< 2 Chronicles 20 >

1 Lẹ́yìn èyí, àwọn ọmọ Moabu àti àwọn ọmọ Ammoni àti díẹ̀ nínú àwọn ọmọ Mehuni wá láti gbé ogun ti Jehoṣafati.
Potem na wojnę przeciwko Jehoszafatowi wyruszyli synowie Moabu i synowie Ammona, a wraz z nimi niektórzy [mieszkający] z Ammonitami.
2 Àwọn díẹ̀ nínú àwọn ọkùnrin wá láti sọ fún Jehoṣafati, “Àwọn ọ̀pọ̀ ọ̀wọ́ ogun ń bọ̀ wá bá ọ láti apá kejì Òkun láti Siria. Ó ti wà ní Hasason Tamari náà” (èyí tí í ṣe En-Gedi).
Wtedy jacyś ludzie przyszli do Jehoszafata i powiedzieli do niego: Nadciąga przeciwko tobie wielki tłum zza morza, z Syrii, a oto są w Chaseson-Tamar, to [jest] w En-Gedi.
3 Nípa ìró ìdágìrì, Jehoṣafati pinnu láti wádìí lọ́wọ́ Olúwa, ó sì kéde àwẹ̀ kíákíá fún gbogbo Juda.
Jehoszafat więc uląkł się i postanowił szukać PANA, i zapowiedział post w całej Judzie.
4 Àwọn ènìyàn Juda sì kó ara wọn jọ pọ̀ láti wá ìrànlọ́wọ́ láti ọ̀dọ̀ Olúwa; pẹ̀lúpẹ̀lú, wọ́n wá láti gbogbo ìlú ní Juda láti wá a.
Wówczas lud Judy zgromadził się, aby szukać PANA. Zeszli się także ze wszystkich miast Judy, aby szukać PANA.
5 Nígbà náà Jehoṣafati dìde dúró níwájú àpéjọ Juda àti Jerusalẹmu ní ilé Olúwa níwájú àgbàlá tuntun.
Jehoszafat stanął pośrodku zgromadzenia Judy i Jerozolimy w domu PANA, przed nowym dziedzińcem.
6 O sì wí pé, “Olúwa, Ọlọ́run àwọn baba wa, ìwọ kì ha ṣe Ọlọ́run tí ń bẹ ní ọ̀run? Ìwọ ń ṣe alákòóso lórí gbogbo ìjọba àwọn orílẹ̀-èdè. Agbára àti ipá ń bẹ ní ọwọ́ rẹ, kò sì sí ẹnìkan tí ó lè kò ọ́ lójú.
I powiedział: PANIE, Boże naszych ojców! Czy ty nie jesteś sam Bogiem na niebie? Czy nie ty panujesz nad wszystkimi królestwami narodów? Czy nie w twoich rękach jest moc i siła, tak że nie ma nikogo, kto by mógł się ostać przed tobą?
7 Ìwọ ha kọ́ Ọlọ́run wa, tí o ti lé àwọn olùgbé ilẹ̀ yìí jáde níwájú àwọn ènìyàn Israẹli, tí o sì fi fún irú-ọmọ Abrahamu ọ̀rẹ́ rẹ láéláé?
Czy to nie ty, nasz Boże, wypędziłeś mieszkańców tej ziemi przed swoim ludem Izraelem i dałeś ją potomstwu Abrahama, swojego przyjaciela, na wieki?
8 Wọ́n ti ń gbé nínú rẹ̀ wọ́n sì ti kọ́ sínú rẹ ibi mímọ́ fún orúkọ rẹ wí pé,
Zamieszkali w niej i zbudowali ci w niej świątynię dla twojego imienia, mówiąc:
9 ‘Tí ibi bá wá sí orí wa, bóyá idà ìjìyà tàbí àjàkálẹ̀-ààrùn àwọn yóò dúró níwájú rẹ níwájú ilé yìí tí ń jẹ́ orúkọ rẹ, àwa yóò sì sọkún jáde, ìwọ yóò sì gbọ́ wa. Ìwọ yóò sì gbà wá là?’
