< 2 Chronicles 21 >

1 Nígbà náà Jehoṣafati sùn pẹ̀lú àwọn baba a rẹ̀, a sì sin ín pẹ̀lú wọn ní ìlú ńlá Dafidi. Jehoramu ọmọ rẹ̀ sì rọ́pò rẹ̀ gẹ́gẹ́ bí ọba.
Pimmusay ni Jehosafat ket naitabon isuna iti siudad ni David; ni Jehoram a putotna a lalaki ti naisaad nga ari a kasukatna.
2 Àwọn arákùnrin Jehoramu ọmọ Jehoṣafati jẹ́ Asariah, Jehieli, Sekariah. Asariahu, Mikaeli àti Ṣefatia. Gbogbo àwọn wọ̀nyí ni àwọn ọmọ Jehoṣafati ọba Israẹli.
Adda lallaki a kakabsat ni Jehoram a putot a lalaki ni Jehosafat: da Azarias, Jehiel, Zacarias, Azarias, Michael, ken ni Sefatias. Amin dagitoy ket putot a lallaki ni Jehosafat nga ari ti Israel.
3 Baba wọn ti fún wọn ní ẹ̀bùn púpọ̀ ti fàdákà àti wúrà àti àwọn ohun èlò iyebíye pẹ̀lú àwọn ìlú ààbò ní Juda, ṣùgbọ́n, ó ti gbé ìjọba fún Jehoramu nítorí òun ni àkọ́bí ọmọkùnrin.
Inikkan ida ti amada iti adu a sagsagut a pirak, balitok, ken dadduma pay a napapateg a banbanag, ken kasta met kadagiti nasarikedkedan a siudad idiay Juda; nupay kasta, intedna ti trono kenni Jehoram, gapu ta isuna ti inauna a putotna a lalaki.
4 Nígbà tí Jehoramu fi ẹsẹ̀ rẹ̀ múlẹ̀ gidigidi lórí ìjọba baba a rẹ̀, ó sì fi idà pa gbogbo àwọn arákùnrin rẹ̀ pẹ̀lú àwọn ọmọbìnrin ọba Israẹli.
Ita, idi naan-anayen ti panagturay ni Jehoram iti pagarian ti amana ken natalgeden ti pannakaisaadna nga ari, pinapatayna dagiti amin a kakabsatna a lallaki babaen iti kampilan, ken kasta met dagiti dadduma a mangidadaulo iti Israel.
5 Jehoramu jẹ́ ẹni ọdún méjìlélọ́gbọ̀n nígbà tí ó di ọba, ó sì jẹ ọba ní Jerusalẹmu fún ọdún mẹ́jọ.
Tallo-pulo ket dua ti tawen ni Jehoram idi nangrugi isuna a nagturay, ket nagturay isuna iti walo a tawen idiay Jerusalem.
6 Ó rìn ní ọ̀nà àwọn ọba Israẹli gẹ́gẹ́ bí ìdílé Ahabu ti ṣe, nítorí ó fẹ́ ọmọbìnrin Ahabu. Ó ṣe búburú lójú Olúwa.
Sinurotna dagiti wagas dagiti ari ti Israel, a kasla iti inar-aramid ti balay ni Ahab; ta inasawana ti putot a babai ni Ahab; ket inaramidna dagiti dakes iti imatang ni Yahweh.
7 Bí ó tilẹ̀ rí bẹ́ẹ̀, nítorí tí májẹ̀mú tí Olúwa ti dá fún Dafidi kì í ṣe ìfẹ́ Olúwa láti pa ìdílé Dafidi run ó ti ṣe ìlérí láti tọ́jú fìtílà kan fún un àti àwọn àtẹ̀lé rẹ̀ títí láé.
Nupay kasta, saan a kinayat ni Yahweh a dadaelen ti balay ni David, gapu iti tulagda kenni David; inkarina a dagiti kaputotan ni David ti kanayon nga agturay iti Juda.
