< 2 Chronicles 23 >
1 Ní ọdún keje, Jehoiada fi agbára rẹ̀ hàn. O dá májẹ̀mú pẹ̀lú àwọn alákòóso ọ̀rọ̀ọ̀rún kan, Asariah ọmọ Jerohamu, Iṣmaeli ọmọ Jehohanani Asariah ọmọ Obedi, Maaseiah ọmọ Adaiah àti Elisafati ọmọ Sikri.
Na rĩrĩ, mwaka wa mũgwanja Jehoiada nĩonanirie hinya wake. Nĩathondekire kĩrĩkanĩro na anene a ita a thigari 100 nao maarĩ: Azaria mũrũ wa Jerohamu, na Ishumaeli mũrũ wa Jehohanani, na Azaria mũrũ wa Obedi, na Maaseia mũrũ wa Adaia, na Elishafatu mũrũ wa Zikiri.
2 Wọ́n lọ sí gbogbo Juda, wọ́n sì pe àwọn ará Lefi àti àwọn olórí àwọn ìdílé àwọn ará Israẹli láti gbogbo àwọn ìlú jọ. Nígbà tí wọ́n wá sí Jerusalẹmu.
Nao magĩthiĩ bũrũri wa Juda wothe makĩũnganagia Alawii na atongoria a nyũmba cia andũ a Isiraeli kuuma matũũra-inĩ mothe. Rĩrĩa mookire Jerusalemu-rĩ,
3 Gbogbo ìpéjọ náà dá májẹ̀mú pẹ̀lú ọba ní ilé Ọlọ́run. Jehoiada wí fún wọn pé, “Ọmọkùnrin ọba yóò jẹ ọba, bí Olúwa ti ṣèlérí nípa àwọn ìran Dafidi.
kĩũngano gĩothe nĩkĩagĩire kĩrĩkanĩro na mũthamaki kũu hekarũ-inĩ ya Ngai. Jehoiada akĩmeera atĩrĩ, “Mũriũ wa mũthamaki no nginya athamake, o ta ũrĩa Jehova eeranĩire ũhoro-inĩ ũkoniĩ njiaro cia Daudi.
4 Nísinsin yìí èyí ni ohun tí ó yẹ kí ó ṣe, ìdámẹ́ta àlùfáà yín àti àwọn ará Lefi tí ó ń lọ fún iṣẹ́ ìsìn ní ọjọ́ ìsinmi ni kí ó bojútó àwọn ìlẹ̀kùn.
Na rĩrĩ, ũũ nĩguo mũgwĩka: Gĩcunjĩ gĩa gatatũ kĩa inyuĩ athĩnjĩri-Ngai na Alawii arĩa megũthiĩ wĩra mũthenya wa Thabatũ mũrangĩre mĩrango,
5 Ìdámẹ́ta yín níbi ààfin ọba àti ìdámẹ́ta níbi ẹnu odi ìdásílẹ̀ àti gbogbo ọkùnrin mìíràn ni kí ó wà ní àgbàlá ààfin ilé Olúwa.
gĩcunjĩ gĩa gatatũ kĩanyu mũrangĩre nyũmba ya ũthamaki, na gĩcunjĩ gĩa gatatũ mũrangĩre kĩhingo kĩa mũthingi, nao andũ acio angĩ othe maikare nja cia hekarũ ya Jehova.
6 Kò sí ẹnìkan tí ó gbọdọ̀ wọ inú ilé Olúwa yàtọ̀ sí àwọn àlùfáà àti àwọn ará Lefi tí a rán ní iṣẹ́ ìsìn. Wọ́n lè wọlé nítorí tí a ti yà wọ́n sọ́tọ̀, ṣùgbọ́n gbogbo ọkùnrin mìíràn ni kí wọn ó sọ ohun tí Olúwa ti yàn fún wọn.
Mũtikanareke mũndũ o na ũmwe atoonye hekarũ ya Jehova tiga o athĩnjĩri-Ngai na Alawii arĩa marĩ wĩra-inĩ; acio no matoonye tondũ nĩ aamũre, no andũ acio angĩ othe marangĩre kĩrĩa Jehova oigĩte marangĩre.
7 Àwọn ará Lefi gbọdọ̀ wà ní ìdúró ṣinṣin yí ọba ká. Olúkúlùkù pẹ̀lú àwọn nǹkan ìjà ní ọwọ́ rẹ̀. Ẹnikẹ́ni tí ó bá wọ ilé Olúwa ni kí ẹ pa. Ẹ dúró ti ọba níbikíbi tí ó bá lọ.”
Alawii makeiga mathiũrũrũkĩirie mũthamaki, o mũndũ arĩ na indo ciake cia mbaara guoko-inĩ. Mũndũ o wothe ũngĩtoonya hekarũ no nginya oragwo. Ikaragai hakuhĩ na mũthamaki kũrĩa guothe angĩthiĩ.”
