< 2 Chronicles 18 >

1 Nísinsin yìí Jehoṣafati sì ní ọrọ̀ àti ọlá púpọ̀, ó sì dá àna pẹ̀lú Ahabu nípa fífẹ́ ọmọ rẹ̀.
Ita, bimmaknang ken mararaem iti kasta unay ni Jehosafat; nakigayyem isuna kenni Ahab babaen iti panangipaasawana iti maysa kadagiti pamiliana iti putot a babai ni Ahab.
2 Lẹ́yìn ọjọ́ díẹ̀, ó sọ̀kalẹ̀ láti lọ bá Ahabu lálejò ní Samaria. Ahabu sì pa àgùntàn àti màlúù púpọ̀ fún àti àwọn ènìyàn tí ó wà pẹ̀lú rẹ̀ ó sì rọ̀ ọ́ láti dojú ìjà kọ Ramoti Gileadi.
Kalpasan iti sumagmamano a tawen, simmalog isuna iti ayan ni Ahab idiay Samaria. Nangparti ni Ahab iti adu a karnero ken baka para kenkuana ken kadagiti tattao a kaduana. Inallukoy met isuna ni Ahab a makikadua kenkuana a mangraut iti Ramot Galaad.
3 Ahabu ọba Israẹli sì béèrè lọ́wọ́ ọba Jehoṣafati, ọba Juda pé, “Ṣé ìwọ yóò lọ pẹ̀lú mi sí Ramoti Gileadi?” Jehoṣafati sì dá a lóhùn pé, “Èmi wà gẹ́gẹ́ bí ìwọ ti ṣe wà, àti àwọn ènìyàn mi gẹ́gẹ́ bí ènìyàn rẹ àwa yóò pẹ̀lú rẹ nínú ogun náà”.
Kinuna ni Ahab nga ari ti Israel kenni Jehosafat nga ari ti Juda, “Sumurotka kadi kaniak idiay Ramot Galaad?” Insungbat ni Jehosafat iti ari ti Israel, “Kaslaak kenka, ken dagiti tattaok ket kasla kadagiti tattaom; kaduaandakayonto a makigubat.”
4 Ṣùgbọ́n Jehoṣafati náà sì tún wí fún ọba Israẹli pé, “Kọ́kọ́ béèrè lọ́wọ́ Olúwa.”
Kinuna ni Jehosafat iti ari ti Israel, “Pangaasim ta ammoem pay nga umuna ti ibaga ni Yahweh para iti sungbatmo.”
5 Bẹ́ẹ̀ ọba Israẹli kó àwọn wòlíì papọ̀, irinwó ọkùnrin ó sì bi wọ́n pé, “Kí àwa kí lọ sí ogun Ramoti Gileadi tàbí kí èmi kí ó jọ̀wọ́ rẹ?” Wọ́n dáhùn pé, “Lọ, nítorí tí Ọlọ́run yóò fi lé ọba lọ́wọ́.”
Ket inummong ti ari ti Israel dagiti profetana, 400 a lallaki, ket kinunana kadakuada, “Mapanmi kadi rauten ti Ramot Galaad wenno saan? Kinunada, “Rautenyo, ta pagballigiento ti Dios ti ari.”
6 Ṣùgbọ́n Jehoṣafati béèrè pé, “Ṣé kò ha sí wòlíì Olúwa níbí ẹni tí àwa ìbá béèrè lọ́wọ́ rẹ̀?”
Ngem kinuna ni Jehosafat, “Awan kadin ditoy ti sabali pay a profeta ni Yahweh a mabalintayo a pagkiddawan iti balakad?”
7 Ọba Israẹli dá Jehoṣafati lóhùn pé, “Ọkùnrin kan wà síbẹ̀ lọ́dọ̀ ẹni tí àwa ìbá tún béèrè lọ́wọ́ Olúwa, ṣùgbọ́n èmi kórìíra rẹ̀ nítorí kò jẹ́ sọ àsọtẹ́lẹ̀ ohun rere kan nípa mi ṣùgbọ́n bí kò ṣe ohun búburú, ní gbogbo ìgbà òun náà ni Mikaiah ọmọ Imla.” Jehoṣafati sì dá lóhùn pé, “Ọba kò gbọdọ̀ sọ bẹ́ẹ̀.”