8 Ní àkókò Jehoramu, Edomu ṣọ̀tẹ̀ sí Juda, wọ́n sì gbé ọba tiwọn kalẹ̀.
Kadagiti aldaw ni Jehoram, immalsa ti Edom a maibusor iti panagturay ti Juda, ket nangisaadda iti ari a mangituray kadakuada.
9 Bẹ́ẹ̀ ni, Jehoramu lọ síbẹ̀ pẹ̀lú àwọn ìjòyè rẹ̀ àti gbogbo àwọn kẹ̀kẹ́. Àwọn ará Edomu yí i ká àti àwọn alákòóso àwọn kẹ̀kẹ́ rẹ̀. Ṣùgbọ́n ó dìde ní òru ó sì ṣẹ́gun wọn ní òru.
Ket bimmallasiw ni Jehoram iti beddeng ket napan idiay Edom a kadduana dagiti mangidadaulo ken amin a karwahena. Nagriing isuna iti rabii ket rinautna dagiti taga-Edom, a nanglawlaw kenkuana ken kadagiti mangidadaulo kadagiti karwahe.
10 Títí di ọjọ́ òní ni Edomu ti wà ní ìṣọ̀tẹ̀ sí Juda. Libina ṣọ̀tẹ̀ ní àkọ́kọ́ náà, nítorí tí Jehoramu ti kọ Olúwa sílẹ̀, Ọlọ́run àwọn baba a rẹ̀.
Immalsa ngarud ti Edom a maibusor iti panagturay ti Juda agingga kadagitoy nga aldaw. Immalsa met ti Libna iti dayta met laeng a tiempo a maibusor iti panangiturayna, gapu ta tinallikudan ni Jehoram ni Yahweh, a Dios dagiti kapuonanna.
11 Òun pẹ̀lú ti kọ́ àwọn ibi gíga lórí àwọn òkè Juda. Ó sì ti fà á kí àwọn ènìyàn Jerusalẹmu ó ṣe àgbèrè pẹ̀lú ara wọn. Ó sì ti jẹ́ kí wọn ó ṣáko lọ.
Malaksid kadagitoy, nangipatakder pay ni Jehoram kadagiti pagdaydayawan kadagiti bantay ti Juda; insungsongna dagiti agnanaed iti Jerusalem a tallikudanda ni Yahweh ket agserbida kadagiti didiosen, a kas iti panagserbi dagiti balangkantis kadagiti lallaki a saanda nga asawa. Iti kastoy a wagas, insungsongna ti Juda a saanen a sumurot kenni Yahweh.
12 Jehoramu gba ìwé láti ọwọ́ Elijah wòlíì, tí ó wí pé, “Èyí ní ohun tí Olúwa, Ọlọ́run baba à rẹ Dafidi wí: ‘Ìwọ kò tí ì rìn ní ọ̀nà àwọn baba à rẹ Jehoṣafati tàbí Asa ọba Juda.
Maysa a surat manipud kenni profeta Elias ti nakadanon kenni Jehoram. Kastoy ti kunana, “Kastoy ti kuna ni Yahweh, a Dios ni David, a kapuonam: Gapu ta saanmo a sinurot dagiti wagas ni Jehosafat nga amam, wenno dagiti wagas ni Asa nga ari ti Juda,
13 Ṣùgbọ́n ìwọ ti rìn ní ọ̀nà àwọn ọba Israẹli, ìwọ sì ti tọ́ Juda àti àwọn ènìyàn Jerusalẹmu láti ṣe àgbèrè sí ara wọn, gẹ́gẹ́ bí ilé Ahabu ti ṣe. Ìwọ sì ti pa àwọn arákùnrin rẹ, ẹ̀yà ara ilé baba à rẹ, àwọn ọkùnrin tí ó dára jù ọ́ lọ.
