie królował, tak jak PAN zapowiedział o synach Dawida.
4 Nísinsin yìí èyí ni ohun tí ó yẹ kí ó ṣe, ìdámẹ́ta àlùfáà yín àti àwọn ará Lefi tí ó ń lọ fún iṣẹ́ ìsìn ní ọjọ́ ìsinmi ni kí ó bojútó àwọn ìlẹ̀kùn.
Oto co macie uczynić: Trzecia część z was – kapłanów i Lewitów, którzy przychodzicie w szabat – [będzie] odźwiernymi przy bramach.
5 Ìdámẹ́ta yín níbi ààfin ọba àti ìdámẹ́ta níbi ẹnu odi ìdásílẹ̀ àti gbogbo ọkùnrin mìíràn ni kí ó wà ní àgbàlá ààfin ilé Olúwa.
Trzecia część [będzie] w domu królewskim i trzecia część będzie w bramie fundamentu. Cały zaś lud [zostanie] w dziedzińcach domu PANA.
6 Kò sí ẹnìkan tí ó gbọdọ̀ wọ inú ilé Olúwa yàtọ̀ sí àwọn àlùfáà àti àwọn ará Lefi tí a rán ní iṣẹ́ ìsìn. Wọ́n lè wọlé nítorí tí a ti yà wọ́n sọ́tọ̀, ṣùgbọ́n gbogbo ọkùnrin mìíràn ni kí wọn ó sọ ohun tí Olúwa ti yàn fún wọn.
Niech [nikt] nie wchodzi do domu PANA prócz kapłanów i usługujących Lewitów. Oni mogą wchodzić, gdyż są poświęceni. A cały lud niech trzyma straż PANA.
7 Àwọn ará Lefi gbọdọ̀ wà ní ìdúró ṣinṣin yí ọba ká. Olúkúlùkù pẹ̀lú àwọn nǹkan ìjà ní ọwọ́ rẹ̀. Ẹnikẹ́ni tí ó bá wọ ilé Olúwa ni kí ẹ pa. Ẹ dúró ti ọba níbikíbi tí ó bá lọ.”
Lewici otoczą króla ze wszystkich stron, każdy z bronią w ręku. Ktokolwiek wejdzie do domu, poniesie śmierć. Bądźcie przy królu, gdy będzie wchodził i gdy będzie wychodził.
8 Àwọn ará Lefi àti gbogbo ọkùnrin Juda ṣe gẹ́gẹ́ bí Jehoiada àlùfáà ti paláṣẹ. Olúkúlùkù mú àwọn ọkùnrin rẹ̀, àwọn tí wọ́n lọ fún iṣẹ́ ìsìn ní ọjọ́ ìsinmi àti àwọn tí wọ́n ń kúrò ní ibi iṣẹ́. Nítorí Jehoiada àlùfáà kò ì tí tú ìpín kankan sílẹ̀.
I uczynili Lewici oraz cały lud Judy według wszystkiego, co rozkazał kapłan Jehojada. Każdy wziął swoich ludzi, którzy przychodzili w szabat, i tych, którzy odchodzili w szabat, bo kapłan Jehojada nie zwolnił [tych] zmian.
9 Jehoiada àlùfáà, sì fi ọ̀kọ̀ àti asà, àti àpáta wọ̀n-ọn-nì, tí ó jẹ́ ti ọba Dafidi tí wọn wà ní ilé Ọlọ́run, fún àwọn balógun ọ̀rọ̀ọ̀rún.
I kapłan Jehojada rozdał setnikom włócznie, tarcze i puklerze, które [należały do] króla Dawida, a które [znajdowały się] w domu Bożym.
10 Ó sì to gbogbo àwọn ènìyàn ti ọba káàkiri, olúkúlùkù pẹ̀lú ohun ìjà rẹ̀ ní ọwọ́ rẹ̀, láti apá ọ̀tún ilé náà títí dé apá òsì ilé náà, lẹ́bàá pẹpẹ àti lẹ́bàá ilé náà.
Ustawił też cały lud, a każdy miał broń w ręku, od prawej strony domu aż do lewej strony domu, [przy] ołtarzu i domu, dokoła króla.
11 Jehoiada àti àwọn ọmọkùnrin rẹ̀ mú ọmọkùnrin ọba jáde wá wọ́n sì gbé adé sórí rẹ̀; wọ́n mú ẹ̀dà májẹ̀mú kan fún un. Wọ́n sì kéde rẹ̀ lọ́ba. Wọ́n fi àmì òróró yàn án, wọ́n sì kígbe pé, “Kí ọba kí ó pẹ́!”
Wtedy wyprowadzili syna króla, włożyli mu koronę, [wręczyli mu] Świadectwo i ustanowili go królem. Jehojada i jego synowie namaścili go i wołali: Niech żyje król!
12 Nígbà tí Ataliah gbọ́ igbe àwọn ènìyàn tí wọ́n ń sáré tí wọ́n ń kígbe ọba, ó lọ sí ọ̀dọ̀ wọn ní ilé Olúwa.
Kiedy Atalia usłyszała krzyk zbiegającego się ludu, który chwalił króla, przyszła do ludu do domu PANA.
