< 2 Chronicles 23 >

1 Ní ọdún keje, Jehoiada fi agbára rẹ̀ hàn. O dá májẹ̀mú pẹ̀lú àwọn alákòóso ọ̀rọ̀ọ̀rún kan, Asariah ọmọ Jerohamu, Iṣmaeli ọmọ Jehohanani Asariah ọmọ Obedi, Maaseiah ọmọ Adaiah àti Elisafati ọmọ Sikri.
Or, en la septième année, Joïada, plein d’un nouveau courage, prit les centurions; à savoir, Azarias fils de Jéroham, Ismahël fils de Johanan, Azarias fils d’Obed, Maasias fils d’Adaïas, et Elisaphat fils de Zéchri, et fit alliance avec eux;
2 Wọ́n lọ sí gbogbo Juda, wọ́n sì pe àwọn ará Lefi àti àwọn olórí àwọn ìdílé àwọn ará Israẹli láti gbogbo àwọn ìlú jọ. Nígbà tí wọ́n wá sí Jerusalẹmu.
Lesquels, parcourant la Judée, assemblèrent les Lévites de toutes les villes de Juda et les princes des familles d’Israël, puis ils vinrent à Jérusalem.
3 Gbogbo ìpéjọ náà dá májẹ̀mú pẹ̀lú ọba ní ilé Ọlọ́run. Jehoiada wí fún wọn pé, “Ọmọkùnrin ọba yóò jẹ ọba, bí Olúwa ti ṣèlérí nípa àwọn ìran Dafidi.
Toute cette multitude fit donc un traité dans la maison de Dieu avec le roi, et Joïada leur dit: Voilà que le fils du roi régnera, comme l’a dit le Seigneur touchant les fils de David.
4 Nísinsin yìí èyí ni ohun tí ó yẹ kí ó ṣe, ìdámẹ́ta àlùfáà yín àti àwọn ará Lefi tí ó ń lọ fún iṣẹ́ ìsìn ní ọjọ́ ìsinmi ni kí ó bojútó àwọn ìlẹ̀kùn.
Voici donc ce que vous ferez:
5 Ìdámẹ́ta yín níbi ààfin ọba àti ìdámẹ́ta níbi ẹnu odi ìdásílẹ̀ àti gbogbo ọkùnrin mìíràn ni kí ó wà ní àgbàlá ààfin ilé Olúwa.
Une troisième partie de vous, prêtres, Lévites et portiers, qui venez pour le jour du sabbat, sera aux portes; mais une troisième partie auprès du palais du roi, et une troisième à la porte qui est appelée du Fondement; quant à tout le reste du peuple, qu’il soit dans les parvis de la maison du Seigneur.
6 Kò sí ẹnìkan tí ó gbọdọ̀ wọ inú ilé Olúwa yàtọ̀ sí àwọn àlùfáà àti àwọn ará Lefi tí a rán ní iṣẹ́ ìsìn. Wọ́n lè wọlé nítorí tí a ti yà wọ́n sọ́tọ̀, ṣùgbọ́n gbogbo ọkùnrin mìíràn ni kí wọn ó sọ ohun tí Olúwa ti yàn fún wọn.
Que personne n’entre dans la maison du Seigneur, si ce n’est les prêtres et ceux qui font le service d’entre les Lévites: que ceux-là seulement entrent, parce qu’ils sont sanctifiés; et que tout le reste du peuple observe les veilles du Seigneur.
7 Àwọn ará Lefi gbọdọ̀ wà ní ìdúró ṣinṣin yí ọba ká. Olúkúlùkù pẹ̀lú àwọn nǹkan ìjà ní ọwọ́ rẹ̀. Ẹnikẹ́ni tí ó bá wọ ilé Olúwa ni kí ẹ pa. Ẹ dúró ti ọba níbikíbi tí ó bá lọ.”
Mais que les Lévites entourent le roi, ayant chacun leurs armes (et si quelque autre entre dans le temple, qu’il soit tué), et qu’ils soient avec le roi, lorsqu’il entrera, et qu’il sortira.
