< 2 Chronicles 19 >

1 Nígbà tí Jehoṣafati ọba Juda padà ní àlàáfíà sí ilé rẹ̀ ní Jerusalẹmu,
Josaphat, roi de Juda, retourna en paix dans sa maison, à Jérusalem.
2 Jehu aríran, ọmọ Hanani jáde lọ láti lọ pàdé rẹ̀, ó sì wí fún ọba pé, “Ṣé ìwọ yóò máa ran ènìyàn búburú lọ́wọ́, kí o sì fẹ́ràn àwọn tí ó kórìíra Olúwa? Nítorí èyí, ìbínú Olúwa wà lórí wa.
Jéhu, fils de Hanani, le devin, sortit à sa rencontre et dit au roi Josaphat: « Veux-tu aider les méchants et aimer ceux qui haïssent Yahvé? A cause de cela, la colère est sur toi de la part de Yahvé.
3 Bí ó ti wù kí ó rí, ohun rere wà nínú rẹ, nítorí tí ìwọ ti mú àwọn ilé àwọn ère òrìṣà Aṣerah kúrò, tí o sì múra ọkàn rẹ láti wá Ọlọ́run.”
Cependant, il y a du bon en toi, car tu as fait disparaître les ashéroth du pays et tu as mis ton cœur à chercher Dieu. »
4 Jehoṣafati sì ń gbé ní Jerusalẹmu ó sì jáde lọ padà láàrín àwọn ènìyàn láti Beerṣeba dé òkè ìlú Efraimu, ó sì mú wọn padà sọ́dọ̀ Olúwa Ọlọ́run baba wọn.
Josaphat habitait à Jérusalem. Il sortit de nouveau au milieu du peuple, depuis Beer Schéba jusqu'à la montagne d'Ephraïm, et il le ramena à Yahvé, le Dieu de ses pères.
5 Ó sì yan àwọn onídàájọ́ sí ilẹ̀ náà, ní olúkúlùkù ìlú olódi Juda.
Il établit des juges dans le pays, dans toutes les villes fortes de Juda, ville par ville,
6 Ó sì wí fun wọ́n pé, “Ẹ kíyèsi ohun tí ẹ̀yin ń ṣe, nítorí ìwọ kò ṣe ìdájọ́ fun ènìyàn ṣùgbọ́n fún Olúwa, ẹni tí ó wà pẹ̀lú rẹ ní ìdájọ́.
et il dit aux juges: « Considérez ce que vous faites, car vous ne jugez pas pour un homme, mais pour Yahvé, et il est avec vous dans le jugement.
7 Nísinsin yìí jẹ́ kí ìbẹ̀rù Olúwa kí ó wá sí ọkàn rẹ̀. Ṣe ìdájọ́ pẹ̀lẹ́pẹ̀lẹ́, nítorí pẹ̀lú Olúwa Ọlọ́run kò sí àìṣedéédéé tàbí ojúsàájú tàbí gbígba àbẹ̀tẹ́lẹ̀.”
Maintenant, que la crainte de Yahvé soit sur vous. Prenez garde et faites-le, car il n'y a pas d'iniquité avec l'Éternel, notre Dieu, ni de respect des personnes, ni d'acceptation de pots-de-vin. »
8 Ní Jerusalẹmu pẹ̀lú, Jehoṣafati yan díẹ̀ lára àwọn Lefi, àwọn àlùfáà àti àwọn olórí ìdílé Israẹli si pípa òfin Olúwa mọ́ àti láti ṣe ìdájọ́. Wọn sì ń gbé ní Jerusalẹmu.
Josaphat nomma à Jérusalem des lévites, des prêtres et des chefs de famille d'Israël pour qu'ils rendent des jugements en faveur de Yahvé et en cas de litige. Ils retournèrent à Jérusalem.
9 Ó sì kìlọ̀ fún wọn wí pé. “Ìwọ gbọdọ̀ sìn pẹ̀lú òtítọ́ àti pẹ̀lú ọkàn pípé ní ìbẹ̀rù Olúwa.
Il leur donna cet ordre: « Vous ferez cela dans la crainte de Yahvé, fidèlement et avec un cœur parfait.
10 Ní gbogbo ẹjọ́ tí ó bá wà níwájú rẹ láti ọ̀dọ̀ àwọn arákùnrin yín tí ń gbé ìlú wọn bóyá ẹ̀jẹ̀ tí ń sàn tàbí ìyókù òfin pẹ̀lú, pa á láṣẹ ìlànà àti ẹ̀tọ́, ìwọ gbọdọ̀ kìlọ̀ fún wọn láti má ṣe dẹ́ṣẹ̀ sí Olúwa bí bẹ́ẹ̀ kọ́, ìbínú yóò sì wá sórí yín, àti sórí àwọn arákùnrin. Ṣe èyí, ìwọ kì yóò sì jẹ̀bi.
Chaque fois qu'une controverse vous viendra de vos frères qui habitent dans leurs villes, entre le sang et le sang, entre la loi et le commandement, les statuts et les ordonnances, vous les avertirez, afin qu'ils ne soient pas coupables envers Yahvé, et qu'ainsi la colère ne vienne pas sur vous et sur vos frères. Fais cela, et tu ne seras pas coupable.
11 “Amariah àlùfáà ni yóò jẹ́ olórí yín nínú gbogbo ọ̀ràn tí ó jẹ́ ti Olúwa, àti Sebadiah ọmọ Iṣmaeli alákòóso ìdílé Juda, ní yóò jẹ́ olórí ní gbogbo ọ̀rọ̀ tí ọba, àti àwọn ará Lefi pẹ̀lú yin yóò sìn gẹ́gẹ́ bí ìjòyè níwájú yín. Ẹ ṣe é pẹ̀lú ìmọ́kànle, Olúwa yóò sì wà pẹ̀lú àwọn tó bá ń ṣe rere.”
Voici, Amaria, le grand prêtre, est au-dessus de vous pour toutes les affaires de Yahvé; et Zebadia, fils d'Ismaël, chef de la maison de Juda, pour toutes les affaires du roi. Les Lévites seront aussi des officiers devant toi. Agis avec courage, et que Yahvé soit avec le bien. »

< 2 Chronicles 19 >