Jeśli spadnie na nas nieszczęście, miecz pomsty, zaraza albo głód, a staniemy przed tym domem i przed tobą, gdyż twoje imię przebywa w tym domu, i zawołamy do ciebie w naszym ucisku, wtedy wysłuchasz [nas] i wybawisz.
10 “Ṣùgbọ́n nísinsin yìí, àwọn ọkùnrin nìyí láti Ammoni, Moabu àti òkè Seiri, agbègbè ibi ti ìwọ kò ti gba àwọn ọmọ Israẹli láyè láti gbóguntì nígbà tí wọn wá láti Ejibiti, bẹ́ẹ̀ ni wọ́n yípadà kúrò ní ọ̀dọ̀ wọn, wọn kò sì pa wọ́n run.
Oto teraz synowie Ammona i Moabu oraz [lud] z góry Seir, przez których nie dopuściłeś Izraelowi przejść, gdy szedł z ziemi Egiptu, tak że ominęli ich i nie wytracili;
11 Sì kíyèsi i, bí wọ́n ti san án padà fún wa; láti wá lé wa jáde kúrò nínú ìní rẹ, tí ìwọ ti fi fún wa láti ní.
Oto [jak] nam odpłacają! Przyszli, aby wyrzucić nas z twojego dziedzictwa, które nam dałeś w posiadanie.
12 Ọlọ́run wa, ṣé ìwọ kò ní ṣe ìdájọ́ fún wọn? Nítorí àwa kò ní agbára láti dojúkọ àwọn ọ̀pọ̀ ogun ńlá yìí tí ń bọ̀ wá kó wa. Àwa kò mọ̀ ohun tó yẹ ká ṣe, ṣùgbọ́n ojú wa wà ní ọ̀dọ̀ rẹ.”
O nasz Boże, czy nie osądzisz ich? Nie mamy bowiem żadnej mocy przeciw tak wielkiemu mnóstwu, które przyszło na nas, i nie wiemy, co mamy czynić, ale [zwracamy] nasze oczy ku tobie.
13 Gbogbo àwọn ọkùnrin Juda, pẹ̀lú àwọn aya wọn àti ọmọ wọn àti àwọn kéékèèké, dúró níbẹ̀ níwájú Olúwa.
A cały lud Judy stał przed PANEM z małymi dziećmi, żonami i synami.
14 Nígbà náà, ẹ̀mí Olúwa sì bà lé Jahasieli ọmọ Sekariah, ọmọ Benaiah, ọmọ Jeieli, ọmọ Mattaniah ọmọ Lefi àti ọmọ Asafu, gẹ́gẹ́ bí ó ṣe dìde dúró láàrín àpéjọ ènìyàn.
Wówczas pośród zgromadzenia Duch PANA zstąpił na Jehaziela, syna Zachariasza, syna Benajasza, syna Jejela, syna Mattaniasza, Lewitę z synów Asafa;
15 Ó sì wí pé, “Ẹ tẹ́tí sílẹ̀, ọba Jehoṣafati àti gbogbo àwọn tí ń gbé ní Juda àti Jerusalẹmu! Èyí ní ohun tí Olúwa sọ wí pé kí a ṣe: ‘Ẹ má ṣe bẹ̀rù tàbí fòyà nítorí ọ̀pọ̀ ogun ńlá yìí. Nítorí ogun náà kì í ṣe tiyín, ṣùgbọ́n ti Ọlọ́run ni.
Który powiedział: Słuchajcie, wszyscy z Judy i mieszkańcy Jerozolimy, i ty, królu Jehoszafacie. [Tak] mówi do was PAN: Nie bójcie się ani nie lękajcie tego wielkiego mnóstwa, bo nie wasza [jest] ta walka, ale Boża.