13 Ó sì wò, sì kíyèsi, ọba dúró ní ibùdó rẹ̀ ní ẹ̀bá ẹnu-ọ̀nà, àti àwọn balógun àti àwọn afùnpè lọ́dọ̀ ọba, gbogbo àwọn ènìyàn ilẹ̀ náà sì yọ̀, wọ́n sì fọn ìpè, àti àwọn akọrin pẹ̀lú ohun èlò ìyìn. Nígbà náà ni Ataliah fa aṣọ rẹ̀ ya, ó sì kégbe wí pé, “Ọ̀tẹ̀! Ọ̀tẹ̀!”
A gdy spojrzała, oto król stał przy kolumnie u wejścia, a wokół króla książęta i trąby. Cały lud tej ziemi radował się i dął w trąby, także śpiewacy z instrumentami muzycznymi oraz ci, którzy kierowali śpiewem. Wtedy Atalia rozdarła swoje szaty, mówiąc: Zdrada! Zdrada!
14 Jehoiada àlùfáà mú àwọn alákòóso ọ̀rọ̀ọ̀rún, tí ó wà ní àbojútó àwọn ọ̀wọ́ ogun, ó sì wá wí fún wọn pé, “Mú un jáde wá láàrín àwọn ọgbà, kí a sì fi idà pa ẹnikẹ́ni tí ó bá tẹ̀lé.” Nítorí tí àlùfáà ti wí pé, “Má ṣe pa á nínú ilé Olúwa.”
Wówczas kapłan Jehojada rozkazał wystąpić setnikom dowodzącym wojskiem i powiedział do nich: Wyprowadźcie ją poza szeregi, a ktokolwiek pójdzie za nią, niech będzie zabity mieczem. Kapłan bowiem powiedział: Nie zabijajcie jej w domu PANA.
15 Bẹ́ẹ̀ ni wọ́n fi ipá mú un kí ó tó dé ẹnu-ọ̀nà àbáwọlé ẹṣin ti ilé ọba, wọ́n sì ti pa á níbẹ̀.
Pochwycili ją więc, a gdy przyszła do wejścia Bramy Końskiej przy domu królewskim, tam ją zabili.
16 Nígbà náà ni Jehoiada, dá májẹ̀mú pé òun àti àwọn ènìyàn àti ọba yóò jẹ́ ènìyàn Olúwa.
Wtedy Jehojada zawarł przymierze między nim a całym ludem i królem, aby byli ludem PANA.
17 Gbogbo àwọn ènìyàn lọ sí ilé Baali, wọ́n sì fà á ya lulẹ̀. Wọ́n fọ́ àwọn pẹpẹ àti àwọn òrìṣà, wọ́n sì pa Mattani àlùfáà Baali níwájú àwọn pẹpẹ.
Potem cały lud wszedł do domu Baala i zburzył go. Pokruszyli jego ołtarze i posągi, a Mattana, kapłana Baala, zabili przed ołtarzami.
18 Nígbà náà, Jehoiada tẹ àwòrán ilé Olúwa sí ọwọ́ àwọn àlùfáà tí wọ́n jẹ́ ará Lefi ẹni tí Dafidi ti fi ṣe iṣẹ́ ní ilé Olúwa láti tẹ ẹbọ sísun ti Olúwa bí a ti kọ ọ́ nínú òfin Mose, pẹ̀lú ayọ̀ àti orin kíkọ, gẹ́gẹ́ bí Dafidi ti pàṣẹ.
I Jehojada ustanowił przełożonych nad domem PANA pod władzą kapłanów i Lewitów, których Dawid podzielił w domu PANA, aby z radością i pieśniami składali PANU całopalenia, jak jest napisane w Prawie Mojżesza, według rozporządzenia Dawida.
19 Ó mú àwọn olùṣọ́nà wà ni ipò ìdúró ní ẹnu odi ilé Olúwa kí ẹni aláìmọ́ nínú ohunkóhun kó má ba à wọlé.
Postawił też odźwiernych przy bramach domu PANA, aby nie wchodził nikt, kto byłby w jakikolwiek sposób nieczysty.
20 Ó mú pẹ̀lú rẹ̀ àwọn alákòóso ọ̀rọ̀ọ̀rún, àwọn ẹni ọlá, àwọn olórí àwọn ènìyàn àti gbogbo àwọn ènìyàn ilẹ̀ náà. Ó sì mú ọba sọ̀kalẹ̀ wá láti ilé Olúwa. Wọ́n lọ sínú ààfin láti ẹnu òde ti òkè. Wọ́n sì fi ọba jókòó lórí ìtẹ́.
Potem wziął setników, dostojników i przełożonych ludu oraz cały lud ziemi i wyprowadzili króla z domu PANA. Przeszli przez bramę wyższą do domu królewskiego i posadzili króla na tronie królestwa.
21 Gbogbo àwọn ènìyàn ilẹ̀ náà sì yọ̀, ìlú náà sì dákẹ́ rọ́rọ́. Nítorí a pa Ataliah pẹ̀lú idà.
I radował się cały lud ziemi. A miasto zaznało pokoju, gdy Atalię zabito mieczem.

< 2 Chronicles 23 >