< 2 Chronicles 21 >
1 Nígbà náà Jehoṣafati sùn pẹ̀lú àwọn baba a rẹ̀, a sì sin ín pẹ̀lú wọn ní ìlú ńlá Dafidi. Jehoramu ọmọ rẹ̀ sì rọ́pò rẹ̀ gẹ́gẹ́ bí ọba.
Hagi Jehosafati'a frige'za Deviti rankumapi agehemokizmima asezmante'naza matipi ome asente'naze. Higeno nemofo ne' Jehoramu agri nona erino kinia mani'ne.
2 Àwọn arákùnrin Jehoramu ọmọ Jehoṣafati jẹ́ Asariah, Jehieli, Sekariah. Asariahu, Mikaeli àti Ṣefatia. Gbogbo àwọn wọ̀nyí ni àwọn ọmọ Jehoṣafati ọba Israẹli.
Jehoramu'a Jehosafati mofavregino, 6si'a afu aganahe'mokizmi zamagi'a, Azaria'ma, Jekieli'ma, Zekaraia'ma, Azariahu'ma, Maikoli'ma, Sefataia'e. Ama ana maka Juda vahe kini ne' Jehosafati ne' mofavrerami mani'naze.
3 Baba wọn ti fún wọn ní ẹ̀bùn púpọ̀ ti fàdákà àti wúrà àti àwọn ohun èlò iyebíye pẹ̀lú àwọn ìlú ààbò ní Juda, ṣùgbọ́n, ó ti gbé ìjọba fún Jehoramu nítorí òun ni àkọ́bí ọmọkùnrin.
Hagi nezmafa Jehosafati'a silvama, golima, zago'amo'ma marerisa zantamine, Juda mopafima hanave vihu keginama hugagi'naza rankumataminena refko huno mofavre'zaga'a zami vagare'ne. Hianagi Jehoramuna kini tra'a amigeno kinia mani'ne. Na'ankure agra ese ne' mofavre'a mani'ne.
4 Nígbà tí Jehoramu fi ẹsẹ̀ rẹ̀ múlẹ̀ gidigidi lórí ìjọba baba a rẹ̀, ó sì fi idà pa gbogbo àwọn arákùnrin rẹ̀ pẹ̀lú àwọn ọmọbìnrin ọba Israẹli.
Hagi Jehoramu'ma kini trate'ma umani hankavenetino'a, maka aganahe'ine, mago'a Israeli kva vahetaminena bainati kazinteti zamahe fri vagare'ne.
5 Jehoramu jẹ́ ẹni ọdún méjìlélọ́gbọ̀n nígbà tí ó di ọba, ó sì jẹ ọba ní Jerusalẹmu fún ọdún mẹ́jọ.
Hagi Jehoramu'a, 32'a kafu hu'neno kinia efore hu'neankino, 8'a kafufi Jerusalemi kumatera kinia mani'ne.
6 Ó rìn ní ọ̀nà àwọn ọba Israẹli gẹ́gẹ́ bí ìdílé Ahabu ti ṣe, nítorí ó fẹ́ ọmọbìnrin Ahabu. Ó ṣe búburú lójú Olúwa.
Hagi Jehoramu'a Israeli kini vahe'mo'zama hu'naza zamavu'zmava nezmavaririno Ahapu naga'mo'zama hu'nazankna kumi Ra Anumzamofo avurera hu'ne. Na'ankure agra Ahapu mofa ara eri'neno, Ra Anumzamofo avurera kumi hu'ne.
7 Bí ó tilẹ̀ rí bẹ́ẹ̀, nítorí tí májẹ̀mú tí Olúwa ti dá fún Dafidi kì í ṣe ìfẹ́ Olúwa láti pa ìdílé Dafidi run ó ti ṣe ìlérí láti tọ́jú fìtílà kan fún un àti àwọn àtẹ̀lé rẹ̀ títí láé.
Hianagi Ra Anumzamo'a Deviti nagara zamahe ofri'ne. Na'ankure Agra Deviti'ene huhagerafi huvempage huno kagripinti'ma fore hu anante anante'ma hu'zama vanaza vahe'mo'za tavikna hu'za kinia mani vava hugahaze huno hu'ne.
