< 2 Chronicles 21 >

1 Nígbà náà Jehoṣafati sùn pẹ̀lú àwọn baba a rẹ̀, a sì sin ín pẹ̀lú wọn ní ìlú ńlá Dafidi. Jehoramu ọmọ rẹ̀ sì rọ́pò rẹ̀ gẹ́gẹ́ bí ọba.
És feküdt Jehósáfát ősei mellé és eltemették ősei mellé Dávid városában; és király lett helyette fia, Jehórám.
2 Àwọn arákùnrin Jehoramu ọmọ Jehoṣafati jẹ́ Asariah, Jehieli, Sekariah. Asariahu, Mikaeli àti Ṣefatia. Gbogbo àwọn wọ̀nyí ni àwọn ọmọ Jehoṣafati ọba Israẹli.
Neki voltak testvérei, Jehósáfát fiai: Azarja, Jechíél, Zekharjáhú, Azarjáhú, Mikháél és Sefatjáhú; mindezek Jehósáfátnak, Izrael királyának fiai.
3 Baba wọn ti fún wọn ní ẹ̀bùn púpọ̀ ti fàdákà àti wúrà àti àwọn ohun èlò iyebíye pẹ̀lú àwọn ìlú ààbò ní Juda, ṣùgbọ́n, ó ti gbé ìjọba fún Jehoramu nítorí òun ni àkọ́bí ọmọkùnrin.
És adott nekik atyjuk sok ajándékot, ezüstből, aranyból s drágaságokból, Jehúdában levő erősített városokkal együtt; a királyságot pedig átadta Jehórámnak, mert ő volt az elsőszülött.
4 Nígbà tí Jehoramu fi ẹsẹ̀ rẹ̀ múlẹ̀ gidigidi lórí ìjọba baba a rẹ̀, ó sì fi idà pa gbogbo àwọn arákùnrin rẹ̀ pẹ̀lú àwọn ọmọbìnrin ọba Israẹli.
Midőn Jehórám támadt atyja királysága fölött s megerősödött, akkor megölte mind a testvéreit karddal, és Izrael nagyjai közül is.
5 Jehoramu jẹ́ ẹni ọdún méjìlélọ́gbọ̀n nígbà tí ó di ọba, ó sì jẹ ọba ní Jerusalẹmu fún ọdún mẹ́jọ.
Harminckét éves volt Jehórám, midőn királlyá lett és nyolc évig uralkodott Jeruzsálemben.
6 Ó rìn ní ọ̀nà àwọn ọba Israẹli gẹ́gẹ́ bí ìdílé Ahabu ti ṣe, nítorí ó fẹ́ ọmọbìnrin Ahabu. Ó ṣe búburú lójú Olúwa.
És járt Izrael királyainak útján, amint cselekedtek az Acháb házából valók, mert Achábnak leányát vette feleségül; tette azt, ami rossz az Örökkévaló szemeiben.
7 Bí ó tilẹ̀ rí bẹ́ẹ̀, nítorí tí májẹ̀mú tí Olúwa ti dá fún Dafidi kì í ṣe ìfẹ́ Olúwa láti pa ìdílé Dafidi run ó ti ṣe ìlérí láti tọ́jú fìtílà kan fún un àti àwọn àtẹ̀lé rẹ̀ títí láé.
De nem akarta az Örökkévaló elpusztítani Dávid házát a szövetség kedvéért, amelyet Dáviddal kötött, s amint mondta, hogy ad mécsest neki a fiainak minden időben.
8 Ní àkókò Jehoramu, Edomu ṣọ̀tẹ̀ sí Juda, wọ́n sì gbé ọba tiwọn kalẹ̀.
Az ő napjaiban pártolt el Edóm Jehúda keze alól, és tettek maguk fölé királyt.
9 Bẹ́ẹ̀ ni, Jehoramu lọ síbẹ̀ pẹ̀lú àwọn ìjòyè rẹ̀ àti gbogbo àwọn kẹ̀kẹ́. Àwọn ará Edomu yí i ká àti àwọn alákòóso àwọn kẹ̀kẹ́ rẹ̀. Ṣùgbọ́n ó dìde ní òru ó sì ṣẹ́gun wọn ní òru.
Ekkor vonult Jehórám a vezéreivel és az egész szekérhaddal ővele; s ő felkelt éjjel s megverte Edómot, amely körülvette őt és a szekérhad vezéreit.
10 Títí di ọjọ́ òní ni Edomu ti wà ní ìṣọ̀tẹ̀ sí Juda. Libina ṣọ̀tẹ̀ ní àkọ́kọ́ náà, nítorí tí Jehoramu ti kọ Olúwa sílẹ̀, Ọlọ́run àwọn baba a rẹ̀.
Így elpártolt Edóm Jehúda keze alól mind e mai napig; akkor pártolt el Libna abban az időben keze alól, mert elhagyta az Örökkévalót, ősei Istenét.
11 Òun pẹ̀lú ti kọ́ àwọn ibi gíga lórí àwọn òkè Juda. Ó sì ti fà á kí àwọn ènìyàn Jerusalẹmu ó ṣe àgbèrè pẹ̀lú ara wọn. Ó sì ti jẹ́ kí wọn ó ṣáko lọ.