Kinuna ti ari ti Israel kenni Jehosafat, “Adda pay maysa a tao a mabalintayo a pagdawatan iti balakad manipud kenni Yahweh, ni Micaias a putot ni Imla, ngem kagurgurak isuna ta saan a pulos a mangipadto iti aniaman a nasayaat a banag maipanggep kaniak, ngem ketdi pasig a kinarigat laeng.” Ngem kinuna ni Jehosafat, “Saan koma nga ibaga ti ari dayta.”
8 Bẹ́ẹ̀ ni ọba Israẹli pe ọ̀kan lára àwọn ìjòyè ó sì wí pé, “Ẹ mú Mikaiah ọmọ Imla kí ó yára wá.”
Ket nangayab ti ari ti Israel iti opisial ket binilinna, “Iyegyo itan ni Micaias a putot ni Imla.”
9 Wọ́n wọ aṣọ ìgúnwà wọn, ọba Israẹli àti Jehoṣafati ọba Juda wọ́n jókòó sórí ìtẹ́ wọ́n ní ìta ẹnu-bodè Samaria, pẹ̀lú gbogbo àwọn wòlíì tí ń sọtẹ́lẹ̀ níwájú wọn.
Ita, nakatugaw ni Ahab nga ari ti Israel ken ni Jehosafat nga ari ti Juda kadagiti tronoda, nakakawesda kadagiti pagan-anayda a kas ari, iti nawaya a lugar iti pagserkan ti ruangan ti Samaria, ket agipadpadto dagiti amin a profeta, iti sangoananda.
10 Nísinsin yìí Sedekiah ọmọ Kenaana sì ti ṣe ìwo irin, ó sì wí pé, “Èyí ni ohun tí Olúwa sọ: ‘Pẹ̀lú èyí ìwọ yóò kan àwọn ará Siria títí ìwọ ó fi pa wọ́n run.’”
Nangaramid ni Zedekias a putot ni Kenaana iti sinan-sara a landok ket kinunana, “Kastoy ti imbaga ni Yahweh: 'Babaen kadagitoy maparmekyonto dagiti taga-Aram agingga a maibusda.”
11 Gbogbo àwọn wòlíì tí ó kù ni wọn ń sọtẹ́lẹ̀ ní àkókò kan náà. Wọ́n sì wí pé, “Dojúkọ Ramoti Gileadi ìwọ yóò sì ṣẹ́gun, nítorí Olúwa yóò fi lé ọba lọ́wọ́.”
Ket kasta met laeng ti impadto dagiti amin a profeta, a kunada, “Rautenyo ti Ramot Galaad ket agballigikayo, ta inyawat daytoy ni Yahweh iti ima ti ari.”
12 Ìránṣẹ́ tí ó ti lọ pe Mikaiah sì wí fún un pé, “Ẹ wò ó, gẹ́gẹ́ bí ọkùnrin kan àti òmíràn wòlíì fi ẹnu kan sọ rere fún ọba. Jẹ́ kí ọ̀rọ̀ rẹ kí ó dàbí ọ̀kan nínú tiwọn, kí o sì sọ rere.”
Nakisao kenni Micaias ti mensahero a napan nangayab kenkuana, a kunana, “Ita dumngegka, pasig a nasayaat a banbanag dagiti sasao nga imbaga dagiti profeta ti ari. Pangngaasim ta ibagam koma ti kas iti imbaga ti maysa kadakuada ket nasayaat a banbanag ti ibagam.”
13 Ṣùgbọ́n Mikaiah wí pe, “Gẹ́gẹ́ bí ó ti dájú pé Olúwa ń bẹ láààyè, èmi yóò sọ ohun tí Ọlọ́run mi sọ.”