8 Ní àkókò Jehoramu, Edomu ṣọ̀tẹ̀ sí Juda, wọ́n sì gbé ọba tiwọn kalẹ̀.
Hagi Jehoramu'ma kinima mani'nege'za Idomu vahe'mo'za Juda vahera hahunezmante'za atre'za vu'za zamagrazmi kini ome azeri oti'naze.
9 Bẹ́ẹ̀ ni, Jehoramu lọ síbẹ̀ pẹ̀lú àwọn ìjòyè rẹ̀ àti gbogbo àwọn kẹ̀kẹ́. Àwọn ará Edomu yí i ká àti àwọn alákòóso àwọn kẹ̀kẹ́ rẹ̀. Ṣùgbọ́n ó dìde ní òru ó sì ṣẹ́gun wọn ní òru.
Ana'ma hazageno'a, Jehoramu'a sondia vahete kva vahetamine, karisifima vanoma nehu'za ha'ma hu sondia vahetaminena zamavareno Idomu vu'ne. Anama hige'za kenagera Idomu vahe'mo'zama agri'ene karisifima maniza ha'ma nehaza sondia vahe zmahenaku'ma eme avazagi kaginafinti hahu'za kenageke zamatre'za fre'naze.
10 Títí di ọjọ́ òní ni Edomu ti wà ní ìṣọ̀tẹ̀ sí Juda. Libina ṣọ̀tẹ̀ ní àkọ́kọ́ náà, nítorí tí Jehoramu ti kọ Olúwa sílẹ̀, Ọlọ́run àwọn baba a rẹ̀.
E'ina higeno ananteti agafa hu'za Idomu vahe'mo'za Juda vahera hara renezmante'za, zamagra hankavere oti'naze. E'ina knafinke Libna Jehoramuna hara rente'za agri kvafintira atre'za vu'naze. Na'ankure Jehoramu'a Ra Anumzana zamagehe'i Anumzamofona atreno amefi humi'negu anara hu'ne.
11 Òun pẹ̀lú ti kọ́ àwọn ibi gíga lórí àwọn òkè Juda. Ó sì ti fà á kí àwọn ènìyàn Jerusalẹmu ó ṣe àgbèrè pẹ̀lú ara wọn. Ó sì ti jẹ́ kí wọn ó ṣáko lọ.
Ana nehuno Jehoramu'a Juda mopafima me'nea agonaramimpi havi anumzama mono'ma hunte nontamina kinenteno, Jerusalemi kumate'ma nemaniza vahetmina hige'za havi anumzante monora hunentazageno, agranena Juda vahera zamavare hazagrege'za Ra Anumzamofona atre'za zamefi humi'naze.
12 Jehoramu gba ìwé láti ọwọ́ Elijah wòlíì, tí ó wí pé, “Èyí ní ohun tí Olúwa, Ọlọ́run baba à rẹ Dafidi wí: ‘Ìwọ kò tí ì rìn ní ọ̀nà àwọn baba à rẹ Jehoṣafati tàbí Asa ọba Juda.
Hagi kasnampa ne' Elaija'a mago avona Jehoramuna amanage huno kremi'ne, Ra Anumzana negafa Deviti Anumzamo'a amanage hie, negafa Jehosafetima Juda vahe kini ne' Asa'ma hu'neaza hunka kagra Ra Anumzamofona amagera ontananki,
13 Ṣùgbọ́n ìwọ ti rìn ní ọ̀nà àwọn ọba Israẹli, ìwọ sì ti tọ́ Juda àti àwọn ènìyàn Jerusalẹmu láti ṣe àgbèrè sí ara wọn, gẹ́gẹ́ bí ilé Ahabu ti ṣe. Ìwọ sì ti pa àwọn arákùnrin rẹ, ẹ̀yà ara ilé baba à rẹ, àwọn ọkùnrin tí ó dára jù ọ́ lọ.
Israeli kini vahe'mo'zama hu'nazaza hunka Juda vahe'ene Jerusalemi kumapima nemaniza vahe'mokizmia antahintahi zaminke'za, Ahapu nagamofo avu'avaza avaririza monko a'nemo'zama nehazaza hu'za havi anumzantera monora hunentaze. Ana nehunka kagri'ma kagatere'za soe'ma hu'naza kaganahe'inena zamahe fri vagare'nane.
