< 2 Chronicles 20 >

1 Lẹ́yìn èyí, àwọn ọmọ Moabu àti àwọn ọmọ Ammoni àti díẹ̀ nínú àwọn ọmọ Mehuni wá láti gbé ogun ti Jehoṣafati.
Și s-a întâmplat de asemenea după aceasta, că au venit copiii lui Moab și copiii lui Amon și cu ei alții în afară de amoniți, împotriva lui Iosafat, la bătălie.
2 Àwọn díẹ̀ nínú àwọn ọkùnrin wá láti sọ fún Jehoṣafati, “Àwọn ọ̀pọ̀ ọ̀wọ́ ogun ń bọ̀ wá bá ọ láti apá kejì Òkun láti Siria. Ó ti wà ní Hasason Tamari náà” (èyí tí í ṣe En-Gedi).
Atunci au venit câțiva care i-au spus lui Iosafat, zicând: Vine o mare mulțime împotriva ta, de dincolo de mare, de partea aceasta a Siriei; și, iată, ei sunt în Hațațon-Tamar, care este En-Ghedi.
3 Nípa ìró ìdágìrì, Jehoṣafati pinnu láti wádìí lọ́wọ́ Olúwa, ó sì kéde àwẹ̀ kíákíá fún gbogbo Juda.
Și Iosafat s-a temut și s-a pus să caute pe DOMNUL și a proclamat un post prin tot Iuda.
4 Àwọn ènìyàn Juda sì kó ara wọn jọ pọ̀ láti wá ìrànlọ́wọ́ láti ọ̀dọ̀ Olúwa; pẹ̀lúpẹ̀lú, wọ́n wá láti gbogbo ìlú ní Juda láti wá a.
Și Iuda s-a strâns împreună să ceară ajutor de la DOMNUL, din toate cetățile lui Iuda au venit să caute pe DOMNUL.
5 Nígbà náà Jehoṣafati dìde dúró níwájú àpéjọ Juda àti Jerusalẹmu ní ilé Olúwa níwájú àgbàlá tuntun.
Și Iosafat a stat în picioare în adunarea lui Iuda și Ierusalim, în casa DOMNULUI, înaintea curții noi,
6 O sì wí pé, “Olúwa, Ọlọ́run àwọn baba wa, ìwọ kì ha ṣe Ọlọ́run tí ń bẹ ní ọ̀run? Ìwọ ń ṣe alákòóso lórí gbogbo ìjọba àwọn orílẹ̀-èdè. Agbára àti ipá ń bẹ ní ọwọ́ rẹ, kò sì sí ẹnìkan tí ó lè kò ọ́ lójú.
Și a spus: DOAMNE Dumnezeul părinților noștri, nu ești tu Dumnezeu în cer? Și nu domnești peste toate împărățiile păgânilor? Și nu este în mâna ta putere și tărie, astfel încât nimeni nu este în stare să ți se împotrivească?
7 Ìwọ ha kọ́ Ọlọ́run wa, tí o ti lé àwọn olùgbé ilẹ̀ yìí jáde níwájú àwọn ènìyàn Israẹli, tí o sì fi fún irú-ọmọ Abrahamu ọ̀rẹ́ rẹ láéláé?
Nu ești tu Dumnezeul nostru, care ai alungat pe locuitorii acestei țări dinaintea poporului tău, Israel, și ai dat-o seminței lui Avraam, prietenul tău, pentru totdeauna?
8 Wọ́n ti ń gbé nínú rẹ̀ wọ́n sì ti kọ́ sínú rẹ ibi mímọ́ fún orúkọ rẹ wí pé,
Și au locuit în ea și ți-au construit în ea un sanctuar pentru numele tău, spunând:
9 ‘Tí ibi bá wá sí orí wa, bóyá idà ìjìyà tàbí àjàkálẹ̀-ààrùn àwọn yóò dúró níwájú rẹ níwájú ilé yìí tí ń jẹ́ orúkọ rẹ, àwa yóò sì sọkún jáde, ìwọ yóò sì gbọ́ wa. Ìwọ yóò sì gbà wá là?’
