< 2 Chronicles 20 >
1 Lẹ́yìn èyí, àwọn ọmọ Moabu àti àwọn ọmọ Ammoni àti díẹ̀ nínú àwọn ọmọ Mehuni wá láti gbé ogun ti Jehoṣafati.
Og det skete derefter, at Moabs Børn og Ammons Børn og med dem nogle af Meuniterne kom imod Josafat til Krig.
2 Àwọn díẹ̀ nínú àwọn ọkùnrin wá láti sọ fún Jehoṣafati, “Àwọn ọ̀pọ̀ ọ̀wọ́ ogun ń bọ̀ wá bá ọ láti apá kejì Òkun láti Siria. Ó ti wà ní Hasason Tamari náà” (èyí tí í ṣe En-Gedi).
Og man kom og gav Josafat det til Kende og sagde: Der kommer en stor Hob imod dig fra hin Side Havet fra Syrien, og se, de ere i Hazezon-Thamar, det er Engedi.
3 Nípa ìró ìdágìrì, Jehoṣafati pinnu láti wádìí lọ́wọ́ Olúwa, ó sì kéde àwẹ̀ kíákíá fún gbogbo Juda.
Og Josafat frygtede og vendte sit Ansigt til at søge Herren og lod udraabe en Faste over al Juda.
4 Àwọn ènìyàn Juda sì kó ara wọn jọ pọ̀ láti wá ìrànlọ́wọ́ láti ọ̀dọ̀ Olúwa; pẹ̀lúpẹ̀lú, wọ́n wá láti gbogbo ìlú ní Juda láti wá a.
Og Juda samlede sig for at søge Hjælp af Herren; ogsaa af alle Judas Stæder kom de for at søge Herren.
5 Nígbà náà Jehoṣafati dìde dúró níwájú àpéjọ Juda àti Jerusalẹmu ní ilé Olúwa níwájú àgbàlá tuntun.
Og Josafat stod i Judas og Jerusalems Forsamling, i Herrens Hus foran den nye Forgaard,
6 O sì wí pé, “Olúwa, Ọlọ́run àwọn baba wa, ìwọ kì ha ṣe Ọlọ́run tí ń bẹ ní ọ̀run? Ìwọ ń ṣe alákòóso lórí gbogbo ìjọba àwọn orílẹ̀-èdè. Agbára àti ipá ń bẹ ní ọwọ́ rẹ, kò sì sí ẹnìkan tí ó lè kò ọ́ lójú.
og han sagde: Herre, vore Fædres Gud! er du ej selv den Gud i Himmelen? ja, du er den, som regerer i alle Hedningernes Riger, og i din Haand er Kraft og Vælde, og der er ingen, som kan bestaa imod dig.
7 Ìwọ ha kọ́ Ọlọ́run wa, tí o ti lé àwọn olùgbé ilẹ̀ yìí jáde níwájú àwọn ènìyàn Israẹli, tí o sì fi fún irú-ọmọ Abrahamu ọ̀rẹ́ rẹ láéláé?
Har du ikke, vor Gud! fordrevet dette Lands Indbyggere fra dit Folk Israels Ansigt og givet det til Abrahams, din Vens, Sæd evindelig?
8 Wọ́n ti ń gbé nínú rẹ̀ wọ́n sì ti kọ́ sínú rẹ ibi mímọ́ fún orúkọ rẹ wí pé,
Og de have boet derudi og bygget dig en Helligdom deri for dit Navn og sagt:
9 ‘Tí ibi bá wá sí orí wa, bóyá idà ìjìyà tàbí àjàkálẹ̀-ààrùn àwọn yóò dúró níwájú rẹ níwájú ilé yìí tí ń jẹ́ orúkọ rẹ, àwa yóò sì sọkún jáde, ìwọ yóò sì gbọ́ wa. Ìwọ yóò sì gbà wá là?’
Om Ulykke kommer over os, Sværd, Straffedom eller Pest eller Hunger, skulle vi staa foran dette Hus og for dit Ansigt (thi dit Navn er i dette Hus), og raabe til dig i vor Nød, saa ville du høre og frelse!
10 “Ṣùgbọ́n nísinsin yìí, àwọn ọkùnrin nìyí láti Ammoni, Moabu àti òkè Seiri, agbègbè ibi ti ìwọ kò ti gba àwọn ọmọ Israẹli láyè láti gbóguntì nígbà tí wọn wá láti Ejibiti, bẹ́ẹ̀ ni wọ́n yípadà kúrò ní ọ̀dọ̀ wọn, wọn kò sì pa wọ́n run.
