< 2 Chronicles 2 >

1 Solomoni pinnu láti kọ́ ilé fún orúkọ Olúwa àti ilé kan fún ìjọba rẹ̀
Sulayman Perwerdigarning namigha atap bir öy hem padishahliqi üchün bir orda sélish niyitige keldi.
2 Solomoni sì yan ẹgbẹ̀rún ní ọ̀nà àádọ́rin àwọn ọkùnrin láti ru ẹrù àti ọ̀kẹ́ mẹ́rin àwọn ọkùnrin gẹ́gẹ́ bi olùgé-òkúta ní àwọn òkè àti ẹgbẹ̀rún mẹ́rìndínlógójì gẹ́gẹ́ bí àwọn alábojútó lórí wọn.
Shuningdin kéyin Sulayman yetmish ming ademni hammalliqqa, seksen ming ademni taghda tash késishke, üch ming alte yüz kishini nazaretchilikke teyinlidi.
3 Solomoni rán iṣẹ́ yìí sí Hiramu ọba Tire: “Rán àwọn igi kedari sí mi gẹ́gẹ́ bí o ti ṣe fún baba à mi Dafidi. Nígbà tí ó fi igi kedari ránṣẹ́ sí i láti kọ́ ààfin tí ó ń gbé.
Sulayman Tur padishahi Huramgha adem ewetip: «Özliri atam Dawutning turalghusi bolsun dep orda sélishigha kédir yaghichi yetküzüp bergen idilighu, mangimu shundaq qilghayla.
4 Nísinsin yìí, èmi n kọ́ ilé kan fún orúkọ Olúwa Ọlọ́run mi àti láti yà á sí mímọ́ fún un àti láti sun tùràrí olóòórùn dídùn níwájú rẹ̀, fún gbígbé àkàrà ìfihàn ìgbàkúgbà, àti fún ṣíṣe ẹbọ sísun ní gbogbo àárọ̀ àti ìrọ̀lẹ́ àti ní ọjọọjọ́ ìsinmi àti oṣù tuntun àti ní àjọ̀dún tí a yàn ti Olúwa Ọlọ́run wa. Èyí ni àṣẹ fún Israẹli láéláé.
Mana, men emdi Perwerdigar Xudayimning namigha atap bir öy salmaqchimen; öy uning aldida xushbuy yéqish, «teqdim nanlar»ning üzülmey qoyulushi, herküni ete-axshamlirida, shabat künliride, yéngi ayning birinchi künide we Perwerdigar Xudayimiz békitip bergen héyt-ayemlerde köydürme qurbanliqlarning sunulushi üchün bolidu. Bu ishlar Israil xelqige menggülük bir belgilime bolidu.
5 “Ilé Olúwa tí èmi yóò kọ́ yóò tóbi, nítorí pé Ọlọ́run wa tóbi ju gbogbo àwọn ọlọ́run mìíràn lọ.
Men salmaqchi bolghan öy ajayip heywetlik bolidu; chünki bizning Xudayimiz hemme ilahlardin üstündur.
6 Ṣùgbọ́n ta ni ó le è kọ́ ilé fún Olúwa, níwọ̀n ìgbà tí àwọn ọ̀run, àní ọ̀run àwọn ọ̀run tó ga jùlọ, kò le è gbà á? Ta ni èmi nígbà náà láti kọ́ ilé fún Olúwa, bí kò ṣe kìkì àti sun ẹbọ sun ẹbọ níwájú rẹ̀?
Lékin asmanlar we asmanlarning üstidiki asmanmu Uni sighduralmaydighan tursa, kim Uninggha öy salalisun? Men kim idim, qandaqmu Uninggha öy saldurghudek qudretke ige bolay? Men peqet Uning aldida qurbanliqlarni köydürgüdekla ademmen, xalas!
7 “Nítorí náà, rán ọkùnrin kan sí mi, tí a kọ́ láti ṣiṣẹ́ pẹ̀lú wúrà àti fàdákà àti idẹ àti irin, àti ní àwọ̀ àlùkò àti àwọ̀ pupa fòò àti ní àwọ̀ ojú ọ̀run, tí ó jẹ́ onímọ̀ nínú iṣẹ́ igi gbígbẹ́ láti ṣiṣẹ́ ní Juda àti Jerusalẹmu pẹ̀lú àwọn onímọ̀ oníṣọ̀nà tí baba à mi Dafidi pèsè.
Emdi özliri manga atam Dawut Yehudada we Yérusalémda teyyarlap qoyghan ustilar bilen bille ishlesh üchün, altun-kümüshte, mis we tömürde ishleshke pishshiq, sösün, toq qizil we kök renglik yip ishleshke puxta hem neqqashliqni bilidighan bir ustamni ewetkeyla.
8 “Fi ìtì igi kedari, junifa àti algumu ránṣẹ́ sí mi, láti Lebanoni, nítorí tí mo mọ̀ pé àwọn ọkùnrin rẹ ní ìmọ̀ nínú gígé igi rírẹ́. Àwọn ọkùnrin mi yóò ṣiṣẹ́ pẹ̀lú àwọn ọkùnrin rẹ.
Hem manga Liwandin kédir, archa-qarighay we sendel derexlirini yetküzüp bergen bolsila; chünki özlirining xizmetkarlirining Liwanda yaghachni késishke ustiliqini bilimen; mana, manga köplep yaghachlarni teyyarlap bérish üchün méning xizmetkarlirim özlirining xizmetkarliri bilen bille ishlisun; chünki men salidighan öy intayin heywetlik we ajayib karamet bolidu.
