< 2 Chronicles 20 >

1 Lẹ́yìn èyí, àwọn ọmọ Moabu àti àwọn ọmọ Ammoni àti díẹ̀ nínú àwọn ọmọ Mehuni wá láti gbé ogun ti Jehoṣafati.
Na rĩrĩ, thuutha wa ũguo, andũ a Moabi, na andũ a Amoni marĩ hamwe na Ameuni amwe magĩũka kũrũa na Jehoshafatu.
2 Àwọn díẹ̀ nínú àwọn ọkùnrin wá láti sọ fún Jehoṣafati, “Àwọn ọ̀pọ̀ ọ̀wọ́ ogun ń bọ̀ wá bá ọ láti apá kejì Òkun láti Siria. Ó ti wà ní Hasason Tamari náà” (èyí tí í ṣe En-Gedi).
Andũ amwe magĩũka makĩĩra Jehoshafatu atĩrĩ, “Mbũtũ nene ya ita kuuma Edomu nĩĩroka kũrũa nawe, yumĩte mũrĩmo ũrĩa ũngĩ wa iria. O na rĩu nĩĩkinyĩte Hazezoni-Tamaru” (na nokuo Eni-Gedi).
3 Nípa ìró ìdágìrì, Jehoṣafati pinnu láti wádìí lọ́wọ́ Olúwa, ó sì kéde àwẹ̀ kíákíá fún gbogbo Juda.
Jehoshafatu akĩmaka, na agĩtua itua orie ũtaaro harĩ Jehova, nake akĩanĩrĩra Juda guothe kwĩhingwo kũrĩa irio.
4 Àwọn ènìyàn Juda sì kó ara wọn jọ pọ̀ láti wá ìrànlọ́wọ́ láti ọ̀dọ̀ Olúwa; pẹ̀lúpẹ̀lú, wọ́n wá láti gbogbo ìlú ní Juda láti wá a.
Nao andũ a Juda makĩũngana meethe ũteithio kuuma kũrĩ Jehova; ti-itherũ magĩũka kuuma matũũra mothe ma Juda nĩguo mamũrongorie.
5 Nígbà náà Jehoṣafati dìde dúró níwájú àpéjọ Juda àti Jerusalẹmu ní ilé Olúwa níwájú àgbàlá tuntun.
Nake Jehoshafatu akĩrũgama mbere ya kĩũngano kĩu kĩa andũ a Juda na Jerusalemu, o hau hekarũ-inĩ ya Jehova o mbere ya nja ĩrĩa yarĩ njerũ,
6 O sì wí pé, “Olúwa, Ọlọ́run àwọn baba wa, ìwọ kì ha ṣe Ọlọ́run tí ń bẹ ní ọ̀run? Ìwọ ń ṣe alákòóso lórí gbogbo ìjọba àwọn orílẹ̀-èdè. Agbára àti ipá ń bẹ ní ọwọ́ rẹ, kò sì sí ẹnìkan tí ó lè kò ọ́ lójú.
akiuga atĩrĩ: “Wee Jehova, Ngai wa maithe maitũ, githĩ tiwe Ngai ũrĩa ũrĩ igũrũ? Nĩwe ũthamakagĩra mothamaki mothe ma ndũrĩrĩ. Hinya na ũhoti irĩ guoko-inĩ gwaku, na gũtirĩ mũndũ ũngĩgwĩtiiria.
7 Ìwọ ha kọ́ Ọlọ́run wa, tí o ti lé àwọn olùgbé ilẹ̀ yìí jáde níwájú àwọn ènìyàn Israẹli, tí o sì fi fún irú-ọmọ Abrahamu ọ̀rẹ́ rẹ láéláé?
Wee Ngai witũ-rĩ, githĩ ndwaingatire arĩa maikaraga bũrũri ũyũ mbere ya andũ aku a Isiraeli na ũkĩũhe njiaro cia mũrataguo Iburahĩmu nginya tene?