Nu da, se, Ammons Børn og Moab og de fra Sejrs Bjerg, hos hvilke du ikke tilstedte Israel at drage igennem, der de kom fra Ægyptens Land — thi de gik af Vejen for dem og ødelagde dem ikke —
11 Sì kíyèsi i, bí wọ́n ti san án padà fún wa; láti wá lé wa jáde kúrò nínú ìní rẹ, tí ìwọ ti fi fún wa láti ní.
se, disse betale os det med at komme for at udstøde os af din Ejendom, som du har ladet os indtage til Eje.
12 Ọlọ́run wa, ṣé ìwọ kò ní ṣe ìdájọ́ fún wọn? Nítorí àwa kò ní agbára láti dojúkọ àwọn ọ̀pọ̀ ogun ńlá yìí tí ń bọ̀ wá kó wa. Àwa kò mọ̀ ohun tó yẹ ká ṣe, ṣùgbọ́n ojú wa wà ní ọ̀dọ̀ rẹ.”
Vor Gud! vil du ikke holde Dom over dem? thi der er ingen Kraft i os imod denne store Hob, som kommer imod os, og vi vide ikke, hvad vi skulle gøre; men vore Øjne ere vendte til dig.
13 Gbogbo àwọn ọkùnrin Juda, pẹ̀lú àwọn aya wọn àti ọmọ wọn àti àwọn kéékèèké, dúró níbẹ̀ níwájú Olúwa.
Og al Juda stod for Herrens Ansigt ogsaa deres smaa Børn, deres Hustruer og deres Sønner.
14 Nígbà náà, ẹ̀mí Olúwa sì bà lé Jahasieli ọmọ Sekariah, ọmọ Benaiah, ọmọ Jeieli, ọmọ Mattaniah ọmọ Lefi àti ọmọ Asafu, gẹ́gẹ́ bí ó ṣe dìde dúró láàrín àpéjọ ènìyàn.
Men over Jehasiel, en Søn af Sakaria, der var en Søn af Benaja, der var en Søn af Jejel, en Søn af Matthania, Leviten af Asafs Børn, kom Herrens Aand midt iblandt Forsamlingen,
15 Ó sì wí pé, “Ẹ tẹ́tí sílẹ̀, ọba Jehoṣafati àti gbogbo àwọn tí ń gbé ní Juda àti Jerusalẹmu! Èyí ní ohun tí Olúwa sọ wí pé kí a ṣe: ‘Ẹ má ṣe bẹ̀rù tàbí fòyà nítorí ọ̀pọ̀ ogun ńlá yìí. Nítorí ogun náà kì í ṣe tiyín, ṣùgbọ́n ti Ọlọ́run ni.
og han sagde: Giver Agt, alle I af Juda og I, Indbyggere i Jerusalem, og du, Kong Josafat! saa sagde Herren til eder: I skulle ikke frygte og ikke ræddes for denne store Hob, thi Krigen er ikke eders, men Guds.
16 Ní ọ̀la, ẹ sọ̀kalẹ̀ tọ̀ wọ́n lọ, wọn yóò gòkè pẹ̀lú, ẹ̀yin yóò sì rí wọn ní ìpẹ̀kun odò náà, níwájú aginjù Jerueli.
I Morgen skulle I drage ned imod dem; se, de drage op ad Opgangen til Ziz, og I skulle finde dem ved Enden af Dalen lige over for Jeruels Ørk.
17 Ẹ̀yin kò ní láti bá ogun yìí jà. ẹ dúró ní ààyè yín; ẹ dúró jẹ́ẹ́ kí ẹ sì rí ìgbàlà Olúwa tí yóò fi fún yín, ìwọ Juda àti Jerusalẹmu. Ẹ má ṣe bẹ̀rù; ẹ má sì ṣe fòyà. Ẹ jáde lọ láti lọ dojúkọ wọ́n ní ọ̀la, Olúwa yóò sì wà pẹ̀lú yín.’”
Det skal ikke være eders Sag at stride her, stiller eder hen, bliver staaende og ser, hvorledes Herren frelser eder, o Juda og Jerusalem! I skulle ikke frygte og ikke ræddes, drager i Morgen ud imod dem, thi Herren skal være med eder.
18 Jehoṣafati tẹ orí rẹ̀ ba sílẹ̀ pẹ̀lú ojú rẹ̀, àti gbogbo àwọn ènìyàn Juda àti Jerusalẹmu wólẹ̀ níwájú láti sin Olúwa.
Da bøjede Josafat sit Ansigt ned til Jorden, og al Juda og Indbyggerne i Jerusalem faldt ned for Herrens Ansigt, at nedbøje sig for Herren.
19 Nígbà náà díẹ̀ lára àwọn ọmọ Lefi àti àwọn ọmọ Kohati àti àwọn ọmọ Kora sì dìde dúró wọ́n sì sin Olúwa, Ọlọ́run Israẹli, pẹ̀lú ohùn ariwo ńlá.
Og Leviterne af Kahathiternes Børn og af Koriternes Børn stode op at love Herren, Israels Gud, med overmaade høj Røst.
