< 2 Chronicles 19 >
1 Nígbà tí Jehoṣafati ọba Juda padà ní àlàáfíà sí ilé rẹ̀ ní Jerusalẹmu,
Judov kralj Józafat pa se je v miru vrnil k svoji hiši v Jeruzalem.
2 Jehu aríran, ọmọ Hanani jáde lọ láti lọ pàdé rẹ̀, ó sì wí fún ọba pé, “Ṣé ìwọ yóò máa ran ènìyàn búburú lọ́wọ́, kí o sì fẹ́ràn àwọn tí ó kórìíra Olúwa? Nítorí èyí, ìbínú Olúwa wà lórí wa.
Hananíjev sin Jehú, videc, je odšel ven, da ga sreča in kralju Józafatu rekel: »Ali naj bi pomagal brezbožnikom in ljubil tiste, ki sovražijo Gospoda? Zato je izpred Gospoda na tebi bes.
3 Bí ó ti wù kí ó rí, ohun rere wà nínú rẹ, nítorí tí ìwọ ti mú àwọn ilé àwọn ère òrìṣà Aṣerah kúrò, tí o sì múra ọkàn rẹ láti wá Ọlọ́run.”
Kljub temu so v tebi najdene dobre stvari v tem, da si iz dežele odvzel ašere in si svoje srce pripravil, da išče Boga.
4 Jehoṣafati sì ń gbé ní Jerusalẹmu ó sì jáde lọ padà láàrín àwọn ènìyàn láti Beerṣeba dé òkè ìlú Efraimu, ó sì mú wọn padà sọ́dọ̀ Olúwa Ọlọ́run baba wọn.
Józafat je prebival v Jeruzalemu. In odšel je ponovno ven skozi ljudstvo od Beeršébe do gore Efrájim in jih vodil nazaj h Gospodu, Bogu njihovih očetov.
5 Ó sì yan àwọn onídàájọ́ sí ilẹ̀ náà, ní olúkúlùkù ìlú olódi Juda.
Postavil je sodnike vsepovsod po deželi, po vseh utrjenih Judovih mestih, mestu za mestom
6 Ó sì wí fun wọ́n pé, “Ẹ kíyèsi ohun tí ẹ̀yin ń ṣe, nítorí ìwọ kò ṣe ìdájọ́ fun ènìyàn ṣùgbọ́n fún Olúwa, ẹni tí ó wà pẹ̀lú rẹ ní ìdájọ́.
in sodnikom rekel: »Pazite, kaj počnete, kajti ne sodite za človeka, temveč za Gospoda, ki je z vami v sodbi.
7 Nísinsin yìí jẹ́ kí ìbẹ̀rù Olúwa kí ó wá sí ọkàn rẹ̀. Ṣe ìdájọ́ pẹ̀lẹ́pẹ̀lẹ́, nítorí pẹ̀lú Olúwa Ọlọ́run kò sí àìṣedéédéé tàbí ojúsàájú tàbí gbígba àbẹ̀tẹ́lẹ̀.”
Zatorej naj bo sedaj nad vami Gospodov strah. Pazite in to storite, kajti z Gospodom, svojim Bogom, ni krivičnosti, niti oziranja na osebe, niti sprejemanja darov.
8 Ní Jerusalẹmu pẹ̀lú, Jehoṣafati yan díẹ̀ lára àwọn Lefi, àwọn àlùfáà àti àwọn olórí ìdílé Israẹli si pípa òfin Olúwa mọ́ àti láti ṣe ìdájọ́. Wọn sì ń gbé ní Jerusalẹmu.
Poleg tega je v Jeruzalemu Józafat postavil od Lévijevcev in od duhovnikov in od vodij Izraelovih očetov za Gospodovo sodbo in za oporekanja, ko so se vrnili v Jeruzalem.
9 Ó sì kìlọ̀ fún wọn wí pé. “Ìwọ gbọdọ̀ sìn pẹ̀lú òtítọ́ àti pẹ̀lú ọkàn pípé ní ìbẹ̀rù Olúwa.
Zadolžil jih je, rekoč: »To boste delali v Gospodovem strahu, zvesto in s popolnim srcem.
10 Ní gbogbo ẹjọ́ tí ó bá wà níwájú rẹ láti ọ̀dọ̀ àwọn arákùnrin yín tí ń gbé ìlú wọn bóyá ẹ̀jẹ̀ tí ń sàn tàbí ìyókù òfin pẹ̀lú, pa á láṣẹ ìlànà àti ẹ̀tọ́, ìwọ gbọdọ̀ kìlọ̀ fún wọn láti má ṣe dẹ́ṣẹ̀ sí Olúwa bí bẹ́ẹ̀ kọ́, ìbínú yóò sì wá sórí yín, àti sórí àwọn arákùnrin. Ṣe èyí, ìwọ kì yóò sì jẹ̀bi.
Kakršnakoli zadeva bo prišla k vam od vaših bratov, ki prebivajo v svojih mestih, med krvjo in krvjo, med postavo in zapovedjo, zakoni in sodbami, jih boste torej opozorili, da ne prestopajo zoper Gospoda in tako [ne] pride bes nad vas in nad vaše brate. To delajte in se ne boste pregrešili.
11 “Amariah àlùfáà ni yóò jẹ́ olórí yín nínú gbogbo ọ̀ràn tí ó jẹ́ ti Olúwa, àti Sebadiah ọmọ Iṣmaeli alákòóso ìdílé Juda, ní yóò jẹ́ olórí ní gbogbo ọ̀rọ̀ tí ọba, àti àwọn ará Lefi pẹ̀lú yin yóò sìn gẹ́gẹ́ bí ìjòyè níwájú yín. Ẹ ṣe é pẹ̀lú ìmọ́kànle, Olúwa yóò sì wà pẹ̀lú àwọn tó bá ń ṣe rere.”
Glejte, véliki duhovnik Amarjá je nad vami v vseh Gospodovih zadevah in Jišmaélov sin Zebadjá, vladar Judove hiše, za vse kraljeve zadeve. Prav tako bodo Lévijevci častniki pred vami. Postopajte pogumno in Gospod bo z dobrim.«