Insungbat ni Micaias, “Iti nagan ni Yahweh nga adda iti agnanayon, no ania ti ibaga ni Yahweh kaniak ti sawek.”
14 Nígbà tí ó dé, ọba béèrè lọ́wọ́ rẹ̀, “Mikaiah, ṣe kí àwa ki ó lọ sí ogun ti Ramoti Gileadi, tàbí kí àwa kí ó fàsẹ́yìn?” Ó sì dáhùn pé, “Ẹ dojúkọ wọ́n kí ẹ sì ṣẹ́gun, nítorí a ó fi wọ́n lé yín lọ́wọ́.”
Idi napan isuna iti ayan ti ari, kinuna ti ari kenkuana, “Micaias, mapanmi kadi rauten ti Ramot Galaad, wenno saan?” Insungbat ni Micaias, “Rautem ket agballigika! Ta dakkelto daytoy a balligi.”
15 Ọba sì wí fún un pé, “Ìgbà mélòó ni èmi ó fi ọ́ búra láti sọ ohun kan fún mi bí kò ṣe ọ̀rọ̀ òtítọ́ ní orúkọ Olúwa?”
Ket kinuna ti ari kenkuana, “Namin-ano a daras nga imbagak kenka nga isapatam a ti laeng kinapudno ti ibagam kaniak iti nagan ni Yahweh?”
16 Mikaiah sì dáhùn pé, “Mo rí gbogbo Israẹli túká kiri lórí àwọn òkè bí àgùntàn tí kò ní olùṣọ́, Olúwa sì wí pé, ‘Àwọn wọ̀nyí kò ní olúwa. Jẹ́ kí olúkúlùkù padà sí ilé rẹ̀ ní àlàáfíà.’”
Isu a kinuna ni Micaias, “Nakitak ti entero nga Israel a nawarawara kadagiti banbantay, kasda la karnero nga awan mangipaspastor, ket kinuna ni Yahweh, 'Awan mangipaspastor kadagitoy. Agsubli koma ti tunggal maysa iti balayna nga addaan kappia.”’
17 Ọba Israẹli wí fún Jehoṣafati pé, “Ṣe èmi kò sọ fún ọ wí pé òun kò sọ àsọtẹ́lẹ̀ rere kankan nípa mi rí, ṣùgbọ́n búburú nìkan?”
Isu a kinuna ti ari ti Israel kenni Jehosafat, “Saan kadi nga imbagak kenka a saan isuna nga agipadto iti nasayaat maipanggep kaniak, ngem pasig a didigra laeng?”
18 Mikaiah tẹ̀síwájú pé, “Nítorí náà, gbọ́ ọ̀rọ̀ Olúwa, mo rí Olúwa jókòó lórí ìtẹ́ rẹ̀ gbogbo ogun ọ̀run sì dúró lápá ọ̀tún àti lápá òsì.
Ket kinuna ni Micaias, “Masapul ngarud a denggenyo amin ti sao ni Yahweh: Nakitak ni Yahweh a nakatugaw iti tronona, ken amin dagiti buybuyot ti langit ket agtaktakder iti makannawanna ken iti makannigidna.
19 Olúwa sì wí pé, ‘Ta ni yóò tan Ahabu ọba Israẹli lọ sí Ramoti Gileadi kí ó sì lọ kú ikú rẹ̀ níbẹ̀?’ “Èkínní sì sọ tìhín, òmíràn sì sọ tọ̀hún.
Kinuna ni Yahweh, 'Siasino ti mangallilaw kenni Ahab, nga ari ti Israel tapno sumang-at idiay Ramot Galaad ket maparmek sadiay?' Ket nagduduma ti insungbat ti tunggal maysa.
