< 2 Chronicles 20 >

1 Lẹ́yìn èyí, àwọn ọmọ Moabu àti àwọn ọmọ Ammoni àti díẹ̀ nínú àwọn ọmọ Mehuni wá láti gbé ogun ti Jehoṣafati.
Après cela, les fils de Moab, les fils d'Ammon, et, avec eux, des Minéens, se mirent en campagne pour attaquer Josaphat.
2 Àwọn díẹ̀ nínú àwọn ọkùnrin wá láti sọ fún Jehoṣafati, “Àwọn ọ̀pọ̀ ọ̀wọ́ ogun ń bọ̀ wá bá ọ láti apá kejì Òkun láti Siria. Ó ti wà ní Hasason Tamari náà” (èyí tí í ṣe En-Gedi).
Et des gens vinrent et ils l'apprirent au roi, disant: Une grande multitude est venue contre toi des bords de la mer, du côté de la Syrie, et la voici en Asasan-Thamar (la même qu'Engaddi).
3 Nípa ìró ìdágìrì, Jehoṣafati pinnu láti wádìí lọ́wọ́ Olúwa, ó sì kéde àwẹ̀ kíákíá fún gbogbo Juda.
Et Josaphat eut crainte, et il s'appliqua à chercher le Seigneur, et il proclama un jeûne dans tout Juda.
4 Àwọn ènìyàn Juda sì kó ara wọn jọ pọ̀ láti wá ìrànlọ́wọ́ láti ọ̀dọ̀ Olúwa; pẹ̀lúpẹ̀lú, wọ́n wá láti gbogbo ìlú ní Juda láti wá a.
Et Juda se rassembla pour chercher le Seigneur; et, de toutes les villes de Juda, on vint pour chercher le Seigneur.
5 Nígbà náà Jehoṣafati dìde dúró níwájú àpéjọ Juda àti Jerusalẹmu ní ilé Olúwa níwájú àgbàlá tuntun.
Et Josaphat, avec toute l'Église de Juda en Jérusalem, se tint debout dans le temple du Seigneur devant le parvis neuf.
6 O sì wí pé, “Olúwa, Ọlọ́run àwọn baba wa, ìwọ kì ha ṣe Ọlọ́run tí ń bẹ ní ọ̀run? Ìwọ ń ṣe alákòóso lórí gbogbo ìjọba àwọn orílẹ̀-èdè. Agbára àti ipá ń bẹ ní ọwọ́ rẹ, kò sì sí ẹnìkan tí ó lè kò ọ́ lójú.
Et il dit: Seigneur Dieu de mes pères, n'êtes-vous point Dieu dans le ciel au-dessus de nous? N'êtes-vous pas le Seigneur de tous les royaumes des nations? N'est-ce pas en vos mains que réside la force du pouvoir? Est-il quelqu'un qui puisse vous résister?
7 Ìwọ ha kọ́ Ọlọ́run wa, tí o ti lé àwọn olùgbé ilẹ̀ yìí jáde níwájú àwọn ènìyàn Israẹli, tí o sì fi fún irú-ọmọ Abrahamu ọ̀rẹ́ rẹ láéláé?
N'êtes-vous pas le Seigneur dont le bras a exterminé les habitants de cette terre, devant les fils d'Israël, votre peuple? Ne l'avez-vous point donnée pour toujours à la race d'Abraham, votre bien-aimé?
8 Wọ́n ti ń gbé nínú rẹ̀ wọ́n sì ti kọ́ sínú rẹ ibi mímọ́ fún orúkọ rẹ wí pé,
Elle y demeure; elle y a bâti un lieu saint à votre nom, disant
9 ‘Tí ibi bá wá sí orí wa, bóyá idà ìjìyà tàbí àjàkálẹ̀-ààrùn àwọn yóò dúró níwájú rẹ níwájú ilé yìí tí ń jẹ́ orúkọ rẹ, àwa yóò sì sọkún jáde, ìwọ yóò sì gbọ́ wa. Ìwọ yóò sì gbà wá là?’