8 Àwọn ará Lefi àti gbogbo ọkùnrin Juda ṣe gẹ́gẹ́ bí Jehoiada àlùfáà ti paláṣẹ. Olúkúlùkù mú àwọn ọkùnrin rẹ̀, àwọn tí wọ́n lọ fún iṣẹ́ ìsìn ní ọjọ́ ìsinmi àti àwọn tí wọ́n ń kúrò ní ibi iṣẹ́. Nítorí Jehoiada àlùfáà kò ì tí tú ìpín kankan sílẹ̀.
Les Lévites donc et tout Juda firent selon tout ce que leur avait ordonné Joïada, le pontife; et ils prirent chacun les hommes qui étaient sous eux, et qui venaient, selon l’ordre du sabbat, avec ceux qui avaient accompli le sabbat, et qui devaient sortir; attendu que Joïada, le pontife, n’avait pas laissé aller les bandes qui, à chaque semaine, avaient coutume de se succéder.
9 Jehoiada àlùfáà, sì fi ọ̀kọ̀ àti asà, àti àpáta wọ̀n-ọn-nì, tí ó jẹ́ ti ọba Dafidi tí wọn wà ní ilé Ọlọ́run, fún àwọn balógun ọ̀rọ̀ọ̀rún.
Et Joïada, le prêtre, donna aux centurions les lances, les boucliers et les peltes du roi David, qu’il avait consacrés dans la maison du Seigneur.
10 Ó sì to gbogbo àwọn ènìyàn ti ọba káàkiri, olúkúlùkù pẹ̀lú ohun ìjà rẹ̀ ní ọwọ́ rẹ̀, láti apá ọ̀tún ilé náà títí dé apá òsì ilé náà, lẹ́bàá pẹpẹ àti lẹ́bàá ilé náà.
Et il plaça toute la multitude de ceux qui tenaient des sabres depuis le côté droit du temple jusqu’au côté gauche du temple, devant l’autel et le temple, autour du roi.
11 Jehoiada àti àwọn ọmọkùnrin rẹ̀ mú ọmọkùnrin ọba jáde wá wọ́n sì gbé adé sórí rẹ̀; wọ́n mú ẹ̀dà májẹ̀mú kan fún un. Wọ́n sì kéde rẹ̀ lọ́ba. Wọ́n fi àmì òróró yàn án, wọ́n sì kígbe pé, “Kí ọba kí ó pẹ́!”
Ensuite, ils amenèrent le fils du roi, et ils mirent sur lui le diadème et le témoignage; c’est-à-dire ils mirent en sa main la loi pour qu’il la tînt, et l’établirent roi: de plus, Joïada, le pontife, et ses fils l’oignirent, lui souhaitèrent du bien et dirent: Vive le roi!
12 Nígbà tí Ataliah gbọ́ igbe àwọn ènìyàn tí wọ́n ń sáré tí wọ́n ń kígbe ọba, ó lọ sí ọ̀dọ̀ wọn ní ilé Olúwa.
Lorsque Athalie eut entendu cela; savoir, la voix de ceux qui accouraient et louaient le roi, elle entra vers le peuple dans le temple du Seigneur.
13 Ó sì wò, sì kíyèsi, ọba dúró ní ibùdó rẹ̀ ní ẹ̀bá ẹnu-ọ̀nà, àti àwọn balógun àti àwọn afùnpè lọ́dọ̀ ọba, gbogbo àwọn ènìyàn ilẹ̀ náà sì yọ̀, wọ́n sì fọn ìpè, àti àwọn akọrin pẹ̀lú ohun èlò ìyìn. Nígbà náà ni Ataliah fa aṣọ rẹ̀ ya, ó sì kégbe wí pé, “Ọ̀tẹ̀! Ọ̀tẹ̀!”
Et, lorsqu’elle eut vu le roi qui était sur son estrade, à l’entrée, les princes, les troupes autour de lui, tout le peuple de la terre se réjouissant, sonnant des trompettes et faisant retentir des instruments de divers genre, et qu’elle eut entendu la voix de ceux qui louaient le roi, elle déchira ses vêtements, et dit: Trahison! trahison!
