< 2 Chronicles 19 >

1 Nígbà tí Jehoṣafati ọba Juda padà ní àlàáfíà sí ilé rẹ̀ ní Jerusalẹmu,
Și Iosafat, împăratul lui Iuda, s-a întors la casa lui, în pace, în Ierusalim.
2 Jehu aríran, ọmọ Hanani jáde lọ láti lọ pàdé rẹ̀, ó sì wí fún ọba pé, “Ṣé ìwọ yóò máa ran ènìyàn búburú lọ́wọ́, kí o sì fẹ́ràn àwọn tí ó kórìíra Olúwa? Nítorí èyí, ìbínú Olúwa wà lórí wa.
Și Iehu, fiul lui Hanani, văzătorul, a ieșit să îl întâmpine și a spus împăratului Iosafat: Este drept să ajuți pe cei neevlavioși și să îi iubești pe cei care urăsc pe DOMNUL? De aceea este furie peste tine dinaintea DOMNULUI.
3 Bí ó ti wù kí ó rí, ohun rere wà nínú rẹ, nítorí tí ìwọ ti mú àwọn ilé àwọn ère òrìṣà Aṣerah kúrò, tí o sì múra ọkàn rẹ láti wá Ọlọ́run.”
Totuși s-au găsit lucruri bune în tine, în aceea că ai îndepărtat dumbrăvile din țară și ți-ai pregătit inima să cauți pe Dumnezeu.
4 Jehoṣafati sì ń gbé ní Jerusalẹmu ó sì jáde lọ padà láàrín àwọn ènìyàn láti Beerṣeba dé òkè ìlú Efraimu, ó sì mú wọn padà sọ́dọ̀ Olúwa Ọlọ́run baba wọn.
Și Iosafat a locuit la Ierusalim și a ieșit din nou prin poporul de la Beer-Șeba la muntele Efraim și i-a adus înapoi la DOMNUL Dumnezeul părinților lor.
5 Ó sì yan àwọn onídàájọ́ sí ilẹ̀ náà, ní olúkúlùkù ìlú olódi Juda.
Și a așezat judecători în țară prin toate cetățile întărite din Iuda, cetate de cetate,
6 Ó sì wí fun wọ́n pé, “Ẹ kíyèsi ohun tí ẹ̀yin ń ṣe, nítorí ìwọ kò ṣe ìdájọ́ fun ènìyàn ṣùgbọ́n fún Olúwa, ẹni tí ó wà pẹ̀lú rẹ ní ìdájọ́.
Și a spus judecătorilor: Luați seama ce faceți, fiindcă nu judecați pentru om, ci pentru DOMNUL, care este cu voi în judecată.
7 Nísinsin yìí jẹ́ kí ìbẹ̀rù Olúwa kí ó wá sí ọkàn rẹ̀. Ṣe ìdájọ́ pẹ̀lẹ́pẹ̀lẹ́, nítorí pẹ̀lú Olúwa Ọlọ́run kò sí àìṣedéédéé tàbí ojúsàájú tàbí gbígba àbẹ̀tẹ́lẹ̀.”
De aceea acum, să fie frica de DOMNUL peste voi; luați seama și faceți aceasta, căci nu este nelegiuire cu DOMNUL Dumnezeul nostru, nici căutare la fața omului, nici primire de daruri.
8 Ní Jerusalẹmu pẹ̀lú, Jehoṣafati yan díẹ̀ lára àwọn Lefi, àwọn àlùfáà àti àwọn olórí ìdílé Israẹli si pípa òfin Olúwa mọ́ àti láti ṣe ìdájọ́. Wọn sì ń gbé ní Jerusalẹmu.
Mai mult, Iosafat a așezat în Ierusalim dintre leviți și preoți și dintre mai marii părinților lui Israel, pentru judecata DOMNULUI și pentru certe, când s-au întors la Ierusalim.
9 Ó sì kìlọ̀ fún wọn wí pé. “Ìwọ gbọdọ̀ sìn pẹ̀lú òtítọ́ àti pẹ̀lú ọkàn pípé ní ìbẹ̀rù Olúwa.
Și le-a poruncit, spunând: Astfel să faceți în frică de DOMNUL, cu credincioșie și cu o inimă desăvârșită.
10 Ní gbogbo ẹjọ́ tí ó bá wà níwájú rẹ láti ọ̀dọ̀ àwọn arákùnrin yín tí ń gbé ìlú wọn bóyá ẹ̀jẹ̀ tí ń sàn tàbí ìyókù òfin pẹ̀lú, pa á láṣẹ ìlànà àti ẹ̀tọ́, ìwọ gbọdọ̀ kìlọ̀ fún wọn láti má ṣe dẹ́ṣẹ̀ sí Olúwa bí bẹ́ẹ̀ kọ́, ìbínú yóò sì wá sórí yín, àti sórí àwọn arákùnrin. Ṣe èyí, ìwọ kì yóò sì jẹ̀bi.
Și orice cauză va veni la voi dintre frații voștri care locuiesc în cetățile lor, între sânge și sânge, între lege și poruncă, statute și judecăți, să îi avertizați să nu încalce legea împotriva DOMNULUI și astfel furie să vină peste voi și peste frații voștri; faceți aceasta și nu veți încălca legea.
11 “Amariah àlùfáà ni yóò jẹ́ olórí yín nínú gbogbo ọ̀ràn tí ó jẹ́ ti Olúwa, àti Sebadiah ọmọ Iṣmaeli alákòóso ìdílé Juda, ní yóò jẹ́ olórí ní gbogbo ọ̀rọ̀ tí ọba, àti àwọn ará Lefi pẹ̀lú yin yóò sìn gẹ́gẹ́ bí ìjòyè níwájú yín. Ẹ ṣe é pẹ̀lú ìmọ́kànle, Olúwa yóò sì wà pẹ̀lú àwọn tó bá ń ṣe rere.”
Și, iată, Amaria, mai marele preot, este peste voi în toate treburile DOMNULUI; și Zebadia, fiul lui Ismael, conducătorul casei lui Iuda, pentru toate treburile împăratului; de asemenea leviții vor fi administratori pentru voi. Purtați-vă curajos și DOMNUL va fi cu cel bun.

< 2 Chronicles 19 >