< 2 Chronicles 23 >

1 Ní ọdún keje, Jehoiada fi agbára rẹ̀ hàn. O dá májẹ̀mú pẹ̀lú àwọn alákòóso ọ̀rọ̀ọ̀rún kan, Asariah ọmọ Jerohamu, Iṣmaeli ọmọ Jehohanani Asariah ọmọ Obedi, Maaseiah ọmọ Adaiah àti Elisafati ọmọ Sikri.
And in the year seventh he strengthened himself Jehoiada and he took [the] commanders of the hundreds to Azariah [the] son of Jeroham and to Ishmael [the] son of Jehohanan and to Azariah [the] son of Obed and with Maaseiah [the] son of Adaiah and with Elishaphat [the] son of Zikri with himself in covenant.
2 Wọ́n lọ sí gbogbo Juda, wọ́n sì pe àwọn ará Lefi àti àwọn olórí àwọn ìdílé àwọn ará Israẹli láti gbogbo àwọn ìlú jọ. Nígbà tí wọ́n wá sí Jerusalẹmu.
And they went around in Judah and they gathered the Levites from all [the] cities of Judah and [the] heads of the fathers of Israel and they came to Jerusalem.
3 Gbogbo ìpéjọ náà dá májẹ̀mú pẹ̀lú ọba ní ilé Ọlọ́run. Jehoiada wí fún wọn pé, “Ọmọkùnrin ọba yóò jẹ ọba, bí Olúwa ti ṣèlérí nípa àwọn ìran Dafidi.
And it made all the assembly a covenant in [the] house of God with the king and he said to them here! [the] son of the king he will reign just as he spoke Yahweh on [the] sons of David.
4 Nísinsin yìí èyí ni ohun tí ó yẹ kí ó ṣe, ìdámẹ́ta àlùfáà yín àti àwọn ará Lefi tí ó ń lọ fún iṣẹ́ ìsìn ní ọjọ́ ìsinmi ni kí ó bojútó àwọn ìlẹ̀kùn.
This [is] the thing which you will do the third [part] of you [who] come of the sabbath to the priests and to the Levites [will become] [the] gatekeepers of the thresholds.
5 Ìdámẹ́ta yín níbi ààfin ọba àti ìdámẹ́ta níbi ẹnu odi ìdásílẹ̀ àti gbogbo ọkùnrin mìíràn ni kí ó wà ní àgbàlá ààfin ilé Olúwa.
And the third [part] [will be] at [the] house of the king and the third [part] [will be] at [the] gate of the foundation and all the people [will be] in [the] courts of [the] house of Yahweh.
6 Kò sí ẹnìkan tí ó gbọdọ̀ wọ inú ilé Olúwa yàtọ̀ sí àwọn àlùfáà àti àwọn ará Lefi tí a rán ní iṣẹ́ ìsìn. Wọ́n lè wọlé nítorí tí a ti yà wọ́n sọ́tọ̀, ṣùgbọ́n gbogbo ọkùnrin mìíràn ni kí wọn ó sọ ohun tí Olúwa ti yàn fún wọn.
And may not anyone go [the] house of Yahweh that except the priests and those [who] are serving of the Levites they they will go for [are] holiness they and all the people they will keep [the] duty of Yahweh.
7 Àwọn ará Lefi gbọdọ̀ wà ní ìdúró ṣinṣin yí ọba ká. Olúkúlùkù pẹ̀lú àwọn nǹkan ìjà ní ọwọ́ rẹ̀. Ẹnikẹ́ni tí ó bá wọ ilé Olúwa ni kí ẹ pa. Ẹ dúró ti ọba níbikíbi tí ó bá lọ.”
And they will surround the Levites the king all around each man and weapons his in hand his and the [one who] comes into the house he will be put to death and be with the king when comes he and when goes out he.
8 Àwọn ará Lefi àti gbogbo ọkùnrin Juda ṣe gẹ́gẹ́ bí Jehoiada àlùfáà ti paláṣẹ. Olúkúlùkù mú àwọn ọkùnrin rẹ̀, àwọn tí wọ́n lọ fún iṣẹ́ ìsìn ní ọjọ́ ìsinmi àti àwọn tí wọ́n ń kúrò ní ibi iṣẹ́. Nítorí Jehoiada àlùfáà kò ì tí tú ìpín kankan sílẹ̀.
And they did the Levites and all Judah according to all that he had commanded Jehoiada the priest and they took each men his [who] were coming of the sabbath with [who] were going out of the sabbath for not he dismissed Jehoiada the priest the divisions.
9 Jehoiada àlùfáà, sì fi ọ̀kọ̀ àti asà, àti àpáta wọ̀n-ọn-nì, tí ó jẹ́ ti ọba Dafidi tí wọn wà ní ilé Ọlọ́run, fún àwọn balógun ọ̀rọ̀ọ̀rún.
And he gave Jehoiada the priest to [the] commanders of the hundreds the spears and the shields and the shields which [had belonged] to the king David which [were] [the] house of God.
10 Ó sì to gbogbo àwọn ènìyàn ti ọba káàkiri, olúkúlùkù pẹ̀lú ohun ìjà rẹ̀ ní ọwọ́ rẹ̀, láti apá ọ̀tún ilé náà títí dé apá òsì ilé náà, lẹ́bàá pẹpẹ àti lẹ́bàá ilé náà.
And he stationed all the people and each - weapon his [was] in hand his from [the] side of the house south to [the] side of the house north to the altar and to the house at the king all around.
