< 2 Chronicles 21 >

1 Nígbà náà Jehoṣafati sùn pẹ̀lú àwọn baba a rẹ̀, a sì sin ín pẹ̀lú wọn ní ìlú ńlá Dafidi. Jehoramu ọmọ rẹ̀ sì rọ́pò rẹ̀ gẹ́gẹ́ bí ọba.
Torej Józafat je zaspal s svojimi očeti in bil s svojimi očeti pokopan v Davidovem mestu. Namesto njega je zakraljeval njegov sin Jehorám.
2 Àwọn arákùnrin Jehoramu ọmọ Jehoṣafati jẹ́ Asariah, Jehieli, Sekariah. Asariahu, Mikaeli àti Ṣefatia. Gbogbo àwọn wọ̀nyí ni àwọn ọmọ Jehoṣafati ọba Israẹli.
Ta je imel brate, Józafatove sinove: Azarjája, Jehiéla, Zeharjája, Azarjája, Mihaela in Šefatjája. Vsi ti so bili sinovi Izraelovega kralja Józafata.
3 Baba wọn ti fún wọn ní ẹ̀bùn púpọ̀ ti fàdákà àti wúrà àti àwọn ohun èlò iyebíye pẹ̀lú àwọn ìlú ààbò ní Juda, ṣùgbọ́n, ó ti gbé ìjọba fún Jehoramu nítorí òun ni àkọ́bí ọmọkùnrin.
Njihov oče jim je dal veliko daril iz srebra in iz zlata in dragocenih stvari, z utrjenimi mesti v Judu, toda kraljestvo je dal Jehorámu, ker je bil prvorojenec.
4 Nígbà tí Jehoramu fi ẹsẹ̀ rẹ̀ múlẹ̀ gidigidi lórí ìjọba baba a rẹ̀, ó sì fi idà pa gbogbo àwọn arákùnrin rẹ̀ pẹ̀lú àwọn ọmọbìnrin ọba Israẹli.
Torej ko je bil Jehorám dvignjen h kraljestvu svojega očeta, se je okrepil in vse svoje brate usmrtil z mečem in tudi številne izmed Izraelovih princev.
5 Jehoramu jẹ́ ẹni ọdún méjìlélọ́gbọ̀n nígbà tí ó di ọba, ó sì jẹ ọba ní Jerusalẹmu fún ọdún mẹ́jọ.
Jehorám je bil star dvaintrideset let, ko je začel kraljevati in v Jeruzalemu je kraljeval osem let.
6 Ó rìn ní ọ̀nà àwọn ọba Israẹli gẹ́gẹ́ bí ìdílé Ahabu ti ṣe, nítorí ó fẹ́ ọmọbìnrin Ahabu. Ó ṣe búburú lójú Olúwa.
Hodil je po poti Izraelovih kraljev, podobno kakor je storila Ahábova hiša, kajti za ženo je imel Ahábovo hčer. Počel je to, kar je bilo zlo v Gospodovih očeh.
7 Bí ó tilẹ̀ rí bẹ́ẹ̀, nítorí tí májẹ̀mú tí Olúwa ti dá fún Dafidi kì í ṣe ìfẹ́ Olúwa láti pa ìdílé Dafidi run ó ti ṣe ìlérí láti tọ́jú fìtílà kan fún un àti àwọn àtẹ̀lé rẹ̀ títí láé.
Vendar Gospod ni hotel uničiti Davidove hiše zaradi zaveze, ki jo je sklenil z Davidom in kakor je obljubil, da da luč njemu in njegovim sinovom na veke.
8 Ní àkókò Jehoramu, Edomu ṣọ̀tẹ̀ sí Juda, wọ́n sì gbé ọba tiwọn kalẹ̀.
V njegovih dneh so se Edómci spuntali izpod Judovega gospostva in si postavili kralja.
9 Bẹ́ẹ̀ ni, Jehoramu lọ síbẹ̀ pẹ̀lú àwọn ìjòyè rẹ̀ àti gbogbo àwọn kẹ̀kẹ́. Àwọn ará Edomu yí i ká àti àwọn alákòóso àwọn kẹ̀kẹ́ rẹ̀. Ṣùgbọ́n ó dìde ní òru ó sì ṣẹ́gun wọn ní òru.
Potem je Jehorám s svojimi princi odšel naprej in vsi njegovi bojni vozovi z njim. Ponoči je vstal in udaril Edomce, ki so obkolili njega in stotnike bojnih vozov.
10 Títí di ọjọ́ òní ni Edomu ti wà ní ìṣọ̀tẹ̀ sí Juda. Libina ṣọ̀tẹ̀ ní àkọ́kọ́ náà, nítorí tí Jehoramu ti kọ Olúwa sílẹ̀, Ọlọ́run àwọn baba a rẹ̀.
Tako so se Edómci spuntali izpod Judove roke do današnjega dne. Isti čas se je tudi Libna spuntala izpod njegove roke, ker je zapustil Gospoda, Boga svojih očetov.
11 Òun pẹ̀lú ti kọ́ àwọn ibi gíga lórí àwọn òkè Juda. Ó sì ti fà á kí àwọn ènìyàn Jerusalẹmu ó ṣe àgbèrè pẹ̀lú ara wọn. Ó sì ti jẹ́ kí wọn ó ṣáko lọ.