Si le mal, le glaive, la vengeance, la mort, la famine, viennent sur nous, nous nous tiendrons devant le temple et devant vous, ô Seigneur, parce que votre nom est sur le temple, et, dans notre affliction, nous crierons à vous, et vous nous entendrez, et vous nous sauverez.
10 “Ṣùgbọ́n nísinsin yìí, àwọn ọkùnrin nìyí láti Ammoni, Moabu àti òkè Seiri, agbègbè ibi ti ìwọ kò ti gba àwọn ọmọ Israẹli láyè láti gbóguntì nígbà tí wọn wá láti Ejibiti, bẹ́ẹ̀ ni wọ́n yípadà kúrò ní ọ̀dọ̀ wọn, wọn kò sì pa wọ́n run.
Et maintenant, voilà que les fils d'Ammon, et Moab et ceux de la montagne de Seïr, chez qui vous n'avez point permis à Israël de passer, à sa sortie d'Égypte (car il s'est détourné de leurs territoires, et ne les a point exterminés),
11 Sì kíyèsi i, bí wọ́n ti san án padà fún wa; láti wá lé wa jáde kúrò nínú ìní rẹ, tí ìwọ ti fi fún wa láti ní.
Voilà qu'ils nous attaquent pour entrer dans l'héritage que vous nous avez donné, et pour nous en bannir.
12 Ọlọ́run wa, ṣé ìwọ kò ní ṣe ìdájọ́ fún wọn? Nítorí àwa kò ní agbára láti dojúkọ àwọn ọ̀pọ̀ ogun ńlá yìí tí ń bọ̀ wá kó wa. Àwa kò mọ̀ ohun tó yẹ ká ṣe, ṣùgbọ́n ojú wa wà ní ọ̀dọ̀ rẹ.”
Seigneur notre Dieu, ne les jugerez-vous pas? Car nous n'avons pas la force de résister à l'immense multitude qui marche contre nous, et nous ne savons que leur faire, sinon de tourner nos yeux vers vous.
13 Gbogbo àwọn ọkùnrin Juda, pẹ̀lú àwọn aya wọn àti ọmọ wọn àti àwọn kéékèèké, dúró níbẹ̀ níwájú Olúwa.
Or, tout Juda était là devant le Seigneur, avec leurs enfants et leurs femmes.
14 Nígbà náà, ẹ̀mí Olúwa sì bà lé Jahasieli ọmọ Sekariah, ọmọ Benaiah, ọmọ Jeieli, ọmọ Mattaniah ọmọ Lefi àti ọmọ Asafu, gẹ́gẹ́ bí ó ṣe dìde dúró láàrín àpéjọ ènìyàn.
Et, dans l'Église, l'Esprit du Seigneur descendit sur Oziel, fils de Zacharie, des fils de Bandias, des fils d'Elihel, fils du lévite Matthanias, des fils d'Asaph.
15 Ó sì wí pé, “Ẹ tẹ́tí sílẹ̀, ọba Jehoṣafati àti gbogbo àwọn tí ń gbé ní Juda àti Jerusalẹmu! Èyí ní ohun tí Olúwa sọ wí pé kí a ṣe: ‘Ẹ má ṣe bẹ̀rù tàbí fòyà nítorí ọ̀pọ̀ ogun ńlá yìí. Nítorí ogun náà kì í ṣe tiyín, ṣùgbọ́n ti Ọlọ́run ni.
Et il dit: Écoutez, ô Juda, et vous habitants de Jérusalem, et toi, roi Josaphat: voici ce que vous dit le Seigneur: N'ayez point de crainte, ne tremblez pas devant cette multitude immense; car ce combat n'est point de vous, mais de Dieu.
