< 2 Chronicles 21 >
1 Nígbà náà Jehoṣafati sùn pẹ̀lú àwọn baba a rẹ̀, a sì sin ín pẹ̀lú wọn ní ìlú ńlá Dafidi. Jehoramu ọmọ rẹ̀ sì rọ́pò rẹ̀ gẹ́gẹ́ bí ọba.
Un Jehošafats aizmiga pie saviem tēviem un tapa aprakts pie saviem tēviem Dāvida pilī, un viņa dēls Jehorams palika par ķēniņu viņa vietā.
2 Àwọn arákùnrin Jehoramu ọmọ Jehoṣafati jẹ́ Asariah, Jehieli, Sekariah. Asariahu, Mikaeli àti Ṣefatia. Gbogbo àwọn wọ̀nyí ni àwọn ọmọ Jehoṣafati ọba Israẹli.
Un tam bija brāļi, Jehošafata dēli, Azarija un Jeīels un Zaharija un Acarija un Mikaēls un Šefatija, šie visi bija Jehošafata, Israēla ķēniņa, dēli.
3 Baba wọn ti fún wọn ní ẹ̀bùn púpọ̀ ti fàdákà àti wúrà àti àwọn ohun èlò iyebíye pẹ̀lú àwọn ìlú ààbò ní Juda, ṣùgbọ́n, ó ti gbé ìjọba fún Jehoramu nítorí òun ni àkọ́bí ọmọkùnrin.
Un viņu tēvs tiem deva daudz dāvanas, sudrabu un zeltu un dārgas lietas, arī stipras pilsētas Jūdā, bet valstību viņš deva Jehoramam, tāpēc ka tas bija tas pirmdzimtais.
4 Nígbà tí Jehoramu fi ẹsẹ̀ rẹ̀ múlẹ̀ gidigidi lórí ìjọba baba a rẹ̀, ó sì fi idà pa gbogbo àwọn arákùnrin rẹ̀ pẹ̀lú àwọn ọmọbìnrin ọba Israẹli.
Kad nu Jehorams bija nācis pie sava tēva valstības un bija palicis spēcīgs, tad viņš nokāva visus savus brāļus ar zobenu, arī kādus no Israēla lielkungiem.
5 Jehoramu jẹ́ ẹni ọdún méjìlélọ́gbọ̀n nígbà tí ó di ọba, ó sì jẹ ọba ní Jerusalẹmu fún ọdún mẹ́jọ.
Trīsdesmit divi gadus Jehorams bija vecs, kad palika par ķēniņu, un valdīja astoņus gadus Jeruzālemē.
6 Ó rìn ní ọ̀nà àwọn ọba Israẹli gẹ́gẹ́ bí ìdílé Ahabu ti ṣe, nítorí ó fẹ́ ọmọbìnrin Ahabu. Ó ṣe búburú lójú Olúwa.
Un viņš staigāja Israēla ķēniņu ceļos, tā kā Ahaba nams darīja; jo viņam Ahaba meita bija par sievu, un viņš darīja, kas Tam Kungam nepatika.
7 Bí ó tilẹ̀ rí bẹ́ẹ̀, nítorí tí májẹ̀mú tí Olúwa ti dá fún Dafidi kì í ṣe ìfẹ́ Olúwa láti pa ìdílé Dafidi run ó ti ṣe ìlérí láti tọ́jú fìtílà kan fún un àti àwọn àtẹ̀lé rẹ̀ títí láé.
Bet Tas Kungs Dāvida namu negribēja izdeldēt tās derības dēļ, ko viņš bija derējis ar Dāvidu, un ka bija sacījis, viņam un viņa dēliem dot gaišumu mūžīgi.
8 Ní àkókò Jehoramu, Edomu ṣọ̀tẹ̀ sí Juda, wọ́n sì gbé ọba tiwọn kalẹ̀.
Viņa laikā Edomieši atkrita no Jūda valdības un iecēla sev ķēniņu.
9 Bẹ́ẹ̀ ni, Jehoramu lọ síbẹ̀ pẹ̀lú àwọn ìjòyè rẹ̀ àti gbogbo àwọn kẹ̀kẹ́. Àwọn ará Edomu yí i ká àti àwọn alákòóso àwọn kẹ̀kẹ́ rẹ̀. Ṣùgbọ́n ó dìde ní òru ó sì ṣẹ́gun wọn ní òru.
Tādēļ Jehorams cēlās ar saviem virsniekiem un ar visiem saviem ratiem, un nogāja naktī un kāva Edomiešus, kas viņu bija apstājuši, un tos ratu virsniekus.
10 Títí di ọjọ́ òní ni Edomu ti wà ní ìṣọ̀tẹ̀ sí Juda. Libina ṣọ̀tẹ̀ ní àkọ́kọ́ náà, nítorí tí Jehoramu ti kọ Olúwa sílẹ̀, Ọlọ́run àwọn baba a rẹ̀.
Tomēr Edomieši no Jūda valdības atkrita līdz šai dienai. Tai pašā laikā Libna atkrita no viņa valdības; jo viņš To Kungu, savu tēvu Dievu, bija atstājis.
11 Òun pẹ̀lú ti kọ́ àwọn ibi gíga lórí àwọn òkè Juda. Ó sì ti fà á kí àwọn ènìyàn Jerusalẹmu ó ṣe àgbèrè pẹ̀lú ara wọn. Ó sì ti jẹ́ kí wọn ó ṣáko lọ.
