< 2 Chronicles 21 >

1 Nígbà náà Jehoṣafati sùn pẹ̀lú àwọn baba a rẹ̀, a sì sin ín pẹ̀lú wọn ní ìlú ńlá Dafidi. Jehoramu ọmọ rẹ̀ sì rọ́pò rẹ̀ gẹ́gẹ́ bí ọba.
Ug si Josaphat natulog uban sa iyang mga amahan, ug gilubong siya uban sa iyang mga amahan didto sa ciudad ni David: ug si Joram nga iyang anak nga lalake naghari ilis kaniya,
2 Àwọn arákùnrin Jehoramu ọmọ Jehoṣafati jẹ́ Asariah, Jehieli, Sekariah. Asariahu, Mikaeli àti Ṣefatia. Gbogbo àwọn wọ̀nyí ni àwọn ọmọ Jehoṣafati ọba Israẹli.
Ug siya may mga kaigsoonan, ang mga anak nga lalake ni Josaphat: si Asarias, ug si Jehiel, ug si Zacharias, ug si Asarias, ug si Michael, ug si Sepatias; kining tanan mga anak nga lalake ni Josaphat nga hari sa Israel.
3 Baba wọn ti fún wọn ní ẹ̀bùn púpọ̀ ti fàdákà àti wúrà àti àwọn ohun èlò iyebíye pẹ̀lú àwọn ìlú ààbò ní Juda, ṣùgbọ́n, ó ti gbé ìjọba fún Jehoramu nítorí òun ni àkọ́bí ọmọkùnrin.
Ug ang ilang amahan mihatag kanila ug daghan kaayong mga gasa, sa salapi, ug sa bulawan, ug sa bililhon nga mga butang, uban ang mga kinutaang ciudad sa Juda; apan ang gingharian iyang gihatag kang Joram, tungod kay siya mao ang kamagulangan.
4 Nígbà tí Jehoramu fi ẹsẹ̀ rẹ̀ múlẹ̀ gidigidi lórí ìjọba baba a rẹ̀, ó sì fi idà pa gbogbo àwọn arákùnrin rẹ̀ pẹ̀lú àwọn ọmọbìnrin ọba Israẹli.
Karon sa diha nga nakatindog na si Joram ibabaw sa gingharian sa iyang amahan, ug sa nalig-on na siya sa iyang kaugalingon, iyang gipatay ang iyang mga kaigsoonan nga tanan uban sa pinuti ug ang pila usab ka mga principe sa Israel.
5 Jehoramu jẹ́ ẹni ọdún méjìlélọ́gbọ̀n nígbà tí ó di ọba, ó sì jẹ ọba ní Jerusalẹmu fún ọdún mẹ́jọ.
Si Joram may katloan ug duha ka tuig ang panuigon sa pagsugod niya paghari; ug siya naghari sa walo ka tuig sa Jerusalem.
6 Ó rìn ní ọ̀nà àwọn ọba Israẹli gẹ́gẹ́ bí ìdílé Ahabu ti ṣe, nítorí ó fẹ́ ọmọbìnrin Ahabu. Ó ṣe búburú lójú Olúwa.
Ug siya naglakat sa dalan sa mga hari sa Israel, sumala sa gibuhat sa balay ni Achab; kay iyang gipangasawa ang anak nga babaye ni Achab: ug iyang gihimo kadtong dautan sa mga mata ni Jehova:
7 Bí ó tilẹ̀ rí bẹ́ẹ̀, nítorí tí májẹ̀mú tí Olúwa ti dá fún Dafidi kì í ṣe ìfẹ́ Olúwa láti pa ìdílé Dafidi run ó ti ṣe ìlérí láti tọ́jú fìtílà kan fún un àti àwọn àtẹ̀lé rẹ̀ títí láé.
Apan bisan pa niini si Jehova wala mobuot sa paggun-ob sa balay ni David, tungod sa tugon nga iyang gihimo uban kang David, ug ingon nga siya nagsaad sa paghatag sa usa ka lamparahan kaniya ug sa iyang mga anak sa kanunay.