Poleg tega je postavil visoke kraje po Judovih gorah in prebivalcem Jeruzalema storil, da zagrešijo prešuštvovanje in k temu zapeljal Juda.
12 Jehoramu gba ìwé láti ọwọ́ Elijah wòlíì, tí ó wí pé, “Èyí ní ohun tí Olúwa, Ọlọ́run baba à rẹ Dafidi wí: ‘Ìwọ kò tí ì rìn ní ọ̀nà àwọn baba à rẹ Jehoṣafati tàbí Asa ọba Juda.
In k njemu je prišlo pisanje preroka Elija, rekoč: ›Tako govori Gospod, Bog tvojega očeta Davida: ›Ker nisi hodil po poteh svojega očeta Józafata niti po poteh Judovega kralja Asája,
13 Ṣùgbọ́n ìwọ ti rìn ní ọ̀nà àwọn ọba Israẹli, ìwọ sì ti tọ́ Juda àti àwọn ènìyàn Jerusalẹmu láti ṣe àgbèrè sí ara wọn, gẹ́gẹ́ bí ilé Ahabu ti ṣe. Ìwọ sì ti pa àwọn arákùnrin rẹ, ẹ̀yà ara ilé baba à rẹ, àwọn ọkùnrin tí ó dára jù ọ́ lọ.
temveč si hodil po poti Izraelovih kraljev in si pripravil Juda in prebivalce Jeruzalema, da se vlačugajo, podobno vlačugarstvom Ahábove hiše in si tudi umoril svoje brate od hiše svojega očeta, ki so bili boljši kakor ti sam.
14 Bẹ́ẹ̀ ni nísinsin yìí, Olúwa ti fẹ́rẹ lu àwọn ènìyàn rẹ, àwọn ọmọ rẹ, àwọn ìyàwó rẹ àti gbogbo ohun tí ó jẹ́ tìrẹ, pẹ̀lú àjàkálẹ̀-ààrùn ńlá.
Glej, z veliko nadlogo bo Gospod udaril tvoje ljudstvo, tvoje otroke, tvoje žene in vse tvoje dobrine,
15 Ìwọ tìkára yóò ṣe àárẹ̀ pẹ̀lú àìsàn lílọ́ra ti ìfun, títí tí àìsàn náà yóò fi jẹ́ kí àwọn ìfun rẹ jáde sí ìta.’”
ti pa boš imel veliko slabost z boleznijo svoje notranjosti, dokler tvoja notranjost ne zleze ven zaradi razloga bolezni dan za dnem.«
16 Olúwa ru ìbínú àwọn ará Filistini àti àwọn Arabia tí wọ́n ń gbé ní ẹ̀bá àwọn ará Kuṣi sí Jehoramu.
Poleg tega je Gospod zoper Jehoráma razvnel duha Filistejcev in Arabcev, ki so bili blizu Etiopijcev.
17 Wọ́n dojú ìjà kọ Juda, wọ́n gbà á, wọ́n sì kó gbogbo ọrọ̀ tí a rí ní ilé ọba pẹ̀lú, àwọn ọmọkùnrin rẹ̀ àti àwọn ọmọkùnrin kankan kò kù sílẹ̀ fún un bí kò ṣe Ahasiah, àbíkẹ́yìn nínú àwọn ọmọ rẹ̀.
Ti so prišli gor v Juda in vdrli vanj in odnesli vse imetje, ki je bilo najdeno v kraljevi hiši in tudi njegove sinove in njegove žene, tako da mu ni ostal sin razen Joaháza, najmlajšega izmed njegovih sinov.
18 Lẹ́yìn gbogbo èyí, Olúwa jẹ Jehoramu ní yà pẹ̀lú ààrùn tí kò ṣe é wòsàn nínú ìfun.
Po vsem tem ga je Gospod udaril v njegovi notranjosti z neozdravljivo boleznijo.
19 Ní àkókò kan ní ìparí ọdún kejì, àwọn ìfun rẹ̀ jáde nítorí ààrùn náà ó sì kú nínú ìrora ńlá. Àwọn ènìyàn rẹ̀ kò dá iná láti fi bu ọlá fún un, gẹ́gẹ́ bí wọ́n ti ṣe fún àwọn baba a rẹ̀.
Pripetilo se je tekom časa, po koncu dveh let, da je njegova notranjost zlezla ven zaradi razloga njegove slabosti. Tako je umrl od hudih bolezni. Njegovo ljudstvo zanj ni naredilo nobenega sežiga [dišav], podobnega sežigu njegovim očetom.
20 Jehoramu jẹ́ ẹni ọdún méjìlélọ́gbọ̀n ní ìgbà tí ó di ọba, Ó sì jẹ ọba ní Jerusalẹmu fún ọdún mẹ́jọ. Ó kọjá lọ, kò sí ẹni tí ó kábámọ̀. A sì sin ín si ìlú ńlá ti Dafidi. Ṣùgbọ́n kì í ṣe nínú ibojì àwọn ọba.
Dvaintrideset let je bil star, ko je začel kraljevati in v Jeruzalemu je kraljeval osem let in odšel, brez da bi ga želeli. Vendar so ga pokopali v Davidovem mestu, toda ne v kraljevih mavzolejih.

< 2 Chronicles 21 >