< 2 Chronicles 21 >

1 Nígbà náà Jehoṣafati sùn pẹ̀lú àwọn baba a rẹ̀, a sì sin ín pẹ̀lú wọn ní ìlú ńlá Dafidi. Jehoramu ọmọ rẹ̀ sì rọ́pò rẹ̀ gẹ́gẹ́ bí ọba.
Potom usnul Jozafat s otci svými, a pochován jest s nimi v městě Davidově. I kraloval Jehoram syn jeho místo něho.
2 Àwọn arákùnrin Jehoramu ọmọ Jehoṣafati jẹ́ Asariah, Jehieli, Sekariah. Asariahu, Mikaeli àti Ṣefatia. Gbogbo àwọn wọ̀nyí ni àwọn ọmọ Jehoṣafati ọba Israẹli.
Měl pak bratří, syny Jozafatovy, Azariáše, Jechiele, Zachariáše, Azariáše, Michaele a Sefatiáše. Všickni ti byli synové Jozafata krále Izraelského.
3 Baba wọn ti fún wọn ní ẹ̀bùn púpọ̀ ti fàdákà àti wúrà àti àwọn ohun èlò iyebíye pẹ̀lú àwọn ìlú ààbò ní Juda, ṣùgbọ́n, ó ti gbé ìjọba fún Jehoramu nítorí òun ni àkọ́bí ọmọkùnrin.
Kterýmž byl dal otec jejich darů mnoho, stříbra a zlata, a věcí drahých, s městy hrazenými v Judstvu, království pak dal Jehoramovi, proto že on byl prvorozený.
4 Nígbà tí Jehoramu fi ẹsẹ̀ rẹ̀ múlẹ̀ gidigidi lórí ìjọba baba a rẹ̀, ó sì fi idà pa gbogbo àwọn arákùnrin rẹ̀ pẹ̀lú àwọn ọmọbìnrin ọba Israẹli.
I uvázal se Jehoram v království otce svého, a zmocniv se, zmordoval všecky bratří své mečem, ano i některé z knížat Izraelských.
5 Jehoramu jẹ́ ẹni ọdún méjìlélọ́gbọ̀n nígbà tí ó di ọba, ó sì jẹ ọba ní Jerusalẹmu fún ọdún mẹ́jọ.
Ve dvou a třidcíti letech byl Jehoram, když počal kralovati, a osm let kraloval v Jeruzalémě.
6 Ó rìn ní ọ̀nà àwọn ọba Israẹli gẹ́gẹ́ bí ìdílé Ahabu ti ṣe, nítorí ó fẹ́ ọmọbìnrin Ahabu. Ó ṣe búburú lójú Olúwa.
A chodil po cestě králů Izraelských, tak jako činil dům Achabův; nebo dceru Achabovu měl za manželku, a činil zlé věci před očima Hospodinovýma.
7 Bí ó tilẹ̀ rí bẹ́ẹ̀, nítorí tí májẹ̀mú tí Olúwa ti dá fún Dafidi kì í ṣe ìfẹ́ Olúwa láti pa ìdílé Dafidi run ó ti ṣe ìlérí láti tọ́jú fìtílà kan fún un àti àwọn àtẹ̀lé rẹ̀ títí láé.
Hospodin však nechtěl zahladiti domu Davidova, pro smlouvu, kterouž byl učinil s Davidem, a poněvadž byl řekl, že dá jemu svíci i synům jeho po všecky dny.
8 Ní àkókò Jehoramu, Edomu ṣọ̀tẹ̀ sí Juda, wọ́n sì gbé ọba tiwọn kalẹ̀.
Ve dnech jeho odstoupili Idumejští, aby nebyli poddáni Judovi, a ustanovili nad sebou krále.
9 Bẹ́ẹ̀ ni, Jehoramu lọ síbẹ̀ pẹ̀lú àwọn ìjòyè rẹ̀ àti gbogbo àwọn kẹ̀kẹ́. Àwọn ará Edomu yí i ká àti àwọn alákòóso àwọn kẹ̀kẹ́ rẹ̀. Ṣùgbọ́n ó dìde ní òru ó sì ṣẹ́gun wọn ní òru.
Pročež přitáhl Jehoram s knížaty svými, i se všemi vozy svými, a vstav v noci porazil Idumejské, kteříž jej byli obklíčili, i hejtmany vozů jeho.
10 Títí di ọjọ́ òní ni Edomu ti wà ní ìṣọ̀tẹ̀ sí Juda. Libina ṣọ̀tẹ̀ ní àkọ́kọ́ náà, nítorí tí Jehoramu ti kọ Olúwa sílẹ̀, Ọlọ́run àwọn baba a rẹ̀.
Však předce vytáhli se Idumejští z manství Judova až do tohoto dne. Téhož času zprotivilo se i Lebno, aby nebylo pod jeho mocí, proto že opustil Hospodina Boha otců svých.
11 Òun pẹ̀lú ti kọ́ àwọn ibi gíga lórí àwọn òkè Juda. Ó sì ti fà á kí àwọn ènìyàn Jerusalẹmu ó ṣe àgbèrè pẹ̀lú ara wọn. Ó sì ti jẹ́ kí wọn ó ṣáko lọ.
