< 2 Chronicles 18 >

1 Nísinsin yìí Jehoṣafati sì ní ọrọ̀ àti ọlá púpọ̀, ó sì dá àna pẹ̀lú Ahabu nípa fífẹ́ ọmọ rẹ̀.
És volt Jehósáfátnak gazdagsága s tisztelete bőven; és sógorságra lépett Achábbal.
2 Lẹ́yìn ọjọ́ díẹ̀, ó sọ̀kalẹ̀ láti lọ bá Ahabu lálejò ní Samaria. Ahabu sì pa àgùntàn àti màlúù púpọ̀ fún àti àwọn ènìyàn tí ó wà pẹ̀lú rẹ̀ ó sì rọ̀ ọ́ láti dojú ìjà kọ Ramoti Gileadi.
És évek múltán lement Achábhoz Sómrónba, és Acháb vágott számára juhokat és szarvasmarhát sokat és a vele levő nép számára; és rábeszélte őt, hogy menjen fel Rámót-Gileádba.
3 Ahabu ọba Israẹli sì béèrè lọ́wọ́ ọba Jehoṣafati, ọba Juda pé, “Ṣé ìwọ yóò lọ pẹ̀lú mi sí Ramoti Gileadi?” Jehoṣafati sì dá a lóhùn pé, “Èmi wà gẹ́gẹ́ bí ìwọ ti ṣe wà, àti àwọn ènìyàn mi gẹ́gẹ́ bí ènìyàn rẹ àwa yóò pẹ̀lú rẹ nínú ogun náà”.
És szólt Acháb, Izrael királya, Jehósáfáthoz, Jehúda királyához: Eljössz-e velem Rámót-Gileádba? Mondta neki Én úgy mint te, és úgy mint a te néped az én népem s veled vagyok a háborúban!
4 Ṣùgbọ́n Jehoṣafati náà sì tún wí fún ọba Israẹli pé, “Kọ́kọ́ béèrè lọ́wọ́ Olúwa.”
Majd szólt Jehósáfát Izrael királyához: Kérdezd csak meg ma az Örökkévaló igéjét.
5 Bẹ́ẹ̀ ọba Israẹli kó àwọn wòlíì papọ̀, irinwó ọkùnrin ó sì bi wọ́n pé, “Kí àwa kí lọ sí ogun Ramoti Gileadi tàbí kí èmi kí ó jọ̀wọ́ rẹ?” Wọ́n dáhùn pé, “Lọ, nítorí tí Ọlọ́run yóò fi lé ọba lọ́wọ́.”
És összegyűjtötte Izrael királya a prófétákat, négyszáz embert és szólt hozzájuk: Elmenjünk-e háborúba Rámót-Gileád ellen, vagy abban hagyjam-e? Mondták: Menj fel; adni fogja az Isten a királynak kezébe.
6 Ṣùgbọ́n Jehoṣafati béèrè pé, “Ṣé kò ha sí wòlíì Olúwa níbí ẹni tí àwa ìbá béèrè lọ́wọ́ rẹ̀?”
És mondta Jehósáfát: Nincs-e itt még prófétája az Örökkévalónak, hogy őtőle kérdezhessük?
7 Ọba Israẹli dá Jehoṣafati lóhùn pé, “Ọkùnrin kan wà síbẹ̀ lọ́dọ̀ ẹni tí àwa ìbá tún béèrè lọ́wọ́ Olúwa, ṣùgbọ́n èmi kórìíra rẹ̀ nítorí kò jẹ́ sọ àsọtẹ́lẹ̀ ohun rere kan nípa mi ṣùgbọ́n bí kò ṣe ohun búburú, ní gbogbo ìgbà òun náà ni Mikaiah ọmọ Imla.” Jehoṣafati sì dá lóhùn pé, “Ọba kò gbọdọ̀ sọ bẹ́ẹ̀.”
Szólt Izrael királya Jehósáfáthoz: Még van egy férfiú, akitől megkérdezhetjük az Örökkévalót, de én gyűlölöm őt, mert nem szokott felőlem prófétálni jóra, hanem minden napjaiban rosszra; Mikhájehú, Jimla fia az. Erre szólt Jehósáfát: Ne mondjon ilyent a király.
8 Bẹ́ẹ̀ ni ọba Israẹli pe ọ̀kan lára àwọn ìjòyè ó sì wí pé, “Ẹ mú Mikaiah ọmọ Imla kí ó yára wá.”
Szólított tehát Izrael királya egy udvari tisztet s mondta: Hamar hívd Mikhájehút, Jimla fiát.