16 Ní ọ̀la, ẹ sọ̀kalẹ̀ tọ̀ wọ́n lọ, wọn yóò gòkè pẹ̀lú, ẹ̀yin yóò sì rí wọn ní ìpẹ̀kun odò náà, níwájú aginjù Jerueli.
Jutro ruszajcie przeciwko nim. Oto będą iść zboczem [góry] Sis i znajdziecie ich na końcu potoku przed pustynią Jeruel.
17 Ẹ̀yin kò ní láti bá ogun yìí jà. ẹ dúró ní ààyè yín; ẹ dúró jẹ́ẹ́ kí ẹ sì rí ìgbàlà Olúwa tí yóò fi fún yín, ìwọ Juda àti Jerusalẹmu. Ẹ má ṣe bẹ̀rù; ẹ má sì ṣe fòyà. Ẹ jáde lọ láti lọ dojúkọ wọ́n ní ọ̀la, Olúwa yóò sì wà pẹ̀lú yín.’”
Nie wy będziecie się potykać w tej [bitwie]. Stawcie się, stójcie i oglądajcie wybawienie PANA nad wami, o Judo i Jerozolimo. Nie bójcie się ani nie lękajcie. Jutro wyruszajcie przeciwko nim, a PAN [będzie] z wami.
18 Jehoṣafati tẹ orí rẹ̀ ba sílẹ̀ pẹ̀lú ojú rẹ̀, àti gbogbo àwọn ènìyàn Juda àti Jerusalẹmu wólẹ̀ níwájú láti sin Olúwa.
I pokłonił się Jehoszafat twarzą ku ziemi, a cały lud Judy oraz mieszkańcy Jerozolimy padli przed PANEM, oddając PANU pokłon.
19 Nígbà náà díẹ̀ lára àwọn ọmọ Lefi àti àwọn ọmọ Kohati àti àwọn ọmọ Kora sì dìde dúró wọ́n sì sin Olúwa, Ọlọ́run Israẹli, pẹ̀lú ohùn ariwo ńlá.
A Lewici z synów Kehata i z synów Koracha wstali i chwalili PANA, Boga Izraela, donośnym i wysokim głosem.
20 Ní òwúrọ̀ kùtùkùtù wọ́n jáde lọ sí aginjù Tekoa. Gẹ́gẹ́ bí wọ́n ti ń jáde lọ, Jehoṣafati dìde dúró ó sì wí pé, “Ẹ gbọ́ mi, Juda àti ènìyàn Jerusalẹmu! Ẹ ní ìgbàgbọ́ nínú Olúwa Ọlọ́run yín ẹ̀yin yóò sì borí, ẹ ní ìgbàgbọ́ nínú àwọn wòlíì rẹ̀ ẹ̀yìn yóò sì ṣe rere.”
Wstali potem wczesnym rankiem i wyruszyli na pustynię Tekoa. A gdy wyruszali, Jehoszafat stanął i powiedział: Słuchajcie mnie, Judo i mieszkańcy Jerozolimy. Wierzcie PANU, waszemu Bogu, a będziecie bezpieczni, wierzcie jego prorokom, a poszczęści się wam.
21 Lẹ́yìn ìgbà tí ó bá àwọn ènìyàn náà gbèrò tán, Jehoṣafati yàn wọ́n láti kọrin sí Olúwa àti láti fi ìyìn fún ẹwà ìwà mímọ́ gẹ́gẹ́ bí ó tì ń jáde lọ sí iwájú ogun ńlá náà, wí pé, “Ẹ fi ọpẹ́ fún Olúwa, nítorí àánú rẹ̀ dúró títí láéláé.”
Potem naradził się z ludem i ustanowił śpiewaków dla PANA, by [go] chwalili w ozdobie świętobliwości i szli przed wojskiem, mówiąc: Wysławiajcie PANA, bo na wieki [trwa] jego miłosierdzie.
22 Bí wọ́n ti bẹ̀rẹ̀ sí kọrin àti ìyìn, Olúwa rán ogun ẹ̀yìn sí àwọn ọkùnrin Ammoni àti Moabu àti òkè Seiri tí ó ń gbógun ti Juda, wọ́n sì kọlù wọ́n.