11 Jehoiada àti àwọn ọmọkùnrin rẹ̀ mú ọmọkùnrin ọba jáde wá wọ́n sì gbé adé sórí rẹ̀; wọ́n mú ẹ̀dà májẹ̀mú kan fún un. Wọ́n sì kéde rẹ̀ lọ́ba. Wọ́n fi àmì òróró yàn án, wọ́n sì kígbe pé, “Kí ọba kí ó pẹ́!”
And they brought out [the] son of the king and they put on him the crown and the testimony and they made king him and they anointed him Jehoiada and sons his and they said may he live the king.
12 Nígbà tí Ataliah gbọ́ igbe àwọn ènìyàn tí wọ́n ń sáré tí wọ́n ń kígbe ọba, ó lọ sí ọ̀dọ̀ wọn ní ilé Olúwa.
And she heard Athaliah [the] sound of the people who were running and who were praising the king and she came to the people [the] house of Yahweh.
13 Ó sì wò, sì kíyèsi, ọba dúró ní ibùdó rẹ̀ ní ẹ̀bá ẹnu-ọ̀nà, àti àwọn balógun àti àwọn afùnpè lọ́dọ̀ ọba, gbogbo àwọn ènìyàn ilẹ̀ náà sì yọ̀, wọ́n sì fọn ìpè, àti àwọn akọrin pẹ̀lú ohun èlò ìyìn. Nígbà náà ni Ataliah fa aṣọ rẹ̀ ya, ó sì kégbe wí pé, “Ọ̀tẹ̀! Ọ̀tẹ̀!”
And she saw and there! the king [was] standing at pillar his at the entrance and the officials and the trumpets [were] with the king and all [the] people of the land [was] joyful and [was] giving a blast on trumpets and the singers with [the] instruments of song [were] leading to praise and she tore Athaliah clothes her and she said treason treason.
14 Jehoiada àlùfáà mú àwọn alákòóso ọ̀rọ̀ọ̀rún, tí ó wà ní àbojútó àwọn ọ̀wọ́ ogun, ó sì wá wí fún wọn pé, “Mú un jáde wá láàrín àwọn ọgbà, kí a sì fi idà pa ẹnikẹ́ni tí ó bá tẹ̀lé.” Nítorí tí àlùfáà ti wí pé, “Má ṣe pa á nínú ilé Olúwa.”
And he sent out Jehoiada the priest [the] commanders of the hundreds - [the] officers of the army and he said to them bring out her to from between the ranks and the [one who] goes after her he will be put to death with the sword for he had said the priest not you must put to death her [the] house of Yahweh.
15 Bẹ́ẹ̀ ni wọ́n fi ipá mú un kí ó tó dé ẹnu-ọ̀nà àbáwọlé ẹṣin ti ilé ọba, wọ́n sì ti pa á níbẹ̀.
And they put to her hands and she went to [the] entrance of [the] gate of the horses [the] house of the king and they put to death her there.
16 Nígbà náà ni Jehoiada, dá májẹ̀mú pé òun àti àwọn ènìyàn àti ọba yóò jẹ́ ènìyàn Olúwa.
And he made Jehoiada a covenant between himself and between all the people and between the king to become a people of Yahweh.
17 Gbogbo àwọn ènìyàn lọ sí ilé Baali, wọ́n sì fà á ya lulẹ̀. Wọ́n fọ́ àwọn pẹpẹ àti àwọn òrìṣà, wọ́n sì pa Mattani àlùfáà Baali níwájú àwọn pẹpẹ.
And they went all the people [the] house of Baal and they pulled down it and altars its and images its they broke and Mattan [the] priest of Baal they killed before the altars.
18 Nígbà náà, Jehoiada tẹ àwòrán ilé Olúwa sí ọwọ́ àwọn àlùfáà tí wọ́n jẹ́ ará Lefi ẹni tí Dafidi ti fi ṣe iṣẹ́ ní ilé Olúwa láti tẹ ẹbọ sísun ti Olúwa bí a ti kọ ọ́ nínú òfin Mose, pẹ̀lú ayọ̀ àti orin kíkọ, gẹ́gẹ́ bí Dafidi ti pàṣẹ.
And he put Jehoiada [the] oversight of [the] house of Yahweh in [the] hand of the priests the Levites whom he had assigned David over [the] house of Yahweh to offer up [the] burnt offerings of Yahweh according to [what] is written in [the] law of Moses with joy and with song on [the] hands of David.
19 Ó mú àwọn olùṣọ́nà wà ni ipò ìdúró ní ẹnu odi ilé Olúwa kí ẹni aláìmọ́ nínú ohunkóhun kó má ba à wọlé.
And he stationed the gatekeepers at [the] gates of [the] house of Yahweh and not he came a [person] unclean to any matter.
20 Ó mú pẹ̀lú rẹ̀ àwọn alákòóso ọ̀rọ̀ọ̀rún, àwọn ẹni ọlá, àwọn olórí àwọn ènìyàn àti gbogbo àwọn ènìyàn ilẹ̀ náà. Ó sì mú ọba sọ̀kalẹ̀ wá láti ilé Olúwa. Wọ́n lọ sínú ààfin láti ẹnu òde ti òkè. Wọ́n sì fi ọba jókòó lórí ìtẹ́.
And he took [the] commanders of the hundreds and the nobles and the rulers over the people and - all [the] people of the land and he brought down the king from [the] house of Yahweh and they came in [the] middle of [the] gate upper [the] house of the king and they made sit the king on [the] throne of royalty.
21 Gbogbo àwọn ènìyàn ilẹ̀ náà sì yọ̀, ìlú náà sì dákẹ́ rọ́rọ́. Nítorí a pa Ataliah pẹ̀lú idà.
And they rejoiced all [the] people of the land and the city it was at peace and Athaliah they had put to death with the sword.

< 2 Chronicles 23 >