Când răul vine peste noi, ca sabia, judecata sau ciuma sau foametea, dacă noi stăm înaintea acestei case și în prezența ta (fiindcă numele tău este în această casă) și strigăm către tine în nenorocirea noastră, atunci tu vei asculta și vei ajuta.
10 “Ṣùgbọ́n nísinsin yìí, àwọn ọkùnrin nìyí láti Ammoni, Moabu àti òkè Seiri, agbègbè ibi ti ìwọ kò ti gba àwọn ọmọ Israẹli láyè láti gbóguntì nígbà tí wọn wá láti Ejibiti, bẹ́ẹ̀ ni wọ́n yípadà kúrò ní ọ̀dọ̀ wọn, wọn kò sì pa wọ́n run.
Și acum, iată, copiii lui Amon și ai lui Moab și ai celor din muntele Seir, împotriva cărora nu ai lăsat pe Israel să lupte când au ieșit din țara Egiptului, ci s-au abătut de la ei și nu i-au nimicit;
11 Sì kíyèsi i, bí wọ́n ti san án padà fún wa; láti wá lé wa jáde kúrò nínú ìní rẹ, tí ìwọ ti fi fún wa láti ní.
Iată, spun, cum ne răsplătesc, să vină și să ne arunce din stăpânirea ta, pe care ne-ai dat-o să o moștenim.
12 Ọlọ́run wa, ṣé ìwọ kò ní ṣe ìdájọ́ fún wọn? Nítorí àwa kò ní agbára láti dojúkọ àwọn ọ̀pọ̀ ogun ńlá yìí tí ń bọ̀ wá kó wa. Àwa kò mọ̀ ohun tó yẹ ká ṣe, ṣùgbọ́n ojú wa wà ní ọ̀dọ̀ rẹ.”
O Dumnezeul nostru, nu îi vei judeca? Fiindcă nu avem putere împotriva acestei mari cete care vine împotriva noastră; nici nu știm ce să facem, dar ochii noștri sunt la tine.
13 Gbogbo àwọn ọkùnrin Juda, pẹ̀lú àwọn aya wọn àti ọmọ wọn àti àwọn kéékèèké, dúró níbẹ̀ níwájú Olúwa.
Și tot Iuda a stat în picioare înaintea DOMNULUI, cu micuții lor, soțiile lor și copiii lor.
14 Nígbà náà, ẹ̀mí Olúwa sì bà lé Jahasieli ọmọ Sekariah, ọmọ Benaiah, ọmọ Jeieli, ọmọ Mattaniah ọmọ Lefi àti ọmọ Asafu, gẹ́gẹ́ bí ó ṣe dìde dúró láàrín àpéjọ ènìyàn.
Atunci a venit Duhul DOMNULUI în mijlocul adunării peste Iahaziel, fiul lui Zaharia, fiul lui Benaia, fiul lui Ieiel, fiul lui Matania, un levit dintre fiii lui Asaf;
15 Ó sì wí pé, “Ẹ tẹ́tí sílẹ̀, ọba Jehoṣafati àti gbogbo àwọn tí ń gbé ní Juda àti Jerusalẹmu! Èyí ní ohun tí Olúwa sọ wí pé kí a ṣe: ‘Ẹ má ṣe bẹ̀rù tàbí fòyà nítorí ọ̀pọ̀ ogun ńlá yìí. Nítorí ogun náà kì í ṣe tiyín, ṣùgbọ́n ti Ọlọ́run ni.
Și el a spus: Dați ascultare, tot Iuda și voi locuitori ai Ierusalimului și tu, împărate Iosafat. Astfel vă spune DOMNUL: Nu vă înfricoșați, nici nu vă descurajați din cauza acestei mari mulțimi, fiindcă bătălia nu este a voastră, ci a lui Dumnezeu.