8 Àwọn ará Lefi àti gbogbo ọkùnrin Juda ṣe gẹ́gẹ́ bí Jehoiada àlùfáà ti paláṣẹ. Olúkúlùkù mú àwọn ọkùnrin rẹ̀, àwọn tí wọ́n lọ fún iṣẹ́ ìsìn ní ọjọ́ ìsinmi àti àwọn tí wọ́n ń kúrò ní ibi iṣẹ́. Nítorí Jehoiada àlùfáà kò ì tí tú ìpín kankan sílẹ̀.
Nao Alawii na andũ othe a Juda magĩĩka o ũrĩa Jehoiada ũrĩa mũthĩnjĩri-Ngai aathanire. O mũndũ akĩoya andũ ake arĩa maathiiaga wĩra mũthenya wa Thabatũ na arĩa moimagĩra wĩra, nĩgũkorwo Jehoiada ũrĩa mũthĩnjĩri-Ngai ndarĩ gĩkundi o na kĩmwe aarekereirie.
9 Jehoiada àlùfáà, sì fi ọ̀kọ̀ àti asà, àti àpáta wọ̀n-ọn-nì, tí ó jẹ́ ti ọba Dafidi tí wọn wà ní ilé Ọlọ́run, fún àwọn balógun ọ̀rọ̀ọ̀rún.
Ningĩ akĩhe anene a ita a thigari 100 matimũ na ngo iria nene na nini iria ciarĩ cia Mũthamaki Daudi iria ciarĩ thĩinĩ wa hekarũ ya Ngai.
10 Ó sì to gbogbo àwọn ènìyàn ti ọba káàkiri, olúkúlùkù pẹ̀lú ohun ìjà rẹ̀ ní ọwọ́ rẹ̀, láti apá ọ̀tún ilé náà títí dé apá òsì ilé náà, lẹ́bàá pẹpẹ àti lẹ́bàá ilé náà.
Akĩrũgamia andũ othe, o mũndũ na indo ciake cia mbaara, magĩthiũrũrũkĩria mũthamaki, hau hakuhĩ na kĩgongona, na hakuhĩ na hekarũ, kuuma mwena wa gũthini nginya mwene wa gathigathini wayo.
11 Jehoiada àti àwọn ọmọkùnrin rẹ̀ mú ọmọkùnrin ọba jáde wá wọ́n sì gbé adé sórí rẹ̀; wọ́n mú ẹ̀dà májẹ̀mú kan fún un. Wọ́n sì kéde rẹ̀ lọ́ba. Wọ́n fi àmì òróró yàn án, wọ́n sì kígbe pé, “Kí ọba kí ó pẹ́!”
Jehoiada na ariũ ake makĩruta mũriũ wa mũthamaki na makĩmwĩkĩra thũmbĩ ya ũthamaki; makĩmũnengera ibuku rĩa kĩrĩkanĩro na makĩanĩrĩra atĩ nĩwe mũthamaki. Makĩmũitĩrĩria maguta na makĩanĩrĩra, makiuga atĩrĩ, “Mũthamaki arotũũra nginya tene!”
12 Nígbà tí Ataliah gbọ́ igbe àwọn ènìyàn tí wọ́n ń sáré tí wọ́n ń kígbe ọba, ó lọ sí ọ̀dọ̀ wọn ní ilé Olúwa.
Rĩrĩa Athalia aaiguire inegene rĩa andũ makĩhanyũka magĩkũngũyagĩra mũthamaki, agĩthiĩ kũrĩ o kũu hekarũ-inĩ ya Jehova.
13 Ó sì wò, sì kíyèsi, ọba dúró ní ibùdó rẹ̀ ní ẹ̀bá ẹnu-ọ̀nà, àti àwọn balógun àti àwọn afùnpè lọ́dọ̀ ọba, gbogbo àwọn ènìyàn ilẹ̀ náà sì yọ̀, wọ́n sì fọn ìpè, àti àwọn akọrin pẹ̀lú ohun èlò ìyìn. Nígbà náà ni Ataliah fa aṣọ rẹ̀ ya, ó sì kégbe wí pé, “Ọ̀tẹ̀! Ọ̀tẹ̀!”
Agĩcũthĩrĩria, na akĩona mũthamaki arũgamĩte gĩtugĩ-inĩ gĩake itoonyero-inĩ. Nao anene na ahuhi tũrumbeta marũgamĩte hakuhĩ na mũthamaki, na andũ othe a bũrũri magagĩkena makĩhuhaga tũrumbeta, nao aini marĩ na indo cia kũina magatongoria andũ arĩa angĩ na nyĩmbo cia kũgooca. Nake Athalia agĩtembũranga nguo ciake cia igũrũ, akĩanĩrĩra, akiuga atĩrĩ, “Ungumania! Ungumania!”
14 Jehoiada àlùfáà mú àwọn alákòóso ọ̀rọ̀ọ̀rún, tí ó wà ní àbojútó àwọn ọ̀wọ́ ogun, ó sì wá wí fún wọn pé, “Mú un jáde wá láàrín àwọn ọgbà, kí a sì fi idà pa ẹnikẹ́ni tí ó bá tẹ̀lé.” Nítorí tí àlùfáà ti wí pé, “Má ṣe pa á nínú ilé Olúwa.”
