< 2 Chronicles 19 >

1 Nígbà tí Jehoṣafati ọba Juda padà ní àlàáfíà sí ilé rẹ̀ ní Jerusalẹmu,
Forsothe Josaphat, kyng of Juda, turnede ayen pesibli in to his hows in to Jerusalem.
2 Jehu aríran, ọmọ Hanani jáde lọ láti lọ pàdé rẹ̀, ó sì wí fún ọba pé, “Ṣé ìwọ yóò máa ran ènìyàn búburú lọ́wọ́, kí o sì fẹ́ràn àwọn tí ó kórìíra Olúwa? Nítorí èyí, ìbínú Olúwa wà lórí wa.
Whom the profete Hieu, the sone of Ananye, mette, and seide to hym, Thou yyuest help to a wickid man, and thou art ioyned bi frendschip to hem that haten the Lord; and therfor sotheli thou deseruedist the wraththe of the Lord;
3 Bí ó ti wù kí ó rí, ohun rere wà nínú rẹ, nítorí tí ìwọ ti mú àwọn ilé àwọn ère òrìṣà Aṣerah kúrò, tí o sì múra ọkàn rẹ láti wá Ọlọ́run.”
but good werkis ben foundyn in thee, for thou didist awey wodis fro the lond of Juda, and thou hast maad redi thin herte, for to seke the Lord God of thi fadris.
4 Jehoṣafati sì ń gbé ní Jerusalẹmu ó sì jáde lọ padà láàrín àwọn ènìyàn láti Beerṣeba dé òkè ìlú Efraimu, ó sì mú wọn padà sọ́dọ̀ Olúwa Ọlọ́run baba wọn.
Therfor Josaphat dwellide in Jerusalem; and eft he yede out to the puple fro Bersabee til to the hil of Effraym, and he clepide hem ayen to the Lord God of her fadris.
5 Ó sì yan àwọn onídàájọ́ sí ilẹ̀ náà, ní olúkúlùkù ìlú olódi Juda.
And he ordeynede iugis of the lond in alle the strengthid citees of Juda, bi ech place.
6 Ó sì wí fun wọ́n pé, “Ẹ kíyèsi ohun tí ẹ̀yin ń ṣe, nítorí ìwọ kò ṣe ìdájọ́ fun ènìyàn ṣùgbọ́n fún Olúwa, ẹni tí ó wà pẹ̀lú rẹ ní ìdájọ́.
And he comaundide to the iugis, and seide, Se ye, what ye doen; for ye vsen not the doom of man, but of the Lord; and what euere thing ye demen, schal turne `in to you;
7 Nísinsin yìí jẹ́ kí ìbẹ̀rù Olúwa kí ó wá sí ọkàn rẹ̀. Ṣe ìdájọ́ pẹ̀lẹ́pẹ̀lẹ́, nítorí pẹ̀lú Olúwa Ọlọ́run kò sí àìṣedéédéé tàbí ojúsàájú tàbí gbígba àbẹ̀tẹ́lẹ̀.”
the drede of the Lord be with you, and do ye alle thingis with diligence; for anentis `youre Lord God is no wickidnesse, nether takynge of persoones, nether coueitise of yiftis.
8 Ní Jerusalẹmu pẹ̀lú, Jehoṣafati yan díẹ̀ lára àwọn Lefi, àwọn àlùfáà àti àwọn olórí ìdílé Israẹli si pípa òfin Olúwa mọ́ àti láti ṣe ìdájọ́. Wọn sì ń gbé ní Jerusalẹmu.
Also in Jerusalem Josaphat ordeynede dekenes, and preestis, and the princes of meynees of Israel, that thei schulden deme the doom and cause of the Lord to the dwellers of it.
9 Ó sì kìlọ̀ fún wọn wí pé. “Ìwọ gbọdọ̀ sìn pẹ̀lú òtítọ́ àti pẹ̀lú ọkàn pípé ní ìbẹ̀rù Olúwa.
And he comaundide to hem, and seide, Thus ye schulen do in the drede of the Lord, feithfuli and in perfite herte.
10 Ní gbogbo ẹjọ́ tí ó bá wà níwájú rẹ láti ọ̀dọ̀ àwọn arákùnrin yín tí ń gbé ìlú wọn bóyá ẹ̀jẹ̀ tí ń sàn tàbí ìyókù òfin pẹ̀lú, pa á láṣẹ ìlànà àti ẹ̀tọ́, ìwọ gbọdọ̀ kìlọ̀ fún wọn láti má ṣe dẹ́ṣẹ̀ sí Olúwa bí bẹ́ẹ̀ kọ́, ìbínú yóò sì wá sórí yín, àti sórí àwọn arákùnrin. Ṣe èyí, ìwọ kì yóò sì jẹ̀bi.
Ech cause that cometh to you of youre britheren, that dwellen in her citees, bitwixe kynrede and kynrede, where euere is questioun of the lawe, of `the comaundement, of cerymonyes, `ether sacrifices, of iustifyingis, schewe ye to hem, that thei do not synne ayens the Lord, and that wraththe com not on you and on youre britheren. Therfor ye doynge thus schulen not do synne.
11 “Amariah àlùfáà ni yóò jẹ́ olórí yín nínú gbogbo ọ̀ràn tí ó jẹ́ ti Olúwa, àti Sebadiah ọmọ Iṣmaeli alákòóso ìdílé Juda, ní yóò jẹ́ olórí ní gbogbo ọ̀rọ̀ tí ọba, àti àwọn ará Lefi pẹ̀lú yin yóò sìn gẹ́gẹ́ bí ìjòyè níwájú yín. Ẹ ṣe é pẹ̀lú ìmọ́kànle, Olúwa yóò sì wà pẹ̀lú àwọn tó bá ń ṣe rere.”
Forsothe Amarie, youre preest and bischop, schal be souereyn in these thingis, that perteynen to God. Sotheli Zabadie, the sone of Ismael, which is duyk in the hows of Juda, schal be on tho werkis that perteynen to the office of the kyng, and ye han maistris dekenes bifor you; be ye coumfortid, and do ye diligentli, and the Lord schal be with you in goodis.

< 2 Chronicles 19 >