16 Ní ọ̀la, ẹ sọ̀kalẹ̀ tọ̀ wọ́n lọ, wọn yóò gòkè pẹ̀lú, ẹ̀yin yóò sì rí wọn ní ìpẹ̀kun odò náà, níwájú aginjù Jerueli.
Mâine să coborâți împotriva lor; iată, ei urcă urcușul din Țiț; și îi veți găsi la capătul pârâului, înaintea pustiului lui Ieruel.
17 Ẹ̀yin kò ní láti bá ogun yìí jà. ẹ dúró ní ààyè yín; ẹ dúró jẹ́ẹ́ kí ẹ sì rí ìgbàlà Olúwa tí yóò fi fún yín, ìwọ Juda àti Jerusalẹmu. Ẹ má ṣe bẹ̀rù; ẹ má sì ṣe fòyà. Ẹ jáde lọ láti lọ dojúkọ wọ́n ní ọ̀la, Olúwa yóò sì wà pẹ̀lú yín.’”
Nu va fi nevoie să luptați în această bătălie; așezați-vă, stați liniștiți și vedeți salvarea DOMNULUI pe care v-o va da; O, Iuda și Ierusalim, nu vă temeți, nici nu vă descurajați; mâine ieșiți împotriva lor, fiindcă DOMNUL va fi cu voi.
18 Jehoṣafati tẹ orí rẹ̀ ba sílẹ̀ pẹ̀lú ojú rẹ̀, àti gbogbo àwọn ènìyàn Juda àti Jerusalẹmu wólẹ̀ níwájú láti sin Olúwa.
Și Iosafat și-a plecat capul cu fața la pământ; și tot Iuda și locuitorii Ierusalimului au căzut înaintea DOMNULUI, închinându-se DOMNULUI.
19 Nígbà náà díẹ̀ lára àwọn ọmọ Lefi àti àwọn ọmọ Kohati àti àwọn ọmọ Kora sì dìde dúró wọ́n sì sin Olúwa, Ọlọ́run Israẹli, pẹ̀lú ohùn ariwo ńlá.
Și leviții, dintre copiii chehatiților și dintre copiii coreiților, au stat în picioare să laude pe DOMNUL Dumnezeul lui Israel cu voce tare.
20 Ní òwúrọ̀ kùtùkùtù wọ́n jáde lọ sí aginjù Tekoa. Gẹ́gẹ́ bí wọ́n ti ń jáde lọ, Jehoṣafati dìde dúró ó sì wí pé, “Ẹ gbọ́ mi, Juda àti ènìyàn Jerusalẹmu! Ẹ ní ìgbàgbọ́ nínú Olúwa Ọlọ́run yín ẹ̀yin yóò sì borí, ẹ ní ìgbàgbọ́ nínú àwọn wòlíì rẹ̀ ẹ̀yìn yóò sì ṣe rere.”
Și s-au ridicat devreme dimineața și au ieșit în pustiul din Tecoa; și cum au ieșit, Iosafat a stat în picioare și a spus: Ascultați-mă, Iuda și voi locuitori ai Ierusalimului; Credeți în DOMNUL Dumnezeul vostru, astfel veți fi voi întemeiați; credeți pe profeții lui, astfel veți prospera.
21 Lẹ́yìn ìgbà tí ó bá àwọn ènìyàn náà gbèrò tán, Jehoṣafati yàn wọ́n láti kọrin sí Olúwa àti láti fi ìyìn fún ẹwà ìwà mímọ́ gẹ́gẹ́ bí ó tì ń jáde lọ sí iwájú ogun ńlá náà, wí pé, “Ẹ fi ọpẹ́ fún Olúwa, nítorí àánú rẹ̀ dúró títí láéláé.”
Și după ce s-a sfătuit cu poporul, a rânduit cântăreți DOMNULUI și pe cei care să laude frumusețea sfințeniei; și pe când ieșeau înaintea armatei, spuneau: Lăudați pe DOMNUL, fiindcă mila lui dăinuiește pentru totdeauna.