9 Wọ́n wọ aṣọ ìgúnwà wọn, ọba Israẹli àti Jehoṣafati ọba Juda wọ́n jókòó sórí ìtẹ́ wọ́n ní ìta ẹnu-bodè Samaria, pẹ̀lú gbogbo àwọn wòlíì tí ń sọtẹ́lẹ̀ níwájú wọn.
Izrael királya pedig meg Jehósáfát, Jehúda királya ültek, kiki a trónján, ruhákba öltözve ültek a szérűn Sómrón kapujának bejáratán és mind a próféták prófétáltak előttük.
10 Nísinsin yìí Sedekiah ọmọ Kenaana sì ti ṣe ìwo irin, ó sì wí pé, “Èyí ni ohun tí Olúwa sọ: ‘Pẹ̀lú èyí ìwọ yóò kan àwọn ará Siria títí ìwọ ó fi pa wọ́n run.’”
És készített magának Czidkijáhú, Kenáana fia, vasszarvakat és mondta: Így szól az Örökkévaló: ezekkel döföd le Arámot, míg meg nem semmisíted.
11 Gbogbo àwọn wòlíì tí ó kù ni wọn ń sọtẹ́lẹ̀ ní àkókò kan náà. Wọ́n sì wí pé, “Dojúkọ Ramoti Gileadi ìwọ yóò sì ṣẹ́gun, nítorí Olúwa yóò fi lé ọba lọ́wọ́.”
Mind a próféták is ekképpen prófétáltak, mondván: Vonulj föl Rámót-Gileádba és légy szerencsés, és adja az Örökkévaló a király kezébe.
12 Ìránṣẹ́ tí ó ti lọ pe Mikaiah sì wí fún un pé, “Ẹ wò ó, gẹ́gẹ́ bí ọkùnrin kan àti òmíràn wòlíì fi ẹnu kan sọ rere fún ọba. Jẹ́ kí ọ̀rọ̀ rẹ kí ó dàbí ọ̀kan nínú tiwọn, kí o sì sọ rere.”
A követ pedig, aki ment hívni Mikhájehút, beszélt hozzá, mondván: Lám, a próféták egyhangúlag jót beszéltek a királyhoz, legyen, kérlek, a te szavad olyan, mint azok egyikéé, hogy jót beszélj.
13 Ṣùgbọ́n Mikaiah wí pe, “Gẹ́gẹ́ bí ó ti dájú pé Olúwa ń bẹ láààyè, èmi yóò sọ ohun tí Ọlọ́run mi sọ.”
De mondta Mikhájehú: Él az Örökkévaló, bizony amit majd szól az Istenem, azt fogom beszélni.
14 Nígbà tí ó dé, ọba béèrè lọ́wọ́ rẹ̀, “Mikaiah, ṣe kí àwa ki ó lọ sí ogun ti Ramoti Gileadi, tàbí kí àwa kí ó fàsẹ́yìn?” Ó sì dáhùn pé, “Ẹ dojúkọ wọ́n kí ẹ sì ṣẹ́gun, nítorí a ó fi wọ́n lé yín lọ́wọ́.”
Erre odament a királyhoz, és szólt hozzá a király: Mikha, elmenjünk-e háborúba Rámót-Gileád ellen, avagy abbahagyjam? Szólt: Menjetek föl és legyetek szerencsések és adassanak kezetekbe.
15 Ọba sì wí fún un pé, “Ìgbà mélòó ni èmi ó fi ọ́ búra láti sọ ohun kan fún mi bí kò ṣe ọ̀rọ̀ òtítọ́ ní orúkọ Olúwa?”
Ekkor szólt hozzá a király: Még hányszor eskesselek meg téged, hogy csupán igazat beszélj hozzám az Örökkévaló nevében?
16 Mikaiah sì dáhùn pé, “Mo rí gbogbo Israẹli túká kiri lórí àwọn òkè bí àgùntàn tí kò ní olùṣọ́, Olúwa sì wí pé, ‘Àwọn wọ̀nyí kò ní olúwa. Jẹ́ kí olúkúlùkù padà sí ilé rẹ̀ ní àlàáfíà.’”