Přesto nadělal výsostí po horách Judských, a uvedl v smilství obyvatele Jeruzalémské, nýbrž dostrčil, jako i Judské.
12 Jehoramu gba ìwé láti ọwọ́ Elijah wòlíì, tí ó wí pé, “Èyí ní ohun tí Olúwa, Ọlọ́run baba à rẹ Dafidi wí: ‘Ìwọ kò tí ì rìn ní ọ̀nà àwọn baba à rẹ Jehoṣafati tàbí Asa ọba Juda.
I přišlo k němu psání od Eliáše proroka, řkoucího: Toto praví Hospodin Bůh Davida otce tvého: Proto že jsi nechodil po cestách Jozafata otce svého, a po cestách Azy krále Judského,
13 Ṣùgbọ́n ìwọ ti rìn ní ọ̀nà àwọn ọba Israẹli, ìwọ sì ti tọ́ Juda àti àwọn ènìyàn Jerusalẹmu láti ṣe àgbèrè sí ara wọn, gẹ́gẹ́ bí ilé Ahabu ti ṣe. Ìwọ sì ti pa àwọn arákùnrin rẹ, ẹ̀yà ara ilé baba à rẹ, àwọn ọkùnrin tí ó dára jù ọ́ lọ.
Ale chodil jsi po cestě králů Izraelských, a uvedl jsi v smilství Judu i obyvatele Jeruzalémské, tak jako jest v smilství uvedl dům Achabův Izraele, nadto i bratří své, rodinu otce svého, lepší než jsi sám, zmordoval jsi:
14 Bẹ́ẹ̀ ni nísinsin yìí, Olúwa ti fẹ́rẹ lu àwọn ènìyàn rẹ, àwọn ọmọ rẹ, àwọn ìyàwó rẹ àti gbogbo ohun tí ó jẹ́ tìrẹ, pẹ̀lú àjàkálẹ̀-ààrùn ńlá.
Aj, Hospodin uvede ránu velikou na lid tvůj a na syny tvé, na ženy tvé a na všecko jmění tvé,
15 Ìwọ tìkára yóò ṣe àárẹ̀ pẹ̀lú àìsàn lílọ́ra ti ìfun, títí tí àìsàn náà yóò fi jẹ́ kí àwọn ìfun rẹ jáde sí ìta.’”
Ty pak nemocen budeš těžce nemocí střev svých, až z tebe vyjdou střeva tvá pro nemoc rozmáhající se den ode dne.
16 Olúwa ru ìbínú àwọn ará Filistini àti àwọn Arabia tí wọ́n ń gbé ní ẹ̀bá àwọn ará Kuṣi sí Jehoramu.
A tak vzbudil Hospodin proti Jehoramovi ducha Filistinských a Arabských, kteříž jsou při končinách Chussimských.
17 Wọ́n dojú ìjà kọ Juda, wọ́n gbà á, wọ́n sì kó gbogbo ọrọ̀ tí a rí ní ilé ọba pẹ̀lú, àwọn ọmọkùnrin rẹ̀ àti àwọn ọmọkùnrin kankan kò kù sílẹ̀ fún un bí kò ṣe Ahasiah, àbíkẹ́yìn nínú àwọn ọmọ rẹ̀.
Kteříž vytáhše proti zemi Judské, vtrhli do ní, a rozchvátali všecko jmění, kteréž se nalezlo v domě královském, ano i syny jeho a ženy jeho, tak že mu nezůstalo žádného syna kromě Joachaza, nejmladšího z synů jeho.
18 Lẹ́yìn gbogbo èyí, Olúwa jẹ Jehoramu ní yà pẹ̀lú ààrùn tí kò ṣe é wòsàn nínú ìfun.
Potom pak po všem ranil jej Hospodin na střevách jeho nemocí nezhojitelnou.
19 Ní àkókò kan ní ìparí ọdún kejì, àwọn ìfun rẹ̀ jáde nítorí ààrùn náà ó sì kú nínú ìrora ńlá. Àwọn ènìyàn rẹ̀ kò dá iná láti fi bu ọlá fún un, gẹ́gẹ́ bí wọ́n ti ṣe fún àwọn baba a rẹ̀.
A když se to den po dni rozmáhalo, a již čas vycházel přeběhnutí dvou let, vyšla střeva jeho pro nemoc jeho, i umřel na hrozné bolesti. A nepálil mu lid jeho vonných věcí, jako pálívali otcům jeho.
20 Jehoramu jẹ́ ẹni ọdún méjìlélọ́gbọ̀n ní ìgbà tí ó di ọba, Ó sì jẹ ọba ní Jerusalẹmu fún ọdún mẹ́jọ. Ó kọjá lọ, kò sí ẹni tí ó kábámọ̀. A sì sin ín si ìlú ńlá ti Dafidi. Ṣùgbọ́n kì í ṣe nínú ibojì àwọn ọba.
Ve třidcíti a ve dvou letech byl, když kralovati počal, a osm let kraloval v Jeruzalémě, a sešel tak, že po něm netoužili. A však jej pochovali v městě Davidově, ale ne v hrobích královských.

< 2 Chronicles 21 >