8 Wọ́n ti ń gbé nínú rẹ̀ wọ́n sì ti kọ́ sínú rẹ ibi mímọ́ fún orúkọ rẹ wí pé,
Nĩmatũũrĩte kuo o na magaaka hekarũ kuo ĩrĩa ĩtanĩtio na Rĩĩtwa rĩaku, makiugaga atĩrĩ,
9 ‘Tí ibi bá wá sí orí wa, bóyá idà ìjìyà tàbí àjàkálẹ̀-ààrùn àwọn yóò dúró níwájú rẹ níwájú ilé yìí tí ń jẹ́ orúkọ rẹ, àwa yóò sì sọkún jáde, ìwọ yóò sì gbọ́ wa. Ìwọ yóò sì gbà wá là?’
‘Mũtino ũngĩgatũkora o na ũrĩ wa rũhiũ rwa njora rwa gũtũrũithia, kana mũthiro kana ngʼaragu, tũkaarũgama mbere yaku hekarũ-inĩ ĩno ĩtanĩtio na Rĩĩtwa rĩaku, nĩtũgaagũkaĩra tũrĩ hatĩka-inĩ, nawe nĩũgatũigua ũtũhonokie.’
10 “Ṣùgbọ́n nísinsin yìí, àwọn ọkùnrin nìyí láti Ammoni, Moabu àti òkè Seiri, agbègbè ibi ti ìwọ kò ti gba àwọn ọmọ Israẹli láyè láti gbóguntì nígbà tí wọn wá láti Ejibiti, bẹ́ẹ̀ ni wọ́n yípadà kúrò ní ọ̀dọ̀ wọn, wọn kò sì pa wọ́n run.
“No rĩu, haha harĩ na andũ a kuuma Amoni, na Moabi, na Kĩrĩma kĩa Seiru, arĩa wagiririe andũ a Isiraeli matharĩkĩre mabũrũri mao rĩrĩa moimaga Misiri; nĩ ũndũ ũcio makĩmeherera na matiigana kũmaniina.
11 Sì kíyèsi i, bí wọ́n ti san án padà fún wa; láti wá lé wa jáde kúrò nínú ìní rẹ, tí ìwọ ti fi fún wa láti ní.
Ta kĩone kĩrĩa maragĩtũrĩha nakĩo, tondũ mokĩte gũtũingata kũrĩa watũheire gũtuĩke igai riitũ.
12 Ọlọ́run wa, ṣé ìwọ kò ní ṣe ìdájọ́ fún wọn? Nítorí àwa kò ní agbára láti dojúkọ àwọn ọ̀pọ̀ ogun ńlá yìí tí ń bọ̀ wá kó wa. Àwa kò mọ̀ ohun tó yẹ ká ṣe, ṣùgbọ́n ojú wa wà ní ọ̀dọ̀ rẹ.”
Wee Ngai witũ, githĩ ndũgũkĩmatuĩra ciira? Nĩ ũndũ-rĩ, ithuĩ tũtirĩ na hinya wa kũngʼethanĩra na mbũtũ ĩno nene ũũ ĩrooka gũtũtharĩkĩra. Tũtiũĩ ũrĩa tũgwĩka, no rĩrĩ, maitho maitũ nĩwe macũthĩrĩirie.”
13 Gbogbo àwọn ọkùnrin Juda, pẹ̀lú àwọn aya wọn àti ọmọ wọn àti àwọn kéékèèké, dúró níbẹ̀ níwájú Olúwa.
Arũme othe a Juda, na atumia ao, na ciana na twana twao twa ngenge, makĩrũgama o hau mbere ya Jehova.
14 Nígbà náà, ẹ̀mí Olúwa sì bà lé Jahasieli ọmọ Sekariah, ọmọ Benaiah, ọmọ Jeieli, ọmọ Mattaniah ọmọ Lefi àti ọmọ Asafu, gẹ́gẹ́ bí ó ṣe dìde dúró láàrín àpéjọ ènìyàn.