14 Jehoiada àlùfáà mú àwọn alákòóso ọ̀rọ̀ọ̀rún, tí ó wà ní àbojútó àwọn ọ̀wọ́ ogun, ó sì wá wí fún wọn pé, “Mú un jáde wá láàrín àwọn ọgbà, kí a sì fi idà pa ẹnikẹ́ni tí ó bá tẹ̀lé.” Nítorí tí àlùfáà ti wí pé, “Má ṣe pa á nínú ilé Olúwa.”
Or le pontife Joïada, étant sorti vers les centurions et les princes de l’armée, leur dit: Emmenez-la hors de l’enceinte du temple, et qu’elle soit tuée dehors par le glaive. Et le prêtre ordonna qu’elle ne fût pas tuée dans la maison du Seigneur.
15 Bẹ́ẹ̀ ni wọ́n fi ipá mú un kí ó tó dé ẹnu-ọ̀nà àbáwọlé ẹṣin ti ilé ọba, wọ́n sì ti pa á níbẹ̀.
Ils mirent donc leurs mains sur son cou; et lorsqu’elle fut entrée dans la porte des chevaux de la maison du roi, ils la tuèrent là.
16 Nígbà náà ni Jehoiada, dá májẹ̀mú pé òun àti àwọn ènìyàn àti ọba yóò jẹ́ ènìyàn Olúwa.
Or Joïada fit une alliance entre lui, tout le peuple et le roi, afin qu’ils fussent le peuple du Seigneur.
17 Gbogbo àwọn ènìyàn lọ sí ilé Baali, wọ́n sì fà á ya lulẹ̀. Wọ́n fọ́ àwọn pẹpẹ àti àwọn òrìṣà, wọ́n sì pa Mattani àlùfáà Baali níwájú àwọn pẹpẹ.
C’est pourquoi tout le peuple entra dans la maison de Baal, et ils la détruisirent; ils brisèrent aussi ses autels et ses simulacres: et Mathan lui-même, le prêtre de Baal, ils le tuèrent devant l’autel.
18 Nígbà náà, Jehoiada tẹ àwòrán ilé Olúwa sí ọwọ́ àwọn àlùfáà tí wọ́n jẹ́ ará Lefi ẹni tí Dafidi ti fi ṣe iṣẹ́ ní ilé Olúwa láti tẹ ẹbọ sísun ti Olúwa bí a ti kọ ọ́ nínú òfin Mose, pẹ̀lú ayọ̀ àti orin kíkọ, gẹ́gẹ́ bí Dafidi ti pàṣẹ.
Joïada établit aussi des préposés dans la maison de Seigneur, sous la main des prêtres et des Lévites, que David distribua dans la maison du Seigneur, afin que l’on offrît des holocaustes au Seigneur, comme il est écrit dans la loi de Moïse, avec joie et avec des cantiques, selon les prescriptions de David.
19 Ó mú àwọn olùṣọ́nà wà ni ipò ìdúró ní ẹnu odi ilé Olúwa kí ẹni aláìmọ́ nínú ohunkóhun kó má ba à wọlé.
Et il établit encore les portiers aux portes de la maison du Seigneur, afin qu’il n’y entrât personne d’impur en quoi que ce fût.
20 Ó mú pẹ̀lú rẹ̀ àwọn alákòóso ọ̀rọ̀ọ̀rún, àwọn ẹni ọlá, àwọn olórí àwọn ènìyàn àti gbogbo àwọn ènìyàn ilẹ̀ náà. Ó sì mú ọba sọ̀kalẹ̀ wá láti ilé Olúwa. Wọ́n lọ sínú ààfin láti ẹnu òde ti òkè. Wọ́n sì fi ọba jókòó lórí ìtẹ́.
Et il prit les centurions, les hommes les plus braves, les princes du peuple, et tout le bas peuple du pays; et ils firent descendre le roi de la maison du Seigneur, puis entrer par la porte supérieure dans la maison du roi; et ils le placèrent sur le trône royal.
21 Gbogbo àwọn ènìyàn ilẹ̀ náà sì yọ̀, ìlú náà sì dákẹ́ rọ́rọ́. Nítorí a pa Ataliah pẹ̀lú idà.
Alors tout le peuple du pays se réjouit, et la ville se reposa: or Athalie fut tuée par le glaive.

< 2 Chronicles 23 >