8 Ní àkókò Jehoramu, Edomu ṣọ̀tẹ̀ sí Juda, wọ́n sì gbé ọba tiwọn kalẹ̀.
Sa iyang mga adlaw ang Edom ming-alsa gikan sa ilalum sa kamot sa Juda, ug naghimo ug usa ka hari sa ibabaw nila.
9 Bẹ́ẹ̀ ni, Jehoramu lọ síbẹ̀ pẹ̀lú àwọn ìjòyè rẹ̀ àti gbogbo àwọn kẹ̀kẹ́. Àwọn ará Edomu yí i ká àti àwọn alákòóso àwọn kẹ̀kẹ́ rẹ̀. Ṣùgbọ́n ó dìde ní òru ó sì ṣẹ́gun wọn ní òru.
Unya si Joram milabay uban sa iyang mga capitan, ug ang tanan niyang mga carro uban kaniya: ug mibangon siya sa gabii, ug gidasmagan ang mga Edomhanon nga naglibut kaniya, ug ang mga capitan sa mga carro.
10 Títí di ọjọ́ òní ni Edomu ti wà ní ìṣọ̀tẹ̀ sí Juda. Libina ṣọ̀tẹ̀ ní àkọ́kọ́ náà, nítorí tí Jehoramu ti kọ Olúwa sílẹ̀, Ọlọ́run àwọn baba a rẹ̀.
Busa ang Edom ming-alsa gikan sa ilalum sa kamot sa Juda hangtud niining adlawa: unya ang Libna ming-alsa usab sa maong panahon gikan sa ilalum sa iyang kamot, tungod kay iyang gibiyaan si Jehova, ang Dios sa iyang mga amahan.
11 Òun pẹ̀lú ti kọ́ àwọn ibi gíga lórí àwọn òkè Juda. Ó sì ti fà á kí àwọn ènìyàn Jerusalẹmu ó ṣe àgbèrè pẹ̀lú ara wọn. Ó sì ti jẹ́ kí wọn ó ṣáko lọ.
Labut pa siya naghimo ug mga hatag-as nga dapit sa kabukiran sa Juda, ug gipapakighilawas niya ang mga pumoluyo sa Jerusalem, ug gipasalaag niya ang Juda.
12 Jehoramu gba ìwé láti ọwọ́ Elijah wòlíì, tí ó wí pé, “Èyí ní ohun tí Olúwa, Ọlọ́run baba à rẹ Dafidi wí: ‘Ìwọ kò tí ì rìn ní ọ̀nà àwọn baba à rẹ Jehoṣafati tàbí Asa ọba Juda.
Ug may usa ka sinulat alang kaniya gikan kang Elias nga manalagna, nga nagaingon: Kini mao ang giingon ni Jehova, ang Dios ni David nga imong amahan: Tungod kay ikaw wala maglakat sa mga dalan ni Josaphat nga imong amahan, ni sa mga dalan ni Asa nga hari sa Juda,
13 Ṣùgbọ́n ìwọ ti rìn ní ọ̀nà àwọn ọba Israẹli, ìwọ sì ti tọ́ Juda àti àwọn ènìyàn Jerusalẹmu láti ṣe àgbèrè sí ara wọn, gẹ́gẹ́ bí ilé Ahabu ti ṣe. Ìwọ sì ti pa àwọn arákùnrin rẹ, ẹ̀yà ara ilé baba à rẹ, àwọn ọkùnrin tí ó dára jù ọ́ lọ.
Apan naglakat sa dalan sa mga hari sa Israel, ug imong gipapakighilawas ang Juda ug ang mga pumoluyo sa Jerusalem, sama sa gibuhat sa balay ni Achab, ug nagpatay ka usab sa imong mga kaigsoonan sa balay sa imong amahan, nga labing maayo pa kay kanimo:
14 Bẹ́ẹ̀ ni nísinsin yìí, Olúwa ti fẹ́rẹ lu àwọn ènìyàn rẹ, àwọn ọmọ rẹ, àwọn ìyàwó rẹ àti gbogbo ohun tí ó jẹ́ tìrẹ, pẹ̀lú àjàkálẹ̀-ààrùn ńlá.