Na hĩndĩ ĩyo Roho wa Jehova ũgĩkinyĩrĩra Jahazieli mũrũ wa Zekaria mũrũ wa Benaia, mũrũ wa Jeieli mũrũ wa Matania ũrĩa Mũlawii wa rũciaro rwa Asafu rĩrĩa aarũgamĩte kĩũngano-inĩ kĩu.
15 Ó sì wí pé, “Ẹ tẹ́tí sílẹ̀, ọba Jehoṣafati àti gbogbo àwọn tí ń gbé ní Juda àti Jerusalẹmu! Èyí ní ohun tí Olúwa sọ wí pé kí a ṣe: ‘Ẹ má ṣe bẹ̀rù tàbí fòyà nítorí ọ̀pọ̀ ogun ńlá yìí. Nítorí ogun náà kì í ṣe tiyín, ṣùgbọ́n ti Ọlọ́run ni.
Nake akiuga atĩrĩ, “Ta thikĩrĩria, wee Mũthamaki Jehoshafatu na arĩa othe mũtũũraga Juda na Jerusalemu! Ũũ nĩguo Jehova ekũmwĩra: ‘Mũtigetigĩre kana mũkue ngoro nĩ ũndũ wa mbũtũ ĩno nene ya ita. Nĩgũkorwo mbaara ĩno ti yanyu, no nĩ ya Ngai.
16 Ní ọ̀la, ẹ sọ̀kalẹ̀ tọ̀ wọ́n lọ, wọn yóò gòkè pẹ̀lú, ẹ̀yin yóò sì rí wọn ní ìpẹ̀kun odò náà, níwájú aginjù Jerueli.
Rũciũ, rokai gũikũrũka mũmatharĩkĩre. Magaakorwo makĩhaica magereire Mwanya-inĩ wa Zizi na nĩmũkamakorerera mũthia-inĩ wa mũkuru wa kũu Werũ wa Jerueli.
17 Ẹ̀yin kò ní láti bá ogun yìí jà. ẹ dúró ní ààyè yín; ẹ dúró jẹ́ẹ́ kí ẹ sì rí ìgbàlà Olúwa tí yóò fi fún yín, ìwọ Juda àti Jerusalẹmu. Ẹ má ṣe bẹ̀rù; ẹ má sì ṣe fòyà. Ẹ jáde lọ láti lọ dojúkọ wọ́n ní ọ̀la, Olúwa yóò sì wà pẹ̀lú yín.’”
Ti inyuĩ mũkũrũa mbaara ĩno. Rũgamai mwena wanyu, mwĩhaandei wega na mwĩonere ũrĩa Jehova ekũmũhonokia, inyuĩ andũ a Juda na a Jerusalemu. Mũtigetigĩre, na mũtigakue ngoro. Umagarai mũkangʼethanĩre nao rũciũ, nake Jehova nĩagakorwo hamwe na inyuĩ.’”
18 Jehoṣafati tẹ orí rẹ̀ ba sílẹ̀ pẹ̀lú ojú rẹ̀, àti gbogbo àwọn ènìyàn Juda àti Jerusalẹmu wólẹ̀ níwájú láti sin Olúwa.
Jehoshafatu akĩinamĩrĩra, agĩturumithia ũthiũ thĩ, nao andũ othe a Juda na a Jerusalemu makĩĩgũithia thĩ mbere ya Jehova, makĩmũhooya.
19 Nígbà náà díẹ̀ lára àwọn ọmọ Lefi àti àwọn ọmọ Kohati àti àwọn ọmọ Kora sì dìde dúró wọ́n sì sin Olúwa, Ọlọ́run Israẹli, pẹ̀lú ohùn ariwo ńlá.
