< 2 Chronicles 21 >

1 Nígbà náà Jehoṣafati sùn pẹ̀lú àwọn baba a rẹ̀, a sì sin ín pẹ̀lú wọn ní ìlú ńlá Dafidi. Jehoramu ọmọ rẹ̀ sì rọ́pò rẹ̀ gẹ́gẹ́ bí ọba.
To pacoengah, Jehosaphat loe ampanawk khaeah anghak moe, David vangpui ah ampanaw khaeah aphum o; anih zuengah a capa Jehoram to siangpahrang ah oh.
2 Àwọn arákùnrin Jehoramu ọmọ Jehoṣafati jẹ́ Asariah, Jehieli, Sekariah. Asariahu, Mikaeli àti Ṣefatia. Gbogbo àwọn wọ̀nyí ni àwọn ọmọ Jehoṣafati ọba Israẹli.
Jehosaphat capa, Jehoram ih nawkamyanawk loe Azariah, Jehiel, Zekariah, Azariah, Mikael hoi Shephatiah; hae kaminawk loe Israel siangpahrang Jehosaphat ih caa ah oh o boih.
3 Baba wọn ti fún wọn ní ẹ̀bùn púpọ̀ ti fàdákà àti wúrà àti àwọn ohun èlò iyebíye pẹ̀lú àwọn ìlú ààbò ní Juda, ṣùgbọ́n, ó ti gbé ìjọba fún Jehoramu nítorí òun ni àkọ́bí ọmọkùnrin.
Ampa mah nihcae hanah paroeai kapop sui hoi sum kanglungnawk, atho kana hmuenmaenawk hoi sipae hoi thungh ih Judah vangpuinawk to tangqum ah paek; toe prae loe calu Jehoram hanah paek.
4 Nígbà tí Jehoramu fi ẹsẹ̀ rẹ̀ múlẹ̀ gidigidi lórí ìjọba baba a rẹ̀, ó sì fi idà pa gbogbo àwọn arákùnrin rẹ̀ pẹ̀lú àwọn ọmọbìnrin ọba Israẹli.
Jehoram loe ampa ih prae to toep moe, kacak siangpahrang ah oh, anih loe angmah ih nawkamyanawk to sumsen hoiah hum boih, thoemto Israel angraengnawk doeh a hum.
5 Jehoramu jẹ́ ẹni ọdún méjìlélọ́gbọ̀n nígbà tí ó di ọba, ó sì jẹ ọba ní Jerusalẹmu fún ọdún mẹ́jọ.
Siangpahrang ah oh amtong naah, Jehoram loe saning quithum, hnetto oh, anih mah Jerusalem to saning tazetto thung uk.
6 Ó rìn ní ọ̀nà àwọn ọba Israẹli gẹ́gẹ́ bí ìdílé Ahabu ti ṣe, nítorí ó fẹ́ ọmọbìnrin Ahabu. Ó ṣe búburú lójú Olúwa.
Anih loe Ahab canu to lak moe, Ahab imthung takoh khosakhaih baktiah, Israel siangpahrangnawk caehhaih loklam to pazui; Angraeng mikhnukah hmuen kahoih to sak.
7 Bí ó tilẹ̀ rí bẹ́ẹ̀, nítorí tí májẹ̀mú tí Olúwa ti dá fún Dafidi kì í ṣe ìfẹ́ Olúwa láti pa ìdílé Dafidi run ó ti ṣe ìlérí láti tọ́jú fìtílà kan fún un àti àwọn àtẹ̀lé rẹ̀ títí láé.
Toe Angraeng mah David hoiah lokmaihaih to sak pongah, David imthung to phrae mak ai; anih hoi a caanawk khaeah dungzan aanghaih to paek hanah loksuek boeh.
8 Ní àkókò Jehoramu, Edomu ṣọ̀tẹ̀ sí Juda, wọ́n sì gbé ọba tiwọn kalẹ̀.
Jehoram dung naah, Edom loe Judah prae nuiah misa angthawk moe, angmacae koeh ah siangpahrang to suek o.
9 Bẹ́ẹ̀ ni, Jehoramu lọ síbẹ̀ pẹ̀lú àwọn ìjòyè rẹ̀ àti gbogbo àwọn kẹ̀kẹ́. Àwọn ará Edomu yí i ká àti àwọn alákòóso àwọn kẹ̀kẹ́ rẹ̀. Ṣùgbọ́n ó dìde ní òru ó sì ṣẹ́gun wọn ní òru.
To pongah Jehoram loe angmah ih angraengnawk hoi hrangleengnawk boih to kawk moe, anih hoi nawnto caeh; anih loe aqum ah angthawk moe, nihcae takui khoep Edom kaminawk hoi hrangleeng angthueng misatuh angraengnawk to tuk.
10 Títí di ọjọ́ òní ni Edomu ti wà ní ìṣọ̀tẹ̀ sí Juda. Libina ṣọ̀tẹ̀ ní àkọ́kọ́ náà, nítorí tí Jehoramu ti kọ Olúwa sílẹ̀, Ọlọ́run àwọn baba a rẹ̀.
To pongah vaihni ni khoek to Edom kaminawk loe Judahnawk ih misa ah oh o. Jehoram loe ampanawk ih Angraeng Sithaw to pahnawt ving pongah, to nathuem ah Libnah prae doeh misa angthawk toeng.
11 Òun pẹ̀lú ti kọ́ àwọn ibi gíga lórí àwọn òkè Juda. Ó sì ti fà á kí àwọn ènìyàn Jerusalẹmu ó ṣe àgbèrè pẹ̀lú ara wọn. Ó sì ti jẹ́ kí wọn ó ṣáko lọ.