A w tym czasie, gdy oni zaczęli śpiewać i chwalić, PAN zastawił zasadzkę na synów Ammona i Moabu oraz na [mieszkańców] góry Seir, którzy przyszli przeciw Judzie i zostali pobici.
23 Àwọn ọkùnrin Ammoni àti Moabu dìde dúró sí àwọn ọkùnrin tí ń gbé òkè Seiri láti pa wọ́n run túútúú. Lẹ́yìn ìgbà tí wọ́n sì ti pa àwọn ọkùnrin láti òkè Seiri, wọ́n sì ran ra wọn lọ́wọ́ láti pa ara wọn run.
Powstali bowiem synowie Ammona i Moabu przeciwko mieszkańcom góry Seir, aby ich pobić i wytracić. A gdy skończyli z mieszkańcami góry Seir, jeden pomagał drugiemu, aż się wspólnie wytracili.
24 Nígbà tí àwọn ènìyàn Juda jáde sí ìhà ilé ìṣọ́ ní aginjù, wọn ń wo àwọn ọ̀pọ̀ ènìyàn, òkú nìkan ni wọ́n rí tí ó ṣubú sí ilẹ̀, kò sì sí ẹnìkan tí ó rí ààyè sá.
A kiedy [lud] Judy przybył do wieży strażniczej, blisko pustyni, [spojrzał] na to mnóstwo, a oto trupy leżały na ziemi, nikt nie ocalał.
25 Bẹ́ẹ̀ ni Jehoṣafati àti àwọn ènìyàn rẹ̀ lọ láti kó ìkógun wọn, wọ́n sì rí lára wọn ọ̀pọ̀ iyebíye ọrọ̀ púpọ̀, ó sì ju èyí tí wọ́n lè kó lọ. Ọ̀pọ̀ ìkógun sì wà níbẹ̀, èyí tí ó gbà wọ́n ní ọjọ́ mẹ́ta láti gbà pọ̀.
Przyszedł więc Jehoszafat i jego lud, aby zebrać ich łupy. Znaleźli przy nich, pośród zwłok, bardzo dużo bogactwa i kosztownych klejnotów, które zdarli [z trupów], tak [wiele], że nie mogli tego udźwignąć. Przez trzy dni zbierali te łupy, bo [było] ich tak dużo.
26 Ní ọjọ́ kẹrin, wọn kó ara jọ pọ̀ ní àfonífojì ìbùkún, níbi tí wọ́n ti ń fi ìbùkún fún Olúwa. Ìdí nìyí tí wọ́n fi ń pe ibẹ̀ ní àfonífojì ìbùkún títí di òní.
A w czwartym dniu zebrali się w Dolinie Beraka, bo tam błogosławili PANA. Dlatego nazwano to miejsce Doliną Beraka i tak [nazywa się] aż do dziś.
27 Nígbà náà wọ́n darí pẹ̀lú Jehoṣafati, gbogbo àwọn ènìyàn Juda àti Jerusalẹmu padà pẹ̀lú ayọ̀ sí Jerusalẹmu, nítorí Olúwa ti fún wọn ní ìdí láti yọ̀ lórí àwọn ọ̀tá wọn.
Potem zawrócili wszyscy mężczyźni Judy i Jerozolimy, z Jehoszafatem na czele, aby wrócić do Jerozolimy z radością. PAN bowiem ich rozradował z powodu ich wrogów.
28 Wọ́n sì wọ Jerusalẹmu, wọ́n sì lọ sí ilé Olúwa pẹ̀lú ohun èlò orin olókùn àti dùùrù àti ìpè.
I wkroczyli do Jerozolimy z harfami, cytrami i trąbami – do domu PANA.
29 Ìbẹ̀rù Ọlọ́run wá si orí gbogbo ìjọba ilẹ̀ náà nígbà tí wọ́n gbọ́ bí Olúwa ti bá àwọn ọ̀tá Israẹli jà.