Ő is készített magaslatokat Jehúda hegyein és paráznaságra vitte Jeruzsálem lakóit és eltántorította Jehúdát.
12 Jehoramu gba ìwé láti ọwọ́ Elijah wòlíì, tí ó wí pé, “Èyí ní ohun tí Olúwa, Ọlọ́run baba à rẹ Dafidi wí: ‘Ìwọ kò tí ì rìn ní ọ̀nà àwọn baba à rẹ Jehoṣafati tàbí Asa ọba Juda.
És eljutott hozzá egy írás Élijáhú prófétától, mondván: Így szól az Örökkévaló, ősödnek Dávidnak Istene: mivelhogy nem jártál atyádnak Jehósáfátnak útjain és Ászának, Jehúda királyának útjain,
13 Ṣùgbọ́n ìwọ ti rìn ní ọ̀nà àwọn ọba Israẹli, ìwọ sì ti tọ́ Juda àti àwọn ènìyàn Jerusalẹmu láti ṣe àgbèrè sí ara wọn, gẹ́gẹ́ bí ilé Ahabu ti ṣe. Ìwọ sì ti pa àwọn arákùnrin rẹ, ẹ̀yà ara ilé baba à rẹ, àwọn ọkùnrin tí ó dára jù ọ́ lọ.
hanem jártál Izrael királyainak útján és paráznaságra vitted Jehúdát meg Jeruzsálem lakóit, amint paráznaságot okozott Acháb háza, s testvéreidet is, atyád házát, akik jobbak nálad, megölted:
14 Bẹ́ẹ̀ ni nísinsin yìí, Olúwa ti fẹ́rẹ lu àwọn ènìyàn rẹ, àwọn ọmọ rẹ, àwọn ìyàwó rẹ àti gbogbo ohun tí ó jẹ́ tìrẹ, pẹ̀lú àjàkálẹ̀-ààrùn ńlá.
íme az Örökkévaló sújtja népedet nagy csapással, meg fiaidat és feleségeidet s egész vagyonodat.
15 Ìwọ tìkára yóò ṣe àárẹ̀ pẹ̀lú àìsàn lílọ́ra ti ìfun, títí tí àìsàn náà yóò fi jẹ́ kí àwọn ìfun rẹ jáde sí ìta.’”
Te pedig sokféle betegségben leszel, beleidnek betegségében, mígnem beleid kimennek a betegség által napokon és napokon át.
16 Olúwa ru ìbínú àwọn ará Filistini àti àwọn Arabia tí wọ́n ń gbé ní ẹ̀bá àwọn ará Kuṣi sí Jehoramu.
És fölébresztette az Örökkévaló Jehórám ellen a filiszteusok és az arabok szellemét, akik a Kúsbeliek oldalán laktak.
17 Wọ́n dojú ìjà kọ Juda, wọ́n gbà á, wọ́n sì kó gbogbo ọrọ̀ tí a rí ní ilé ọba pẹ̀lú, àwọn ọmọkùnrin rẹ̀ àti àwọn ọmọkùnrin kankan kò kù sílẹ̀ fún un bí kò ṣe Ahasiah, àbíkẹ́yìn nínú àwọn ọmọ rẹ̀.
És fölvonultak Jehúdába és elfoglalták azt és fogságba vitték az egész vagyont, amely a király házában találtatott, meg fiait s feleségeit is; és nem maradt meg neki fia, csakis Jehóácház, fiainak legkisebbje.
18 Lẹ́yìn gbogbo èyí, Olúwa jẹ Jehoramu ní yà pẹ̀lú ààrùn tí kò ṣe é wòsàn nínú ìfun.
És mindezután sújtotta őt az Örökkévaló belein betegséggel gyógyíthatatlanul.
19 Ní àkókò kan ní ìparí ọdún kejì, àwọn ìfun rẹ̀ jáde nítorí ààrùn náà ó sì kú nínú ìrora ńlá. Àwọn ènìyàn rẹ̀ kò dá iná láti fi bu ọlá fún un, gẹ́gẹ́ bí wọ́n ti ṣe fún àwọn baba a rẹ̀.
És volt napok és napok múlva, midőn két év múlva lejárt a vég, kimentek belei betegsége közben s meghalt kínos betegségekben; és nem rendezett számára a népe máglyaégetést, őseinek máglyaégetése módjára.
20 Jehoramu jẹ́ ẹni ọdún méjìlélọ́gbọ̀n ní ìgbà tí ó di ọba, Ó sì jẹ ọba ní Jerusalẹmu fún ọdún mẹ́jọ. Ó kọjá lọ, kò sí ẹni tí ó kábámọ̀. A sì sin ín si ìlú ńlá ti Dafidi. Ṣùgbọ́n kì í ṣe nínú ibojì àwọn ọba.
Harminckét éves volt, midőn királlyá lett s nyolc évig uralkodott Jeruzsálemben; és ment kedveltetés nélkül, s eltemették őt Dávid városában, de nem a királyok sírjaiban.

< 2 Chronicles 21 >