< 2 Chronicles 19 >

1 Nígbà tí Jehoṣafati ọba Juda padà ní àlàáfíà sí ilé rẹ̀ ní Jerusalẹmu,
A Jehoszafat, król Judy, wrócił do swojego domu w pokoju, do Jerozolimy.
2 Jehu aríran, ọmọ Hanani jáde lọ láti lọ pàdé rẹ̀, ó sì wí fún ọba pé, “Ṣé ìwọ yóò máa ran ènìyàn búburú lọ́wọ́, kí o sì fẹ́ràn àwọn tí ó kórìíra Olúwa? Nítorí èyí, ìbínú Olúwa wà lórí wa.
I wyszedł mu naprzeciw widzący Jehu, syn Chananiego, i powiedział do króla Jehoszafata: Czy powinieneś był pomagać bezbożnym i miłować tych, którzy nienawidzą PANA? Przez to właśnie [wisi] nad tobą gniew PANA.
3 Bí ó ti wù kí ó rí, ohun rere wà nínú rẹ, nítorí tí ìwọ ti mú àwọn ilé àwọn ère òrìṣà Aṣerah kúrò, tí o sì múra ọkàn rẹ láti wá Ọlọ́run.”
Znalazły się jednak dobre czyny w tobie, bo powycinałeś gaje z ziemi i przygotowałeś swoje serce, aby szukać Boga.
4 Jehoṣafati sì ń gbé ní Jerusalẹmu ó sì jáde lọ padà láàrín àwọn ènìyàn láti Beerṣeba dé òkè ìlú Efraimu, ó sì mú wọn padà sọ́dọ̀ Olúwa Ọlọ́run baba wọn.
Zamieszkał więc Jehoszafat w Jerozolimie. I znowu wyruszył na objazd do ludu, od Beer-Szeby aż do góry Efraim, i nawrócił ich do PANA, Boga swoich ojców.
5 Ó sì yan àwọn onídàájọ́ sí ilẹ̀ náà, ní olúkúlùkù ìlú olódi Juda.
I ustanowił sędziów w ziemi we wszystkich warownych miastach Judy, w każdym mieście.
6 Ó sì wí fun wọ́n pé, “Ẹ kíyèsi ohun tí ẹ̀yin ń ṣe, nítorí ìwọ kò ṣe ìdájọ́ fun ènìyàn ṣùgbọ́n fún Olúwa, ẹni tí ó wà pẹ̀lú rẹ ní ìdájọ́.
I powiedział do sędziów: Uważajcie na to, co czynicie, bo sądzicie nie dla człowieka, ale dla PANA, który jest z wami podczas sprawowania sądu.
7 Nísinsin yìí jẹ́ kí ìbẹ̀rù Olúwa kí ó wá sí ọkàn rẹ̀. Ṣe ìdájọ́ pẹ̀lẹ́pẹ̀lẹ́, nítorí pẹ̀lú Olúwa Ọlọ́run kò sí àìṣedéédéé tàbí ojúsàájú tàbí gbígba àbẹ̀tẹ́lẹ̀.”
Niech więc będzie w was bojaźń PANA. Strzeżcie się i czyńcie [sprawiedliwość]. Nie ma bowiem nieprawości u PANA, Boga naszego, i nie ma względu na osoby ani przyjmowania darów.
8 Ní Jerusalẹmu pẹ̀lú, Jehoṣafati yan díẹ̀ lára àwọn Lefi, àwọn àlùfáà àti àwọn olórí ìdílé Israẹli si pípa òfin Olúwa mọ́ àti láti ṣe ìdájọ́. Wọn sì ń gbé ní Jerusalẹmu.
Także i w Jerozolimie Jehoszafat ustanowił [niektórych] spośród Lewitów, kapłanów i naczelników rodów Izraela dla sądu PANA i do [rozstrzygania] sporów tych, którzy się udawali do Jerozolimy.
9 Ó sì kìlọ̀ fún wọn wí pé. “Ìwọ gbọdọ̀ sìn pẹ̀lú òtítọ́ àti pẹ̀lú ọkàn pípé ní ìbẹ̀rù Olúwa.
I nakazał im: Czyńcie to w bojaźni PANA, wiernie i doskonałym sercem.
10 Ní gbogbo ẹjọ́ tí ó bá wà níwájú rẹ láti ọ̀dọ̀ àwọn arákùnrin yín tí ń gbé ìlú wọn bóyá ẹ̀jẹ̀ tí ń sàn tàbí ìyókù òfin pẹ̀lú, pa á láṣẹ ìlànà àti ẹ̀tọ́, ìwọ gbọdọ̀ kìlọ̀ fún wọn láti má ṣe dẹ́ṣẹ̀ sí Olúwa bí bẹ́ẹ̀ kọ́, ìbínú yóò sì wá sórí yín, àti sórí àwọn arákùnrin. Ṣe èyí, ìwọ kì yóò sì jẹ̀bi.
A przy wszystkich sporach, które wam przedłożą wasi bracia mieszkający w swoich miastach, czy dotyczą one przelania krwi, czy prawa, przykazania, ustaw czy sądów, napominajcie ich, aby nie grzeszyli przeciwko PANU, aby gniew nie spadł na was i na waszych braci. Tak czyńcie, a nie zgrzeszycie.
11 “Amariah àlùfáà ni yóò jẹ́ olórí yín nínú gbogbo ọ̀ràn tí ó jẹ́ ti Olúwa, àti Sebadiah ọmọ Iṣmaeli alákòóso ìdílé Juda, ní yóò jẹ́ olórí ní gbogbo ọ̀rọ̀ tí ọba, àti àwọn ará Lefi pẹ̀lú yin yóò sìn gẹ́gẹ́ bí ìjòyè níwájú yín. Ẹ ṣe é pẹ̀lú ìmọ́kànle, Olúwa yóò sì wà pẹ̀lú àwọn tó bá ń ṣe rere.”
A oto najwyższy kapłan Amariasz [będzie] postawiony nad wami we wszystkich sprawach PANA, a Zebadiasz, syn Izmaela, książę w domu Judy – we wszystkich sprawach króla. Lewici będą również waszymi urzędnikami. Umacniajcie się i czyńcie [tak], a PAN będzie z dobrym.

< 2 Chronicles 19 >