Ningĩ Alawii amwe a kuuma rũciaro rwa Kohathu na rwa Kora magĩũkĩra na igũrũ, magĩkumia Jehova Ngai wa Isiraeli maanĩrĩire na mũgambo mũnene mũno.
20 Ní òwúrọ̀ kùtùkùtù wọ́n jáde lọ sí aginjù Tekoa. Gẹ́gẹ́ bí wọ́n ti ń jáde lọ, Jehoṣafati dìde dúró ó sì wí pé, “Ẹ gbọ́ mi, Juda àti ènìyàn Jerusalẹmu! Ẹ ní ìgbàgbọ́ nínú Olúwa Ọlọ́run yín ẹ̀yin yóò sì borí, ẹ ní ìgbàgbọ́ nínú àwọn wòlíì rẹ̀ ẹ̀yìn yóò sì ṣe rere.”
Rũciinĩ tene mũno makiuma merekeire Werũ wa Tekoa. Na rĩrĩa maambĩrĩirie kuuma-rĩ, Jehoshafatu akĩrũgama, akiuga atĩrĩ, “Ta thikĩrĩriai, inyuĩ andũ a Juda o na a Jerusalemu! Ĩtĩkiai Jehova Ngai wanyu na nĩekũmũtirĩrĩra; ĩtĩkiai anabii ake na nĩmũkũgaacĩra.”
21 Lẹ́yìn ìgbà tí ó bá àwọn ènìyàn náà gbèrò tán, Jehoṣafati yàn wọ́n láti kọrin sí Olúwa àti láti fi ìyìn fún ẹwà ìwà mímọ́ gẹ́gẹ́ bí ó tì ń jáde lọ sí iwájú ogun ńlá náà, wí pé, “Ẹ fi ọpẹ́ fún Olúwa, nítorí àánú rẹ̀ dúró títí láéláé.”
Thuutha wa kwaranĩria na andũ, Jehoshafatu agĩthuura andũ a kũinĩra Jehova na a kũmũgooca nĩ ũndũ wa riiri wa ũtheru wake, nao hĩndĩ ĩrĩa megũtongoria mbũtũ ĩyo ya ita, makiugaga atĩrĩ: “Cookeriai Jehova ngaatho, nĩgũkorwo wendo wake ũtũũraga nginya tene.”
22 Bí wọ́n ti bẹ̀rẹ̀ sí kọrin àti ìyìn, Olúwa rán ogun ẹ̀yìn sí àwọn ọkùnrin Ammoni àti Moabu àti òkè Seiri tí ó ń gbógun ti Juda, wọ́n sì kọlù wọ́n.
Na rĩrĩa maambĩrĩirie kũina o na kũgooca-rĩ, Jehova akĩiga andũ mohie andũ a Amoni, na a Moabi, na andũ a kuuma Kĩrĩma kĩa Seiru arĩa maatharĩkagĩra Juda, nao magĩtoorio.
23 Àwọn ọkùnrin Ammoni àti Moabu dìde dúró sí àwọn ọkùnrin tí ń gbé òkè Seiri láti pa wọ́n run túútúú. Lẹ́yìn ìgbà tí wọ́n sì ti pa àwọn ọkùnrin láti òkè Seiri, wọ́n sì ran ra wọn lọ́wọ́ láti pa ara wọn run.
Nao andũ a Amoni na a Moabi magĩũkĩrĩra andũ a kuuma Kĩrĩma kĩa Seiru, makĩmananga na makĩmaniina biũ. Maarĩkia kũũraga andũ a kuuma Seiru, magĩteithĩrĩria kũniinana o ene.
24 Nígbà tí àwọn ènìyàn Juda jáde sí ìhà ilé ìṣọ́ ní aginjù, wọn ń wo àwọn ọ̀pọ̀ ènìyàn, òkú nìkan ni wọ́n rí tí ó ṣubú sí ilẹ̀, kò sì sí ẹnìkan tí ó rí ààyè sá.