16 Ní ọ̀la, ẹ sọ̀kalẹ̀ tọ̀ wọ́n lọ, wọn yóò gòkè pẹ̀lú, ẹ̀yin yóò sì rí wọn ní ìpẹ̀kun odò náà, níwájú aginjù Jerueli.
Marchez demain contre elle; ils monteront le coteau d'Assis, et vous les trouverez à l'extrémité du torrent qui traverse le désert de Jerihel.
17 Ẹ̀yin kò ní láti bá ogun yìí jà. ẹ dúró ní ààyè yín; ẹ dúró jẹ́ẹ́ kí ẹ sì rí ìgbàlà Olúwa tí yóò fi fún yín, ìwọ Juda àti Jerusalẹmu. Ẹ má ṣe bẹ̀rù; ẹ má sì ṣe fòyà. Ẹ jáde lọ láti lọ dojúkọ wọ́n ní ọ̀la, Olúwa yóò sì wà pẹ̀lú yín.’”
Ce n'est point à vous de les combattre; comprenez cela, et voyez comme le Seigneur, ô Juda et Jérusalem, opèrera votre salut. N'ayez point de crainte, n'hésitez pas à marcher demain à leur rencontre: le Seigneur est avec vous.
18 Jehoṣafati tẹ orí rẹ̀ ba sílẹ̀ pẹ̀lú ojú rẹ̀, àti gbogbo àwọn ènìyàn Juda àti Jerusalẹmu wólẹ̀ níwájú láti sin Olúwa.
Et Josaphat, et tout Juda et les habitants de Jérusalem s'étant prosternés la face contre terre tombèrent devant le Seigneur pour l'adorer.
19 Nígbà náà díẹ̀ lára àwọn ọmọ Lefi àti àwọn ọmọ Kohati àti àwọn ọmọ Kora sì dìde dúró wọ́n sì sin Olúwa, Ọlọ́run Israẹli, pẹ̀lú ohùn ariwo ńlá.
Puis, les lévites des fils de Caath et des fils de Coré se levèrent pour chanter à haute voix les louanges du Seigneur Dieu d'Israël.
20 Ní òwúrọ̀ kùtùkùtù wọ́n jáde lọ sí aginjù Tekoa. Gẹ́gẹ́ bí wọ́n ti ń jáde lọ, Jehoṣafati dìde dúró ó sì wí pé, “Ẹ gbọ́ mi, Juda àti ènìyàn Jerusalẹmu! Ẹ ní ìgbàgbọ́ nínú Olúwa Ọlọ́run yín ẹ̀yin yóò sì borí, ẹ ní ìgbàgbọ́ nínú àwọn wòlíì rẹ̀ ẹ̀yìn yóò sì ṣe rere.”
Et le peuple se leva dès l'aurore, et ils sortirent dans le désert de Thécoé; et, pendant qu'ils sortaient, Josaphat, se tenant immobile, cria, et dit: Écoutez-moi, Juda, et vous, habitants de Jérusalem, mettez votre confiance dans le Seigneur notre Dieu, et il se confiera en vous; mettez votre confiance dans son prophète, et vous prospérerez.
21 Lẹ́yìn ìgbà tí ó bá àwọn ènìyàn náà gbèrò tán, Jehoṣafati yàn wọ́n láti kọrin sí Olúwa àti láti fi ìyìn fún ẹwà ìwà mímọ́ gẹ́gẹ́ bí ó tì ń jáde lọ sí iwájú ogun ńlá náà, wí pé, “Ẹ fi ọpẹ́ fún Olúwa, nítorí àánú rẹ̀ dúró títí láéláé.”
Ensuite, il tint conseil avec le peuple; puis, il plaça en tête de l'armée, comme elle sortait, des chantres harpistes pour célébrer et louer les choses saintes, et ils disaient: Rendez gloire au Seigneur, car sa miséricorde est éternelle.
22 Bí wọ́n ti bẹ̀rẹ̀ sí kọrin àti ìyìn, Olúwa rán ogun ẹ̀yìn sí àwọn ọkùnrin Ammoni àti Moabu àti òkè Seiri tí ó ń gbógun ti Juda, wọ́n sì kọlù wọ́n.