Judah prae ah kaom maenawk nuiah hmuensangnawk to a sak, Jerusalem ah kaom kaminawk to tangzat zawhsak moe, Judah to loklam amkhraengsak.
12 Jehoramu gba ìwé láti ọwọ́ Elijah wòlíì, tí ó wí pé, “Èyí ní ohun tí Olúwa, Ọlọ́run baba à rẹ Dafidi wí: ‘Ìwọ kò tí ì rìn ní ọ̀nà àwọn baba à rẹ Jehoṣafati tàbí Asa ọba Juda.
To naah tahmaa Elijah khae ih capat to anih khaeah phak, capat pongah, nam pa David ih Angraeng Sithaw mah hae tiah thuih; nam pa Jehosaphat hoi Judah siangpahrang Asa caehhaih loklam ah na caeh ai boeh,
13 Ṣùgbọ́n ìwọ ti rìn ní ọ̀nà àwọn ọba Israẹli, ìwọ sì ti tọ́ Juda àti àwọn ènìyàn Jerusalẹmu láti ṣe àgbèrè sí ara wọn, gẹ́gẹ́ bí ilé Ahabu ti ṣe. Ìwọ sì ti pa àwọn arákùnrin rẹ, ẹ̀yà ara ilé baba à rẹ, àwọn ọkùnrin tí ó dára jù ọ́ lọ.
toe Israel siangpahrangnawk caehhaih loklam to na pazui, Ahab imthung takoh mah sak ih baktih toengah, Judah hoi Jerusalem ah kaom kaminawk to tangzat zaw kami ah nang coengsak; nangmah pong kahoih kue, nam pa imthung takoh ih nam nawkamya khaeh mataeng doeh na hum boih;
14 Bẹ́ẹ̀ ni nísinsin yìí, Olúwa ti fẹ́rẹ lu àwọn ènìyàn rẹ, àwọn ọmọ rẹ, àwọn ìyàwó rẹ àti gbogbo ohun tí ó jẹ́ tìrẹ, pẹ̀lú àjàkálẹ̀-ààrùn ńlá.
to pongah khenah, vaihiah Angraeng mah nang ih kaminawk, na caanawk, na zunawk hoi na tawnh ih hmuenmaenawk boih nuiah kanung parai danpaekhaih phasak tih boeh.
15 Ìwọ tìkára yóò ṣe àárẹ̀ pẹ̀lú àìsàn lílọ́ra ti ìfun, títí tí àìsàn náà yóò fi jẹ́ kí àwọn ìfun rẹ jáde sí ìta.’”
Nangmah to doeh ni thokkruek na nathaih kasae mah, na zok thung ih tazae to tasa bangah tacawt ai karoek to, kanung parai nathaih mah pha thui tih, tiah tarik pae.
16 Olúwa ru ìbínú àwọn ará Filistini àti àwọn Arabia tí wọ́n ń gbé ní ẹ̀bá àwọn ará Kuṣi sí Jehoramu.
Jehoram tuk hanah Angraeng mah Philistin hoi Ethiopia kaminawk taengah kaom Arab kaminawk ih palungthin to pahruek pae.
17 Wọ́n dojú ìjà kọ Juda, wọ́n gbà á, wọ́n sì kó gbogbo ọrọ̀ tí a rí ní ilé ọba pẹ̀lú, àwọn ọmọkùnrin rẹ̀ àti àwọn ọmọkùnrin kankan kò kù sílẹ̀ fún un bí kò ṣe Ahasiah, àbíkẹ́yìn nínú àwọn ọmọ rẹ̀.
Nihcae loe Judah prae thungah angzoh o moe, misatuk o; siangpahrang imthung ah a hnuk o ih hmuennawk to lak pae o boih moe, a capa hoi a zunawk doeh hoih pae o king; a capa kanawk koek Jehoahaz ai ah loe capa maeto doeh tahmat o ai.
18 Lẹ́yìn gbogbo èyí, Olúwa jẹ Jehoramu ní yà pẹ̀lú ààrùn tí kò ṣe é wòsàn nínú ìfun.
Hae tiah oh pacoengah, Angraeng mah kahoih thai ai tazae nathaih to phaksak.
19 Ní àkókò kan ní ìparí ọdún kejì, àwọn ìfun rẹ̀ jáde nítorí ààrùn náà ó sì kú nínú ìrora ńlá. Àwọn ènìyàn rẹ̀ kò dá iná láti fi bu ọlá fún un, gẹ́gẹ́ bí wọ́n ti ṣe fún àwọn baba a rẹ̀.
Siangpahrang loe atue sawk ah ngannat, saning hnetto boenghaih bangah loe, a nathaih to nung parai pongah, tazae to tasa bangah tacawt pae, anih loe kana nung parai pongah duek. Prae kaminawk loe anih ampanawk han sak pae o ih hmaiqoenghaih baktiah anih hanah sah pae o ai.
20 Jehoramu jẹ́ ẹni ọdún méjìlélọ́gbọ̀n ní ìgbà tí ó di ọba, Ó sì jẹ ọba ní Jerusalẹmu fún ọdún mẹ́jọ. Ó kọjá lọ, kò sí ẹni tí ó kábámọ̀. A sì sin ín si ìlú ńlá ti Dafidi. Ṣùgbọ́n kì í ṣe nínú ibojì àwọn ọba.
Jehoram siangpahrang ah oh tangsuek naah, saning quithum, hnetto oh moe, Jerusalem to saning tazetto thung uk; anih duek naah, mi doeh palungsae o ai. Anih loe David vangpui ah aphum o, siangpahrangnawk ih taprong ah aphum o ai.

< 2 Chronicles 21 >