Hĩndĩ ĩrĩa andũ a Juda maakinyire harĩa hangʼethanĩire na werũ-rĩ, magĩcũthĩrĩria mbũtũ ĩyo nene ya ita, makĩona no ciimba theri ciagwĩte thĩ; gũtirĩ mũndũ o na ũmwe wetharĩte.
25 Bẹ́ẹ̀ ni Jehoṣafati àti àwọn ènìyàn rẹ̀ lọ láti kó ìkógun wọn, wọ́n sì rí lára wọn ọ̀pọ̀ iyebíye ọrọ̀ púpọ̀, ó sì ju èyí tí wọ́n lè kó lọ. Ọ̀pọ̀ ìkógun sì wà níbẹ̀, èyí tí ó gbà wọ́n ní ọjọ́ mẹ́ta láti gbà pọ̀.
Nĩ ũndũ ũcio Jehoshafatu na andũ ake magĩthiĩ gũtaha indo, na thĩinĩ wacio makĩona indo nyingĩ na nguo o na indo cia goro nyingĩ gũkĩra ũrĩa mangĩahotire gũkuua. Ciarĩ nyingĩ ũũ atĩ maaniinire mĩthenya ĩtatũ gũciũngania.
26 Ní ọjọ́ kẹrin, wọn kó ara jọ pọ̀ ní àfonífojì ìbùkún, níbi tí wọ́n ti ń fi ìbùkún fún Olúwa. Ìdí nìyí tí wọ́n fi ń pe ibẹ̀ ní àfonífojì ìbùkún títí di òní.
Mũthenya wa kana makĩũngana Gĩtuamba-inĩ kĩa Beraka, kũrĩa maagooceire Jehova. Kĩu nĩkĩo gĩtũmaga gwĩtwo Gĩtuamba kĩa Beraka nginya ũmũthĩ.
27 Nígbà náà wọ́n darí pẹ̀lú Jehoṣafati, gbogbo àwọn ènìyàn Juda àti Jerusalẹmu padà pẹ̀lú ayọ̀ sí Jerusalẹmu, nítorí Olúwa ti fún wọn ní ìdí láti yọ̀ lórí àwọn ọ̀tá wọn.
Hĩndĩ ĩyo andũ othe a Juda na a Jerusalemu, matongoretio nĩ Jehoshafatu, magĩcooka Jerusalemu makenete, nĩgũkorwo Jehova nĩamaheete gĩtũmi gĩa gũkenerera thũ ciao.
28 Wọ́n sì wọ Jerusalẹmu, wọ́n sì lọ sí ilé Olúwa pẹ̀lú ohun èlò orin olókùn àti dùùrù àti ìpè.
Magĩtoonya Jerusalemu na magĩthiĩ hekarũ-inĩ ya Jehova marĩ na inanda cia mũgeeto, na mĩtũrirũ, na tũrumbeta.
29 Ìbẹ̀rù Ọlọ́run wá si orí gbogbo ìjọba ilẹ̀ náà nígbà tí wọ́n gbọ́ bí Olúwa ti bá àwọn ọ̀tá Israẹli jà.
Namo mothamaki mothe ma mabũrũri magĩĩtigĩra Ngai rĩrĩa maiguire ũrĩa Jehova aarũĩte na thũ cia Isiraeli.
30 Bẹ́ẹ̀ ni ìjọba Jehoṣafati sì wà ní àlàáfíà, nítorí Ọlọ́run rẹ̀ ti fún un ni ìsinmi ní gbogbo àyíká.
Naguo ũthamaki wa Jehoshafatu ũgĩikara ũrĩ na thayũ, nĩgũkorwo Ngai wake nĩamũheete ũhurũko mĩena-inĩ yothe.
31 Báyìí ni Jehoṣafati jẹ ọba lórí Juda. Ó sì jẹ́ ẹni ọdún márùndínlógójì. Nígbà tí ó di ọba Juda, ó sì jẹ ọba ní Jerusalẹmu fún ọdún mẹ́ẹ̀ẹ́dọ́gbọ̀n. Orúkọ ìyá rẹ̀ sì ni Asuba ọmọbìnrin Silihi.