Mondta: Láttam egész Izraelt elszéledve a hegyeken mint a juhok, melyeknek nincs pásztoruk; és szólt az Örökkévaló: nincs ezeknek uruk, menjenek vissza, kiki a házába, békében!
17 Ọba Israẹli wí fún Jehoṣafati pé, “Ṣe èmi kò sọ fún ọ wí pé òun kò sọ àsọtẹ́lẹ̀ rere kankan nípa mi rí, ṣùgbọ́n búburú nìkan?”
Ekkor szólt Izrael királya Jehósáfáthoz: Nemde mondtam neked, nem fog ez rólam jót prófétálni, hanem csak rosszat!
18 Mikaiah tẹ̀síwájú pé, “Nítorí náà, gbọ́ ọ̀rọ̀ Olúwa, mo rí Olúwa jókòó lórí ìtẹ́ rẹ̀ gbogbo ogun ọ̀run sì dúró lápá ọ̀tún àti lápá òsì.
És szólt: Azért halljátok az Örökkévaló igéjét: Láttam az Örökkévalót, ülve a trónján és az égnek egész serege áll jobbjáról s baljáról.
19 Olúwa sì wí pé, ‘Ta ni yóò tan Ahabu ọba Israẹli lọ sí Ramoti Gileadi kí ó sì lọ kú ikú rẹ̀ níbẹ̀?’ “Èkínní sì sọ tìhín, òmíràn sì sọ tọ̀hún.
És mondta az Örökkévaló: Ki beszélné rá Achábot, Izrael királyát, hogy fölvonuljon és elessék Rámót-Gileádban? És szólt – az egyik imígy szólt vala, a másik meg amúgy szólt.
20 Ní ìparí, ni ẹ̀mí kan wá síwájú, ó dúró níwájú Olúwa ó sì wí pé, ‘Èmi yóò tàn án.’ “‘Nípa ọ̀nà wo?’ Olúwa béèrè.
Erre kilépett egy szellem, az Örökkévaló eléállt a mondta: Én beszélem rá! És szólt hozzá az Örökkévaló: Mivel?
21 “‘Èmi yóò lọ láti lọ di ẹ̀mí èké ní ẹnu gbogbo àwọn wòlíì.’ “‘Ìwọ yóò sì borí nínú ìtànjẹ rẹ̀ báyìí,’ ni Olúwa wí. ‘Lọ kí ó sì ṣe bẹ́ẹ̀.’
Mondta: Kimegyek és leszek hazug szellemmé mind az ő prófétáinak szájában. És mondta: Rá fogod beszélni és győzni is fogsz; menj ki és cselekedjél ekképpen!
22 “Bẹ́ẹ̀ ni nísinsin yìí Olúwa ti fi ẹ̀mí èké sí ẹnu àwọn wòlíì rẹ. Olúwa sì ti sọ ibi sí ọ.”
Most tehát íme adott az Örökkévaló hazug szellemet mind a prófétáid szájába, holott az Örökkévaló veszedelmet mondott ki rád.
23 Nígbà náà Sedekiah ọmọ Kenaana lọ sókè ó sì gbá Mikaiah ní ojú. Ó sì béèrè pé, “Ní ọ̀nà wo ni ẹ̀mí Olúwa gbà kọjá lọ kúrò lọ́dọ̀ mi láti bá ọ sọ̀rọ̀?”
Erre odalépett Czidkijáhú, Kenáana fia, és arcul ütötte Mikhájehút és mondta: Mely úton szállt el az Örökkévaló szelleme én tőlem, hogy veled beszéljen?
24 Mikaiah sì dáhùn pé, “Ìwọ yóò ṣe ìwádìí ní ọjọ́ tí ìwọ yóò sá pamọ́ sínú ìyẹ̀wù.”
Mondta Mikhájehú: Ám majd látod ama napon, midőn szobából szobába mész, hogy elrejtőzzél.
25 Ọba Israẹli pa á láṣẹ pé, “Mú Mikaiah kí o sì ran padà sí Amoni olórí ìlú àti sí Joaṣi ọmọ ọba,
Ekkor szólt Izrael királya: Vegyétek Mikhájehút és vezessétek vissza Ámónhoz, a város nagyjához, és Jóáshoz, a király fiához;
26 Ó sì wí pé, ‘Èyí ni ohun tí ọba sọ, ẹ fi ènìyàn yìí sínú túbú kí ẹ má sì ṣe fún un ní ohunkóhun ṣùgbọ́n àkàrà àti omi títí tí èmi yóò fi dé ní àlàáfíà.’”
s mondjátok: így szól a király, vessétek ezt a fogházba s adjatok neki enni szűken kenyeret és szűken vizet, míg visszatérek békében.
