< 2 Chronicles 21 >

1 Nígbà náà Jehoṣafati sùn pẹ̀lú àwọn baba a rẹ̀, a sì sin ín pẹ̀lú wọn ní ìlú ńlá Dafidi. Jehoramu ọmọ rẹ̀ sì rọ́pò rẹ̀ gẹ́gẹ́ bí ọba.
Forsothe Josaphat slepte with hise fadris, and was biried with hem in the citee of Dauid; and Joram, his sone, regnede for hym.
2 Àwọn arákùnrin Jehoramu ọmọ Jehoṣafati jẹ́ Asariah, Jehieli, Sekariah. Asariahu, Mikaeli àti Ṣefatia. Gbogbo àwọn wọ̀nyí ni àwọn ọmọ Jehoṣafati ọba Israẹli.
And he hadde britheren, the sones of Josaphat, Azarie, Jahiel, and Zacarie, Anany, and Mychael, and Saphatie; alle these weren the sones of Josaphat, kyng of Juda.
3 Baba wọn ti fún wọn ní ẹ̀bùn púpọ̀ ti fàdákà àti wúrà àti àwọn ohun èlò iyebíye pẹ̀lú àwọn ìlú ààbò ní Juda, ṣùgbọ́n, ó ti gbé ìjọba fún Jehoramu nítorí òun ni àkọ́bí ọmọkùnrin.
And her fadir yaf to hem many yiftis of gold and of siluer, and rentis, with strongeste citees in Juda; but he yaf the rewme to Joram, for he was the firste gendrid.
4 Nígbà tí Jehoramu fi ẹsẹ̀ rẹ̀ múlẹ̀ gidigidi lórí ìjọba baba a rẹ̀, ó sì fi idà pa gbogbo àwọn arákùnrin rẹ̀ pẹ̀lú àwọn ọmọbìnrin ọba Israẹli.
Forsothe Joram roos on the rewme of his fadir; and whanne he hadde confermyd hym silf, he killide alle hise britheren bi swerd, and summe of the princes of Juda.
5 Jehoramu jẹ́ ẹni ọdún méjìlélọ́gbọ̀n nígbà tí ó di ọba, ó sì jẹ ọba ní Jerusalẹmu fún ọdún mẹ́jọ.
Joram was of two and thritti yeer, whanne he bigan to regne; and he regnede eiyte yeer in Jerusalem.
6 Ó rìn ní ọ̀nà àwọn ọba Israẹli gẹ́gẹ́ bí ìdílé Ahabu ti ṣe, nítorí ó fẹ́ ọmọbìnrin Ahabu. Ó ṣe búburú lójú Olúwa.
And he yede in the weies of the kyngis of Israel, as the hows of Achab hadde do, for the douyter of Achab was his wijf; and he dide yuel in the siyt of the Lord.
7 Bí ó tilẹ̀ rí bẹ́ẹ̀, nítorí tí májẹ̀mú tí Olúwa ti dá fún Dafidi kì í ṣe ìfẹ́ Olúwa láti pa ìdílé Dafidi run ó ti ṣe ìlérí láti tọ́jú fìtílà kan fún un àti àwọn àtẹ̀lé rẹ̀ títí láé.
But the Lord nolde distrie the hows of Dauid, for the couenaunt which he `hadde maad with Dauid, and for he `hadde bihiyte to yyue to hym a lanterne, and to hise sones in al tyme.
8 Ní àkókò Jehoramu, Edomu ṣọ̀tẹ̀ sí Juda, wọ́n sì gbé ọba tiwọn kalẹ̀.
In tho daies Edom rebellide, that it was not suget to Juda, and it ordeynede a kyng to it silf.
9 Bẹ́ẹ̀ ni, Jehoramu lọ síbẹ̀ pẹ̀lú àwọn ìjòyè rẹ̀ àti gbogbo àwọn kẹ̀kẹ́. Àwọn ará Edomu yí i ká àti àwọn alákòóso àwọn kẹ̀kẹ́ rẹ̀. Ṣùgbọ́n ó dìde ní òru ó sì ṣẹ́gun wọn ní òru.
And whanne Joram hadde passide with hise princes, and al the multitude of knyytis, that was with hym, he roos bi niyt, and smoot Edom, that cumpasside him, and alle hise duykis of his multitude of knyytis.
10 Títí di ọjọ́ òní ni Edomu ti wà ní ìṣọ̀tẹ̀ sí Juda. Libina ṣọ̀tẹ̀ ní àkọ́kọ́ náà, nítorí tí Jehoramu ti kọ Olúwa sílẹ̀, Ọlọ́run àwọn baba a rẹ̀.
Netheles Edom rebellide, that it was not vndir the lordschip of Juda `til to this dai. In that tyme also Lobna yede awei, that it was not vndur the hond of hym; for he hadde forsake the Lord God of hise fadris.
11 Òun pẹ̀lú ti kọ́ àwọn ibi gíga lórí àwọn òkè Juda. Ó sì ti fà á kí àwọn ènìyàn Jerusalẹmu ó ṣe àgbèrè pẹ̀lú ara wọn. Ó sì ti jẹ́ kí wọn ó ṣáko lọ.