Et, au moment où ils commençaient à chanter ses louanges, le Seigneur excita la guerre entre les fils d'Ammon et Moab, d'une part, et ceux de la montagne de Seïr, d'autre part; ils avaient tous marché sur Israël, et ils se tournèrent les uns contre les autres.
23 Àwọn ọkùnrin Ammoni àti Moabu dìde dúró sí àwọn ọkùnrin tí ń gbé òkè Seiri láti pa wọ́n run túútúú. Lẹ́yìn ìgbà tí wọ́n sì ti pa àwọn ọkùnrin láti òkè Seiri, wọ́n sì ran ra wọn lọ́wọ́ láti pa ara wọn run.
Les fils d'Ammon et Moab se levèrent pour exterminer ceux de la montagne de Seïr, et, quand ils les eurent broyés, ils s'attaquèrent mutuellement, de sorte qu'ils se détruisirent.
24 Nígbà tí àwọn ènìyàn Juda jáde sí ìhà ilé ìṣọ́ ní aginjù, wọn ń wo àwọn ọ̀pọ̀ ènìyàn, òkú nìkan ni wọ́n rí tí ó ṣubú sí ilẹ̀, kò sì sí ẹnìkan tí ó rí ààyè sá.
Lors donc que Juda arriva sur la hauteur d'où l'on découvre le désert, il regarda et il vit cette multitude, et voilà qu'ils étaient tous tombés morts, et gisant à terre, pas un ne s'était échappé.
25 Bẹ́ẹ̀ ni Jehoṣafati àti àwọn ènìyàn rẹ̀ lọ láti kó ìkógun wọn, wọ́n sì rí lára wọn ọ̀pọ̀ iyebíye ọrọ̀ púpọ̀, ó sì ju èyí tí wọ́n lè kó lọ. Ọ̀pọ̀ ìkógun sì wà níbẹ̀, èyí tí ó gbà wọ́n ní ọjọ́ mẹ́ta láti gbà pọ̀.
Et Josaphat avec tout son peuple descendit pour recueillir les dépouilles; ils trouvèrent quantité de bétail, des bagages, des couvertures et des choses précieuses; ils les prirent et ils mirent trois jours à recueillir le butin, tant il y en avait.
26 Ní ọjọ́ kẹrin, wọn kó ara jọ pọ̀ ní àfonífojì ìbùkún, níbi tí wọ́n ti ń fi ìbùkún fún Olúwa. Ìdí nìyí tí wọ́n fi ń pe ibẹ̀ ní àfonífojì ìbùkún títí di òní.
Le quatrième jour, ils reprirent leurs rangs dans le val de la bénédiction; car, en ce lieu, ils bénirent le Seigneur; à cause de cela cette vallée est appelée encore de nos jours la Vallée de la Bénédiction.
27 Nígbà náà wọ́n darí pẹ̀lú Jehoṣafati, gbogbo àwọn ènìyàn Juda àti Jerusalẹmu padà pẹ̀lú ayọ̀ sí Jerusalẹmu, nítorí Olúwa ti fún wọn ní ìdí láti yọ̀ lórí àwọn ọ̀tá wọn.
Et tout Juda, Josaphat à sa tête, revint à Jérusalem avec une grande allégresse, car le Seigneur les avait comblés de joie aux dépens de leurs ennemis.
28 Wọ́n sì wọ Jerusalẹmu, wọ́n sì lọ sí ilé Olúwa pẹ̀lú ohun èlò orin olókùn àti dùùrù àti ìpè.
Et ils entrèrent à Jérusalem au son des harpes et des cithares, auxquelles se joignirent les trompettes quand ils arrivèrent au temple du Seigneur.