22 Bí wọ́n ti bẹ̀rẹ̀ sí kọrin àti ìyìn, Olúwa rán ogun ẹ̀yìn sí àwọn ọkùnrin Ammoni àti Moabu àti òkè Seiri tí ó ń gbógun ti Juda, wọ́n sì kọlù wọ́n.
Și când au început să cânte și să laude, DOMNUL a pus pânde împotriva copiilor lui Amon, lui Moab și a celor din muntele Seir, care veniseră împotriva lui Iuda; și au fost loviți.
23 Àwọn ọkùnrin Ammoni àti Moabu dìde dúró sí àwọn ọkùnrin tí ń gbé òkè Seiri láti pa wọ́n run túútúú. Lẹ́yìn ìgbà tí wọ́n sì ti pa àwọn ọkùnrin láti òkè Seiri, wọ́n sì ran ra wọn lọ́wọ́ láti pa ara wọn run.
Căci copiii lui Amon și ai lui Moab s-au ridicat împotriva locuitorilor muntelui Seir, să îi ucidă și să îi nimicească în întregime; și când au terminat cu locuitorii din Seir, fiecare a ajutat pentru a nimici pe altul.
24 Nígbà tí àwọn ènìyàn Juda jáde sí ìhà ilé ìṣọ́ ní aginjù, wọn ń wo àwọn ọ̀pọ̀ ènìyàn, òkú nìkan ni wọ́n rí tí ó ṣubú sí ilẹ̀, kò sì sí ẹnìkan tí ó rí ààyè sá.
Și când Iuda a venit spre turnul de veghe în pustiu, s-au uitat la mulțime și, iată, ei erau trupuri moarte căzute la pământ și nimeni nu a scăpat.
25 Bẹ́ẹ̀ ni Jehoṣafati àti àwọn ènìyàn rẹ̀ lọ láti kó ìkógun wọn, wọ́n sì rí lára wọn ọ̀pọ̀ iyebíye ọrọ̀ púpọ̀, ó sì ju èyí tí wọ́n lè kó lọ. Ọ̀pọ̀ ìkógun sì wà níbẹ̀, èyí tí ó gbà wọ́n ní ọjọ́ mẹ́ta láti gbà pọ̀.
Și când Iosafat și poporul său au venit să ia prada de la ei, au găsit printre ei din abundență, deopotrivă bogății la trupurile moarte și bijuterii prețioase, pe care le-au smuls de pe ei, mai mult decât puteau duce și au fost trei zile în strângerea prăzii, atât era de multă.
26 Ní ọjọ́ kẹrin, wọn kó ara jọ pọ̀ ní àfonífojì ìbùkún, níbi tí wọ́n ti ń fi ìbùkún fún Olúwa. Ìdí nìyí tí wọ́n fi ń pe ibẹ̀ ní àfonífojì ìbùkún títí di òní.
Și în a patra zi s-au adunat în valea lui Beraca, pentru că acolo au binecuvântat pe DOMNUL, de aceea numele acelui loc este chemat: Valea lui Beraca, până în această zi.
27 Nígbà náà wọ́n darí pẹ̀lú Jehoṣafati, gbogbo àwọn ènìyàn Juda àti Jerusalẹmu padà pẹ̀lú ayọ̀ sí Jerusalẹmu, nítorí Olúwa ti fún wọn ní ìdí láti yọ̀ lórí àwọn ọ̀tá wọn.
Apoi s-au întors, fiecare om din Iuda și Ierusalim și Iosafat în fruntea lor, să meargă din nou la Ierusalim cu bucurie, fiindcă DOMNUL îi făcuse să se bucure de dușmanii lor.
28 Wọ́n sì wọ Jerusalẹmu, wọ́n sì lọ sí ilé Olúwa pẹ̀lú ohun èlò orin olókùn àti dùùrù àti ìpè.
Și au venit la Ierusalim cu psalterioane și harpe și trâmbițe până la casa DOMNULUI.
29 Ìbẹ̀rù Ọlọ́run wá si orí gbogbo ìjọba ilẹ̀ náà nígbà tí wọ́n gbọ́ bí Olúwa ti bá àwọn ọ̀tá Israẹli jà.