Ferthermore he made hiye places in the citees of Juda, and made the dwelleris of Jerusalem to do fornycacioun, `that is, idolatrie, and Juda to breke the lawe.
12 Jehoramu gba ìwé láti ọwọ́ Elijah wòlíì, tí ó wí pé, “Èyí ní ohun tí Olúwa, Ọlọ́run baba à rẹ Dafidi wí: ‘Ìwọ kò tí ì rìn ní ọ̀nà àwọn baba à rẹ Jehoṣafati tàbí Asa ọba Juda.
Forsothe lettris weren brouyt to hym fro Elie, the prophete, in whiche it was writun, The Lord God of Dauid,
13 Ṣùgbọ́n ìwọ ti rìn ní ọ̀nà àwọn ọba Israẹli, ìwọ sì ti tọ́ Juda àti àwọn ènìyàn Jerusalẹmu láti ṣe àgbèrè sí ara wọn, gẹ́gẹ́ bí ilé Ahabu ti ṣe. Ìwọ sì ti pa àwọn arákùnrin rẹ, ẹ̀yà ara ilé baba à rẹ, àwọn ọkùnrin tí ó dára jù ọ́ lọ.
thi fadir, seith these thingis, For thou `yedist not in the weies of Josaphat, thi fadir, and in the weie of Asa, kyng of Juda, but thou yedist bi the weie of the kyngis of Israel, and madist Juda and the dwelleris of Jerusalem to do fornicacioun, and suedist the fornicacioun of the hows of Achab; ferthermore and thou hast slayn thi britheren and the hows of thi fadir, `that weren betere than thou; lo!
14 Bẹ́ẹ̀ ni nísinsin yìí, Olúwa ti fẹ́rẹ lu àwọn ènìyàn rẹ, àwọn ọmọ rẹ, àwọn ìyàwó rẹ àti gbogbo ohun tí ó jẹ́ tìrẹ, pẹ̀lú àjàkálẹ̀-ààrùn ńlá.
the Lord schal smyte thee with a greet veniaunce, and thi puple, and thi sones, and wyues, and al thi catel;
15 Ìwọ tìkára yóò ṣe àárẹ̀ pẹ̀lú àìsàn lílọ́ra ti ìfun, títí tí àìsàn náà yóò fi jẹ́ kí àwọn ìfun rẹ jáde sí ìta.’”
sotheli thou schalt be sijk `with the worste sorewe of wombe, til thin entrailis go out litil and litil bi ech dai.
16 Olúwa ru ìbínú àwọn ará Filistini àti àwọn Arabia tí wọ́n ń gbé ní ẹ̀bá àwọn ará Kuṣi sí Jehoramu.
Therfor the Lord reiside ayens Joram the spirit of Filisteis and Arabeis, that marchen with Ethiopiens; and thei stieden in to the lond of Juda,
17 Wọ́n dojú ìjà kọ Juda, wọ́n gbà á, wọ́n sì kó gbogbo ọrọ̀ tí a rí ní ilé ọba pẹ̀lú, àwọn ọmọkùnrin rẹ̀ àti àwọn ọmọkùnrin kankan kò kù sílẹ̀ fún un bí kò ṣe Ahasiah, àbíkẹ́yìn nínú àwọn ọmọ rẹ̀.
and wastiden it, and thei token awei al the catel, that was foundun in the hows of the kyng, ferthermore and hise sones, and wyues; and no sone was left to hym, no but Joachaz, that was the leeste in birthe.
18 Lẹ́yìn gbogbo èyí, Olúwa jẹ Jehoramu ní yà pẹ̀lú ààrùn tí kò ṣe é wòsàn nínú ìfun.
And ouer alle these thingis the Lord smoot hym with vncurable sorewe of the wombe.
19 Ní àkókò kan ní ìparí ọdún kejì, àwọn ìfun rẹ̀ jáde nítorí ààrùn náà ó sì kú nínú ìrora ńlá. Àwọn ènìyàn rẹ̀ kò dá iná láti fi bu ọlá fún un, gẹ́gẹ́ bí wọ́n ti ṣe fún àwọn baba a rẹ̀.
And whanne dai cam aftir a dai, and the spaces of tymes weren turned aboute, the cours of twey yeer was fillid; and so he was wastid `bi long rot, so that he castide out also his entrailis, and so he wantide sorewe and liyf togidere, and he was deed in the werste sikenesse. And the puple dide not to hym seruyce of deed men bi the custom of brennyng, as it hadde do to hise grettere, `ether auncetris.
20 Jehoramu jẹ́ ẹni ọdún méjìlélọ́gbọ̀n ní ìgbà tí ó di ọba, Ó sì jẹ ọba ní Jerusalẹmu fún ọdún mẹ́jọ. Ó kọjá lọ, kò sí ẹni tí ó kábámọ̀. A sì sin ín si ìlú ńlá ti Dafidi. Ṣùgbọ́n kì í ṣe nínú ibojì àwọn ọba.
He was of two and thritti yeer whanne he bigan to regne, and he regnede eiyte yeer in Jerusalem, and he yede not riytfuli; and thei birieden hym in the citee of Dauid, netheles not in the sepulcre of kingis.

< 2 Chronicles 21 >