27 Mikaiah sì wí pe, “Tí ìwọ bá padà ní àlàáfíà, Olúwa kò sọ̀rọ̀ láti ọ̀dọ̀ mi.” Nígbà náà, ó sì fi kún un pé, “Ẹ gbọ́ ọ̀rọ̀ mi, gbogbo ẹ̀yin ènìyàn!”
Ekkor szólt Mikhájehú: Ha békében fogsz visszatérni, nem az Örökkévaló beszélt általam. És szólt: halljátok ti népek mind!
28 Bẹ́ẹ̀ ni ọba Israẹli àti Jehoṣafati ọba Juda lọ sókè ní Ramoti Gileadi.
Fölvonult tehát Izrael királya meg Jehósáfát Jehúda királya, Rámót-Gileádba.
29 Ọba Israẹli sọ fún Jehoṣafati pé, “Èmi yóò lọ sí ojú ìjà, ṣùgbọ́n ìwọ wọ aṣọ ìgúnwà rẹ.” Bẹ́ẹ̀ ni ọba Israẹli pa aṣọ rẹ̀ dà, ó sì lọ sí ojú ìjà.
És szólt Izrael királya Jehósáfáthoz: Elmásítván magamat, megyek a harcba, te meg öltsd fel a magad ruháit. És elmásította magát Izrael királya s a harcba mentek.
30 Nísinsin yìí ọba Siria ti pàṣẹ fún àwọn olórí kẹ̀kẹ́ tí ó wà ní ọ̀dọ̀ rẹ̀ pé, “Ẹ má ṣe jà pẹ̀lú ẹnìkankan, èwe tàbí àgbà àyàfi ọba Israẹli.”
Arám királya azonban megparancsolta volt az ő szekérhada vezéreinek, mondván: Ne harcoljatok kicsinnyel, naggyal, hanem egyedül Izrael királyával.
31 Nígbà tí àwọn olórí kẹ̀kẹ́ rí Jehoṣafati, wọ́n rò wí pé, “Èyí ní ọba Israẹli.” Bẹ́ẹ̀ ni wọ́n sì yípadà láti bá a jà. Ṣùgbọ́n Jehoṣafati kégbe sókè, Olúwa sì ràn án lọ́wọ́. Ọlọ́run sì lé wọn kúrò lọ́dọ̀ rẹ̀,
És volt, amint meglátták a szekérhad vezérei Jehósáfátot, azt mondták: bizony Izrael királya az, és körülfogták őt, hogy harcoljanak vele. Ekkor fölsikoltott Jehósáfát, és az Örökkévaló megsegítette őt, és eltérítette Isten őket tőle.
32 Ó sì ṣe, nígbà tí olórí kẹ̀kẹ́ rí i wí pé kì í ṣe ọba Israẹli, wọ́n sì dáwọ́ lílé rẹ̀ dúró.
És volt, amint látták a szekérhad vezérei, hogy nem Izrael királya az, elfordultak tőle.
33 Ṣùgbọ́n ẹnìkan fa ọrun rẹ̀ láì pète, ó sì bá ọba Israẹli láàrín ìpàdé ẹ̀wù irin, ọba sì sọ fún olùtọ́jú kẹ̀kẹ́ rẹ̀ pé, “Yí ọwọ́ rẹ padà, kí o sì wà mí jáde kúrò lójú ìjà. Nítorí èmi ti gbọgbẹ́.”
Egy ember pedig jóhiszemben meghúzta íját és eltalálta Izrael királyát a kapcsok és a páncél között. Ekkor azt mondta a szekérhajtónak: Fordítsd meg kezedet és vigyél ki a táborból, mert megsebesültem.
34 Ní ọjọ́ pípẹ́, ìjà náà sì ń pọ̀ sí i, ọba Israẹli dúró nínú kẹ̀kẹ́ rẹ̀ kọjú sí àwọn ará Siria títí ó fi di àṣálẹ́. Lẹ́yìn náà ní àkókò ìwọ oòrùn, ó sì kú.
És nekihevesedett a harc ama napon, Izrael királya pedig állva marad a kocsiban Arámmal szemben estig; és meghalt a nap lenyugta idején.

< 2 Chronicles 18 >