20 Ní ìparí, ni ẹ̀mí kan wá síwájú, ó dúró níwájú Olúwa ó sì wí pé, ‘Èmi yóò tàn án.’ “‘Nípa ọ̀nà wo?’ Olúwa béèrè.
Ket adda maysa nga espiritu a nagpasango, nagtakder iti sangoanan ni Yahweh, ket kinunana, 'Siak ti mangallilaw kenkuana.' Kinuna ni Yahweh kenkuana, 'Kasano?'
21 “‘Èmi yóò lọ láti lọ di ẹ̀mí èké ní ẹnu gbogbo àwọn wòlíì.’ “‘Ìwọ yóò sì borí nínú ìtànjẹ rẹ̀ báyìí,’ ni Olúwa wí. ‘Lọ kí ó sì ṣe bẹ́ẹ̀.’
Insungbat ti espiritu, 'Mapanak ket pag-ulbodek dagiti amin a profetana.' Insungbat ni Yahweh, 'Allilawem isuna, ket agballigikanto. Mapanka ket aramiden ti imbagam.'
22 “Bẹ́ẹ̀ ni nísinsin yìí Olúwa ti fi ẹ̀mí èké sí ẹnu àwọn wòlíì rẹ. Olúwa sì ti sọ ibi sí ọ.”
'Ita kitaem, pagul-ulboden ni Yahweh dagiti amin a profetam, ket inkeddeng ni Yahweh ti pannakadidigram.”
23 Nígbà náà Sedekiah ọmọ Kenaana lọ sókè ó sì gbá Mikaiah ní ojú. Ó sì béèrè pé, “Ní ọ̀nà wo ni ẹ̀mí Olúwa gbà kọjá lọ kúrò lọ́dọ̀ mi láti bá ọ sọ̀rọ̀?”
Kalpasanna, immasideg ni Zedekaias a putot ni Kenaana, tinungpana ni Micaias, ket kinunana, “Kasano koma a rimmuar kaniak ti Espiritu ni Yahweh tapno makitungtong kenka?”
24 Mikaiah sì dáhùn pé, “Ìwọ yóò ṣe ìwádìí ní ọjọ́ tí ìwọ yóò sá pamọ́ sínú ìyẹ̀wù.”
Kinuna ni Micaias, “Kitaem, maammoamto dayta iti aldaw nga agtarayka a mapan aglemmeng iti akin uneg a siled.”
25 Ọba Israẹli pa á láṣẹ pé, “Mú Mikaiah kí o sì ran padà sí Amoni olórí ìlú àti sí Joaṣi ọmọ ọba,
Kinuna ti ari ti Israel kadagiti dadduma nga adipenna, “Dakayo a tattao tiliwenyo ni Micaias ket ipanyo kenni Amon, a gobernador ti siudad, ken ni Joas, nga anakko.
26 Ó sì wí pé, ‘Èyí ni ohun tí ọba sọ, ẹ fi ènìyàn yìí sínú túbú kí ẹ má sì ṣe fún un ní ohunkóhun ṣùgbọ́n àkàrà àti omi títí tí èmi yóò fi dé ní àlàáfíà.’”
Ibagayo kenkuana, 'Kuna ti ari, Ibaludyo daytoy a tao ket bassit laeng a tinapay ti ipakanyo ken bassit laeng a danum, agingga a makasangpetak a sikakaradkad.”’
27 Mikaiah sì wí pe, “Tí ìwọ bá padà ní àlàáfíà, Olúwa kò sọ̀rọ̀ láti ọ̀dọ̀ mi.” Nígbà náà, ó sì fi kún un pé, “Ẹ gbọ́ ọ̀rọ̀ mi, gbogbo ẹ̀yin ènìyàn!”
Ket kinuna ni Micaias, “No makasublika a sikakaradkad, saan ngarud a nagsao ni Yahweh kaniak.” Ket kinunana pay, “Denggenyo daytoy, dakayo amin a tattao.”
28 Bẹ́ẹ̀ ni ọba Israẹli àti Jehoṣafati ọba Juda lọ sókè ní Ramoti Gileadi.
Simmang-at ngarud da Ahab nga ari ti Israel, ken ni Jehosafat nga ari ti Juda idiay Ramot Galaad.