Nake Jehoiada ũrĩa mũthĩnjĩri-Ngai agĩtũma anene a ita a thigari igana igana, arĩa maarĩ arũgamĩrĩri a mbũtũ cia ita, akĩmeera atĩrĩ, “Mũrutũrũrei, mũmũrehe arĩ gatagatĩ ga thigari, na mũndũ o wothe ũngĩmuuma thuutha, oragwo.” Nĩgũkorwo mũthĩnjĩri-Ngai nĩoigĩte atĩrĩ, “Mũtikamũũragĩre hekarũ-inĩ ya Jehova.”
15 Bẹ́ẹ̀ ni wọ́n fi ipá mú un kí ó tó dé ẹnu-ọ̀nà àbáwọlé ẹṣin ti ilé ọba, wọ́n sì ti pa á níbẹ̀.
Nĩ ũndũ ũcio makĩmũnyiita, agĩkinya itoonyero-inĩ rĩa Kĩhingo kĩa Mbarathi, o kũu nja-inĩ cia nyũmba ya ũthamaki, makĩmũũragĩra hau.
16 Nígbà náà ni Jehoiada, dá májẹ̀mú pé òun àti àwọn ènìyàn àti ọba yóò jẹ́ ènìyàn Olúwa.
Nake Jehoiada akĩgĩa na kĩrĩkanĩro atĩ we, na andũ, na mũthamaki megũtuĩka andũ a Jehova.
17 Gbogbo àwọn ènìyàn lọ sí ilé Baali, wọ́n sì fà á ya lulẹ̀. Wọ́n fọ́ àwọn pẹpẹ àti àwọn òrìṣà, wọ́n sì pa Mattani àlùfáà Baali níwájú àwọn pẹpẹ.
Nao andũ othe magĩthiĩ hekarũ-inĩ ya Baali na makĩmĩtharia. Makiunanga igongona na mĩhianano na makĩũragĩra Matani ũrĩa warĩ mũthĩnjĩri-ngai wa Baali hau mbere ya igongona icio.
18 Nígbà náà, Jehoiada tẹ àwòrán ilé Olúwa sí ọwọ́ àwọn àlùfáà tí wọ́n jẹ́ ará Lefi ẹni tí Dafidi ti fi ṣe iṣẹ́ ní ilé Olúwa láti tẹ ẹbọ sísun ti Olúwa bí a ti kọ ọ́ nínú òfin Mose, pẹ̀lú ayọ̀ àti orin kíkọ, gẹ́gẹ́ bí Dafidi ti pàṣẹ.
Ningĩ Jehoiada akĩneana ũrũgamĩrĩri wa hekarũ ya Jehova moko-inĩ ma athĩnjĩri-Ngai, arĩa maarĩ Alawii, arĩa maaheetwo wĩra hekarũ-inĩ nĩ Daudi, marutagĩre Jehova magongona ma njino o ta ũrĩa kwandĩkĩtwo watho-inĩ wa Musa, o makĩinaga na magakena o ta ũrĩa Daudi aathanĩte.
19 Ó mú àwọn olùṣọ́nà wà ni ipò ìdúró ní ẹnu odi ilé Olúwa kí ẹni aláìmọ́ nínú ohunkóhun kó má ba à wọlé.
O na ningĩ nĩaigire aikaria a mĩrango ihingo-inĩ cia hekarũ ya Jehova nĩgeetha gũtikagĩe mũndũ o na ũmwe ũtetheretie ũngĩtoonya.
20 Ó mú pẹ̀lú rẹ̀ àwọn alákòóso ọ̀rọ̀ọ̀rún, àwọn ẹni ọlá, àwọn olórí àwọn ènìyàn àti gbogbo àwọn ènìyàn ilẹ̀ náà. Ó sì mú ọba sọ̀kalẹ̀ wá láti ilé Olúwa. Wọ́n lọ sínú ààfin láti ẹnu òde ti òkè. Wọ́n sì fi ọba jókòó lórí ìtẹ́.
Akĩoya anene a ita thigari igana, na anene arĩa angĩ, na aathani a andũ, na andũ othe a bũrũri, magĩikũrũkia mũthamaki kuuma hekarũ-inĩ ya Jehova. Magĩtoonya nyũmba ya ũthamaki magereire Kĩhingo kĩa Rũgongo na magĩikarĩria mũthamaki gĩtĩ-inĩ kĩa ũnene,
21 Gbogbo àwọn ènìyàn ilẹ̀ náà sì yọ̀, ìlú náà sì dákẹ́ rọ́rọ́. Nítorí a pa Ataliah pẹ̀lú idà.
nao andũ othe a bũrũri magĩkena. Narĩo itũũra inene rĩkĩhoorera, tondũ Athalia nĩarĩkĩtie kũũragwo na rũhiũ rwa njora.