< 2 Chronicles 21 >

1 Nígbà náà Jehoṣafati sùn pẹ̀lú àwọn baba a rẹ̀, a sì sin ín pẹ̀lú wọn ní ìlú ńlá Dafidi. Jehoramu ọmọ rẹ̀ sì rọ́pò rẹ̀ gẹ́gẹ́ bí ọba.
Și Iosafat a adormit cu părinții săi și a fost îngropat cu părinții săi în cetatea lui David. Și Ioram, fiul său, a domnit în locul său.
2 Àwọn arákùnrin Jehoramu ọmọ Jehoṣafati jẹ́ Asariah, Jehieli, Sekariah. Asariahu, Mikaeli àti Ṣefatia. Gbogbo àwọn wọ̀nyí ni àwọn ọmọ Jehoṣafati ọba Israẹli.
Și a avut frați, pe fiii lui Iosafat: Azaria și Iehiel și Zaharia și Azaria și Mihail și Șefatia, toți aceștia au fost fiii lui Iosafat, împăratul lui Israel.
3 Baba wọn ti fún wọn ní ẹ̀bùn púpọ̀ ti fàdákà àti wúrà àti àwọn ohun èlò iyebíye pẹ̀lú àwọn ìlú ààbò ní Juda, ṣùgbọ́n, ó ti gbé ìjọba fún Jehoramu nítorí òun ni àkọ́bí ọmọkùnrin.
Și tatăl lor le-a dat daruri mari de argint și de aur și de lucruri prețioase, cu cetăți întărite în Iuda, dar împărăția i-a dat-o lui Ioram, deoarece el era întâiul născut.
4 Nígbà tí Jehoramu fi ẹsẹ̀ rẹ̀ múlẹ̀ gidigidi lórí ìjọba baba a rẹ̀, ó sì fi idà pa gbogbo àwọn arákùnrin rẹ̀ pẹ̀lú àwọn ọmọbìnrin ọba Israẹli.
Și când Ioram a fost înălțat la împărăția tatălui său, el s-a întărit și a ucis pe toți frații săi cu sabia și de asemenea pe câțiva dintre prinții lui Israel.
5 Jehoramu jẹ́ ẹni ọdún méjìlélọ́gbọ̀n nígbà tí ó di ọba, ó sì jẹ ọba ní Jerusalẹmu fún ọdún mẹ́jọ.
Ioram era în vârstă de treizeci și doi de ani când a început să domnească și a domnit opt ani în Ierusalim.
6 Ó rìn ní ọ̀nà àwọn ọba Israẹli gẹ́gẹ́ bí ìdílé Ahabu ti ṣe, nítorí ó fẹ́ ọmọbìnrin Ahabu. Ó ṣe búburú lójú Olúwa.
Și a umblat în calea împăraților lui Israel, cum a făcut casa lui Ahab, căci o avea pe fiica lui Ahab de soție; și a lucrat ceea ce era rău în ochii DOMNULUI.
7 Bí ó tilẹ̀ rí bẹ́ẹ̀, nítorí tí májẹ̀mú tí Olúwa ti dá fún Dafidi kì í ṣe ìfẹ́ Olúwa láti pa ìdílé Dafidi run ó ti ṣe ìlérí láti tọ́jú fìtílà kan fún un àti àwọn àtẹ̀lé rẹ̀ títí láé.
Totuși DOMNUL a refuzat să distrugă casa lui David, din cauza legământului pe care l-a făcut cu David și precum a promis să dea o lumină lui și fiilor lui pentru totdeauna.
8 Ní àkókò Jehoramu, Edomu ṣọ̀tẹ̀ sí Juda, wọ́n sì gbé ọba tiwọn kalẹ̀.
În zilele lui, edomiții s-au răzvrătit de sub stăpânirea lui Iuda și și-au pus un împărat peste ei.
9 Bẹ́ẹ̀ ni, Jehoramu lọ síbẹ̀ pẹ̀lú àwọn ìjòyè rẹ̀ àti gbogbo àwọn kẹ̀kẹ́. Àwọn ará Edomu yí i ká àti àwọn alákòóso àwọn kẹ̀kẹ́ rẹ̀. Ṣùgbọ́n ó dìde ní òru ó sì ṣẹ́gun wọn ní òru.
Atunci Ioram a ieșit cu prinții săi și toate carele lui cu el; și s-a ridicat noaptea și a lovit pe edomiții care îl încercuiseră și pe căpeteniile carelor.
10 Títí di ọjọ́ òní ni Edomu ti wà ní ìṣọ̀tẹ̀ sí Juda. Libina ṣọ̀tẹ̀ ní àkọ́kọ́ náà, nítorí tí Jehoramu ti kọ Olúwa sílẹ̀, Ọlọ́run àwọn baba a rẹ̀.
Astfel edomiții s-au răzvrătit de sub mâna lui Iuda până în această zi. În același timp de asemenea Libna s-a răzvrătit de sub mâna lui, pentru că el a părăsit pe DOMNUL Dumnezeul părinților săi.
11 Òun pẹ̀lú ti kọ́ àwọn ibi gíga lórí àwọn òkè Juda. Ó sì ti fà á kí àwọn ènìyàn Jerusalẹmu ó ṣe àgbèrè pẹ̀lú ara wọn. Ó sì ti jẹ́ kí wọn ó ṣáko lọ.