29 Ọba Israẹli sọ fún Jehoṣafati pé, “Èmi yóò lọ sí ojú ìjà, ṣùgbọ́n ìwọ wọ aṣọ ìgúnwà rẹ.” Bẹ́ẹ̀ ni ọba Israẹli pa aṣọ rẹ̀ dà, ó sì lọ sí ojú ìjà.
Kinuna ti ari ti Israel kenni Jehosafat, “Manglimlimoak ket mapanak iti paggugubatan, ngem ikawesmo dagiti pagan-anaymo a kas ari.” Nanglimlimo ngarud ti ari ti Israel ket napan iti paggugubatan.
30 Nísinsin yìí ọba Siria ti pàṣẹ fún àwọn olórí kẹ̀kẹ́ tí ó wà ní ọ̀dọ̀ rẹ̀ pé, “Ẹ má ṣe jà pẹ̀lú ẹnìkankan, èwe tàbí àgbà àyàfi ọba Israẹli.”
Ita, binilin ti ari ti Aram dagiti kapitan ti karwahena, a kunana, “Saanyo a darupen ti siasinoman kadagiti soldado. Ngem ketdi, ti laeng ari ti Israel ti darupenyo.”
31 Nígbà tí àwọn olórí kẹ̀kẹ́ rí Jehoṣafati, wọ́n rò wí pé, “Èyí ní ọba Israẹli.” Bẹ́ẹ̀ ni wọ́n sì yípadà láti bá a jà. Ṣùgbọ́n Jehoṣafati kégbe sókè, Olúwa sì ràn án lọ́wọ́. Ọlọ́run sì lé wọn kúrò lọ́dọ̀ rẹ̀,
Ket napasamak nga idi nakita dagiti kapitan ni Jehosafat kinunada, “Dayta ti ari ti Israel.” Nagbaw-ingda a mangdarup kenkuana, ngem nagriaw ni Jehosafat, ket tinulongan isuna ni Yahweh. Pinagsardeng ida ti Dios iti panangdarupda kenkuana.
32 Ó sì ṣe, nígbà tí olórí kẹ̀kẹ́ rí i wí pé kì í ṣe ọba Israẹli, wọ́n sì dáwọ́ lílé rẹ̀ dúró.
Ket napasamak nga idi nakita dagiti mangidadaulo kadagiti karwahe a saan nga isu ti ari ti Israel, insardengda ti panangkamatda kenkuana.
33 Ṣùgbọ́n ẹnìkan fa ọrun rẹ̀ láì pète, ó sì bá ọba Israẹli láàrín ìpàdé ẹ̀wù irin, ọba sì sọ fún olùtọ́jú kẹ̀kẹ́ rẹ̀ pé, “Yí ọwọ́ rẹ padà, kí o sì wà mí jáde kúrò lójú ìjà. Nítorí èmi ti gbọgbẹ́.”
Ngem adda maysa a lalaki a nangibiat iti panana a saanna a kitkitaen ti mapanana ket natamaan ti ari ti Israel iti nagsaipan ti kabalna. Ket kinuna ni Ahab iti mangiturturong iti karwahena, “Agsublita ket ipanawnak ditoy paggugubatan, ta nasugatanak iti nakaro.”
34 Ní ọjọ́ pípẹ́, ìjà náà sì ń pọ̀ sí i, ọba Israẹli dúró nínú kẹ̀kẹ́ rẹ̀ kọjú sí àwọn ará Siria títí ó fi di àṣálẹ́. Lẹ́yìn náà ní àkókò ìwọ oòrùn, ó sì kú.
Kimmarkaro ti gubat iti dayta nga aldaw, ket sisasadag ti ari ti Israel iti karwahena a nakasango kadagiti taga-Aram agingga iti rumabii. Idi dandanin a lumnek ti init, natay isuna.

< 2 Chronicles 18 >