I strach Boży padł na wszystkie królestwa ziemi, gdy usłyszały, że PAN walczył przeciw wrogom ludu Izraela.
30 Bẹ́ẹ̀ ni ìjọba Jehoṣafati sì wà ní àlàáfíà, nítorí Ọlọ́run rẹ̀ ti fún un ni ìsinmi ní gbogbo àyíká.
I tak królestwo Jehoszafata żyło w pokoju. Jego Bóg bowiem dał mu odpoczynek ze wszystkich stron.
31 Báyìí ni Jehoṣafati jẹ ọba lórí Juda. Ó sì jẹ́ ẹni ọdún márùndínlógójì. Nígbà tí ó di ọba Juda, ó sì jẹ ọba ní Jerusalẹmu fún ọdún mẹ́ẹ̀ẹ́dọ́gbọ̀n. Orúkọ ìyá rẹ̀ sì ni Asuba ọmọbìnrin Silihi.
I Jehoszafat królował nad Judą. Miał trzydzieści pięć lat, kiedy zaczął królować, i dwadzieścia pięć lat królował w Jerozolimie. Jego matka [miała] na imię Azuba [i była] córką Szilchiego.
32 Ó sì rin ọ̀nà baba rẹ̀ Asa kò sì yà kúrò nínú rẹ̀, ó sì ṣe èyí tí ó tọ́ ní ojú Olúwa.
A kroczył on drogą swojego ojca Asy i nie zboczył z niej, czyniąc to, co było prawe w oczach PANA.
33 Ní ibi gíga, pẹ̀lúpẹ̀lú, kò mu wọn kúrò, gbogbo àwọn ènìyàn náà kò sì fi ọkàn wọn fún Ọlọ́run àwọn baba wọn.
Wyżyny jednak nie zostały zniesione, bo lud jeszcze nie przygotował swojego serca ku Bogu swoich ojców.
34 Ìyókù iṣẹ́ ìjọba Jehoṣafati, láti ìbẹ̀rẹ̀ títí dé òpin, ni a kọ sí inú ìwé ìtàn ti Jehu ọmọ Hanani, tí a kọ sí inú ìwé àwọn ọba Israẹli.
A pozostałe dzieje Jehoszafata, od pierwszych do ostatnich, są zapisane w księdze Jehu, syna Chananiego, o którym [jest] napisane w księdze królów Izraela.
35 Nígbà tí ó yá, Jehoṣafati ọba Juda da ara rẹ̀ pọ̀ pẹ̀lú Ahasiah, ọba Israẹli, ẹni tí ó jẹ̀bi ìwà búburú.
Potem Jehoszafat, król Judy, sprzymierzył się z Achazjaszem, królem Izraela, który postępował niegodziwie.
36 Ó sì gbà pẹ̀lú rẹ̀ láti kan ọkọ̀ láti lọ sí Tarṣiṣi, lẹ́yìn èyí wọ́n kan ọkọ̀ ní Esioni-Geberi.
A sprzymierzył się z nim po to, aby zbudować okręty płynące do Tarszisz. Te okręty zbudowali w Esjon-Geber.
37 Elieseri ọmọ Dodafahu ti Meraṣa sọtẹ́lẹ̀ sí Jehoṣafati, wí pe, “Nítorí tí ìwọ ti da ara rẹ̀ pọ̀ mọ́ Ahasiah, Olúwa yóò pa ohun ti ìwọ ti ṣe run.” Àwọn ọkọ̀ náà sì fọ́, wọn kò sì le lọ sí ibi ìtajà.
Dlatego Eliezer, syn Dodawahu z Mareszy, prorokował przeciwko Jehoszafatowi, mówiąc: Ponieważ sprzymierzyłeś się z Achazjaszem, PAN zniszczył twoje dzieło. I rozbiły się okręty tak, że nie mogły popłynąć do Tarszisz.

< 2 Chronicles 20 >