29 Ìbẹ̀rù Ọlọ́run wá si orí gbogbo ìjọba ilẹ̀ náà nígbà tí wọ́n gbọ́ bí Olúwa ti bá àwọn ọ̀tá Israẹli jà.
Et il y eut un grand trouble venant du Seigneur, parmi tous les royaumes de la terre, quand ils surent que le Seigneur avait combattu les ennemis d'Israël.
30 Bẹ́ẹ̀ ni ìjọba Jehoṣafati sì wà ní àlàáfíà, nítorí Ọlọ́run rẹ̀ ti fún un ni ìsinmi ní gbogbo àyíká.
Ainsi le royaume de Josaphat fut en paix; car le Seigneur, alentour, apaisa tout.
31 Báyìí ni Jehoṣafati jẹ ọba lórí Juda. Ó sì jẹ́ ẹni ọdún márùndínlógójì. Nígbà tí ó di ọba Juda, ó sì jẹ ọba ní Jerusalẹmu fún ọdún mẹ́ẹ̀ẹ́dọ́gbọ̀n. Orúkọ ìyá rẹ̀ sì ni Asuba ọmọbìnrin Silihi.
Et Josaphat régna en Jérusalem; il avait trente-cinq ans lorsqu'il monta sur le trône, et son règne dura vingt-cinq ans. Sa mère s'appelait Azuba, fille de Sali.
32 Ó sì rin ọ̀nà baba rẹ̀ Asa kò sì yà kúrò nínú rẹ̀, ó sì ṣe èyí tí ó tọ́ ní ojú Olúwa.
Et il marcha dans les voies d'Asa, son père, et il ne s'en détourna pas, et il fit ce qui est droit aux yeux du Seigneur.
33 Ní ibi gíga, pẹ̀lúpẹ̀lú, kò mu wọn kúrò, gbogbo àwọn ènìyàn náà kò sì fi ọkàn wọn fún Ọlọ́run àwọn baba wọn.
Cependant, les hauts lieux subsistèrent encore, et le peuple ne dirigea pas encore son cœur vers le Seigneur Dieu de ses pères.
34 Ìyókù iṣẹ́ ìjọba Jehoṣafati, láti ìbẹ̀rẹ̀ títí dé òpin, ni a kọ sí inú ìwé ìtàn ti Jehu ọmọ Hanani, tí a kọ sí inú ìwé àwọn ọba Israẹli.
Le reste des actes de Josaphat, des premiers et des derniers, est compris dans les récits de Jéhu, fils d'Anani, qui écrivit le livre des Rois d'Israël.
35 Nígbà tí ó yá, Jehoṣafati ọba Juda da ara rẹ̀ pọ̀ pẹ̀lú Ahasiah, ọba Israẹli, ẹni tí ó jẹ̀bi ìwà búburú.
Après cela, Josaphat, roi de Juda, fit alliance avec Ochozias, roi d'Israël, et il pécha,
36 Ó sì gbà pẹ̀lú rẹ̀ láti kan ọkọ̀ láti lọ sí Tarṣiṣi, lẹ́yìn èyí wọ́n kan ọkọ̀ ní Esioni-Geberi.
En agissant et en marchant avec lui pour construire une flotte qui partit d'Asion-Gaber, allant à Tharsis.
37 Elieseri ọmọ Dodafahu ti Meraṣa sọtẹ́lẹ̀ sí Jehoṣafati, wí pe, “Nítorí tí ìwọ ti da ara rẹ̀ pọ̀ mọ́ Ahasiah, Olúwa yóò pa ohun ti ìwọ ti ṣe run.” Àwọn ọkọ̀ náà sì fọ́, wọn kò sì le lọ sí ibi ìtajà.
Alors, Eliézer, fils de Dodia de Marine, prophétisa contre Josaphat, disant: Parce que tu t'es lié avec Ochosias, le Seigneur a détruit ton ouvrage; il a brisé ta flotte, et elle n'a pu aller jusqu'à Tharsis.

< 2 Chronicles 20 >