20 Ní òwúrọ̀ kùtùkùtù wọ́n jáde lọ sí aginjù Tekoa. Gẹ́gẹ́ bí wọ́n ti ń jáde lọ, Jehoṣafati dìde dúró ó sì wí pé, “Ẹ gbọ́ mi, Juda àti ènìyàn Jerusalẹmu! Ẹ ní ìgbàgbọ́ nínú Olúwa Ọlọ́run yín ẹ̀yin yóò sì borí, ẹ ní ìgbàgbọ́ nínú àwọn wòlíì rẹ̀ ẹ̀yìn yóò sì ṣe rere.”
Og de stode tidligt op om Morgenen og droge ud til Thekoas Ørk; og der de droge ud, stod Josafat og sagde: Hører mig, Juda, og I, Indbyggere i Jerusalem! tror paa Herren eders Gud, saa skulle I være sikre, tror paa hans Profeter, saa skulle I faa Lykke.
21 Lẹ́yìn ìgbà tí ó bá àwọn ènìyàn náà gbèrò tán, Jehoṣafati yàn wọ́n láti kọrin sí Olúwa àti láti fi ìyìn fún ẹwà ìwà mímọ́ gẹ́gẹ́ bí ó tì ń jáde lọ sí iwájú ogun ńlá náà, wí pé, “Ẹ fi ọpẹ́ fún Olúwa, nítorí àánú rẹ̀ dúró títí láéláé.”
Og han raadførte sig med Folket og beskikkede Sangere for Herren, at de skulde love den hellige Majestæt, og, naar de droge ud frem for de bevæbnede, da skulde de sige: Lover Herren, thi hans Miskundhed er evindelig.
22 Bí wọ́n ti bẹ̀rẹ̀ sí kọrin àti ìyìn, Olúwa rán ogun ẹ̀yìn sí àwọn ọkùnrin Ammoni àti Moabu àti òkè Seiri tí ó ń gbógun ti Juda, wọ́n sì kọlù wọ́n.
Og den Tid de begyndte med Frydeskrig og Lovsang, lod Herren et Baghold komme over Ammons Børn, Moab og dem fra Sejrs Bjerg, som vare komne imod Juda, og de kæmpede med hinanden.
23 Àwọn ọkùnrin Ammoni àti Moabu dìde dúró sí àwọn ọkùnrin tí ń gbé òkè Seiri láti pa wọ́n run túútúú. Lẹ́yìn ìgbà tí wọ́n sì ti pa àwọn ọkùnrin láti òkè Seiri, wọ́n sì ran ra wọn lọ́wọ́ láti pa ara wọn run.
Thi Ammons Børn og Moab stode imod Indbyggerne af Sejrs Bjerg for at bandlyse og ødelægge dem; og der de havde gjort Ende paa Indbyggerne af Sejr, hjalp de den ene den anden med at ødelægge hinanden.
24 Nígbà tí àwọn ènìyàn Juda jáde sí ìhà ilé ìṣọ́ ní aginjù, wọn ń wo àwọn ọ̀pọ̀ ènìyàn, òkú nìkan ni wọ́n rí tí ó ṣubú sí ilẹ̀, kò sì sí ẹnìkan tí ó rí ààyè sá.
Der Juda var kommen til Bjerghøjden ved Ørken, da vendte de deres Ansigter over imod Hoben, og se, der laa de døde Kroppe, som vare faldne til Jorden, og der var ingen undkommen.
25 Bẹ́ẹ̀ ni Jehoṣafati àti àwọn ènìyàn rẹ̀ lọ láti kó ìkógun wọn, wọ́n sì rí lára wọn ọ̀pọ̀ iyebíye ọrọ̀ púpọ̀, ó sì ju èyí tí wọ́n lè kó lọ. Ọ̀pọ̀ ìkógun sì wà níbẹ̀, èyí tí ó gbà wọ́n ní ọjọ́ mẹ́ta láti gbà pọ̀.
Og Josafat og hans Folk kom for at røve deres Bytte, og de fandt hos dem i Mangfoldighed baade Gods hos de døde Kroppe og kosteligt Tøj, og de toge for sig, saa de ikke kunde bære det; og de røvede Bytte i tre Dage, thi der var meget.
26 Ní ọjọ́ kẹrin, wọn kó ara jọ pọ̀ ní àfonífojì ìbùkún, níbi tí wọ́n ti ń fi ìbùkún fún Olúwa. Ìdí nìyí tí wọ́n fi ń pe ibẹ̀ ní àfonífojì ìbùkún títí di òní.
Og paa den fjerde Dag forsamledes de i Lovsangsdalen, thi der lovede de Herren; derfor kaldte de samme Steds Navn Lovsangsdal indtil denne Dag.