Viņš arī cēla altārus Jūda kalnos un darīja, ka Jeruzālemes iedzīvotāji maukoja, un pievīla Jūdu.
12 Jehoramu gba ìwé láti ọwọ́ Elijah wòlíì, tí ó wí pé, “Èyí ní ohun tí Olúwa, Ọlọ́run baba à rẹ Dafidi wí: ‘Ìwọ kò tí ì rìn ní ọ̀nà àwọn baba à rẹ Jehoṣafati tàbí Asa ọba Juda.
Tad grāmata pie tā nāca no pravieša Elijas ar šiem vārdiem: tā saka Tas Kungs, tava tēva Dāvida Dievs: tāpēc ka tu neesi staigājis sava tēva Jehošafata un Asas, Jūda ķēniņa, ceļos,
13 Ṣùgbọ́n ìwọ ti rìn ní ọ̀nà àwọn ọba Israẹli, ìwọ sì ti tọ́ Juda àti àwọn ènìyàn Jerusalẹmu láti ṣe àgbèrè sí ara wọn, gẹ́gẹ́ bí ilé Ahabu ti ṣe. Ìwọ sì ti pa àwọn arákùnrin rẹ, ẹ̀yà ara ilé baba à rẹ, àwọn ọkùnrin tí ó dára jù ọ́ lọ.
Bet esi staigājis Israēla ķēniņu ceļos un esi darījis, ka Jūda un Jeruzālemes iedzīvotāji maukoja pēc Ahaba nama maukošanas, un arī esi nokāvis savus brāļus no sava tēva nama, kas bija labāki nekā tu, -
14 Bẹ́ẹ̀ ni nísinsin yìí, Olúwa ti fẹ́rẹ lu àwọn ènìyàn rẹ, àwọn ọmọ rẹ, àwọn ìyàwó rẹ àti gbogbo ohun tí ó jẹ́ tìrẹ, pẹ̀lú àjàkálẹ̀-ààrùn ńlá.
Redzi, tad Tas Kungs tevi mocīs ar lielu mocību pie taviem ļaudīm, pie taviem bērniem un pie tavām sievām un pie visas tavas mantas.
15 Ìwọ tìkára yóò ṣe àárẹ̀ pẹ̀lú àìsàn lílọ́ra ti ìfun, títí tí àìsàn náà yóò fi jẹ́ kí àwọn ìfun rẹ jáde sí ìta.’”
Un tev uzies liela slimība, ka tavas iekšas sirgs, tiekams tavas iekšas caur šo sērgu ar laiku pavisam izbeigsies.
16 Olúwa ru ìbínú àwọn ará Filistini àti àwọn Arabia tí wọ́n ń gbé ní ẹ̀bá àwọn ará Kuṣi sí Jehoramu.
Un Tas Kungs pamodināja pret Jehoramu Fīlistu un Arābu prātu, kas dzīvo gar Moru zemi.
17 Wọ́n dojú ìjà kọ Juda, wọ́n gbà á, wọ́n sì kó gbogbo ọrọ̀ tí a rí ní ilé ọba pẹ̀lú, àwọn ọmọkùnrin rẹ̀ àti àwọn ọmọkùnrin kankan kò kù sílẹ̀ fún un bí kò ṣe Ahasiah, àbíkẹ́yìn nínú àwọn ọmọ rẹ̀.
Un tie cēlās pret Jūdu un ielauzās un aizveda visu mantu, kas atradās ķēniņa namā, arī viņa bērnus un viņa sievas, tā kā neviens dēls viņam neatlika, kā vien Joakas (Ahazija), viņa jaunākais dēls.
18 Lẹ́yìn gbogbo èyí, Olúwa jẹ Jehoramu ní yà pẹ̀lú ààrùn tí kò ṣe é wòsàn nínú ìfun.
Un pēc visa tā Tas Kungs viņu mocīja viņa iekšās ar tādu sērgu, ko nevarēja dziedināt.
19 Ní àkókò kan ní ìparí ọdún kejì, àwọn ìfun rẹ̀ jáde nítorí ààrùn náà ó sì kú nínú ìrora ńlá. Àwọn ènìyàn rẹ̀ kò dá iná láti fi bu ọlá fún un, gẹ́gẹ́ bí wọ́n ti ṣe fún àwọn baba a rẹ̀.
Tas notika jo dienas jo vairāk, un kad divu gadu laiks bija pagājis, tad viņa iekšas ar to sērgu izbeidzās, ka tas lielās mokās nomira. Un viņa ļaudis par viņu nededzināja tādu dedzināšanu, kā tie bija darījuši viņa tēviem.
20 Jehoramu jẹ́ ẹni ọdún méjìlélọ́gbọ̀n ní ìgbà tí ó di ọba, Ó sì jẹ ọba ní Jerusalẹmu fún ọdún mẹ́jọ. Ó kọjá lọ, kò sí ẹni tí ó kábámọ̀. A sì sin ín si ìlú ńlá ti Dafidi. Ṣùgbọ́n kì í ṣe nínú ibojì àwọn ọba.
Viņš bija trīsdesmit divus gadus vecs, kad palika par ķēniņu, un valdīja astoņus gadus Jeruzālemē, un viņš aizgāja, un nevienam viņa nebija žēl, un to apraka Dāvida pilī, bet ne ķēniņu kapos.