Și frica de DOMNUL era în toate împărățiile acestor țări, când au auzit că DOMNUL a luptat împotriva dușmanilor lui Israel.
30 Bẹ́ẹ̀ ni ìjọba Jehoṣafati sì wà ní àlàáfíà, nítorí Ọlọ́run rẹ̀ ti fún un ni ìsinmi ní gbogbo àyíká.
Astfel împărăția lui Iosafat era liniștită, pentru că Dumnezeul lui i-a dat odihnă de jur împrejur.
31 Báyìí ni Jehoṣafati jẹ ọba lórí Juda. Ó sì jẹ́ ẹni ọdún márùndínlógójì. Nígbà tí ó di ọba Juda, ó sì jẹ ọba ní Jerusalẹmu fún ọdún mẹ́ẹ̀ẹ́dọ́gbọ̀n. Orúkọ ìyá rẹ̀ sì ni Asuba ọmọbìnrin Silihi.
Și Iosafat a domnit peste Iuda și era în vârstă de treizeci și cinci de ani când a început să domnească; și a domnit douăzeci și cinci de ani în Ierusalim. Și numele mamei lui era Azuba, fiica lui Șilhi.
32 Ó sì rin ọ̀nà baba rẹ̀ Asa kò sì yà kúrò nínú rẹ̀, ó sì ṣe èyí tí ó tọ́ ní ojú Olúwa.
Și a umblat în calea lui Asa, tatăl său, și nu s-a depărtat de ea, făcând ceea ce era drept înaintea ochilor DOMNULUI.
33 Ní ibi gíga, pẹ̀lúpẹ̀lú, kò mu wọn kúrò, gbogbo àwọn ènìyàn náà kò sì fi ọkàn wọn fún Ọlọ́run àwọn baba wọn.
Totuși, înălțimile nu au fost îndepărtate, căci poporul încă nu și-a îndreptat inima către Dumnezeul părinților lor.
34 Ìyókù iṣẹ́ ìjọba Jehoṣafati, láti ìbẹ̀rẹ̀ títí dé òpin, ni a kọ sí inú ìwé ìtàn ti Jehu ọmọ Hanani, tí a kọ sí inú ìwé àwọn ọba Israẹli.
Și restul faptelor lui Iosafat, cele dintâi și cele din urmă, iată, sunt scrise în cartea lui Iehu, fiul lui Hanani, care este menționat în cartea împăraților lui Israel.
35 Nígbà tí ó yá, Jehoṣafati ọba Juda da ara rẹ̀ pọ̀ pẹ̀lú Ahasiah, ọba Israẹli, ẹni tí ó jẹ̀bi ìwà búburú.
Și, după aceasta, Iosafat, împăratul lui Iuda, s-a alăturat lui Ahazia, împăratul lui Israel, care s-a purtat foarte stricat;
36 Ó sì gbà pẹ̀lú rẹ̀ láti kan ọkọ̀ láti lọ sí Tarṣiṣi, lẹ́yìn èyí wọ́n kan ọkọ̀ ní Esioni-Geberi.
Și s-a alăturat lui pentru a face corăbii ca să meargă la Tarsis; și au făcut corăbiile în Ețion-Gheber.
37 Elieseri ọmọ Dodafahu ti Meraṣa sọtẹ́lẹ̀ sí Jehoṣafati, wí pe, “Nítorí tí ìwọ ti da ara rẹ̀ pọ̀ mọ́ Ahasiah, Olúwa yóò pa ohun ti ìwọ ti ṣe run.” Àwọn ọkọ̀ náà sì fọ́, wọn kò sì le lọ sí ibi ìtajà.
Atunci Eliezer, fiul lui Dodava, din Mareșa, a profețit împotriva lui Iosafat, spunând: Deoarece te-ai alăturat lui Ahazia, DOMNUL a frânt lucrările tale. Și corăbiile au fost frânte, încât nu au fost în stare să meargă la Tarsis.

< 2 Chronicles 20 >