14 Bẹ́ẹ̀ ni nísinsin yìí, Olúwa ti fẹ́rẹ lu àwọn ènìyàn rẹ, àwọn ọmọ rẹ, àwọn ìyàwó rẹ àti gbogbo ohun tí ó jẹ́ tìrẹ, pẹ̀lú àjàkálẹ̀-ààrùn ńlá.
E'ina hu'nanku ko, vaheka'ane, mofavre'raminka'ane, a'neka'ane, maka feno zanka'anena Ra Anumzamo'a eri haviza hugahie.
15 Ìwọ tìkára yóò ṣe àárẹ̀ pẹ̀lú àìsàn lílọ́ra ti ìfun, títí tí àìsàn náà yóò fi jẹ́ kí àwọn ìfun rẹ jáde sí ìta.’”
Ana'ma hanigenka kagra kefo kri erigahanankino, krimpamo'a kata negrinigeno uravemo'a akoheno kasonepena krimpamo'a fragu vaziramina katagu nehunka frigahane.
16 Olúwa ru ìbínú àwọn ará Filistini àti àwọn Arabia tí wọ́n ń gbé ní ẹ̀bá àwọn ará Kuṣi sí Jehoramu.
Hagi Filistia vahe'ene, Itiopia vahe tva'onte'ma nemaniza Arapu vahe'enena Ra Anumzamo'a zamarimpa zamazeri otige'za, Jehoramuna ha' rente'naze.
17 Wọ́n dojú ìjà kọ Juda, wọ́n gbà á, wọ́n sì kó gbogbo ọrọ̀ tí a rí ní ilé ọba pẹ̀lú, àwọn ọmọkùnrin rẹ̀ àti àwọn ọmọkùnrin kankan kò kù sílẹ̀ fún un bí kò ṣe Ahasiah, àbíkẹ́yìn nínú àwọn ọmọ rẹ̀.
Ana nehu'za Juda vahera ha' eme huzmante'za maka kini ne'mofo nompima me'nea fenoramina e'neri'za, ne' mofavre'ramima'ane, a'ne'anena zamavare hana nehu'za, amitena ne'a (Jehoa'asi) Ahazianke atre'naze.
18 Lẹ́yìn gbogbo èyí, Olúwa jẹ Jehoramu ní yà pẹ̀lú ààrùn tí kò ṣe é wòsàn nínú ìfun.
Ana'ma huteno'a, Ra Anumzamo'a Jehoramuna rimpafi krima ami'neana tusagino azeri onkanamre kri ami'ne.
19 Ní àkókò kan ní ìparí ọdún kejì, àwọn ìfun rẹ̀ jáde nítorí ààrùn náà ó sì kú nínú ìrora ńlá. Àwọn ènìyàn rẹ̀ kò dá iná láti fi bu ọlá fún un, gẹ́gẹ́ bí wọ́n ti ṣe fún àwọn baba a rẹ̀.
Hagi Jehoramu'a tare kafu anankrifina manigeno, uravemo'a tagatiramigeno tusi atagu nehuno fri'ne. Hagi afahe'zama nefrizage'za antahizamiza tevema hunegrazaza hu'za, agrama frige'za naga'amo'za tevea huonkre'naze.
20 Jehoramu jẹ́ ẹni ọdún méjìlélọ́gbọ̀n ní ìgbà tí ó di ọba, Ó sì jẹ ọba ní Jerusalẹmu fún ọdún mẹ́jọ. Ó kọjá lọ, kò sí ẹni tí ó kábámọ̀. A sì sin ín si ìlú ńlá ti Dafidi. Ṣùgbọ́n kì í ṣe nínú ibojì àwọn ọba.
Jehoramu'a 32'a kafu huteno, kini efore huno Jerusalemi kumatera 8'a kafu kinia maniteno fri'neanagi, vahe'mo'za zavira nete'za zamasunkura huonte'naze. Hagi anama hige'za kini vahe'ma Deviti kumapima asemanezmantazafi aseote'nazanki, rurega asente'naze.