Nĩ ũndũ ũcio, Jehoshafatu agĩthamakĩra Juda; nake aarĩ wa mĩaka mĩrongo ĩtatũ na ĩtano rĩrĩa aatuĩkire mũthamaki wa Juda, na agĩthamaka arĩ Jerusalemu mĩaka mĩrongo ĩĩrĩ na ĩtano. Nyina eetagwo Azuba mwarĩ wa Shilihi.
32 Ó sì rin ọ̀nà baba rẹ̀ Asa kò sì yà kúrò nínú rẹ̀, ó sì ṣe èyí tí ó tọ́ ní ojú Olúwa.
Nake akĩrũmĩrĩra mĩthiĩre ya ithe Asa na ndaigana gũtigana nayo; agĩĩka ũrĩa kwagĩrĩire maitho-inĩ ma Jehova.
33 Ní ibi gíga, pẹ̀lúpẹ̀lú, kò mu wọn kúrò, gbogbo àwọn ènìyàn náà kò sì fi ọkàn wọn fún Ọlọ́run àwọn baba wọn.
No rĩrĩ, kũndũ kũrĩa gũtũũgĩru gũtiigana kweherio, nao andũ matiigana kwerekeria ngoro ciao kũrĩ Ngai wa maithe mao.
34 Ìyókù iṣẹ́ ìjọba Jehoṣafati, láti ìbẹ̀rẹ̀ títí dé òpin, ni a kọ sí inú ìwé ìtàn ti Jehu ọmọ Hanani, tí a kọ sí inú ìwé àwọn ọba Israẹli.
Ciĩko iria ingĩ cia wathani wa Jehoshafatu kuuma kĩambĩrĩria nginya mũthia, nĩciandĩkĩtwo ibuku-inĩ rĩa maũndũ ma o mwaka rĩa Jehu mũrũ wa Hanani, marĩa mandĩkĩtwo ibuku-inĩ rĩa athamaki a Isiraeli.
35 Nígbà tí ó yá, Jehoṣafati ọba Juda da ara rẹ̀ pọ̀ pẹ̀lú Ahasiah, ọba Israẹli, ẹni tí ó jẹ̀bi ìwà búburú.
Thuutha ũcio Jehoshafatu mũthamaki wa Juda agĩtuma ũrata na Ahazia mũthamaki wa Isiraeli, ũrĩa warĩ na maũndũ maingĩ ma waganu.
36 Ó sì gbà pẹ̀lú rẹ̀ láti kan ọkọ̀ láti lọ sí Tarṣiṣi, lẹ́yìn èyí wọ́n kan ọkọ̀ ní Esioni-Geberi.
Makĩiguana nake atĩ maake marikabu cia wonjoria. Nao maarĩkia gũciakĩra kũu Ezioni-Geberi,
37 Elieseri ọmọ Dodafahu ti Meraṣa sọtẹ́lẹ̀ sí Jehoṣafati, wí pe, “Nítorí tí ìwọ ti da ara rẹ̀ pọ̀ mọ́ Ahasiah, Olúwa yóò pa ohun ti ìwọ ti ṣe run.” Àwọn ọkọ̀ náà sì fọ́, wọn kò sì le lọ sí ibi ìtajà.
Eliezeri mũrũ wa Dodavahu wa kuuma Maresha akĩrathĩra Jehoshafatu ũrathi wa ũrĩa akoona ũũru, akiuga atĩrĩ, “Tondũ nĩũgĩĩte ũrata na Ahazia, Jehova nĩekwananga kĩrĩa wakĩte.” Nacio marikabu igĩtharũranio, na itiigana gũthiĩ iria-inĩ ikarute wĩra wa wonjoria.

< 2 Chronicles 20 >