9 Láti pèsè ọ̀pọ̀ igi rírẹ́ fún mi, nítorí ilé Olúwa tí mo kọ́ gbọdọ̀ tóbi kí o sì lógo púpọ̀.
10 Èmi yóò fún àwọn ìránṣẹ́ rẹ, àwọn ọkùnrin agégi tí ó ń gé ìtì igi náà ni ogún ẹgbẹ̀rún, alikama ilẹ̀ àti ogún ẹgbẹ̀rún, ọ̀pọ̀lọpọ̀ ti barle; ogún ẹgbẹ̀rún, bati ọtí wáìnì àti ogún ẹgbẹ̀rún bati òróró olifi.”
Mana, men özlirining yaghach késidighan xizmetkarlirigha yigirme ming kor bughday, yigirme ming kor arpa, yigirme ming bat sharab, yigirme ming bat zeytun méyi bérimen» — dédi.
11 Hiramu ọba Tire fèsì padà nípasẹ̀ ìwé sí Solomoni: “Nítorí tí Olúwa fẹ́ràn àwọn ènìyàn rẹ̀, ó ti ṣe ọ́ ní ọba wọn.”
Turning padishahi Huram Sulayman’gha jawaben mektup yollap: «Perwerdigar Öz xelqini söygechke U özlirini ularning üstige padishah qildi» — dédi.
12 Hiramu fi kún un pe, “Ìyìn ni fún Olúwa, Ọlọ́run Israẹli, tí ó dá ọ̀run òun ayé! O ti fún ọba Dafidi ní ọmọ tí ó gbọ́n, tí ó kún fún ìmọ̀ àti òye, tí yóò kọ́ ilé fún Olúwa àti ààfin fún ara rẹ̀.
Huram yene: «Asman-pelek bilen yer-zéminni yaratqan Israilning Xudasi Perwerdigargha Hemdusana bolghay! Chünki U padishah Dawutqa yorutulghan, pem-parasetlik, Perwerdigar üchün bir öy, uning padishahliqi üchün bir orda salalaydighan bir danishmen oghul berdi.
13 “Èmi ń rán Huramu-Abi, ọkùnrin tí ó kún fún ìmọ̀ àti òye sí ọ.
Mana men hazir özlirige hünerde kamaletke yetken, eqil-paraset bilen yorutulghan, Huram-Abi dégen bir ademni ewetey.
14 Ọmọbìnrin kan nínú àwọn ọmọbìnrin Dani àti tí baba a rẹ̀ wá láti Tire tí ó gbọ́ngbọ́n àti ṣiṣẹ́ ní wúrà àti ní fàdákà, ní idẹ, ní irin, ní òkúta àti ní ìtì igi, ní èse-àlùkò, ní aláró, àti ní ọ̀gbọ̀ tí ó dára, àti òdòdó, láti gbẹ́ onírúurú ohun gbígbẹ́ pẹ̀lú, àti láti ṣe àwárí ìmọ̀ ẹ̀rọ irú ẹ̀yàkẹ́yà tí a ó fún un ṣe. Òun yóò ṣiṣẹ́ pẹ̀lú àwọn ọlọ́gbọ́n rẹ̀, àti pẹ̀lú àwọn ọlọ́gbọ́n olúwa mi, Dafidi baba a rẹ.
Uning anisi Dan qebilisilik bir ayal, atisi Turluq iken. U altun, kümüsh, mis, tömür, tashlar, yaghachchiliq ishlirigha mahir, sösün, toq qizil, aq we kök renglik yip ishleshke puxta, herxil neqqashliq ishlirighimu usta, tapshurulghan herqandaq layihige amalini qilalaydu. Bu kishi özlirining hünerwenliri bilen we atiliri bolghan xojam Dawutning hünerwenliri bilen bille ishlisun.
15 “Nísinsin yìí, jẹ́ kí olúwa mi rán àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀ ní alikama àti barle àti òróró Olifi náà àti ọtí tí ó ti ṣe ìlérí.
Emdi xojam tilgha alghan bughday, arpa, may we sharab bolsa, bularni öz xizmetkarlirigha yetküzüp bergeyla.
16 Àwa yóò sì gé gbogbo àwọn ìtí igi láti Lebanoni tí ìwọ yóò lò pẹ̀lú a ó gbé wọn fò lójú omi òkun lọ sí Joppa. Lẹ́yìn náà ìwọ lè kó wọn gòkè lọ sí Jerusalẹmu.”
Biz bolsaq silige qanche kérek bolsa Liwanda shunche yaghach késip, sal qilip baghlap, déngiz arqiliq Yoppagha yetküzüp bérimiz; andin sili u yerdin Yérusalémgha toshup ketsile bolidu» dédi.
17 Solomoni ka iye àwọn àjèjì tí ó wà ní Israẹli lẹ́yìn kíka iye wọn tí baba a rẹ̀ Dafidi ti ṣe; a sì ka iye wọn sí ọ̀kẹ́ mẹ́jọ ó dín egbèjìlélọ́gbọ̀n.
Atisi Dawut Israil zéminida turushluq yaqa yurtluqlarni sanaqtin ötküzgendek, Sulaymanmu ularni sanaqtin ötküzdi. Ular jemiy bir yüz ellik üch ming alte yüz adem chiqti.
18 Ó sì yan ẹgbẹ̀rún ní ọ̀nà àádọ́rin nínú wọn láti ru ẹrù, àti ọ̀kẹ́ mẹ́rin láti ṣe àgọ́ òkúta lórí òkè, àti egbèjìdínlógún alábojútó láti kó àwọn ènìyàn ṣiṣẹ́.
U ulardin yetmish ming kishini hammalliqqa, seksen ming kishini taghda tash késishke we ish qiliwatqanlar üstidin nazaret qilip turushqa üch ming alte yüz kishini teyinlidi.

< 2 Chronicles 2 >