ngem ketdi dagiti wagas dagiti ari ti Israel ti sinurotmo, ken insungsongmo ti Juda ken dagiti agnanaed iti Jerusalem a tallikudanda ni Yahweh ket agserbida kadagiti didiosen, a kas iti panagserbi dagiti balangkantis kadagiti lallaki a saanda nga asawa, a kas iti inaramid ti balay ni Ahab-ken gapu ta pinapataymo met dagiti kakabsatmo a lallaki iti pamilia ti amam babaen iti kampilan, lallaki a nasaysayaat ngem sika-
14 Bẹ́ẹ̀ ni nísinsin yìí, Olúwa ti fẹ́rẹ lu àwọn ènìyàn rẹ, àwọn ọmọ rẹ, àwọn ìyàwó rẹ àti gbogbo ohun tí ó jẹ́ tìrẹ, pẹ̀lú àjàkálẹ̀-ààrùn ńlá.
kitaem, saplitento ni Yahweh iti nakaro a didigra dagiti tattaom, annakmo, assawam, ken dagiti amin a kinabaknangmo.
15 Ìwọ tìkára yóò ṣe àárẹ̀ pẹ̀lú àìsàn lílọ́ra ti ìfun, títí tí àìsàn náà yóò fi jẹ́ kí àwọn ìfun rẹ jáde sí ìta.’”
Sika a mismo ket agsakitto iti nakaro gapu ta kaptento iti sakit dagiti bagismo, agingga a rummuar dagiti bagismo gapu iti sakit, iti inaldaw.”
16 Olúwa ru ìbínú àwọn ará Filistini àti àwọn Arabia tí wọ́n ń gbé ní ẹ̀bá àwọn ará Kuṣi sí Jehoramu.
Pinagpungtot iti kasta unay ni Yahweh a maibusor kenni Jehoram dagiti Filisteo ken dagiti taga-Arab nga asideg kadagiti taga-Etiopia.
17 Wọ́n dojú ìjà kọ Juda, wọ́n gbà á, wọ́n sì kó gbogbo ọrọ̀ tí a rí ní ilé ọba pẹ̀lú, àwọn ọmọkùnrin rẹ̀ àti àwọn ọmọkùnrin kankan kò kù sílẹ̀ fún un bí kò ṣe Ahasiah, àbíkẹ́yìn nínú àwọn ọmọ rẹ̀.
Rinautda ti Juda, sinakupda daytoy, ket sinamsamda dagiti amin a kinabaknang a nasarakanda iti balay ti ari. Impanawda pay dagiti annakna a lallaki ken dagiti assawana. Awan nabati kenkuana a putotna a lalaki malaksid kenni Jehoiahas, a buridek a putotna a lalaki.
18 Lẹ́yìn gbogbo èyí, Olúwa jẹ Jehoramu ní yà pẹ̀lú ààrùn tí kò ṣe é wòsàn nínú ìfun.
Kalpasan amin dagitoy, pinagsakit ni Yahweh dagiti bagisna iti sakit a saan a maagasan.
19 Ní àkókò kan ní ìparí ọdún kejì, àwọn ìfun rẹ̀ jáde nítorí ààrùn náà ó sì kú nínú ìrora ńlá. Àwọn ènìyàn rẹ̀ kò dá iná láti fi bu ọlá fún un, gẹ́gẹ́ bí wọ́n ti ṣe fún àwọn baba a rẹ̀.
Napasamak daytoy iti umno a tiempo, kalpasan iti dua a tawen, rimmuar dagiti bagisna gapu iti sakitna, ket natay isuna gapu iti nakaro a sakit. Saan a nangpasged iti apuy dagiti tattaona a kas panangipakita iti panagraemda kenkuana a kas iti inaramidda kadagiti kapuonananna.
20 Jehoramu jẹ́ ẹni ọdún méjìlélọ́gbọ̀n ní ìgbà tí ó di ọba, Ó sì jẹ ọba ní Jerusalẹmu fún ọdún mẹ́jọ. Ó kọjá lọ, kò sí ẹni tí ó kábámọ̀. A sì sin ín si ìlú ńlá ti Dafidi. Ṣùgbọ́n kì í ṣe nínú ibojì àwọn ọba.
Nangrugi isuna a nagturay idi 32 ti tawenna; nagturay isuna idiay Jerusalem iti 8 a tawen, ket natay a saan a nadung-awan. Intabonda isuna iti siudad ni David, ngem saan nga iti tanem dagiti ari.

< 2 Chronicles 21 >