27 Nígbà náà wọ́n darí pẹ̀lú Jehoṣafati, gbogbo àwọn ènìyàn Juda àti Jerusalẹmu padà pẹ̀lú ayọ̀ sí Jerusalẹmu, nítorí Olúwa ti fún wọn ní ìdí láti yọ̀ lórí àwọn ọ̀tá wọn.
Siden vendte hver Mand af Juda og Jerusalem om, og Josafat fremmerst for dem, for at drage tilbage til Jerusalem med Glæde; thi Herren havde givet dem Glæde over deres Fjender.
28 Wọ́n sì wọ Jerusalẹmu, wọ́n sì lọ sí ilé Olúwa pẹ̀lú ohun èlò orin olókùn àti dùùrù àti ìpè.
Og de kom til Jerusalem med Psaltre og med Harper og med Basuner op til Herrens Hus.
29 Ìbẹ̀rù Ọlọ́run wá si orí gbogbo ìjọba ilẹ̀ náà nígbà tí wọ́n gbọ́ bí Olúwa ti bá àwọn ọ̀tá Israẹli jà.
Og Frygt for Gud kom over alle Landenes Riger, der de hørte, at Herren havde stridt imod Israels Fjender.
30 Bẹ́ẹ̀ ni ìjọba Jehoṣafati sì wà ní àlàáfíà, nítorí Ọlọ́run rẹ̀ ti fún un ni ìsinmi ní gbogbo àyíká.
Saa fik Josafats Rige Hvile, og hans Gud skaffede ham Rolighed trindt omkring.
31 Báyìí ni Jehoṣafati jẹ ọba lórí Juda. Ó sì jẹ́ ẹni ọdún márùndínlógójì. Nígbà tí ó di ọba Juda, ó sì jẹ ọba ní Jerusalẹmu fún ọdún mẹ́ẹ̀ẹ́dọ́gbọ̀n. Orúkọ ìyá rẹ̀ sì ni Asuba ọmọbìnrin Silihi.
Og Josafat regerede over Juda; han var fem og tredive Aar gammel, der han blev Konge, og regerede fem og tyve Aar i Jerusalem, og hans Moders Navn var Asuba, Silhis Datter.
32 Ó sì rin ọ̀nà baba rẹ̀ Asa kò sì yà kúrò nínú rẹ̀, ó sì ṣe èyí tí ó tọ́ ní ojú Olúwa.
Og han vandrede i Asas, sin Faders, Vej og veg ikke fra den, idet han gjorde det, som var ret for Herrens Øjne.
33 Ní ibi gíga, pẹ̀lúpẹ̀lú, kò mu wọn kúrò, gbogbo àwọn ènìyàn náà kò sì fi ọkàn wọn fún Ọlọ́run àwọn baba wọn.
Dog bleve Højene ikke borttagne; thi Folket havde endnu ikke rettelig beredet deres Hjerte for deres Fædres Gud.
34 Ìyókù iṣẹ́ ìjọba Jehoṣafati, láti ìbẹ̀rẹ̀ títí dé òpin, ni a kọ sí inú ìwé ìtàn ti Jehu ọmọ Hanani, tí a kọ sí inú ìwé àwọn ọba Israẹli.
Men det øvrige af Josafats Handeler, de første og de sidste, se, de Ting ere skrevne i Jehu, Hananis Søns, Krønike, som er indrykket i Israels Kongers Bog.
35 Nígbà tí ó yá, Jehoṣafati ọba Juda da ara rẹ̀ pọ̀ pẹ̀lú Ahasiah, ọba Israẹli, ẹni tí ó jẹ̀bi ìwà búburú.
Men derefter forbandt Josafat, Judas Konge, sig med Ahasia, Israels Konge; denne var ugudelig i sine Gerninger.
36 Ó sì gbà pẹ̀lú rẹ̀ láti kan ọkọ̀ láti lọ sí Tarṣiṣi, lẹ́yìn èyí wọ́n kan ọkọ̀ ní Esioni-Geberi.
Og han forbandt sig med ham om at udruste Skibe, som skulde fare til Tharsis, og de udrustede Skibe i Ezion-Geber.
37 Elieseri ọmọ Dodafahu ti Meraṣa sọtẹ́lẹ̀ sí Jehoṣafati, wí pe, “Nítorí tí ìwọ ti da ara rẹ̀ pọ̀ mọ́ Ahasiah, Olúwa yóò pa ohun ti ìwọ ti ṣe run.” Àwọn ọkọ̀ náà sì fọ́, wọn kò sì le lọ sí ibi ìtajà.
Men Elieser, Dodavas Søn, fra Maresa, spaaede imod Josafat og sagde: Fordi du forbandt dig med Ahasia, har Herren sønderrevet, hvad du har for; da bleve Skibene sønderslagne, og de formaaede ikke at fare til Tharsis.