Ania karon, si Jehova magahampak sa imong katawohan uban sa usa ka dakung kamatay, ug sa imong mga anak, ug sa imong mga asawa, ug sa tanan mong mga manggad;
15 Ìwọ tìkára yóò ṣe àárẹ̀ pẹ̀lú àìsàn lílọ́ra ti ìfun, títí tí àìsàn náà yóò fi jẹ́ kí àwọn ìfun rẹ jáde sí ìta.’”
Ug ikaw pagatakboyan sa usa ka dakung sakit sa imong mga tinae, hangtud nga ang imong mga tinae mangahabwa tungod sa imong sakit, sa adlaw-adlaw.
16 Olúwa ru ìbínú àwọn ará Filistini àti àwọn Arabia tí wọ́n ń gbé ní ẹ̀bá àwọn ará Kuṣi sí Jehoramu.
Ug gipukaw ni Jehova batok kang Joram ang espiritu sa mga Filistehanon, ug sa mga Arabianhon nga anaa tupad sa mga Etiopiahanon:
17 Wọ́n dojú ìjà kọ Juda, wọ́n gbà á, wọ́n sì kó gbogbo ọrọ̀ tí a rí ní ilé ọba pẹ̀lú, àwọn ọmọkùnrin rẹ̀ àti àwọn ọmọkùnrin kankan kò kù sílẹ̀ fún un bí kò ṣe Ahasiah, àbíkẹ́yìn nínú àwọn ọmọ rẹ̀.
Ug sila nangadto batok sa Juda, ug mingsulod niana, ug gidala ang tanang manggad nga makaplagan diha sa balay sa hari, ug ang iyang mga anak nga lalake usab, ug ang iyang mga asawa; mao nga walay usa ka anak nga lalake nga nahabilin kaniya, gawas kang Joachaz, ang kamanghuran sa iyang mga anak nga lalake.
18 Lẹ́yìn gbogbo èyí, Olúwa jẹ Jehoramu ní yà pẹ̀lú ààrùn tí kò ṣe é wòsàn nínú ìfun.
Ug sa tapus niining tanan gihampak siya ni Jehova sa iyang mga tinae sa usa ka sakit nga walay kaayohan.
19 Ní àkókò kan ní ìparí ọdún kejì, àwọn ìfun rẹ̀ jáde nítorí ààrùn náà ó sì kú nínú ìrora ńlá. Àwọn ènìyàn rẹ̀ kò dá iná láti fi bu ọlá fún un, gẹ́gẹ́ bí wọ́n ti ṣe fún àwọn baba a rẹ̀.
Ug nahitabo, sa nagalakat ang panahon, tapus ang duha ka tuig, nga ang iyang mga tinae nangahabwa tungod sa iyang sakit, ug siya namatay sa mangil-ad nga mga balatian. Ug ang iyang katawohan wala magsunog alang kaniya, sama sa pagsunog sa iyang mga amahan.
20 Jehoramu jẹ́ ẹni ọdún méjìlélọ́gbọ̀n ní ìgbà tí ó di ọba, Ó sì jẹ ọba ní Jerusalẹmu fún ọdún mẹ́jọ. Ó kọjá lọ, kò sí ẹni tí ó kábámọ̀. A sì sin ín si ìlú ńlá ti Dafidi. Ṣùgbọ́n kì í ṣe nínú ibojì àwọn ọba.
Katloan ug duha ka tuig ang iyang panuigon sa pagsugod niya paghari ug siya naghari sa Jerusalem sa walo ka tuig: ug siya migikan nga wala kawilihi; ug ilang gilubong siya sa ciudad ni David, apan dili sa mga lubnganan sa mga hari.

< 2 Chronicles 21 >