Mai mult, a făcut înălțimi în munții lui Iuda și a făcut pe locuitorii Ierusalimului să curvească și a constrâns și pe Iuda să facă la fel.
12 Jehoramu gba ìwé láti ọwọ́ Elijah wòlíì, tí ó wí pé, “Èyí ní ohun tí Olúwa, Ọlọ́run baba à rẹ Dafidi wí: ‘Ìwọ kò tí ì rìn ní ọ̀nà àwọn baba à rẹ Jehoṣafati tàbí Asa ọba Juda.
Și a venit o scriere la el de la profetul Ilie, spunând: Astfel spune DOMNUL Dumnezeul lui David, tatăl tău: Pentru că nu ai umblat în căile lui Iosafat, tatăl tău, nici în căile lui Asa, împăratul lui Iuda,
13 Ṣùgbọ́n ìwọ ti rìn ní ọ̀nà àwọn ọba Israẹli, ìwọ sì ti tọ́ Juda àti àwọn ènìyàn Jerusalẹmu láti ṣe àgbèrè sí ara wọn, gẹ́gẹ́ bí ilé Ahabu ti ṣe. Ìwọ sì ti pa àwọn arákùnrin rẹ, ẹ̀yà ara ilé baba à rẹ, àwọn ọkùnrin tí ó dára jù ọ́ lọ.
Ci ai umblat în calea împăraților lui Israel și ai făcut pe Iuda și pe locuitorii Ierusalimului să curvească după curviile casei lui Ahab; și de asemenea ai ucis pe frații tăi din casa tatălui tău, care erau mai buni decât tine,
14 Bẹ́ẹ̀ ni nísinsin yìí, Olúwa ti fẹ́rẹ lu àwọn ènìyàn rẹ, àwọn ọmọ rẹ, àwọn ìyàwó rẹ àti gbogbo ohun tí ó jẹ́ tìrẹ, pẹ̀lú àjàkálẹ̀-ààrùn ńlá.
Iată, cu o mare plagă va lovi DOMNUL poporul tău și copiii tăi și soțiile tale și toate bunurile tale;
15 Ìwọ tìkára yóò ṣe àárẹ̀ pẹ̀lú àìsàn lílọ́ra ti ìfun, títí tí àìsàn náà yóò fi jẹ́ kí àwọn ìfun rẹ jáde sí ìta.’”
Și tu vei cădea în boală cumplită, o boală de măruntaie, până când, din cauza bolii, măruntaiele tale vor cădea zi de zi.
16 Olúwa ru ìbínú àwọn ará Filistini àti àwọn Arabia tí wọ́n ń gbé ní ẹ̀bá àwọn ará Kuṣi sí Jehoramu.
Mai mult, DOMNUL a stârnit împotriva lui Ioram, duhul filistenilor și al arabilor, care erau aproape de etiopieni;
17 Wọ́n dojú ìjà kọ Juda, wọ́n gbà á, wọ́n sì kó gbogbo ọrọ̀ tí a rí ní ilé ọba pẹ̀lú, àwọn ọmọkùnrin rẹ̀ àti àwọn ọmọkùnrin kankan kò kù sílẹ̀ fún un bí kò ṣe Ahasiah, àbíkẹ́yìn nínú àwọn ọmọ rẹ̀.
Și s-au urcat în Iuda și au năvălit în ea și au dus toată averea care s-a găsit în casa împăratului și pe fiii lui de asemenea și pe soțiile lui, astfel încât nu i-a fost lăsat niciun fiu, în afară de Ioahaz, cel mai tânăr dintre fiii săi.
18 Lẹ́yìn gbogbo èyí, Olúwa jẹ Jehoramu ní yà pẹ̀lú ààrùn tí kò ṣe é wòsàn nínú ìfun.
Și, după toate acestea, DOMNUL l-a lovit în măruntaiele lui cu o boală fără vindecare.
19 Ní àkókò kan ní ìparí ọdún kejì, àwọn ìfun rẹ̀ jáde nítorí ààrùn náà ó sì kú nínú ìrora ńlá. Àwọn ènìyàn rẹ̀ kò dá iná láti fi bu ọlá fún un, gẹ́gẹ́ bí wọ́n ti ṣe fún àwọn baba a rẹ̀.
Și s-a întâmplat că, după un timp, la sfârșitul a doi ani, măruntaiele lui au căzut din cauza bolii lui, astfel a murit de boli cumplite. Și poporul său nu a făcut ardere pentru el, ca arderea pentru părinții lui.
20 Jehoramu jẹ́ ẹni ọdún méjìlélọ́gbọ̀n ní ìgbà tí ó di ọba, Ó sì jẹ ọba ní Jerusalẹmu fún ọdún mẹ́jọ. Ó kọjá lọ, kò sí ẹni tí ó kábámọ̀. A sì sin ín si ìlú ńlá ti Dafidi. Ṣùgbọ́n kì í ṣe nínú ibojì àwọn ọba.
A fost în vârstă de treizeci și doi de ani când a început să domnească și a domnit în Ierusalim opt ani și a plecat fără să fie dorit. Totuși l-au îngropat în cetatea lui David, dar nu în mormântul împăraților.

< 2 Chronicles 21 >